< Yeremya 25 >
1 Yahuda Kralı Yoşiya oğlu Yehoyakim'in döneminin dördüncü yılında, RAB Yahuda halkıyla ilgili olarak Yeremya'ya seslendi. Nebukadnessar'ın Babil Kralı oluşunun birinci yılıydı bu.
Ọ̀rọ̀ sì tọ Jeremiah wá nípa àwọn ènìyàn Juda ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kìn-ín-ní Nebukadnessari ọba Babeli.
2 Peygamber Yeremya Yahuda halkına ve Yeruşalim'de yaşayanlara RAB'bin sözünü aktararak şöyle dedi:
Nítorí náà, Jeremiah wòlíì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti sí àwọn olùgbé Jerusalẹmu.
3 Yirmi üç yıldır, Yahuda Kralı Amon oğlu Yoşiya'nın döneminin on üçüncü yılından bugüne dek, RAB bana sesleniyor. Ben de RAB'bin sözünü defalarca size aktardım, ama dinlemediniz.
Fún odidi ọdún mẹ́tàlélógún, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún kẹtàlá Josiah, ọmọ Amoni ọba Juda, títí di ọjọ́ yìí, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, mo sì ti sọ ọ́ fún un yín láti ìgbà dé ìgbà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
4 RAB peygamber kullarını defalarca size gönderdi, ama dinlemediniz, kulak asmadınız.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì sí i yín láti ìgbà dé ìgbà, ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
5 Sizi uyardılar, “Şimdi herkes kötü yolundan, kötü işlerinden dönsün ki, RAB'bin sonsuza dek size ve atalarınıza verdiği toprakta yaşayasınız” dediler,
Wọ́n sì wí pé, “Ẹ yípadà olúkúlùkù yín kúrò ní inú ibi rẹ̀ àti ní ọ̀nà ibi rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì lè dúró ní ilẹ̀ tí Olúwa fún un yín àti àwọn baba yín títí láéláé.
6 “Kulluk etmek, tapınmak için başka ilahların ardınca gitmeyin; elinizle yaptığınız putlarla beni öfkelendirmeyin ki, ben de size zarar vermeyeyim.”
Má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn láti sìn wọ́n tàbí bọ wọ́n; ẹ má ṣe mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ ti fi ọwọ́ yín ṣe. Nígbà náà ni Èmi kò ní ṣe yín ní ibi.”
7 “Ama beni dinlemediniz” diyor RAB, “Sonuç olarak elinizle yaptığınız putlarla beni öfkelendirip kendinizi zarara soktunuz.”
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni ẹ sì ti mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ fi ọwọ́ yín ṣe, ẹ sì ti mú ibi wá sórí ara yín.”
8 Bunun için Her Şeye Egemen RAB diyor ki, “Madem sözlerimi dinlemediniz,
Nítorí náà, Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ èyí: “Nítorí wí pé ẹ̀yin kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi,
9 ben de bütün kuzeydeki halkları ve kulum Babil Kralı Nebukadnessar'ı çağırtacağım” diyor RAB, “Onları bu ülkeye de burada yaşayanlarla çevresindeki bütün uluslara da karşı getireceğim. Bu halkı tamamen yok edeceğim, ülkelerini dehşet ve alay konusu edip sonsuz bir viraneye çevireceğim.
Èmi yóò pe gbogbo àwọn ènìyàn àríwá, àti ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò sì mú wọn dìde lòdì sí ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé rẹ̀ àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè àyíká rẹ̀. Èmi yóò pa wọ́n run pátápátá, Èmi yóò sọ wọ́n di nǹkan ẹ̀rù àti yẹ̀yẹ́ àti ìparun ayérayé.
10 Sevinç ve neşe sesini, gelin güvey sesini, değirmen taşlarının sesini, kandil ışığını onlardan uzaklaştıracağım.
Èmi yóò sì mú ìró ayọ̀ àti inú dídùn kúrò lọ́dọ̀ wọn; ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó, ìró ọlọ òkúta àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà.
11 Bütün ülke bir virane, dehşet verici bir yer olacak. Bu uluslar Babil Kralı'na yetmiş yıl kulluk edecekler.
Gbogbo orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì sìn ọba Babeli ní àádọ́rin ọdún.
12 “Ama yetmiş yıl dolunca” diyor RAB, “Suçları yüzünden Babil Kralı'yla ulusunu, Kildan ülkesini cezalandıracak, sonsuz bir viranelik haline getireceğim.
“Ṣùgbọ́n, nígbà tí àádọ́rin ọdún náà bá pé, Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Babeli àti orílẹ̀-èdè rẹ, ilẹ̀ àwọn ará Babeli nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò sọ ọ́ di ahoro títí láé.
13 O ülke için söylediklerimin hepsini, Yeremya'nın uluslara ettiği bu kitapta yazılı bütün peygamberlik sözlerini ülkenin başına getireceğim.
Èmi yóò sì mú gbogbo ohun tí mo ti sọ wọ̀nyí wá sórí ilẹ̀ náà, gbogbo ohun tí a ti sọ àní gbogbo èyí tí a ti kọ sínú ìwé yìí, èyí tí Jeremiah ti sọtẹ́lẹ̀ sí gbogbo orílẹ̀-èdè.
14 Pek çok ulus, büyük krallar onları köle edinecek. Yaptıklarına ve ellerinden çıkan işe göre karşılık vereceğim onlara.”
Àwọn fúnra wọn yóò sì sin orílẹ̀-èdè púpọ̀ àti àwọn ọba ńlá. Èmi yóò sì sán fún oníkálùkù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”
15 İsrail'in Tanrısı RAB bana şöyle dedi: “Elimdeki öfke şarabıyla dolu kâseyi al, seni göndereceğim bütün uluslara içir.
Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí fún mi: “Gba ago yìí ní ọwọ́ mí tí ó kún fún ọtí wáìnì ìbínú mi, kí o sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè ti mo rán ọ sí mu ún.
16 Şarabı içince sendeleyecek, üzerlerine göndereceğim kılıç yüzünden çıldıracaklar.”
Nígbà tí wọ́n bá mu ún, wọn yóò ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n: bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n di aṣiwèrè nítorí idà tí yóò ránṣẹ́ sí àárín wọn.”
17 Böylece kâseyi RAB'bin elinden alıp beni gönderdiği bütün uluslara içirdim:
Mo sì gba ago náà lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó rán mi sí mu ún.
18 Bugün olduğu gibi viranelik, dehşet ve alay konusu, lanetlik olsunlar diye Yeruşalim'e, Yahuda kentlerine, krallarıyla önderlerine;
Jerusalẹmu àti àwọn ìlú Juda, àwọn ọba wọn pẹ̀lú àwọn aláṣẹ wọn, láti sọ wọ́n di ohun ìparun, ohun ẹ̀rù, ẹ̀sìn àti ègún, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti rí lónìí yìí.
19 Firavunla görevlilerine, önderlerine ve halkına,
Farao ọba Ejibiti, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn aláṣẹ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
20 Mısır'da yaşayan bütün yabancılara; Ûs krallarına, Filist krallarına –Aşkelon'a, Gazze'ye, Ekron'a, Aşdot'tan sağ kalanlara–
Àti gbogbo àwọn ènìyàn àjèjì tí ó wà níbẹ̀; gbogbo àwọn ọba Usi, gbogbo àwọn ọba Filistini, gbogbo àwọn ti Aṣkeloni, Gasa, Ekroni àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kù sí Aṣdodu.
21 Edom'a, Moav'a, Ammon'a;
Edomu, Moabu àti Ammoni;
22 bütün Sur ve Sayda krallarına, deniz aşırı ülkelerin krallarına;
gbogbo àwọn ọba Tire àti Sidoni; gbogbo àwọn ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá Òkun.
23 Dedan'a, Tema'ya, Bûz'a, zülüflerini kesen bütün halklara;
Dedani, Tema, Busi àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jíjìn réré.
24 Arabistan krallarına, çölde yaşayan yabancı halkın krallarına;
Gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn ọba àwọn àjèjì ènìyàn tí ń gbé inú aginjù.
25 Zimri, Elam, Med krallarına;
Gbogbo àwọn ọba Simri, Elamu àti Media.
26 sırasıyla uzak yakın bütün kuzey krallarına, yeryüzündeki bütün ulusların krallarına içirdim. Hepsinden sonra Şeşak Kralı da içecektir.
Àti gbogbo àwọn ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jíjìn, ẹnìkínní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, ọba Ṣeṣaki náà yóò sì mu.
27 “Sonra onlara de ki, ‘İsrail'in Tanrısı, Her Şeye Egemen RAB şöyle diyor: Üzerinize salacağım kılıç yüzünden sarhoş olana dek için, kusun, düşüp kalkmayın.’
“Nígbà náà, sọ fún wọn, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí. Mu, kí o sì mú àmuyó kí o sì bì, bẹ́ẹ̀ ni kí o sì ṣubú láì dìde mọ́ nítorí idà tí n ó rán sí àárín yín.
28 Eğer kâseyi elinden alır, içmek istemezlerse, de ki, ‘Her Şeye Egemen RAB şöyle diyor: Kesinlikle içeceksiniz!
Ṣùgbọ́n bí wọ́n ba kọ̀ láti gba ago náà ní ọwọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹyin gbọdọ̀ mu ún!
29 Bana ait olan kentin üzerine felaket getirmeye başlıyorum. Cezasız kalacağınızı mı sanıyorsunuz? Sizi cezasız bırakmayacağım. İşte dünyada yaşayan herkesin üzerine kılıcı çağırıyorum. Her Şeye Egemen RAB böyle diyor.’
Wò ó, èmi ń mú ibi bọ̀ sí orí orílẹ̀-èdè tí ó ń jẹ́ orúkọ mi; ǹjẹ́ yóò ha a lè lọ láìjìyà? Ẹ̀yin ń pe idà sọ̀kalẹ̀ sórí gbogbo àwọn olùgbé ayé, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ.’
30 “Bütün bu peygamberlik sözlerini onlara ilet: “‘Yükseklerden kükreyecek RAB, Kutsal konutundan gürleyecek, Ağılına şiddetle kükreyecek. Dünyada yaşayanların tümüne Üzüm ezenler gibi bağıracak.
“Nísinsin yìí, sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nípa wọn: “‘Kí o sì sọ pé, Olúwa yóò bú láti òkè wá, yóò sì bú kíkankíkan sí ilẹ̀ náà. Yóò parí gbogbo olùgbé ayé, bí àwọn tí ń tẹ ìfúntí.
31 Gürültü yeryüzünün dört yanında yankılanacak. Çünkü RAB uluslara dava açacak; Herkesi yargılayacak Ve kötüleri kılıca teslim edecek’” diyor RAB.
Ìrọ́kẹ̀kẹ̀ yóò wà títí dé òpin ilẹ̀ ayé, nítorí pé Olúwa yóò mú ìdààmú wá sí orí àwọn orílẹ̀-èdè náà, yóò mú ìdájọ́ wá sórí gbogbo ènìyàn, yóò sì fi àwọn olùṣe búburú fún idà,’” ni Olúwa wí.
32 Her Şeye Egemen RAB diyor ki, “İşte felaket ulustan ulusa yayılıyor! Dünyanın dört bucağından büyük kasırga kopuyor.”
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan sí òmíràn; ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
33 O gün RAB dünyayı bir uçtan bir uca öldürülenlerle dolduracak. Onlar için yas tutulmayacak, toplanıp gömülmeyecekler. Toprağın üzerinde gübre gibi kalacaklar.
Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò ṣọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
34 Haykırın, ey çobanlar, Acı acı bağırın! Toprakta yuvarlanın, ey sürü başları! Çünkü boğazlanma zamanınız doldu, Değerli bir kap gibi düşüp parçalanacaksınız.
Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, ẹ yí nínú eruku, ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran. Nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé, ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.
35 Çobanlar kaçamayacak, Sürü başları kurtulamayacak!
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn kì yóò rí ibi sálọ kì yóò sì ṣí àsálà fún olórí agbo ẹran.
36 Duy çobanların haykırışını, Sürü başlarının bağırışını! RAB onların otlaklarını yok ediyor.
Gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn, àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olórí agbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.
37 RAB'bin kızgın öfkesi yüzünden Güvenlikte oldukları ağıllar yok oldu.
Ibùgbé àlàáfíà yóò di ahoro, nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
38 İnini terk eden genç aslan gibi, RAB inini bıraktı. Zorbanın kılıcı Ve RAB'bin kızgın öfkesi yüzünden Ülkeleri viraneye döndü.
Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn aninilára, àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.