< Ezra 7 >

1 Bu olaylardan sonra, Pers Kralı Artahşasta'nın krallığı döneminde, Başkâhin Harun oğlu Elazar oğlu Pinehas oğlu Avişua oğlu Bukki oğlu Uzzi oğlu Zerahya oğlu Merayot oğlu Azarya oğlu Amarya oğlu Ahituv oğlu Sadok oğlu Şallum oğlu Hilkiya oğlu Azarya oğlu Seraya oğlu Ezra adında biri Babil'den geldi. Ezra İsrail'in Tanrısı RAB'bin Musa'ya verdiği yasayı iyi bilen bir bilgindi. Tanrısı RAB'bin yardımıyla kral ona her istediğini verdi.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ní àkókò ìjọba ọba Artasasta ní Persia, Esra ọmọ Seraiah, ọmọ Asariah, ọmọ Hilkiah,
2
ọmọ Ṣallumu, ọmọ Sadoku, ọmọ Ahitubu,
3
ọmọ Amariah, ọmọ Asariah, ọmọ Meraioti,
4
ọmọ Serahiah, ọmọ Ussi, ọmọ Bukki,
5
ọmọ Abiṣua, ọmọ Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni olórí àlùfáà—
6
Esra yìí sì gòkè wá láti Babeli. Olùkọ́ tí ó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa òfin Mose, èyí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ti fi fún wọn. Ọba sì fi gbogbo ohun tí ó béèrè fún un, nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára rẹ̀.
7 Kral Artahşasta'nın krallığının yedinci yılında İsrail halkından, kâhinlerden, Levililer'den, ezgicilerden, tapınak görevlilerinden ve kapı nöbetçilerinden bazıları Yeruşalim'e gitti.
Ní ọdún keje ọba Artasasta díẹ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà àti àwọn tí ń ṣiṣẹ́ nínú tẹmpili náà gòkè wá sí Jerusalẹmu.
8 Ezra, Artahşasta'nın krallığının yedinci yılının beşinci ayında Yeruşalim'e vardı.
Ní oṣù karùn-ún ọdún keje ọba yìí ni Esra dé sí Jerusalẹmu.
9 Birinci ayın birinci günü Babil'den ayrılmıştı. Tanrısı'nın koruyucu eli sayesinde beşinci ayın birinci günü Yeruşalim'e vardı.
Ó bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ láti Babeli ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ó sì dé Jerusalẹmu ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run rẹ̀ wà ní ara rẹ̀.
10 Ezra kendini RAB'bin Yasası'nı inceleyip uygulamaya ve İsrail'de kuralları, ilkeleri öğretmeye adamıştı.
Esra ti fi ara rẹ̀ jì fún kíkọ́ àti pípa òfin Olúwa mọ́, ó sì ń kọ́ òfin àti ìlànà Mose ní Israẹli.
11 Kral Artahşasta'nın RAB'bin buyruklarını, İsrail için koyduğu kuralları iyi bilen Kâhin ve Bilgin Ezra'ya verdiği mektubun bir örneği şudur:
Èyí ni ẹ̀dà lẹ́tà ti ọba Artasasta fún àlùfáà Esra olùkọ́ni, ẹni tó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú àkọsílẹ̀ òfin àti ìlànà Olúwa fún Israẹli.
12 “Kralların Kralı Artahşasta'dan Gökler Tanrısı'nın Yasası'nın bilgini Kâhin Ezra'ya selamlar!
Artasasta, ọba àwọn ọba. Sí àlùfáà Esra, olùkọ́ òfin Ọlọ́run ọ̀run. Àlàáfíà.
13 “Krallığımda yaşayan İsrail halkından, kâhinlerden ve Levililer'den Yeruşalim'e gitmek isteyen herkesin seninle gidebilmesi için buyruk veriyorum.
Mo pàṣẹ pé ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi, ti ó wà ní abẹ́ ìṣàkóso ìjọba mi, tí ó bá fẹ́ láti bá ọ lọ sí Jerusalẹmu lè tẹ̀lé ọ lọ.
14 Elindeki Tanrın'ın Yasası'nın uygulanıp uygulanmadığı konusunda Yahuda ve Yeruşalim'de araştırma yapman için, ben ve yedi danışmanım seni görevlendirdik.
Ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ méjèèje rán ọ lọ láti wádìí nípa òfin Ọlọ́run rẹ tí ó wà ní ọwọ́ rẹ nípa Juda àti Jerusalẹmu.
15 Benim ve danışmanlarımın Yeruşalim'de konut kuran İsrail'in Tanrısı'na gönülden verdiğimiz altını, gümüşü birlikte götürmelisin.
Síwájú sí i, kí ìwọ kí ó kó fàdákà àti wúrà lọ pẹ̀lú rẹ èyí tí ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ fi tọkàntọkàn fún Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ibùjókòó rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu,
16 Babil İli'nden elde edeceğin altının, gümüşün tümünü, halkın ve kâhinlerin Tanrıları'nın Yeruşalim'deki Tapınağı'na gönülden verdikleri armağanları da alıp götürmelisin.
pẹ̀lú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ìwọ lè rí ní agbègbè ìjọba Babeli àti àwọn ọrẹ àtinúwá àwọn ènìyàn àti ti àwọn àlùfáà fún tẹmpili Ọlọ́run wọn ní Jerusalẹmu.
17 “Bu parayla hemen boğalar, koçlar, kuzular, tahıl sunuları ve dökmelik sunular satın alacak ve hepsini Tanrın'ın Yeruşalim'deki Tapınağı'nın sunağı üzerinde sunacaksın.
Pẹ̀lú owó yìí, rí i dájú pé ó ra àwọn akọ màlúù, àwọn àgbò àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, àti ọrẹ ohun mímu, kí ìwọ kí ó fi wọ́n rú ẹbọ lórí pẹpẹ tẹmpili Ọlọ́run rẹ ní Jerusalẹmu.
18 Sen ve kardeşlerin artan altını, gümüşü Tanrınız'ın isteği uyarınca dilediğiniz gibi kullanın.
Ìwọ àti àwọn Júù arákùnrin rẹ lè fi èyí tókù fàdákà àti wúrà ṣe ohunkóhun tí ó bá dára lójú yín, ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run yín.
19 Tanrın'ın Tapınağı'nın hizmetinde kullanılmak üzere sana verilen kapların hepsini Yeruşalim'in Tanrısı'na sun.
Kó gbogbo ohun èlò tí a fi sí ìkáwọ́ rẹ fún Ọlọ́run Jerusalẹmu fún ìsìn nínú tẹmpili Ọlọ́run rẹ.
20 Tanrın'ın Tapınağı için ödemen gereken başka bir şey varsa, giderleri kralın hazinesinden karşılarsın.
Ohunkóhun mìíràn tí o bá nílò fún tẹmpili Ọlọ́run rẹ tí ó sì ní láti pèsè, o lè mú u láti inú ìṣúra ọba.
21 “Ben, Kral Artahşasta, Fırat'ın batı yakasındaki bölgenin bütün hazine görevlilerine buyruk veriyorum: Gökler Tanrısı'nın Yasası'nın bilgini Kâhin Ezra'nın sizden her istediğini özenle yerine getirin.
Èmi, ọba Artasasta, pàṣẹ fún gbogbo olùtọ́jú ilé ìṣúra agbègbè Eufurate láìrójú láti pèsè ohunkóhun tí àlùfáà Esra, olùkọ́ni ní òfin Ọlọ́run ọ̀run bá béèrè lọ́wọ́ yín
22 Kendisine gerektiğinde yüz talanta kadar gümüş, yüz kor buğday, yüz bat şarap, yüz bat zeytinyağı ve istediği kadar tuz sağlayın.
tó ọgọ́rùn-ún kan tálẹ́ǹtì fàdákà, ọgọ́rùn-ún kan òsùwọ̀n àlìkámà, àti dé ọgọ́rùn-ún bati ọtí wáìnì, àti dé ọgọ́rùn-ún bati òróró olifi, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ iyọ̀.
23 Göklerin Tanrısı kendi tapınağı için ne buyurursa, özenle yerine getirin. Öyle ki, bana ve oğullarıma öfkelenmesin.
Ohunkóhun tí Ọlọ́run ọ̀run bá fẹ́, jẹ́ kí ó di ṣíṣe ní pípé fún tẹmpili Ọlọ́run ọ̀run. Èéṣe tí ìbínú yóò ṣe wá sí agbègbè ọba àti sí orí àwọn ọmọ rẹ̀?
24 Şunu da bilesiniz ki, kâhinlerden, Levililer'den, ezgicilerden, tapınak görevlilerinden ve kapı nöbetçilerinden, Tanrı'nın Tapınağı'nın öbür hizmetkârlarından vergi almaya yetkiniz yoktur.
Ìwọ sì ní láti mọ̀ pé ìwọ kò ní àṣẹ láti sọ sísan owó orí, owó òde tàbí owó bodè di dandan fún àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà, àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili tàbí àwọn òṣìṣẹ́ mìíràn nínú ilé Ọlọ́run yìí.
25 “Sana gelince, Ezra, sendeki Tanrı bilgeliği uyarınca yargıçlar ata. Bunlar Fırat'ın batı yakasındaki bölgede yaşayan bütün halka, Tanrın'ın yasalarını bilenlerin hepsine adalet sağlasınlar. Yasayı bilmeyenlere de siz öğreteceksiniz.
Ìwọ Esra, ní ìbámu pẹ̀lú ọgbọ́n Ọlọ́run rẹ̀, èyí tí ó ní, yan àwọn adájọ́ àgbà àti àwọn onídàájọ́ láti máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ènìyàn agbègbè Eufurate, gbogbo àwọn tí ó mọ òfin Ọlọ́run rẹ. Ìwọ yóò sì kọ́ ẹnikẹ́ni tí kò mọ̀ àwọn òfin náà.
26 Tanrın'ın Yasası'na ve kralın buyruklarına uymayanlar ya ölümle, ya sürgünle, ya mallarına el konarak, ya da hapsedilerek cezalandırılsın.”
Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣe ìgbọ́ràn sí òfin Ọlọ́run rẹ àti sí òfin ọba ní ó gbọdọ̀ kú tàbí kí a lé e jáde tàbí kí a gbẹ́sẹ̀ lé ẹrù rẹ̀ tàbí kí a sọ ọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.
27 Atalarımızın Tanrısı RAB'be övgüler olsun! Kralın yüreğine Yeruşalim'deki tapınağını onurlandırma isteğini koydu.
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ẹni tí ó fi sí ọkàn ọba láti mú ọlá wá sí ilé Olúwa ní Jerusalẹmu ní ọ̀nà yìí.
28 Kralın, danışmanlarının, güçlü komutanlarının bana iyi davranmalarını sağladı. Tanrım RAB'bin eli üzerimde olduğundan yüreklendim. İsrail ileri gelenlerinin bazılarını toplayıp benimle Yeruşalim'e dönmelerini sağladım.
Ẹni tí ó jẹ́ kí ojúrere rẹ̀ tàn kàn mí níwájú ọba àti àwọn olùbádámọ̀ràn àti ní iwájú àwọn alágbára ìjòyè ọba. Nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára mi, mo mú ọkàn le, mo sì kó àwọn olórí jọ láàrín àwọn ènìyàn Israẹli láti gòkè lọ pẹ̀lú mi.

< Ezra 7 >