< Yeşu 2 >
1 Nun oğlu Yeşu Şittim'den gizlice iki casus gönderdi. “Gidip ülkeyi, özellikle de Eriha'yı araştırın” dedi. Böylece yola çıkan casuslar, Rahav adında bir fahişenin evine gidip geceyi orada geçirdiler.
Nígbà náà ni Joṣua ọmọ Nuni rán àwọn ayọ́lẹ̀wò méjì jáde ní àṣírí láti Ṣittimu. Ó sì wí pé, “Ẹ lọ wo ilẹ̀ náà, pàápàá Jeriko.” Wọ́n sì lọ, wọ́n wọ ilé panṣágà kan, tí à ń pè ní Rahabu wọ́n sì dúró síbẹ̀.
2 Bu arada Eriha Kralı'na, “Ülkemizi araştırmak üzere bu gece İsrail halkından buraya adamlar geldi” diye haber verildi.
A sì sọ fún ọba Jeriko, “Wò ó! Àwọn ará Israẹli kan wá ibí ní alẹ́ yìí láti wá yọ́ ilẹ̀ yí wò.”
3 Bunun üzerine Eriha Kralı, Rahav'a, “Sana gelip evinde kalan o adamları dışarı çıkar” diye haber gönderdi, “Çünkü onlar ülkemizi araştırmak için geldiler.”
Ọba Jeriko sì ránṣẹ́ sí Rahabu pé, “Mú àwọn ọkùnrin nì tí ó tọ̀ ọ́ wá, tí ó wọ inú ilé rẹ jáde wá, nítorí wọ́n wá láti yọ́ gbogbo ilẹ̀ yìí wò ni.”
4 İki adamı saklamış olan Rahav, “Adamların bana geldikleri doğru” dedi, “Ama ben nereli olduklarını bilmiyordum.
Ṣùgbọ́n obìnrin náà ti mú àwọn ọkùnrin méjì náà o sì fi wọ́n pamọ́. Ó sì wí pé, “Lóòtítọ́ ní àwọn ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ibi tí wọ́n ti wá.
5 Karanlık basar basmaz, kentin kapısı kapanmak üzereyken çıktılar. Nereye gittiklerini bilmiyorum. Hemen peşlerinden giderseniz yetişirsiniz.”
Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, nígbà tí ó tó àkókò láti ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè, àwọn ọkùnrin náà sì jáde lọ. Èmi kò sì mọ ọ̀nà tí wọ́n gbà lọ. Ẹ lépa wọn kíákíá. Ẹ̀yin yóò bá wọn.”
6 Aslında kadın onları dama çıkarmış, oraya sermiş olduğu keten saplarının altına gizlemişti.
(Ṣùgbọ́n ó ti mú wọn gòkè àjà ó sì fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ pòròpòrò ọkà tó tò jọ sí orí àjà.)
7 Kralın adamlarıysa casusları Şeria Irmağı'nın geçitlerine giden yol boyunca kovaladılar. Onlar kentten çıkar çıkmaz kapı sürgülenmişti.
Àwọn ọkùnrin náà jáde lọ láti lépa àwọn ayọ́lẹ̀wò náà ní ọ̀nà tí ó lọ sí ìwọdò Jordani, bí àwọn tí ń lépa wọn sì ti jáde, wọ́n ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè.
8 Damdaki adamlar yatmadan önce kadın yanlarına çıktı.
Kí àwọn ayọ́lẹ̀wò náà tó sùn ní alẹ́, ó gòkè tọ̀ wọ́n lọ lókè àjà.
9 “RAB'bin bu ülkeyi size verdiğini biliyorum” dedi, “Sizden ötürü dehşete kapıldık; ülkede yaşayan herkesin korkudan dizlerinin bağı çözüldü.
Ó sì sọ fún wọn, “Èmi mọ̀ pé Olúwa ti fún un yín ní ilẹ̀ yìí àti pé ẹ̀rù u yín ti sọ wá di ojo dé ibi pé ìdí gbogbo àwọn tí ó n gbé ilẹ̀ yìí ti di omi nítorí i yín.
10 Çünkü Mısır'dan çıktığınızda RAB'bin Kamış Denizi'ni önünüzde nasıl kuruttuğunu, Şeria Irmağı'nın ötesindeki Amorlu iki krala –Sihon ve Og'a– neler yaptığınızı, onları nasıl yok ettiğinizi duyduk.
Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Sihoni àti Ogu, àwọn ọba méjèèjì ti Amori ti ìlà-oòrùn Jordani, tí ẹ̀yin parun pátápátá.
11 Bunları duyduğumuzda korkudan dizlerimizin bağı çözüldü. Sizin korkunuzdan kimsede derman kalmadı. Çünkü Tanrınız RAB hem yukarıda göklerde, hem de aşağıda yeryüzünde Tanrı'dır.
Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ọkàn wa pami kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé.
12 Size iyilik ettiğim gibi, siz de aileme iyilik edeceğinize lütfen RAB adına ant için. Annemi, babamı, erkek ve kız kardeşlerimle ailelerini ölümden kurtarıp hepimizi sağ bırakacağınıza ilişkin bana güvenilir bir işaret verin.”
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ jọ̀wọ́ ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ̀yin yóò fún mi ní àmì tó dájú:
pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábìnrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”
14 Adamlar, “Eğer bu yaptıklarımızı açığa vurmazsanız, yerinize ölmeye hazırız” dediler, “RAB bu ülkeyi bize verdiğinde sana iyilik edip sözümüzü tutacağız.”
“Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”
15 Kent surlarında bir evde oturan Rahav, adamları iple pencereden aşağı indirdi.
Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú.
16 Onlara, “Dağa çıkın, yoksa sizi kovalayanlarla karşılaşabilirsiniz” dedi, “Onlar dönene kadar üç gün orada saklanın. Sonra yolunuza devam edersiniz.”
Ó sì ti sọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má ba à rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”
17 Adamlar Rahav'a, “Bize içirdiğin andı tutmasına tutarız” dediler,
Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa ba à lè mọ́ kúrò nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí.
18 “Ama ülkeye girdiğimizde şu kırmızı ipi bizi indirdiğin pencereye bağla. Anneni, babanı, kardeşlerinle babanın bütün ev halkını yanına, kendi evine topla.
Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò so okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ.
19 Evinin kapısından dışarıya çıkan, kendi kanından sorumlu olacak; böyle biri için sorumluluk kabul etmeyiz. Ama seninle birlikte evinde olan herhangi birine gelecek zarardan biz sorumluyuz.
Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án.
20 Ancak bu yaptıklarımızı açığa vurursan, içirdiğin ant bizi bağlamaz.”
Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò bọ́ nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú.”
21 Kadın, “Dediğiniz gibi olsun” diye karşılık verdi. Onları yola çıkarıp uğurladıktan sonra kırmızı ipi pencereye bağladı.
Ó dáhùn pé, “Ó dára bẹ́ẹ̀. Ẹ jẹ́ kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí sọ.” Ó sì rán wọn lọ wọ́n sì lọ. Ó sì so okùn òdòdó náà sí ojú fèrèsé.
22 Adamlar ayrılıp dağa çıktılar; kendilerini kovalayanlar dönünceye dek üç gün orada kaldılar. Kovalayanlar yol boyu onları aradılarsa da bulamadılar.
Nígbà tí wọ́n kúrò, wọ́n sì lọ sí orí òkè wọ́n sì dúró ní ibẹ̀ ní ọjọ́ mẹ́ta, títí àwọn alépa fi wá wọn ní gbogbo ọ̀nà wọ́n sì padà láìrí wọn.
23 İki adam geri dönmek üzere dağdan indi. Irmağı geçip Nun oğlu Yeşu'nun yanına vardılar ve başlarından geçen her şeyi ona anlattılar.
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin méjì náà padà. Wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, wọ odò, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ọmọ Nuni wọ́n sì sọ fún un gbogbo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wọn.
24 Yeşu'ya, “RAB gerçekten bütün ülkeyi elimize teslim etti” dediler, “Orada yaşayan herkesin korkudan dizlerinin bağı çözüldü.”
Wọ́n sì sọ fún Joṣua, “Nítòótọ́ ni Olúwa tí fi gbogbo ilẹ̀ náà lé wa lọ́wọ́; gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà ni ìbẹ̀rùbojo ti mú nítorí i wa.”