< Yeremya 22 >
1 RAB bana dedi ki, “Yahuda Kralı'nın sarayına gidip şu haberi bildir:
Báyìí ni Olúwa wí, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ààfin ọba Juda, kí o sì sọ ọ̀rọ̀ yìí níbẹ̀:
2 ‘RAB'bin sözünü dinleyin, ey Davut'un tahtında oturan Yahuda Kralı'yla görevlileri ve bu kapılardan giren halk!
‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ìwọ ọba Juda, tí ó jókòó ní ìtẹ́ Dafidi, ìwọ, àwọn ènìyàn rẹ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí ó wọlé láti ẹnu ibodè wọ̀nyí.
3 RAB diyor ki: Adil ve doğru olanı yapın. Soyguna uğrayanı zorbanın elinden kurtarın. Yabancıya, öksüze, dula haksızlık etmeyin, şiddete başvurmayın. Burada suçsuz kanı dökmeyin.
Báyìí ni Olúwa wí: Ṣé ohun tí ó jẹ́ òtítọ́ tí ó sì yẹ, kí o sì gba ẹni tí a fi ẹ̀tọ́ rẹ̀ dù ú kúrò lọ́wọ́ aninilára. Kí ó má ṣe fi agbára àti ìkà lé àlejò, aláìní baba, tàbí opó, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ níbí yìí.
4 Bu buyrukları özenle yerine getirirseniz, Davut'un tahtında oturan krallar savaş arabalarıyla, atlarıyla bu sarayın kapılarından girecekler; görevlileriyle halkları da onları izleyecek.
Nítorí bí ẹ̀yin bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, nígbà náà ni àwọn ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba inú ààfin láti ẹnu-ọ̀nà, wọn yóò gun kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin, àwọn àti ìránṣẹ́ wọn àti àwọn ènìyàn wọn.
5 Ancak bu buyruklara uymazsanız, diyor RAB, adım üzerine ant içerim ki, bu saray viraneye dönecek.’”
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, mo búra fúnra mi pé ààfin yìí yóò di ìparun ni Olúwa wí.’”
6 Çünkü Yahuda Kralı'nın sarayı için RAB diyor ki, “Sen benim için Gilat gibisin, Lübnan'ın doruğu gibi. Ama hiç kuşkun olmasın, seni çöle döndürecek, Kimsenin yaşamadığı kentlere çevireceğim.
Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa ààfin ọba Juda, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ dàbí Gileadi sí mi, gẹ́gẹ́ bí góńgó òkè Lebanoni, dájúdájú Èmi yóò sọ ọ́ di aṣálẹ̀, àní gẹ́gẹ́ bí ìlú tí a kò gbé inú wọn.
7 Eli silahlı yok ediciler görevlendireceğim sana karşı. En iyi sedir ağaçlarını kesecek, Ateşe atacaklar.
Èmi ó ya àwọn apanirun sọ́tọ̀ fún ọ, olúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀, wọn yóò sì gé àṣàyàn igi kedari rẹ lulẹ̀, wọn ó sì kó wọn jù sínú iná.
8 “Bu kentten geçen birçok ulus birbirlerine, ‘RAB bu büyük kente neden bunu yaptı?’ diye soracaklar.
“Àwọn ènìyàn láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò rékọjá lẹ́bàá ìlú yìí wọn yóò sì máa bi ara wọn léèrè pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe irú èyí sí ìlú ńlá yìí?’
9 “Yanıt şöyle olacak: ‘Çünkü Tanrıları RAB'bin antlaşmasını bıraktılar, başka ilahlara tapıp kulluk ettiler.’”
Ìdáhùn wọn yóò sì jẹ́: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọn ti ń fi orí balẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì sìn wọ́n.’”
10 Ölen için ağlamayın, yasa bürünmeyin; Ancak sürgüne giden için ağlayın acı acı. Çünkü bir daha dönmeyecek, Anayurdunu görmeyecek.
Nítorí náà má ṣe sọkún nítorí ọba tí ó ti kú tàbí ṣọ̀fọ̀ fún àdánù rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ sọkún kíkorò fún ẹni tí a lé kúrò nílùú nítorí kì yóò padà wá mọ́ tàbí fi ojú rí ilẹ̀ tí a ti bí i.
11 Babası Yoşiya'nın yerine Yahuda Kralı olan ve buradan çıkıp giden Yoşiya oğlu Şallum için RAB diyor ki, “Bir daha dönmeyecek buraya.
Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa Ṣallumu ọmọ Josiah ọba Juda tí ó jẹ ọba lẹ́yìn baba rẹ̀, ṣùgbọ́n tí ó jáde kúrò níhìn-ín: “Òun kì yóò padà wá mọ́.
12 Sürgüne gönderildiği yerde ölecek, bir daha bu ülkeyi görmeyecek.”
Yóò kú ni ibi tí a mú u ní ìgbèkùn lọ, kì yóò sì rí ilẹ̀ yìí mọ́.”
13 “Sarayını haksızlıkla, Yukarı odalarını adaletsizlikle yapan, Komşusunu parasız çalıştıran, Ücretini ödemeyen adamın vay başına!
“Ègbé ni fún ẹni tí a kọ́ ààfin rẹ̀ lọ́nà àìṣòdodo, àti àwọn yàrá òkè rẹ̀ lọ́nà àìtọ́ tí ó mú kí àwọn ará ìlú rẹ ṣiṣẹ́ lásán láìsan owó iṣẹ́ wọn fún wọn.
14 ‘Kendim için yukarı odaları havadar, Geniş bir saray yapacağım’ diyenin vay başına! Sarayına büyük pencereler açar, Sedir ağacıyla kaplar, Kırmızıya boyar.
Ó wí pé, ‘Èmi ó kọ́ ààfin ńlá fún ara mi àwọn yàrá òkè tí ó fẹ̀, ojú fèrèsé rẹ̀ yóò tóbi.’ A ó sì fi igi kedari bò ó, a ó fi ohun aláwọ̀ pupa ṣe é ní ọ̀ṣọ́.
15 “Bol bol sedir ağacı kullandın diye Kral mı oldun sanırsın? Baban doyasıya yiyip içti, Ama iyi ve doğru olanı yaptı; Onun için de işleri iyi gitti.
“Ìwọ ó ha jẹ ọba kí ìwọ kí ó lè ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi kedari? Baba rẹ kò ha ní ohun jíjẹ àti mímu? Ó ṣe ohun tí ó tọ́ àti òdodo, nítorí náà ó dára fún un.
16 Ezilenin, yoksulun davasını savundu, Onun için de işleri iyi gitti. Beni tanımak bu değil midir?” diyor RAB.
Ó gbèjà òtòṣì àti aláìní, ohun gbogbo sì dára fún un. Bí a ti mọ̀ mí kọ́ ni èyí?” ni Olúwa wí.
17 “Seninse gözlerin de yüreğin de yalnız kazanca, Suçsuz kanı dökmeye, Baskı, zorbalık yapmaya yönelik.”
“Ṣùgbọ́n ojú rẹ àti ọkàn rẹ wà lára èrè àìṣòótọ́ láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ìnilára àti ìlọ́nilọ́wọ́gbà.”
18 Bu yüzden RAB Yahuda Kralı Yoşiya oğlu Yehoyakim için diyor ki, “Onun için kimse, ‘Ah kardeşim! Vah kızkardeşim!’ diye dövünmeyecek. Onun için kimse, ‘Ah efendim! Vah onun görkemi!’ diye dövünmeyecek.
Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, nípa Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda: “Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, arákùnrin mi! Ó ṣe, arábìnrin mi!’ Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, olúwa tàbí ó ṣe ọlọ́lá!’
19 Sürüklenip Yeruşalim kapılarından dışarı atılacak, Eşek gömülür gibi gömülecek o.”
A ó sin òkú rẹ̀ bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí a wọ́ sọnù láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.”
20 “Lübnan'a git, feryat et, Sesin Başan'dan duyulsun, Haykır Avarim'den, Çünkü bütün oynaşların ezildi.
“Gòkè lọ sí Lebanoni, kígbe síta, kí a sì gbọ́ ohùn rẹ ní Baṣani, kí o kígbe sókè láti Abarimu, nítorí a ti ṣẹ́ gbogbo olùfẹ́ rẹ túútúú.
21 Kendini güvenlikte sandığında seni uyardım. Ama, ‘Dinlemem’ dedin. Gençliğinden bu yana böyleydi tutumun, Sözümü hiç dinlemedin.
Èmi ti kìlọ̀ fún ọ nígbà tí o rò pé kò séwu, ṣùgbọ́n o sọ pé, ‘Èmi kì yóò fetísílẹ̀!’ Èyí ni iṣẹ́ rẹ láti ìgbà èwe rẹ, ìwọ kò fìgbà kan gba ohùn mi gbọ́.
22 Rüzgar bütün çobanlarını alıp götürecek, Oynaşların sürgüne gidecek. İşte o zaman yaptığın kötülükler yüzünden Utanacak, aşağılanacaksın.
Ẹ̀fúùfù yóò lé gbogbo àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ lọ, gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ yóò lọ sí ìgbèkùn, nígbà náà ni a ó kẹ́gàn rẹ, ojú yóò tì ọ́ nítorí gbogbo ìwà búburú rẹ.
23 Ey sen, Lübnan'da yaşayan, Yuvasını sedir ağacından kuran adam! Sana doğuran kadın gibi acılar, sancılar geldiğinde, Nasıl da inleyeceksin!”
Ìwọ tí ń gbé ‘Lebanoni,’ tí ó tẹ́ ìtẹ́ sí orí igi kedari, ìwọ yóò ti kérora pẹ́ tó, nígbà tí ìrora bá dé bá ọ, ìrora bí i ti obìnrin tí ń rọbí!
24 “Varlığım hakkı için derim ki” diyor RAB, “Ey Yahuda Kralı Yehoyakim oğlu Yehoyakin, sağ elimdeki mühür yüzüğü olsan bile, çıkarıp atardım seni.
“Dájúdájú bí èmi ti wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Bí Koniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda tilẹ̀ jẹ́ òrùka èdìdì lọ́wọ́ ọ̀tún mi, síbẹ̀ èmi ó fà ọ́ tu kúrò níbẹ̀.
25 Seni can düşmanlarının, korktuğun kişilerin, Babil Kralı Nebukadnessar'la Kildaniler'in eline teslim edeceğim.
Èmi ó sì fà ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí rẹ, àwọn tí ìwọ bẹ̀rù, àní lé ọwọ́ Nebukadnessari, ọba Babeli àti ọwọ́ àwọn ará Babeli.
26 Seni de seni doğuran anneni de doğmadığınız bir ülkeye atacağım; orada öleceksiniz.
Èmi ó fi ìwọ àti ìyá tí ó bí ọ sọ̀kò sí ilẹ̀ mìíràn, níbi tí a kò bí ẹnikẹ́ni nínú yín sí. Níbẹ̀ ni ẹ̀yin méjèèjì yóò kú sí.
27 Dönmeye can attığınız ülkeye bir daha dönemeyeceksiniz.”
Ẹ̀yin kì yóò padà sí ilẹ̀ tí ẹ̀yin fẹ́ mọ́ láéláé.”
28 Bu mu Yehoyakin? Bu hor görülmüş kırık çömlek, Kimsenin istemediği kap? Neden kendisi de çocukları da Bilmedikleri bir ülkeye atıldılar?
Ǹjẹ́ Jehoiakini ẹni ẹ̀gàn yàtọ̀ sí ìkòkò òfìfo, ohun èlò tí ẹnìkan kò fẹ́? Èéṣe tí a fi òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sókè sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.
29 Ülke, ey ülke, RAB'bin sözünü dinle, ey ülke!
Ìwọ ilẹ̀, ilẹ̀, ilẹ̀, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
30 RAB diyor ki, “Bu adamı çocuksuz, Ömrünce başarısız biri olarak yazın. Çünkü soyundan gelen hiç kimse başarılı olmayacak, Soyundan gelen hiç kimse Davut'un tahtında oturamayacak, Yahuda'da bir daha krallık etmeyecek.”
Báyìí ni Olúwa wí: “Kọ àkọsílẹ̀ ọkùnrin yìí sínú ìwé gẹ́gẹ́ bí aláìlọ́mọ, ẹni tí kì yóò ṣe rere ní ọjọ́ ayé rẹ̀; nítorí ọ̀kan nínú irú-ọmọ rẹ̀ kì yóò ṣe rere, èyíkéyìí wọn kì yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi tàbí jẹ ọba ní Juda mọ́.”