< Yeşu 23 >
1 RAB İsrail'i çevresindeki bütün düşmanlarından kurtarıp esenliğe kavuşturdu. Aradan uzun zaman geçmişti. Yeşu kocamış, yaşı hayli ilerlemişti.
Lẹ́yìn ọjọ́ pípẹ́, nígbà tí Olúwa sì ti fún Israẹli ní ìsinmi kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká, nígbà náà Joṣua sì ti di arúgbó.
2 Bu nedenle ileri gelenleri, boy başlarını, hâkimleri, görevlileri, bütün İsrail halkını topladı. Onlara, “Kocadım, yaşım hayli ilerledi” dedi,
Ó sì pe gbogbo Israẹli jọ: àgbàgbà wọn, olórí wọn, adájọ́ àti àwọn ìjòyè, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti pọ̀ ní ọdún èmi ti di arúgbó.
3 “Tanrınız RAB'bin sizin yararınıza bütün bu uluslara neler yaptığını gördünüz. Çünkü sizin için savaşan Tanrınız RAB'di.
Ẹ̀yin tìkára yín sì ti rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí nítorí yín, Olúwa Ọlọ́run yín ni ó jà fún yín.
4 İşte Şeria Irmağı'ndan gün batısındaki Akdeniz'e dek yok ettiğim bütün bu uluslarla birlikte, geri kalan ulusların topraklarını da kurayla oymaklarınıza mülk olarak böldüm.
Ẹ rántí bí mo ṣe pín ogún ìní fún àwọn ẹ̀yà yín ní ilẹ̀ orílẹ̀-èdè gbogbo tí ó kù; àwọn orílẹ̀-èdè tí mo ti ṣẹ́gun ní àárín Jordani àti Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
5 Tanrınız RAB bu ulusları önünüzden püskürtüp sürecektir. Tanrınız RAB'bin size söz verdiği gibi, onların topraklarını mülk edineceksiniz.
Olúwa Ọlọ́run yín fúnra rẹ̀ yóò lé wọn jáde kúrò ní ọ̀nà yín, yóò sì tì wọ́n jáde ní iwájú yín, ẹ̀yin yóò sì gba ilẹ̀ ìní wọn, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún yín.
6 Musa'nın Yasa Kitabı'nda yazılı olan her şeyi korumak ve yerine getirmek için çok güçlü olun. Yazılanlardan sağa sola sapmayın.
“Ẹ jẹ́ alágbára gidigidi, kí ẹ sì ṣọ́ra láti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun tí a kọ sí inú ìwé òfin Mose, láìyí padà sí ọ̀tún tàbí sí òsì.
7 Aranızda kalan uluslarla hiçbir ilişkiniz olmasın; ilahlarının adını anmayın; kimseye onların adıyla ant içirmeyin; onlara kulluk edip tapmayın.
Ẹ má ṣe ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ṣẹ́kù láàrín yín; ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà wọn tàbí kí ẹ fi wọ́n búra. Ẹ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n tàbí ki ẹ tẹríba fún wọn.
8 Bugüne dek yaptığınız gibi, Tanrınız RAB'be sımsıkı bağlı kalın.
Ṣùgbọ́n ẹ di Olúwa Ọlọ́run yín mú ṣinṣin gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ń ṣe tẹ́lẹ̀ títí di àkókò yìí.
9 Çünkü RAB büyük ve güçlü ulusları önünüzden sürdü. Bugüne dek hiçbiri önünüzde tutunamadı.
“Olúwa ti lé àwọn orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára kúrò níwájú yín; títí di òní yìí kò sí ẹnìkan tí ó le dojúkọ yín.
10 Biriniz bin kişiyi kovalayacak. Çünkü Tanrınız RAB, size söylediği gibi, yerinize savaşacak.
Ọ̀kan nínú yín lé ẹgbẹ̀rún ọ̀tá, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín jà fún yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí.
11 Bunun için Tanrınız RAB'bi sevmeye çok dikkat edin.
Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ ṣọ́ra gidigidi láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín.
12 Çünkü O'na sırt çevirir, sağ kalıp aranızda yaşayan bu uluslarla birlik olur, onlara kız verip onlardan kız alır, onlarla oturup kalkarsanız,
“Ṣùgbọ́n bí ẹ bá yí padà, tí ẹ sì gba ìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú àwọn tó ṣẹ́kù lára àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù láàrín yín, tí ẹ sì ń fọmọ fún ara yín ní ìyàwó, tí ẹ sì bá wọn ní àjọṣepọ̀.
13 iyi bilin ki, Tanrınız RAB bu ulusları artık önünüzden sürmeyecek. Ve sizler Tanrınız RAB'bin size verdiği bu güzel topraklardan yok oluncaya dek bu uluslar sizin için tuzak, kapan, sırtınızda kırbaç, gözlerinizde diken olacaklar.
Nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ dájú pé Olúwa Ọlọ́run yín kì yóò lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde mọ́ kúrò níwájú yín. Dípò èyí, wọn yóò jẹ́ ìkẹ́kùn àti tàkúté fún un yín, pàṣán ní ẹ̀yin yín àti ẹ̀gún ní ojú yín, títí ẹ ó fi ṣègbé kúrò ní ilẹ̀ dáradára yí, èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fi fún yín.
14 “İşte her insan gibi ben de bu dünyadan göçüp gitmek üzereyim. Bütün varlığınızla ve yüreğinizle biliyorsunuz ki, Tanrınız RAB'bin size verdiği sözlerden hiçbiri boş çıkmadı; hepsi gerçekleşti, boş çıkan olmadı.
“Nísinsin yìí èmi ti fẹ́ máa lọ sí ibi tí àwọn àgbà ń rè. Ẹ mọ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti àyà yín pé, kò sí ohun kan tí ó kùnà nínú àwọn ìlérí rere gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín. Gbogbo ìlérí tó ti ṣe kò sí ọ̀kan tí ó kùnà.
15 Tanrınız RAB'bin size verdiği sözlerin tümü nasıl gerçekleştiyse, Tanrınız RAB verdiği bu güzel topraklardan sizi yok edene dek sözünü ettiği bütün kötülükleri de öylece başınıza getirecektir.
Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí ìlérí dáradára gbogbo ti Olúwa Ọlọ́run yín ti wá sí ìmúṣẹ, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò mú ibi gbogbo tí ó ti kìlọ̀ wá sí orí yín, títí yóò fi pa yín run kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.
16 Tanrınız RAB'bin size buyurduğu antlaşmayı bozarsanız, gidip başka ilahlara kulluk eder, taparsanız, RAB'bin öfkesi size karşı alevlenecek; RAB'bin size verdiği bu güzel ülkeden çabucak yok olup gideceksiniz.”
Bí ẹ bá sẹ̀ sí májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín, èyí tí ó pàṣẹ fún un yín, tí ẹ bá sì lọ tí ẹ sì sin àwọn òrìṣà tí ẹ sì tẹ orí ba fún wọn, ìbínú gbígbóná Olúwa yóò wá sórí i yín, ẹ̀yin yóò sì ṣègbé kíákíá kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.”