< Eyüp 21 >

1 Eyüp şöyle yanıtladı:
Jobu wá dáhùn, ó sì wí pé,
2 “Sözümü dikkatle dinleyin, Bana verdiğiniz avuntu bu olsun.
“Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ dáradára sì àwọn ọ̀rọ̀ mi, kí èyí kí ó jásí ìtùnú fún mi.
3 Bırakın ben de konuşayım, Ben konuştuktan sonra alay edin.
Ẹ jọ̀wọ́ mi ki èmi sọ̀rọ̀; lẹ́yìn ìgbà ìwọ le máa fi mi ṣẹ̀sín ń ṣo.
4 “Yakınmam insana mı karşı? Niçin sabırsızlanmayayım?
“Àròyé mi ha ṣe sí ènìyàn bí? Èétise tí ọkàn mi kì yóò fi ṣe àìbalẹ̀?
5 Bana bakın da şaşın, Elinizi ağzınıza koyun.
Ẹ wò mí fín, kí ẹnu kí ó sì yà yín, kí ẹ sì fi ọwọ́ lé ẹnu yín.
6 Bunu düşündükçe içimi korku sarıyor, Bedenimi titreme alıyor.
Àní nígbà tí mo rántí, ẹ̀rù bà mí, ìwárìrì sì mú mi lára.
7 Kötüler niçin yaşıyor, Yaşlandıkça güçleri artıyor?
Nítorí kí ní ènìyàn búburú fi wà ní ayé, tí wọ́n gbó, àní tí wọ́n di alágbára ní ipa?
8 Çocukları sapasağlam çevrelerinde, Soyları gözlerinin önünde.
Irú-ọmọ wọn fi ìdí kalẹ̀ ní ojú wọn pẹ̀lú wọn, àti ọmọ ọmọ wọn ní ojú wọn.
9 Evleri güvenlik içinde, korkudan uzak, Tanrı'nın sopası onlara dokunmuyor.
Ilé wọn wà láìní ewu àti ẹ̀rù, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá ìbínú Ọlọ́run kò sí lára wọn.
10 Boğalarının çiftleşmesi hiç boşa çıkmaz, İnekleri hep doğurur, hiç düşük yapmaz.
Akọ màlúù wọn a máa gùn, kì í sì tàsé; abo màlúù wọn a máa bí, kì í sì í ṣẹ́yun.
11 Çocuklarını sürü gibi salıverirler, Yavruları oynaşır.
Wọn a máa rán àwọn ọmọ wọn wẹ́wẹ́ jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa jo kiri.
12 Tef ve lir eşliğinde şarkı söyler, Ney sesiyle eğlenirler.
Wọ́n mú ohun ọ̀nà orin, ìlù àti haapu; wọ́n sì ń yọ̀ sí ohùn fèrè.
13 Ömürlerini bolluk içinde geçirir, Esenlik içinde ölüler diyarına inerler. (Sheol h7585)
Wọ́n n lo ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọn sì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà. (Sheol h7585)
14 Tanrı'ya, ‘Bizden uzak dur!’ derler, ‘Yolunu öğrenmek istemiyoruz.
Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa!’ Nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ.
15 Her Şeye Gücü Yeten kim ki, O'na kulluk edelim? Ne kazancımız olur O'na dua etsek?’
Kí ni Olódùmarè tí àwa ó fi máa sìn in? Èrè kí ni a ó sì jẹ bí àwa ba gbàdúrà sí i?
16 Ama zenginlikleri kendi ellerinde değil. Kötülerin öğüdü benden uzak olsun.
Kíyèsi i, àlàáfíà wọn kò sí nípa ọwọ́ wọn; ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi réré.
17 “Kaç kez kötülerin kandili söndü, Başlarına felaket geldi, Tanrı öfkelendiğinde paylarına düşen kederi verdi?
“Ìgbà mélòó mélòó ní a ń pa fìtílà ènìyàn búburú kú? Ìgbà mélòó mélòó ní ìparun wọn dé bá wọn, tí Ọlọ́run sì í máa pín ìbìnújẹ́ nínú ìbínú rẹ̀?
18 Kaç kez rüzgarın sürüklediği saman gibi, Kasırganın uçurduğu saman çöpü gibi oldular?
Wọ́n dàbí àgékù koríko níwájú afẹ́fẹ́, àti bí ìyàngbò, tí ẹ̀fúùfù ńlá fẹ́ lọ.
19 ‘Tanrı babaların cezasını çocuklarına çektirir’ diyorsunuz, Kendilerine çektirsin de bilsinler nasıl olduğunu.
Ẹ̀yin wí pé, ‘Ọlọ́run to ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jọ fún àwọn ọmọ rẹ̀.’ Jẹ́ kí ó san án fún un, yóò sì mọ̀ ọ́n.
20 Yıkımlarını kendi gözleriyle görsünler, Her Şeye Gücü Yeten'in gazabını içsinler.
Ojú rẹ̀ yóò rí ìparun ara rẹ̀, yóò sì máa mu nínú ríru ìbínú Olódùmarè.
21 Çünkü sayılı ayları sona erince Geride bıraktıkları aileleri için niye kaygı çeksinler?
Nítorí pé àlàáfíà kí ni ó ní nínú ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí a bá ké iye oṣù rẹ̀ kúrò ní agbede-méjì?
22 “En yüksektekileri bile yargılayan Tanrı'ya Kim akıl öğretebilir?
“Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni le kọ Ọlọ́run ní ìmọ̀? Òun ní í sá à ń ṣe ìdájọ́ ẹni ibi gíga.
23 Biri gücünün doruğunda ölür, Büsbütün rahat ve kaygısız.
Ẹnìkan a kú nínú pípé agbára rẹ̀, ó wà nínú ìrora àti ìdákẹ́ pátápátá.
24 Bedeni iyi beslenmiş, İlikleri dolu.
Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú, egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.
25 Ötekiyse acı içinde ölür, İyilik nedir hiç tatmamıştır.
Ẹlòmíràn a sì kú nínú kíkorò ọkàn rẹ̀, tí kò sì fi inú dídùn jẹun.
26 Toprakta birlikte yatarlar, Üzerlerini kurt kaplar.
Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínú erùpẹ̀, kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.
27 “Bakın, düşüncelerinizi, Bana zarar vermek için kurduğunuz düzenleri biliyorum.
“Kíyèsi i, èmi mọ̀ èrò inú yín àti àrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.
28 ‘Büyük adamın evi nerede?’ diyorsunuz, ‘Kötülerin çadırları nerede?’
Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní ilé ọmọ-aládé, àti níbo ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’
29 Yolculara hiç sormadınız mı? Anlattıklarına kulak asmadınız mı?
Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjá lọ ní ọ̀nà? Ẹ̀yin kò mọ̀ àmì wọn,
30 Felaket günü kötü insan esirgenir, Gazap günü ona kurtuluş yolu gösterilir.
pé ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fún ọjọ́ ìparun. A ó sì mú wọn jáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.
31 Kim davranışını onun yüzüne vurur? Kim yaptığının karşılığını ona ödetir?
Ta ni yóò tako ipa ọ̀nà rẹ̀ lójúkojú, ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?
32 Mezarlığa taşınır, Kabri başında nöbet tutulur.
Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú, a ó sì máa ṣọ́ ibojì òkú.
33 Vadi toprağı tatlı gelir ona, Herkes ardından gider, Önüsıra gidenlerse sayısızdır.
Ògúlùtu àfonífojì yóò dùn mọ́ ọn. Gbogbo ènìyàn yóò sì máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, bí ènìyàn àìníye ti lọ síwájú rẹ̀.
34 “Boş laflarla beni nasıl avutursunuz? Yanıtlarınızdan çıkan tek sonuç yalandır.”
“Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin fi ń tù mí nínú lásán, bí ò ṣe pé ní ìdáhùn yín, àrékérekè wa níbẹ̀!”

< Eyüp 21 >