< Yeremya 9 >
1 Keşke başım bir pınar, Gözlerim bir gözyaşı kaynağı olsa! Halkımın öldürülenleri için Ağlasam gece gündüz!
Háà! Orí ìbá jẹ́ orísun omi kí ojú mi sì jẹ́ orísun omijé! Èmi yóò sì sọkún tọ̀sán tòru nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.
2 Keşke halkımı bırakabilmem, Onlardan uzaklaşabilmem için Çölde konaklayacak bir yerim olsa! Hepsi zina ediyor, Hain bir topluluk!
Háà, èmi ìbá ní ni aginjù ilé àgbàwọ̀ fún àwọn arìnrìn-àjò, kí n ba à lè fi àwọn ènìyàn mi sílẹ̀ kí n sì lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn: nítorí gbogbo wọn jẹ́ panṣágà àjọ aláìṣòótọ́ ènìyàn.
3 “Yalan söylemek için ülkede Dillerini yay gibi geriyor, Güçlerini gerçek yolunda kullanmıyorlar. Kötülük üstüne kötülük yapıyor, Beni tanımıyorlar” diyor RAB.
Wọ́n ti pèsè ahọ́n wọn sílẹ̀ bí ọfà láti fi pa irọ́; kì í ṣe nípa òtítọ́ ni wọ́n fi borí ní ilẹ̀ náà. Wọ́n ń lọ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ kan sí òmíràn; wọn kò sì náání mi, ní Olúwa wí.
4 “Herkes dostundan sakınsın, Kardeşlerinizin hiçbirine güvenmeyin. Çünkü her kardeş Yakup gibi aldatıcı, Her dost iftiracıdır.
“Ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ; má ṣe gbẹ́kẹ̀lé àwọn arákùnrin rẹ. Nítorí pé oníkálùkù arákùnrin jẹ́ atannijẹ, oníkálùkù ọ̀rẹ́ sì jẹ́ abanijẹ́.
5 Dost dostu aldatıyor, Kimse gerçeği söylemiyor. Dillerine yalan söylemeyi öğrettiler, Suç işleye işleye yorgun düştüler.
Ọ̀rẹ́ ń dalẹ̀ ọ̀rẹ́. Kò sì ṣí ẹni tó sọ òtítọ́, wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọn láti máa purọ́. Wọ́n sọ ara wọn di onírẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀
6 Sen, ey Yeremya, Aldatıcılığın ortasında yaşıyorsun. Aldatıcılıkları yüzünden Beni tanımak istemiyorlar.” Böyle diyor RAB.
Ó ń gbé ní àárín ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti mọ̀ mí nínú ẹ̀tàn wọn,” ni Olúwa wí.
7 Bundan ötürü Her Şeye Egemen RAB diyor ki, “İşte, onları arıtıp sınayacağım, Halkımın günahı yüzünden Başka ne yapabilirim ki?
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Wò ó, èmi dán wọn wo; nítorí pé kí ni èmi tún le è ṣe? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi?
8 Dilleri öldürücü bir ok, Hep aldatıyor. Komşusuna esenlik diliyor, Ama içinden ona tuzak kuruyor.
Ahọ́n wọn dàbí ọfà olóró; ó ń sọ ẹ̀tàn. Oníkálùkù sì ń fi ẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò rẹ̀, ní inú ọkàn rẹ̀, ó dẹ tàkúté sílẹ̀.
9 Bu yüzden onları cezalandırmayayım mı?” diyor RAB, “Böyle bir ulustan öcümü almayayım mı?”
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n nítorí èyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò ha gbẹ̀san ara mi lórí irú orílẹ̀-èdè yìí bí?”
10 Dağlar için ağlayıp yas tutacağım, Otlaklar için ağıt yakacağım. Çöle dönüştüler, Kimse geçmiyor oralardan. Sığırların böğürmesi duyulmuyor, Kuşlar, yabanıl hayvanlar kaçıp gitti.
Èmi yóò sì sọkún, pohùnréré ẹkún fún àwọn òkè àti ẹkún ìrora lórí pápá oko aginjù wọ̀n-ọn-nì. Nítorí wọ́n di ahoro, wọn kò sì kọjá ní ibẹ̀. A kò sì gbọ́ igbe ẹran ọ̀sìn. Àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ti sálọ, bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn ẹranko sì ti lọ.
11 “Yeruşalim'i taş yığını, Çakalların barınağı haline getireceğim. Yahuda kentlerini Kimsenin yaşayamayacağı bir viraneye döndüreceğim.”
“Èmi yóò sì sọ Jerusalẹmu di òkìtì àlàpà àti ihò àwọn ìkookò. Èmi ó sì sọ ìlú Juda di ahoro tí ẹnikẹ́ni kò sì ní le è gbé.”
12 Hangi bilge kişi buna akıl erdirecek? RAB'bin seslendiği kişi kim ki, sözünü açıklayabilsin? Ülke neden yıkıldı? Neden kimsenin geçemediği bir çöle dönüştü?
Ta ni ẹni náà tí ó ní ọgbọ́n láti mòye nǹkan wọ̀nyí? Ta ni Olúwa ti sọ èyí fún, tí ó sì lè ṣàlàyé rẹ̀? Èéṣe tí ilẹ̀ náà fi ṣègbé bí aginjù, tí ẹnìkankan kò sì le là á kọjá?
13 RAB, “Kendilerine verdiğim yasayı bıraktılar, sözümü dinlemediler, yasamı izlemediler” diyor,
Olúwa sì wí pé, nítorí pé wọ́n ti kọ òfin mi sílẹ̀, èyí tí mo gbé kalẹ̀ níwájú wọn, wọn ṣe àìgbọ́ràn sí wọn, wọn kò sì rìn nínú òfin mi.
14 “Onun yerine yüreklerinin inadını, atalarının öğrettiği gibi Baallar'ı izlediler.”
Dípò èyí, wọ́n ti tẹ̀lé agídí ọkàn wọn, wọ́n ti tẹ̀lé Baali gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe kọ́ wọn.
15 Bunun için İsrail'in Tanrısı, Her Şeye Egemen RAB diyor ki, “Bu halka pelinotu yedirecek, zehirli su içireceğim.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, “Wò ó, Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ oúnjẹ kíkorò àti láti mu omi májèlé.
16 Onları kendilerinin de atalarının da tanımadığı ulusların arasına dağıtacak, tümünü yok edene dek peşlerine kılıcı salacağım.”
Èmi yóò sì tú wọn ká láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, nínú èyí tí àwọn tàbí àwọn baba wọn kò mọ̀. Èmi yóò sì lépa wọn pẹ̀lú idà títí èmi yóò fi pa wọ́n run.”
17 Her Şeye Egemen RAB diyor ki, “İyi düşünün! Ağıt yakan kadınları çağırın gelsinler. En iyilerini çağırın gelsinler.
Èyí sì ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí: “Sá à wò ó nísinsin yìí! Ké sí obìnrin ti ń ṣọ̀fọ̀ nì kí ó wá; sì ránṣẹ́ pe àwọn tí ó mòye nínú wọn.
18 Hemen gelip bizim için ağıt yaksınlar; Gözlerimiz gözyaşı döksün, Gözkapaklarımızdan sular aksın.
Jẹ́ kí wọn wá kíákíá, kí wọn wá pohùnréré ẹkún lé wa lórí títí ojú wa yóò fi sàn fún omijé tí omi yóò sì máa sàn àwọn ìpéǹpéjú wa.
19 Siyon'dan ağlama sesi duyuluyor: ‘Yıkıma uğradık! Büyük utanç içindeyiz, Çünkü ülkemizi terk ettik, Evlerimiz yerle bir oldu.’”
A gbọ́ igbe ìpohùnréré ẹkún ní Sioni: ‘Àwa ti ṣègbé tó! A gbọdọ̀ fi ilẹ̀ wa sílẹ̀, nítorí pé àwọn ilé wa ti parun.’”
20 Ey kadınlar, RAB'bin sözünü dinleyin! Ağzından çıkan her söze kulak verin. Kızlarınıza yas tutmayı, Komşunuza ağıt yakmayı öğretin.
Nísinsin yìí, ẹ̀yin obìnrin ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa; ṣí etí yín sí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ. Kọ́ àwọn ọmọbìnrin yín ní ìpohùnréré ẹkún, kí ẹ sì kọ́ ara yín ní arò.
21 Ölüm pencerelerimize tırmandı, Kalelerimize girdi; Sokakları çocuksuz, Meydanları gençsiz bıraktı.
Ikú ti gba ojú fèrèsé wa wọlé ó sì ti wọ odi alágbára wa ó ti ké àwọn ọmọ kúrò ní àdúgbò àti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò ní gbọ̀ngàn ìta gbangba.
22 Onlara de ki, “RAB şöyle diyor: ‘İnsan cesetleri gübre gibi, Biçicinin ardındaki demetler gibi toprağa serilecek. Onları toplayacak kimse olmayacak.’”
Sọ pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Òkú àwọn ènìyàn yóò ṣubú bí ààtàn ní oko gbangba àti bí ìbùkúnwọ́ lẹ́yìn olùkórè láìsí ẹnìkankan láti kó wọn jọ.’”
23 RAB şöyle diyor: “Bilge kişi bilgeliğiyle, Güçlü kişi gücüyle, Zengin kişi zenginliğiyle övünmesin.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Má ṣe jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n yangàn nítorí agbára ọgbọ́n rẹ̀, tàbí alágbára nítorí agbára rẹ̀, tàbí ọlọ́rọ̀ nítorí ọrọ̀ rẹ̀.
24 Dünyada iyilik yapanın, Adaleti, doğruluğu sağlayanın Ben RAB olduğumu anlamakla Ve beni tanımakla övünsün övünen. Çünkü ben bunlardan hoşlanırım” diyor RAB.
Ẹ jẹ́ kí ẹni tí ń ṣògo nípa èyí nì wí pé: òun ní òye, òun sì mọ̀ mí wí pé, Èmi ni Olúwa tí ń ṣe òtítọ́, ìdájọ́ àti òdodo ní ayé, nínú èyí ni mo ní inú dídùn sí,” Olúwa wí.
25 “Yalnız bedence sünnetli olanları cezalandıracağım günler geliyor” diyor RAB.
“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí a kọ ilà fún nínú ara nìkan.
26 “Mısır'ı, Yahuda'yı, Edom'u, Ammon'u, Moav'ı, çölde yaşayan ve zülüflerini kesenlerin hepsini cezalandıracağım. Çünkü bütün bu uluslar gerçekte sünnetsiz, bütün İsrail halkı da yürekte sünnetsizdir.”
Ejibiti, Juda, Edomu, Ammoni, Moabu àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní ọ̀nà jíjìn réré ní aginjù. Nítorí pé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jẹ́ aláìkọlà gbogbo àwọn ará ilé Israẹli sì jẹ́ aláìkọlà ọkàn.”