< Hezekiel 39 >
1 “İnsanoğlu, Gog'a karşı peygamberlik et ve ona de ki, ‘Egemen RAB şöyle diyor: Ey Roş'un, Meşek'in, Tuval'ın önderi Gog, sana karşıyım.
“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí Gogu, kí ó sì wí pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, Ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé ti Meṣeki àti Tubali.
2 Seni geri çevirip sürükleyeceğim. Seni uzak kuzeyden çıkarıp İsrail'in dağlarına getireceğim.
Èmi yóò dá ọ padà, èmi yóò sì darí rẹ. Èmi yóò mú ọ wá láti jìnnàjìnnà ìhà àríwá, Èmi yóò rán ọ lòdì sí orí àwọn òkè gíga Israẹli.
3 Sol elindeki yayını vuracak, sağ elindeki oklarını düşüreceğim.
Nígbà náà èmi yóò lu ọrùn awọ rẹ ní ọwọ́ òsì rẹ, èmi yóò sì mú kí àwọn ọfà rẹ jábọ́ ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
4 Sen de askerlerinle senden yana olan uluslar da İsrail dağlarına serileceksiniz. Sizi yem olarak her çeşit yırtıcı kuşa, yabanıl hayvana vereceğim.
Ìwọ yóò sì ṣubú ní orí àwọn òkè Israẹli, ìwọ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn onírúurú ẹyẹ àti fún àwọn ẹranko igbó.
5 Açık kırlarda düşüp öleceksiniz. Çünkü bunu ben söyledim. Egemen RAB böyle diyor.
Ìwọ yóò ṣubú ní gbangba pápá, nítorí tì mo ti sọ̀rọ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
6 Magog'un ve kıyıda güvenlik içinde yaşayanların üzerine ateş yağdıracağım. O zaman benim RAB olduğumu anlayacaklar.
Èmi yóò fi iná sí Magogu àti sí àwọn tí ń gbé ní agbègbè ilẹ̀ ibẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
7 “‘Halkım İsrail arasında kutsal adımı tanıtacağım. Bundan böyle kutsal adımın aşağılanmasına izin vermeyeceğim. Uluslar benim İsrail'de kutsal olan RAB olduğumu anlayacaklar.
“‘Èmi yóò sọ orúkọ mímọ́ mí di mí mọ̀ láàrín àwọn ènìyàn mì Israẹli. Èmi ki yóò jẹ́ kí orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́ àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, Èmi ni ẹni mímọ́ ní Israẹli.
8 O gün yaklaştı! Söylediklerim olacak. Egemen RAB böyle diyor. Budur sözünü ettiğim gün!
Ó ń bọ̀! Ó dájú pé yóò ṣẹlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè. Èyí yìí ni ọjọ́ tí mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.
9 “‘O zaman İsrail kentlerinde yaşayanlar dışarı çıkıp topladıkları silahları yakacaklar. Küçük büyük kalkanları, yayları, okları, sopaları, mızrakları ateşe atacaklar. Bunlarla yedi yıl ateş yakacaklar.
“‘Nígbà náà, àwọn ti ó ń gbé nì àárín àwọn ìlú tí ó wà ni Israẹli yóò jáde, wọn yóò sì lo àwọn ohun ìjà bi epo ìdáná yóò sì jó wọ́n kanlẹ̀—àpáta kéékèèké àti àpáta ńlá, àwọn ọfà, àwọn kùmọ̀ ogun àti ọ̀kọ̀ fún ọdún méje wọn yóò lò wọ́n bi epo ìdáná.
10 Kırdan odun toplamayacak, ormandan odun kesmeyecekler. Yakmak için silahları kullanacaklar. Mallarını yağmalayanları yağmalayacak, kendilerini soyanları soyacaklar. Egemen RAB böyle diyor.
Wọn kò ní nílò láti kó igi jọ láti inú pápá, tàbí gé e láti inú igbó, nítorí pé wọ́n yóò lo òhun ìjà ogun bi epo ìdáná. Wọn yóò sì kógun àwọn tí ó ṣe ìgárá sí wọn, wọn yóò sì bo ilé àwọn tí ó bo ilé wọn, ni Olúwa Olódùmarè.
11 “‘O gün Lut Gölü'nün doğusunda, Gezginler Deresi'nde Gog'a İsrail'de bilinen bir mezar yeri vereceğim. Gog'la bütün ordusu orada gömülecek. Oraya Hamon-Gog Vadisi adı verilecek. Oradan geçecek gezginlerin önü kesilecek.
“‘Ní ọjọ́ náà èmi yóò sì fi ibi ìsìnkú fún Gogu ní Israẹli, ni àfonífojì àwọn ti ó rìn ìrìnàjò lọ sí agbègbè ilà oòrùn Òkun. Yóò di ojú ọ̀nà àwọn arìnrìn-àjò, nítorí Gogu àti gbogbo ìjọ rẹ̀ ni àwa yóò sin síbẹ̀. Nítorí náà, a yóò pè é ní àfonífojì tí Ammoni Gogu.
12 İsrail halkı ülkeyi arındırmak için onları gömecek. Bu yedi ay sürecek.
“‘Fún oṣù méje ní ilé Israẹli yóò fi máa sìn wọ́n láti ṣe àfọ̀mọ́ ilẹ̀ náà.
13 Onları bütün ülke halkı gömecek. Görkemimi açıkladığım gün onlar için onur olacak. Egemen RAB böyle diyor.
Gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà yóò sìn wọ́n, ọjọ́ tí a yìn mi lógo yóò jẹ́ ọjọ́ ìrántí, ní Olúwa Olódùmarè wí.
14 “‘Ülkeyi arındırmak için adamlar görevlendirilecek. Bazıları ülkeyi sürekli dolaşacak, öbürleriyse yerde kalan cesetleri gömecekler. Yedi aylık süre bitince, araştırma işine başlayacaklar.
“‘Wọn yóò gbà àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ lóòrèkóòrè láti ṣe àfọ̀mọ́ náà. Ọ̀pọ̀ yóò lọ káàkiri ilẹ̀ náà, ní àfikún pẹ̀lú wọn, àwọn tókù yóò sìn àwọn tí ó kú lórí ilẹ̀. Ní ìparí oṣù keje wọn yóò bẹ̀rẹ̀ wíwá kiri wọn.
15 Bu adamlar ülkenin her yanını dolaşacak. Bir insan kemiği görünce, mezarcılar onu Hamon-Gog Vadisi'ne gömünceye dek, yanına bir işaret koyacak.
Bí wọ́n n lọ káàkiri ilẹ̀ náà ọ̀kan nínú wọn rí egungun ènìyàn, òun yóò gbé àmì ńlá kalẹ̀ ni ẹ̀gbẹ́ rẹ títí àwọn asìnkú yóò fi sìn ín ní àfonífojì Hamoni Gogu.
16 Orada Hamona adında bir kent olacak. Böylelikle ülke arındırılacak.’
Bákan náà ìlú kan tí a ń pè ni Hamona yóò wà níbẹ̀. Nítorí náà wọn yóò wẹ ilẹ̀ náà.’
17 “İnsanoğlu, Egemen RAB şöyle diyor: Her çeşit kuşa ve yabanıl hayvana seslen: ‘Sizin için hazırlayacağım kurbana, İsrail dağları üzerindeki büyük kurbana gelin, her yandan toplanın! Orada et yiyecek, kan içeceksiniz.
“Ọmọ ènìyàn èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí pé, pe gbogbo oríṣìíríṣìí ẹyẹ àti gbogbo àwọn ẹranko igbó jáde, ‘Kí wọn péjọpọ̀ láti gbogbo agbègbè sí ìrúbọ tí mó ń múra rẹ̀ fún ọ, ìrúbọ ńlá náà ní orí òkè gíga tí Israẹli. Níbẹ̀ ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀.
18 Başan'ın besili hayvanlarının –koçların, kuzuların, tekelerin, boğaların– etini yiyip kanını içer gibi yiğitlerin etini yiyecek, dünya önderlerinin kanını içeceksiniz.
Ẹ̀yin yóò jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn ńlá, ẹ o sì mú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ-aládé ayé bí ẹni pé wọn jẹ́ àgbò àti ọ̀dọ́-àgùntàn, ewúrẹ́ àti akọ màlúù gbogbo wọn jẹ́ ẹran ọlọ́ràá láti Baṣani.
19 Sizin için hazırlayacağım kurbandan doyana dek yağ yiyeceksiniz, sarhoş oluncaya dek kan içeceksiniz.
Níbi ìrúbọ tí mo ń múra kalẹ̀ fún yín, ẹ̀yin yóò jẹ ọ̀rá títí ẹ̀yin yóò fi jẹ àjẹkì, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ títí ẹ̀yin yóò fi yó.
20 Soframda atlardan, atlılardan, yiğitlerden ve her çeşit askerden bol bol yiyip doyacaksınız.’ Egemen RAB böyle diyor.
Ní orí tábìlì mi ni àwa yóò ti fi ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin bọ yín yó, pẹ̀lú àwọn alágbára ńlá àti oríṣìíríṣìí jagunjagun,’ ni Olúwa Olódùmarè wí.
21 “Görkemimi uluslar arasında açıklayacağım. Bütün uluslar kendilerine verdiğim cezayı, üzerlerine koyduğum elimi görecekler.
“Èmi yóò ṣe àfihàn ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì rí ìyà tí mo fi jẹ wọ́n.
22 İsrail halkı o günden başlayarak benim Tanrıları RAB olduğumu anlayacak.
Láti ọjọ́ náà lọ, ilé Israẹli yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.
23 Uluslar İsrail halkının işlediği suç yüzünden, bana ihanet ettiği için sürgüne gittiğini anlayacaklar. Yüzümü onlardan gizledim, onları düşmanlarının eline teslim ettim, hepsi kılıçtan geçirildi.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì mọ̀ pé àwọn ènìyàn Israẹli lọ sí ìgbèkùn nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí pé wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi. Nítorí náà mo mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, mo sì fi wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, gbogbo wọn sì ṣubú nípasẹ̀ idà.
24 Onları kirliliklerine, isyanlarına göre cezalandırdım, yüzümü onlardan gizledim.
Mo ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí àìmọ́ àti àìṣedéédéé wọn, mo sì mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
25 “Bundan ötürü Egemen RAB şöyle diyor: Yakup'un sürgündeki soyunu geri getirecek, İsrail halkına acıyacağım. Kutsal adımı kıskançlıkla koruyacağım.
“Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Jakọbu padà kúrò ní oko ẹrú, èmi yóò ní ìyọ́nú si gbogbo ènìyàn Israẹli, èmi yóò sì ní ìtara fún orúkọ mímọ́ mi.
26 Ülkelerinde güvenlik içinde yaşayınca, onları korkutan kimse olmayınca, utançlarını, bana ettikleri bütün ihanetleri unutacaklar.
Wọn yóò gbàgbé ìtìjú wọn àti gbogbo àìṣòdodo tí wọ́n fihàn sí mi nígbà tí wọn ń gbé ni àìléwu ni ilẹ̀ wọn níbi tí kò ti sí ẹnikẹ́ni láti dẹ́rùbà wọ́n.
27 Onları uluslar arasından geri getirip düşman ülkelerinden topladığım zaman, onlar aracılığıyla birçok ulusa kutsallığımı göstereceğim.
Nígbà tí mo ti mú wọn padà kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì kó wọn jọ pọ̀ kúrò ni ìlú àwọn ọ̀tá wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ wọn ní ojú àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀.
28 O zaman benim Tanrıları RAB olduğumu anlayacaklar. Onları uluslar arasına sürgüne göndermeme karşın, hiçbirini bırakmadan ülkelerine geri getireceğim.
Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn nítorí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo rán wọn lọ sí ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò kó wọn jọ sí orí ilẹ̀ wọn, láìfi nǹkan kan sẹ́yìn.
29 Onlardan bir daha yüzümü gizlemeyeceğim, çünkü İsrail halkı üzerine Ruhum'u dökeceğim.” Egemen RAB böyle diyor.
Èmi kì yóò sì fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn mọ nítorí èmi yóò tú èémí mi jáde sí ilé Israẹli, ní Olúwa Olódùmarè wí.”