< Yeşaya 61 >

1 Egemen RAB'bin Ruhu üzerimdedir. Çünkü O beni yoksullara müjde iletmek için meshetti. Yüreği ezik olanların yaralarını sarmak için, Tutsaklara serbest bırakılacaklarını, Zindanlarda bulunanlara kurtulacaklarını, RAB'bin lütuf yılını, Tanrımız'ın öç alacağı günü ilan etmek, Yas tutanların hepsini avutmak, Siyon'da yas tutanlara yardım sağlamak –Kül yerine çelenk, Yas yerine sevinç yağı, Çaresizlik ruhu yerine Onlara övgü giysisini vermek– için RAB beni gönderdi. Öyle ki, RAB'bin görkemini yansıtmak için, Onlara “RAB'bin diktiği doğruluk ağaçları” densin.
Ẹ̀mí Olúwa Olódùmarè wà lára mi nítorí Olúwa ti fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìyìnrere fún àwọn tálákà. Ó ti rán mi láti ṣe àwòtán oníròbìnújẹ́ láti kéde ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn àti ìtúsílẹ̀ kúrò nínú òkùnkùn fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n,
2
láti kéde ọdún ojúrere Olúwa àti ọjọ́ ẹ̀san ti Ọlọ́run wa, láti tu àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú,
3
àti láti pèsè fún àwọn tí inú wọn bàjẹ́ ní Sioni láti dé wọn ládé ẹwà dípò eérú, òróró ayọ̀ dípò ọ̀fọ̀, àti aṣọ ìyìn dípò ìpòrúru ọkàn. A ó sì pè wọ́n ní igi óákù òdodo, irúgbìn Olúwa láti fi ọláńlá rẹ̀ hàn.
4 O zaman eski yıkıntıları yeniden inşa edecek, Çoktan viraneye dönmüş yerleri yeniden kuracak, Kuşaklar boyu yıkık kalmış kentleri onaracaklar.
Wọn yóò tún àwọn ahoro àtijọ́ kọ́ wọn yóò sì mú àwọn ibi ìparun àtijọ́-tijọ́ náà bọ̀ sípò; wọn yóò jí àwọn ahoro ìlú náà padà tí a ti parun láti ìrandíran sẹ́yìn.
5 Yabancılar sürülerinizi güdecek, Irgatınız, bağcınız olacaklar.
Àwọn àjèjì ni yóò máa da ọ̀wọ́ ẹran rẹ; àwọn àlejò yóò sì ṣiṣẹ́ nínú oko àti ọgbà àjàrà rẹ.
6 Sizlerse RAB'bin kâhinleri, Tanrımız'ın görevlileri diye çağrılacaksınız. Ulusların servetiyle beslenecek, Zenginlikleriyle övüneceksiniz.
A ó sì máa pè yín ní àlùfáà Olúwa, a ó pè yín ní ìránṣẹ́ Ọlọ́run wa. Ẹ ó máa jẹ nínú ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè àti nínú ọrọ̀ wọn ni ẹ̀yin yóò máa ṣògo.
7 Utanç yerine iki kat onur bulacaksınız, Aşağılanma yerine payınızla sevineceksiniz, Böylece ülkenizde iki kat mülk edineceksiniz; Sevinciniz sonsuz olacak.
Dípò àbùkù wọn àwọn ènìyàn mi yóò gba ìlọ́po méjì, àti dípò àbùkù wọn wọn yóò yọ̀ nínú ìní wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jogún ìlọ́po méjì ní ilẹ̀ wọn, ayọ̀ ayérayé yóò sì jẹ́ tiwọn.
8 “Çünkü ben RAB adaleti severim, Nefret ederim soygun ve haksızlıktan. Sözümde durup hak ettiklerini verecek, Onlarla ebedi bir antlaşma yapacağım.
“Nítorí Èmi, Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òdodo; mo kórìíra olè jíjà àti ẹ̀ṣẹ̀. Ní òtítọ́ mi èmi yóò sẹ̀san fún wọn èmi yóò sì dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú wọn.
9 Soylarından gelenler uluslar arasında, Torunları halklar arasında tanınacak. Onları gören herkes RAB'bin kutsadığı soy olduklarını anlayacak.”
A ó mọ ìrandíran wọn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ìran wọn láàrín àwọn ènìyàn. Gbogbo àwọn tí ó bá rí wọn yóò mọ̀ pé wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tí Olúwa ti bùkún.”
10 RAB'de büyük sevinç bulacağım, Tanrım'la yüreğim coşacak. Çünkü çelenkle süslenmiş güvey gibi, Takılarını kuşanmış gelin gibi, Bana kurtuluş giysisini giydirdi, Beni doğruluk kaftanıyla örttü.
Èmi yọ̀ gidigidi nínú Olúwa; ọkàn mi yọ̀ nínú Ọlọ́run mi. Nítorí ó ti wọ̀ mí ní aṣọ ìgbàlà ó sì ṣe mí lọ́ṣọ̀ọ́ nínú aṣọ òdodo; gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ti ṣe orí rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ bí àlùfáà, àti bí ìyàwó ṣe ń ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́.
11 Toprak filizlerini nasıl çıkartır, Bahçe ekilen tohumları nasıl yetiştirirse, Egemen RAB de doğruluk ve övgüyü Bütün ulusların önünde öyle yetiştirecek.
Gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ti í mú irúgbìn jáde àti bí ọgbà ṣe ń mú irúgbìn dàgbà, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè yóò ṣe mú òdodo àti ìyìn kí ó ru sókè níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè.

< Yeşaya 61 >