< Yeşaya 49 >
1 Ey kıyı halkları, işitin beni, Uzaktaki halklar, iyi dinleyin. RAB beni ana rahmindeyken çağırdı, Annemin karnındayken adımı koydu.
Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin erékùṣù: gbọ́ èyí, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè jíjìnnà réré: kí a tó bí mi Olúwa ti pè mí; láti ìgbà bíbí mi ni ó ti dá orúkọ mi.
2 Ağzımı keskin kılıç yaptı, Elinin gölgesinde gizledi beni. Beni keskin bir ok yaptı, Kendi ok kılıfına sakladı.
Ó ṣe ẹnu mi bí idà tí a pọ́n, ní abẹ́ òjìji ọwọ́ rẹ̀ ni ó ti pa mí mọ́: ó ṣe mí ní ọfà tí a ti dán, ó sì fi mí pamọ́ sínú àpò rẹ̀.
3 Bana, “Kulumsun, ey İsrail, Görkemimi senin aracılığınla göstereceğim” dedi.
Ó sọ fún mi pé, “Ìránṣẹ́ mi ni ìwọ í ṣe, Israẹli nínú ẹni tí n ó ti fi ògo mi hàn.”
4 Ama ben, “Boşuna emek verdim” dedim, “Gücümü boş yere, bir hiç için tükettim. RAB yine de hakkımı savunur, Tanrım yaptıklarımın karşılığını verir.”
Ṣùgbọ́n èmi sọ pé, “Mo ti ṣe wàhálà lórí asán; mo ti lo gbogbo ipá mi lórí asán àti ìmúlẹ̀mófo. Síbẹ̀síbẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi ṣì wà lọ́wọ́ Olúwa, èrè mi sì ń bẹ pẹ̀lú Ọlọ́run mi.”
5 Kulu olmam için, Yakup soyunu kendisine geri getirmem, İsrail'i önünde toplamam için Rahimde beni biçimlendiren RAB şimdi şöyle diyor: –O'nun gözünde onurluyum, Tanrım bana güç kaynağı oldu.–
Nísinsin yìí Olúwa wí pé ẹni tí ó mọ̀ mí láti inú wá láti jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ láti mú Jakọbu padà tọ̀ mí wá àti láti kó Israẹli jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀, nítorí pé a bọ̀wọ̀ fún mi ní ojú Olúwa Ọlọ́run mi sì ti jẹ́ agbára mi,
6 “Yakup'un oymaklarını canlandırmak, Sağ kalan İsrailliler'i geri getirmek için Kulum olman yeterli değil. Seni uluslara ışık yapacağım. Öyle ki, kurtarışım yeryüzünün dört bucağına ulaşsın.”
Òun wí pé: “Ó jẹ́ ohun kékeré fún ọ láti jẹ́ ìránṣẹ́ mi láti mú ẹ̀yà Jakọbu padà bọ̀ sípò àti láti mú àwọn ti Israẹli tí mo ti pamọ́. Èmi yóò sì fi ọ́ ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn kèfèrí, kí ìwọ kí ó lè mú ìgbàlà mi wá sí òpin ilẹ̀ ayé.”
7 İnsanların hor gördüğüne, Ulusların iğrendiğine, Egemenlerin kulu olana İsrail'in Kurtarıcısı ve Kutsalı RAB diyor ki, “Seni seçmiş olan İsrail'in Kutsalı sadık RAB'den ötürü Krallar seni görünce ayağa kalkacak, Önderler yere kapanacak.”
Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Olùdáǹdè àti Ẹni Mímọ́ Israẹli— sí ẹni náà tí a gàn tí a sì kórìíra lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, sí ìránṣẹ́ àwọn aláṣẹ: “Àwọn ọba yóò rí ọ wọn yóò sì dìde sókè, àwọn ọmọ ọba yóò rí i wọn yóò sì wólẹ̀, nítorí Olúwa ẹni tí í ṣe olóòtítọ́, Ẹni Mímọ́ Israẹli tí ó ti yàn ọ́.”
8 RAB şöyle diyor: “Lütuf zamanında seni yanıtlayacağım, Kurtuluş günü sana yardım edecek, Seni koruyacağım. Seni halka antlaşma olarak vereceğim. Öyle ki, yıkık ülkeyi yeniden kurasın, Mülk olarak yeni sahiplerine veresin.
Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Ní àkókò ojúrere mi, èmi yóò dá ọ lóhùn, àti ní ọjọ́ ìgbàlà, èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́; Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́ láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, láti mú ilẹ̀ padà bọ̀ sípò àti láti ṣe àtúnpín ogún rẹ̀ tí ó ti dahoro,
9 Tutsaklara, ‘Çıkın’, Karanlıktakilere, ‘Dışarı çıkın’ diyeceksin. Yol boyunca beslenecek, Her çıplak tepede otlak bulacaklar.
láti sọ fún àwọn ìgbèkùn pé, ‘Ẹ jáde wá,’ àti fún àwọn tí ó wà nínú òkùnkùn pé, ‘Ẹ gba òmìnira!’ “Wọn yóò máa jẹ ní ẹ̀bá ọ̀nà àti koríko tútù lórí òkè aláìléwéko.
10 Acıkmayacak, susamayacaklar, Kavurucu sıcak ve güneş çarpmayacak onları. Çünkü onlara merhamet eden kendilerine yol gösterecek Ve onları pınarlara götürecek.
Ebi kì yóò pa wọ́n bẹ́ẹ̀ ni òǹgbẹ kì yóò gbẹ wọ́n, tàbí kí ooru inú aṣálẹ̀ tàbí oòrùn kí ó pa wọ́n. Ẹni tí ó ṣàánú fún wọn ni yóò máa tọ́ wọn, tí yóò sì mú wọn lọ sí ibi orísun omi.
11 Bütün dağlarımı yola dönüştüreceğim, Anayollarım yükseltilecek.
Èmi yóò sọ gbogbo àwọn òkè ńlá mi di ojú ọ̀nà àti gbogbo òpópónà mi ni a ó gbé sókè.
12 İşte halkım ta uzaklardan, Kimi kuzeyden, kimi batıdan, kimi de Sinim'den gelecek.”
Kíyèsi i, wọn yóò wá láti ọ̀nà jíjìn àwọn díẹ̀ láti àríwá àti àwọn díẹ̀ láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn díẹ̀ láti ẹkùn Siene.”
13 Ey gökler, sevinçle haykırın, Neşeyle coş, ey yeryüzü! Ey dağlar, sevinç çığlıklarına katılın, Çünkü RAB halkını avutacak, Ezilene merhamet gösterecek.
Ẹ hó fún ayọ̀, ẹyin ọ̀run; yọ̀, ìwọ ilẹ̀ ayé; bú sórin, ẹ̀yin òkè ńlá! Nítorí Olúwa tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú yóò sì ṣàánú fún àwọn ẹni tí a ń pọ́n lójú.
14 Oysa Siyon, “RAB beni terk etti, Rab beni unuttu” diyordu.
Ṣùgbọ́n Sioni sọ pé, “Olúwa ti kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa ti gbàgbé è mi.”
15 Ama RAB, “Kadın emzikteki çocuğunu unutabilir mi?” diyor, “Rahminden çıkan çocuktan sevecenliği esirger mi? Kadın unutabilir, Ama ben seni asla unutmam.
“Ǹjẹ́ abiyamọ ha le gbàgbé ọmọ ọmú rẹ̀ kí ó má sì ṣàánú fún ọmọ rẹ̀ tí ó ti bí? Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun le gbàgbé, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ!
16 Bak, adını avuçlarıma kazıdım, Duvarlarını gözlüyorum sürekli.
Kíyèsi i, mo ti kọ ọ́ sí àtẹ́lẹwọ́ mi ògiri rẹ wà níwájú mi nígbà gbogbo.
17 Oğulların koşar adım geliyor, Seni yıkıp viran edenlerse çıkıp gidecek.
Àwọn ọmọ rẹ ti kánjú padà, àti àwọn tí ó sọ ọ́ dahoro ti padà lẹ́yìn rẹ.
18 Başını kaldır da çevrene bir bak: Hepsi toplanmış sana geliyor. Ben RAB, varlığım hakkı için diyorum ki, Onların hepsi senin süsün olacak, Bir gelin gibi takınacaksın onları.
Gbójú rẹ sókè kí o sì wò yíká; gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ kórajọ wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ. Níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Ìwọ yóò wọ gbogbo wọ́n gẹ́gẹ́ bí ohun ọ̀ṣọ́; ìwọ yóò wọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí ìyàwó.
19 “Çünkü yıkılmış, viraneye dönmüştün, Ülken yerle bir olmuştu. Ama şimdi halkına dar geleceksin, Seni harap etmiş olanlar senden uzak duracaklar.
“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí run ọ́, a sì sọ ọ́ di ahoro tí gbogbo ilẹ̀ rẹ sì di ìparun, ní ìsinsin yìí, ìwọ yóò kéré jù fún àwọn ènìyàn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó jẹ ọ́ run ni yóò wà láti ọ̀nà jíjìn réré.
20 Yitirdiğini sandığın çocuklarının sesini yine duyacaksın: ‘Burası bize dar geliyor, Yaşayacak bir yer ver bize’ diyecekler.
Àwọn ọmọ tí a bí ní àkókò ọ̀fọ̀ rẹ yóò sọ ní etígbọ̀ọ́ rẹ, ‘Ibi yìí ti kéré jù fún wa; ẹ fún wa láyè sí i tí a ó máa gbé.’
21 O zaman içinden, ‘Kim doğurdu bunları bana?’ diyeceksin, ‘Çocuklarımı yitirmiştim, doğuramıyordum. Sürgüne gönderilmiş, dışlanmıştım. Öyleyse bunları kim büyüttü? Yapayalnız kalmıştım, Nereden çıkıp geldi bunlar?’”
Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní ọkàn rẹ pé, ‘Ta ló bí àwọn yìí fún mi? Mo ti ṣọ̀fọ̀ mo sì yàgàn; a sọ mi di àtìpó a sì kọ̀ mí sílẹ̀. Ta ló wo àwọn yìí dàgbà? A fi èmi nìkan sílẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí níbo ni wọ́n ti wá?’”
22 Egemen RAB diyor ki, “Bakın, uluslara elimle işaret verdiğimde, Sancağımı yükselttiğimde halklara, Senin oğullarını kucaklarında getirecek, Kızlarını omuzlarında taşıyacaklar.
Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyìí, “Kíyèsi i, Èmi yóò ké sí àwọn aláìkọlà, Èmi yóò gbé àsíá mi sókè sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn; wọn yóò kó àwọn ọmọkùnrin yín wá ní apá wọn wọn yóò sì gbé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ní èjìká wọn.
23 Krallar size babalık, Prensesler sütannelik yapacak, Yüzüstü yere kapanıp Ayaklarının tozunu yalayacaklar. O zaman benim RAB olduğumu anlayacaksın. Bana umut bağlayan utandırılmayacak.”
Àwọn ọba ni yóò jẹ́ alágbàtọ́ baba fún ọ, àwọn ayaba wọn ni yóò sì jẹ́ ìyá-alágbàtọ́. Wọn yóò foríbalẹ̀ ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ojú wọn dídàbolẹ̀; wọn yóò máa lá erùpẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; gbogbo àwọn tí wọ́n ní ìrètí nínú mi ni a kì yóò jákulẹ̀.”
24 Güçlünün ganimeti elinden alınabilir mi? Zorbanın elindeki tutsak kurtulabilir mi?
Ǹjẹ́ a le gba ìkógun lọ́wọ́ jagunjagun, tàbí kí á gba ìgbèkùn lọ́wọ́ akíkanjú?
25 Ama RAB diyor ki, “Evet, güçlünün elindeki tutsaklar alınacak, Zorbanın aldığı ganimet de kurtarılacak. Seninle çekişenle ben çekişeceğim, Senin çocuklarını ben kurtaracağım.
Ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Bẹ́ẹ̀ ni, a ó gba àwọn ìgbèkùn lọ́wọ́ àwọn jagunjagun, àti ìkógun lọ́wọ́ àwọn akíkanjú; ẹni tí ó bá ọ jà ni èmi ó bá jà, àti àwọn ọmọ rẹ ni èmi ó gbàlà.
26 Sana zulmedenlere kendi etlerini yedireceğim, Tatlı şarap içmiş gibi kendi kanlarıyla sarhoş olacaklar. Böylece bütün insanlar bilecek ki Seni kurtaran RAB benim; Kurtarıcın, Yakup'un Güçlüsü benim.”
Èmi yóò mú kí àwọn aninilára rẹ̀ jẹ ẹran-ara wọn; wọn yóò mu ẹ̀jẹ̀ ara wọn yó bí ẹni mu wáìnì. Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi, Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ, Olùdáǹdè rẹ, Alágbára kan ṣoṣo ti Jakọbu.”