< Yeşaya 45 >

1 RAB meshettiği kişiye, Sağ elinden tuttuğu Koreş'e sesleniyor. Uluslara onun önünde baş eğdirecek, Kralları silahsızlandıracak, Bir daha kapanmayacak kapılar açacak. Ona şöyle diyor:
“Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀, sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀ àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn, láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.
2 “Senin önünsıra gidip Dağları düzleyecek, Tunç kapıları kırıp Demir sürgülerini parçalayacağım.
Èmi yóò lọ síwájú rẹ, Èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ èmi ó sì gé ọ̀pá irin.
3 Seni adınla çağıranın Ben RAB, İsrail'in Tanrısı olduğumu anlayasın diye Karanlıkta kalmış hazineleri, Gizli yerlerde saklı zenginlikleri sana vereceğim.
Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn, ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin, tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.
4 Sen beni tanımadığın halde Kulum Yakup soyu ve seçtiğim İsrail uğruna Seni adınla çağırıp onurlu bir unvan vereceğim.
Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi àti Israẹli ẹni tí mo yàn, Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ, mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.
5 RAB benim, başkası yok, Benden başka Tanrı yok. Beni tanımadığın halde seni güçlü kılacağım.
Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn; yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan, Èmi yóò fún ọ ní okun, bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,
6 Öyle ki, doğudan batıya dek Benden başkası olmadığını herkes bilsin. RAB benim, başkası yok.
tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀ kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi. Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.
7 Işığı biçimlendiren, karanlığı yapan, Esenliği ve felaketi yaratan, Bütün bunları yapan RAB benim.
Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn, Mo mú àlàáfíà wá, Mo sì dá àjálù; Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.
8 Ey gökler, yukarıdan doğruluk damlatın, Ey bulutlar, doğruluk yağdırın. Toprak yarılsın, kurtuluş meyvesi versin, Onunla birlikte doğruluk yetiştirsin. Bunları yaratan RAB benim.”
“Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀; jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀. Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada, jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè, jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀; Èmi Olúwa ni ó ti dá a.
9 Kendine biçim verenle çekişenin vay haline! Kil, topraktan yapılmış çömlek parçası, Kendisine biçim verene, “Ne yapıyorsun? Yarattığın nesnenin tutacağı yok” diyebilir mi?
“Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà, ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀. Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé: ‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’ Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé, ‘Òun kò ní ọwọ́?’ (questioned)
10 Babasına, “Dünyaya ne getirdin?” Ya da annesine, “Ne biçim şey doğurdun?” Diyenin vay haline!
Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé, ‘Kí ni o bí?’ tàbí sí ìyá rẹ̀, ‘Kí ni ìwọ ti bí?’
11 İsrail'in Kutsalı, Ona biçim veren RAB diyor ki, “Çocuklarımın geleceği hakkında beni sorgulayabilir, Ellerimin yapıtları hakkında bana buyruk verebilir misiniz?
“Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Nípa ohun tí ó ń bọ̀, ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi, tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?
12 Dünyayı ben yaptım, Üzerindeki insanı ben yarattım. Benim ellerim gerdi gökleri, Bütün gök cisimleri benim buyruğumda.
Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀. Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run; mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta.
13 Koreş'i doğrulukla harekete geçirecek, Yollarını düzleyeceğim. Kentimi o onaracak, Sürgünlerimi ücret ya da ödül almadan o özgür kılacak.” Böyle diyor Her Şeye Egemen RAB.
Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi. Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́. Òun yóò tún ìlú mi kọ́ yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
14 RAB diyor ki, “Mısır'ın ürettikleri, Kûş'un ticaret gelirleri Ve uzun boylu Sevalılar size gelecek, sizin olacak. Zincire vurulmuş olarak ardınızsıra yürüyecekler. Önünüzde yere kapanıp yalvaracaklar: ‘Tanrı yalnız sizinledir, Başkası, başka Tanrı yok.’”
Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi, àti àwọn Sabeani— wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ; wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn, wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́. Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀, wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé, ‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn; kò sí ọlọ́run mìíràn.’”
15 Gerçekten sen kendini gizleyen bir Tanrı'sın, Ey İsrail'in Tanrısı, ey Kurtarıcı!
Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́, Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli,
16 Put yapanların hepsi utandırılacak, rezil olacak. Utanç içinde uzaklaşacaklar.
Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì wọn yóò sì kan àbùkù; gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.
17 Ama İsrail RAB tarafından kurtarılacak, Sonsuza dek sürecek kurtuluşu. Çağlar boyunca utandırılmayacak, Asla rezil olmayacak.
Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé; a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín, títí ayé àìnípẹ̀kun.
18 Çünkü gökleri yaratan RAB, Dünyayı yaratıp biçimlendiren, pekiştiren, Üzerinde yaşanmasın diye değil, yaşansın diye Biçimlendiren RAB –Tanrı O'dur– şöyle diyor: “RAB benim, başkası yok.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run, Òun ni Ọlọ́run; ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé, Òun ló ṣe é; Òun kò dá a láti wà lófo, ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀, Òun wí pé: “Èmi ni Olúwa, kò sì ṣí ẹlòmíràn.
19 Ben gizlide, Karanlıklar ülkesinin bir köşesinde konuşmadım. Yakup soyuna, ‘Beni olmayacak yerlerde arayın’ demedim. Doğru olanı söyleyen, adil olanı bildiren RAB benim.”
Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin, láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn, Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé, ‘Ẹ wá mi lórí asán.’ Èmi Olúwa sọ òtítọ́, Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.
20 “Ey sizler, uluslardan kaçıp kurtulanlar, Toplanıp gelin, birlikte yaklaşın! Tahtadan oyma putlar taşıyan, Kurtaramayan ilahlara yakaranlar bilgisizdir.
“Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá; ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn orílẹ̀-èdè wá. Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri, tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.
21 Konuşun, davanızı sunun, Birbirinize danışın. Bunları çok önceden duyurup bildiren kim? Ben RAB, bildirmedim mi? Benden başka Tanrı yok, adil Tanrı ve Kurtarıcı benim. Yok benden başkası.
Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá, jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀. Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́, ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe? Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa? Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi, Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà; kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.
22 “Ey dünyanın dört bucağındakiler, Bana dönün, kurtulursunuz. Çünkü Tanrı benim, başkası yok.
“Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là, ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé; nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.
23 Kendi üzerime ant içtim, Ağzımdan çıkan söz doğrudur, boşa çıkmaz: Her diz önümde çökecek, Her dil bana ant içecek.
Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra, ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi, ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́. Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀; nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.
24 “Benim için şöyle diyecekler: ‘Doğruluk ve güç yalnız RAB'dedir’, İnsanlar O'na gelecek. RAB'be öfkelenenlerin hepsi utandırılacak.
Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni òdodo àti agbára wà.’” Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí; yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.
25 Ama bütün İsrail soyu RAB tarafından aklanacak, O'nunla övünecek.
Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.

< Yeşaya 45 >