< Hezekiel 5 >

1 “Ey insanoğlu, keskin bir kılıç al, berber usturası gibi kullanarak başını, sakalını tıraş et. Sonra bir terazi getir, kılları bölümlere ayır.
“Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
2 Yeruşalim'in kuşatılması bitince, kılların üçte birini kentin ortasında yakacaksın. Üçte birini kılıçla kentin çevresine fırlatacak, kalan üçte birini de rüzgara savuracaksın. Ben de yalın kılıç onların peşine düşeceğim.
Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
3 Birkaç tel kıl bırak, giysinin kıvrımlarına tak.
Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
4 Yine birkaçını alıp ateşe at, yansın. O kıllardan bütün İsrail halkına ateş yayılacak.
Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
5 “Egemen RAB diyor ki: Bu Yeruşalim'i ulusların ortasına yerleştirdim, çevresini ülkelerle kuşattım.
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
6 Öyleyken Yeruşalim çevresindeki bütün uluslardan ve ülkelerden daha çok kötülük yaparak ilkelerimi, kurallarımı çiğnedi. İlkelerime karşı geldi, kurallarım uyarınca davranmadı.
Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
7 Bundan ötürü Egemen RAB diyor ki: Çevrenizde yaşayan uluslardan daha azgındınız, kurallarımı izlemediniz, ilkelerime uymadınız. Çevrenizde yaşayan ulusların ilkelerine de uymadınız.
“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
8 “Bundan ötürü Egemen RAB diyor ki: İşte ben size karşıyım, ulusların gözü önünde sizi cezalandıracağım.
“Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
9 Yaptığınız bütün iğrençlikler yüzünden önceden yapmadığımı, bir daha yapmayacağımı size yapacağım.
Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
10 Böylece aranızda babalar çocuklarını, çocuklar da babalarını yiyecekler. Sizi cezalandıracağım, sağ kalanlarınızı her yana dağıtacağım.
Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
11 Egemen RAB varlığım hakkı için diyor, madem tapınağımı iğrenç put ve uygulamalarınızla kirlettiniz, ben de sizi esirgemeyecek, size acımayacak, sizi kayırmayacağım.
Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
12 Kentte yaşayanlarınızın üçte biri salgın hastalık ya da kıtlık yüzünden yok olacak; üçte biriniz çevrede kılıçtan geçirilecek; üçte birinizi de her yana dağıtıp yalın kılıç peşinize düşeceğim.
Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
13 “Böylece kızgınlığım son bulacak, onlara karşı öfkemi yatıştıracağım. O zaman ben de rahata kavuşacağım. Öfkemi onların üzerine boşaltınca, ben RAB'bin kıskançlığımdan onlarla konuştuğumu anlayacaklar.
“Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
14 “Çevrenizdeki uluslar arasında, yoldan her geçenin gözü önünde sizi yıkıma uğratacak, aşağılayacağım.
“Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
15 Öfke, kızgınlık ve acı paylamalarla sizi cezalandırdığımda çevrenizdeki uluslar arasında alay konusu olacak, aşağılanacaksınız; ders alınacak, şaşılacak bir duruma düşeceksiniz. Ben, RAB bunu söyledim.
O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
16 Sizi yok etmek için üzerinize öldürücü, yıkıcı kıtlık oklarını salacağım. Üzerinize salacağım kıtlığı daha da artıracak, sizi her türlü yiyecekten yoksun bırakacağım.
Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
17 Üzerinize kıtlık ve yabanıl hayvanlar salacağım, sizi çocuklarınızdan edecekler. Salgın hastalık ve dökülen kan sizi süpürüp yok edecek; başınıza da kılıç getireceğim. Ben, RAB böyle söyledim.”
Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”

< Hezekiel 5 >