< Mika 7 >
1 Vay halime benim! Yazın meyve toplandıktan Ve bağbozumundan artakalan üzümler alındıktan sonra Tek bir salkım bulamayan adam gibiyim. Canım turfanda inciri nasıl da çekiyor!
Ègbé ni fún mi! Nítorí èmi sì dàbí ẹni tí ń kó èso ẹ̀ẹ̀rùn jọ, ìpèsè ọgbà àjàrà; kò sì ṣí odidi àjàrà kankan láti jẹ, kò sì ṣí àkọ́so ọ̀pọ̀tọ́ nítorí tí ebi ń pa mí.
2 Ülkede Tanrı'ya sadık kul kalmadı. İnsanlar arasında dürüst kimse yok. Herkes kan dökmek için pusuda. Kardeş kardeşe tuzak kuruyor.
Àwọn olódodo sì ti kúrò ní ilẹ̀ náà, kò sì ṣí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù tí ó jọ olóòtítọ́; gbogbo wọn sì ń purọ́ ní dídúró nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀, olúkúlùkù wọ́n sì ń fi àwọ̀n de arákùnrin rẹ̀.
3 Kötülük yapmakta elleri ne becerikli! Önderler armağan istiyor, yargıçlar rüşvet alıyor. Güçlüler her istediklerini zorla yaptırıyor, Düzen üstüne düzen kuruyorlar.
Ọwọ́ wọn méjèèjì ti múra tán láti ṣe búburú; àwọn alákòóso ń béèrè fún ẹ̀bùn, àwọn onídàájọ́ sì ń gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ alágbára sì ń pàṣẹ ohun tí wọ́n fẹ́, gbogbo wọn sì jùmọ̀ ń dìtẹ̀.
4 En iyileri çalı çırpıdan değersiz, En dürüstleri dikenli çitten beterdir. Ama peygamberlerinin uyardığı gibi, Cezalandırılacakları gün geldi çattı. Şaşkınlık içindeler şimdi.
Ẹni tí ó sàn jùlọ nínú wọn sì dàbí ẹ̀gún, ẹni tí ó jẹ́ olódodo jùlọ burú ju ẹ̀gún ọgbà lọ. Ọjọ́ àwọn olùṣọ́ rẹ̀ ti dé, àti ọjọ́ tí Ọlọ́run bẹ̀ ọ́ wò. Nísinsin yìí ní àkókò ìdààmú wọn.
5 İnanmayın komşunuza, Dostunuza güvenmeyin. Koynunuzda yatan karınızın yanında bile Sıkı tutun ağzınızı.
Ẹ má ṣe gba ọ̀rẹ́ kan gbọ́; ẹ má sì ṣe gbẹ́kẹ̀lé amọ̀nà kankan. Pa ìlẹ̀kùn ẹnu rẹ fún ẹni tí ó sùn ní oókan àyà rẹ.
6 Çünkü oğul babasına saygısızlık ediyor, Kız annesine, gelin kaynanasına karşı geliyor. İnsanın düşmanı kendi ev halkıdır.
Nítorí tí ọmọkùnrin kò bọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọbìnrin sì dìde sí ìyá rẹ̀, aya ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀, ọ̀tá olúkúlùkù ni àwọn ará ilé rẹ̀.
7 Ama ben umutla RAB'be bakıyor, Kurtarıcım olan Tanrı'yı bekliyorum. Duyacak beni Tanrım.
Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi ní ìwòye ní ìrètí sí Olúwa, èmi dúró de Ọlọ́run olùgbàlà mi; Ọlọ́run mi yóò sì tẹ́tí sí mi.
8 Halime sevinme, ey düşmanım! Düşsem de kalkarım. Karanlıkta kalsam bile RAB bana ışık olur.
Má ṣe yọ̀ mí, ìwọ ọ̀tá mi. Bí mó bá ṣubú, èmi yóò dìde. Nígbà tí mo bá jókòó sínú òkùnkùn Olúwa yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ fún mi.
9 RAB'be karşı günah işlediğim için, O'nun öfkesine dayanmalıyım. Sonunda davamı savunup hakkımı alacak, Beni ışığa çıkaracak, adaletini göreceğim.
Nítorí èmi ti dẹ́ṣẹ̀ sí i, èmi yóò faradà ìbínú Olúwa, títí òun yóò ṣe gba ẹjọ́ mi rò, tí yóò sì ṣe ìdájọ́ mi. Òun yóò sì mú mi wá sínú ìmọ́lẹ̀; èmi yóò sì rí òdodo rẹ̀.
10 Düşmanım da görecek ve utanç içinde kalacak. O düşman ki, “Hani Tanrın RAB nerede?” diye soruyordu bana. Onun düşüşünü gözlerimle göreceğim. Sokaktaki çamur gibi ayak altında çiğnenecek.
Nígbà náà ni ọ̀tá mi yóò rí i ìtìjú yóò sì bo ẹni tí ó wí fún mi pé, “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wà?” Ojú mi yóò rí ìṣubú rẹ̀; nísinsin yìí ni yóò di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ òpópó.
11 Ey Yeruşalim, Surlarının onarılacağı, Sınırlarının genişletileceği gün gelecek.
Ọjọ́ tí a ó mọ odi rẹ yóò dé, ọjọ́ náà ni àṣẹ yóò jìnnà réré.
12 Halkımızdan olanlar o gün Asur'dan Mısır'a, Mısır'dan Fırat'a kadar uzanan topraklardan, Denizler arasında, dağlar arasında kalan topraklardan sana gelecekler.
Ní ọjọ́ náà àwọn ènìyàn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ láti Asiria àti ìlú ńlá Ejibiti àní láti Ejibiti dé Eufurate láti Òkun dé Òkun àti láti òkè ńlá dé òkè ńlá.
13 Ama ülke, içinde yaşayanların yaptığı kötülükler yüzünden viraneye dönecek.
Ilẹ̀ náà yóò di ahoro fún àwọn olùgbé inú rẹ̀, nítorí èso ìwà wọn.
14 Ya RAB, mirasın olan Ve Karmel'in ortasındaki ormanda ayrı yaşayan sürünü, halkını Değneğinle güt. Geçmişte olduğu gibi, Başan'da ve Gilat'ta beslensinler.
Fi ọ̀pá rẹ bọ́ àwọn ènìyàn, agbo ẹran ìní rẹ, èyí tí ó ń dágbé nínú igbó ní àárín Karmeli. Jẹ́ kí wọn jẹun ní Baṣani àti Gileadi bí ọjọ́ ìgbàanì.
15 Bizi Mısır'dan çıkardığın günlerdeki gibi, Harikalar yarat halkın için.
“Bí i ọjọ́ tí ó jáde kúrò ní Ejibiti wá, ni èmi yóò fi ohun ìyanu hàn án.”
16 Uluslar bunu görünce Yaptıkları bunca zorbalıktan utanacaklar. Elleriyle ağızlarını kapayacak, kulaklarını tıkayacaklar.
Orílẹ̀-èdè yóò rí i, ojú yóò sì tì wọ́n, nínú gbogbo agbára wọn. Wọn yóò fi ọwọ́ lé ẹnu wọn, etí wọn yóò sì di.
17 Yılanlar gibi, sürüngenler gibi toprak yalayacak, Titreyerek sığınaklarından çıkacaklar. Ey Tanrımız RAB, dehşet içinde sana dönecek Ve senden korkacaklar.
Wọn yóò lá erùpẹ̀ bí ejò, wọn yóò sì jáde kúrò nínú ihò wọn bí ekòló. Wọn yóò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, wọn yóò sì bẹ̀rù nítorí rẹ̀.
18 Senin gibi suçları silen, Kendi halkından geride kalanların isyanlarını bağışlayan başka tanrı var mı? Sonsuza dek öfkeli kalmazsın, Çünkü merhametten hoşlanırsın.
Ta ni Ọlọ́run bí rẹ̀, ẹni tí ó dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì, tí ó sì fojú fo ìrékọjá èyí tókù ìní rẹ̀? Kì í dúró nínú ìbínú rẹ̀ láéláé nítorí òun ní inú dídùn sí àánú.
19 Bize yine acıyacaksın, Çiğneyeceksin suçlarımızı ayak altında. Bütün günahlarımızı denizin dibine atacaksın.
Òun yóò tún padà yọ́nú sí wa; òun yóò tẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa mọ́lẹ̀, yóò sì fa gbogbo àìṣedéédéé wa sínú ibú Òkun.
20 Geçmişte atalarımıza ant içtiğin gibi, Yakup'un ve İbrahim'in torunları olan bizlere de Verdiğin sözü tutacak ve sadık kalacaksın.
Ìwọ yóò fi òtítọ́ hàn sí Jakọbu ìwọ yóò sì fi àánú hàn sí Abrahamu, bí ìwọ ṣe búra fún àwọn baba wa láti ọjọ́ ìgbàanì.