< Hoşea 9 >
1 Ey İsrail, öteki halklar gibi sevinme, coşma! Çünkü kendi Tanrın'a vefasızlık ederek zina ettin, Harman yerlerinin tümünde zina kazancına gönül verdin.
Má ṣe yọ̀, ìwọ Israẹli; má ṣe hó ìhó ayọ̀ bí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù. Nítorí ẹ ti jẹ́ aláìṣòótọ́ si Ọlọ́run yín. Ẹ fẹ́ràn láti gba owó iṣẹ́ àgbèrè ní gbogbo ilẹ̀ ìpakà.
2 Ama harman yeri, şarap teknesi halkı doyurmayacak, Yeni şarap umutları boşa çıkacak.
Àwọn ilẹ̀ ìpakà àti ilé ìfun wáìnì kò ní fún àwọn ènìyàn lóúnjẹ wáìnì tuntun yóò tàn láìròtẹ́lẹ̀.
3 RAB'bin diyarında kalmayacaklar, Mısır'a dönecek Efrayim, Asur'da kirli sayılan şeyleri yiyecekler.
Wọn kò ní ṣẹ́kù sí ilé Olúwa Efraimu yóò padà sí Ejibiti, yóò sì jẹ oúnjẹ àìmọ́ ní Asiria.
4 RAB'be şarap sunuları dökmeyecekler, O'nu hoşnut etmeyecek kurbanları. Kurbanları yas yemeğine dönecek, Kirli sayılacak onları yiyenlerin hepsi. Yalnız kendi karınlarını doyuracak yiyecekleri, RAB'bin Tapınağı'na girmeyecek.
Wọn kò ní fi ọrẹ ohun mímu fún Olúwa. Bẹ́ẹ̀ ni ìrúbọ wọn kò ní mú, inú rẹ̀ dùn. Ìrú ẹbọ bẹ́ẹ̀ yóò dàbí oúnjẹ àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀. Gbogbo àwọn tó bá sì jẹ ẹ́ yóò di aláìmọ́. Oúnjẹ yìí yóò wà fún wọn fúnra wọn kò ní wá sí orí tẹmpili Olúwa.
5 Ne yapacaksınız dinsel bayramlarda, RAB'bin bayram gününde?
Kí ni ẹ̀yin ó ṣe ní ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn ní àwọn ọjọ́ àjọ̀dún Olúwa?
6 Yıkımdan kaçsalar bile, Mısır bir araya toplayacak onları, Mof gömecek. Değerli gümüş eşyalarını yabanıl otlar saracak, Diken bitecek çadırlarında.
Bí wọ́n tilẹ̀ yọ́ kúrò lọ́wọ́ ìparun Ejibiti yóò kó wọn jọ, Memfisi yóò sì sin wọ́n. Ibi ìsọjọ̀ fàdákà wọn ni ẹ̀gún yóò jogún, Ẹ̀gún yóò bo àpótí ìṣúra fàdákà wọn. Ẹ̀gún yóò sì bo gbogbo àgọ́ wọn.
7 Onların ceza günleri geldi, Hesap günleri çattı. Bunu bilsin İsrail! Suçunuzun çokluğundan, Düşmanlığınızın büyüklüğü yüzünden, Peygamber aptal, ruhsal insan deli sayıldı.
Àwọn ọjọ́ ìjìyà ń bọ̀; àwọn ọjọ́ ìṣirò iṣẹ́ ti dé. Jẹ́ kí Israẹli mọ èyí. Nítorí pé ẹ̀ṣẹ̀ yín pọ̀ ìkórìíra yín sì pọ̀ gan an ni. A ka àwọn wòlíì sí òmùgọ̀, a ka ẹni ìmísí sí asínwín.
8 Peygamber Tanrım'ın yanısıra Efrayim'e gözcülük eder, Ama tuzak kurulmuş bütün yollarına, Düşmanlık var Tanrı'nın Tapınağı'nda.
Wòlíì, papọ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run, ni olùṣọ́ ọ Efraimu. Síbẹ̀ ìdẹ̀kùn dúró dè é ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìkórìíra ní ilé Ọlọ́run rẹ̀.
9 Alabildiğine yozlaştılar, Giva'da olduğu gibi. Tanrı suçlarını anımsayacak, Günahlarının cezasını verecek.
Wọ́n ti gbilẹ̀ nínú ìwà ìbàjẹ́ gẹ́gẹ́ bí i ọjọ́ Gibeah Ọlọ́run yóò rántí ìwà búburú wọn yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
10 “İsrail çölde Bir salkım üzüm gibi geldi bana, Atalarıysa incir ağacının ilk ürünü gibi. Ama Baal-Peor'a geldiklerinde Utanç dolu puta adadılar kendilerini, Sevdikleri şey kadar iğrenç oldular.
“Mo rí Israẹli bí èso àjàrà ní aginjù. Mo rí àwọn baba yín, bí àkọ́pọ́n nínú igi ọ̀pọ̀tọ́ ní àkọ́so rẹ̀. Ṣùgbọ́n wọ́n tọ Baali-Peori lọ, wọ́n yà wọn sọ́tọ̀ fún òrìṣà tó ń mú ìtìjú bá ni, ohun ìríra wọn sì rí gẹ́gẹ́ bí wọn ti fẹ́.
11 Efrayim'in görkemi bir kuş gibi uçup gidecek, Ne doğum ne gebelik olacak, kimse gebe kalmayacak.
Ògo Efraimu yóò fò lọ bí ẹyẹ kò ní sí ìfẹ́rakù, ìlóyún àti ìbímọ.
12 Çocuklarını büyütseler bile, Çocuklarından edeceğim onları, Kimse kalmayıncaya dek; Evet, vay başlarına, Onları terk ettiğimde!
Bí wọ́n tilẹ̀ tọ́ ọmọ dàgbà. Èmi yóò mú wọn ṣọ̀fọ̀ lórí gbogbo wọn. Ègbé ni fún wọn, nígbà tí mo yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn!
13 Efrayim'i, Sur Kenti gibi, Güzel bir yere kurulmuş gördüm. Ama Efrayim çocuklarını celladın önüne götürecek.”
Mo rí Efraimu bí ìlú Tire tí a tẹ̀dó sí ibi dáradára ṣùgbọ́n Efraimu yóò kó àwọn ọmọ rẹ̀ jáde fún àwọn apànìyàn.”
14 Ya RAB, ver onlara ne vereceksen! Düşük yapan rahimler, sütsüz memeler ver.
Fún wọn, Olúwa! Kí ni ìwọ yóò fún wọn? Fún wọn ní inú tí ń ba oyún jẹ́ àti ọyàn gbígbẹ.
15 “Gilgal'daki kötülükleri yüzünden, Nefret ettim orada onlardan. İşledikleri günahlardan ötürü, Onları evimden kovacağım. Artık sevmeyeceğim onları, Bütün önderleri asidir.
“Nítorí gbogbo ìwà búburú tí wọ́n hù ní Gilgali, Mo kórìíra wọn níbẹ̀, nítorí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Èmi yóò lé wọn jáde ní ilé mi, Èmi kò ní ní ìfẹ́ wọn mọ́ ọlọ̀tẹ̀ ni gbogbo olórí wọn.
16 Vuruldu Efrayim, Kökleri kurudu, Meyve vermeyecekler artık. Çocuk doğursalar bile, Rahimlerinin değerli meyvelerini öldüreceğim.”
Efraimu ti rẹ̀ dànù gbogbo rẹ̀ sì ti rọ, kò sì so èso. Bí wọ́n tilẹ̀ bímọ. Èmi ó pa àwọn ọmọ wọn tí wọ́n fẹ́ràn jùlọ.”
17 Reddedecek Tanrım onları, Çünkü O'nu dinlemediler, Uluslar arasında dolaşıp duracaklar.
Ọlọ́run mi yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ nítorí pé wọn kò gbọ́rọ̀ sí i; wọn yóò sì di alárìnkiri láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.