< Hezekiel 22 >

1 RAB bana şöyle seslendi:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 “İnsanoğlu, Yeruşalim'i yargılayacak mısın? Kan döken bu kenti yargılayacak mısın? Öyleyse bütün iğrenç uygulamalarını ona bildir.
“Ọmọ ènìyàn ǹjẹ́ ìwọ yóò ha ṣe ìdájọ́ rẹ̀? Ǹjẹ́ ìwọ ha ṣe ìdájọ́ ìlú atàjẹ̀sílẹ̀? Tó bá rí bẹ́ẹ̀ dojúkọ wọn pẹ̀lú gbogbo ìwà ìríra wọn.
3 Şöyle diyeceksin: ‘Egemen RAB diyor ki: Ey kendi içinde kan dökerek yıkımını hazırlayan, putlar yaparak kendini kirleten kent!
Kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ìlú ńlá tí ó mú ìparun wá sórí ara rẹ nípa títàjẹ̀sílẹ̀ ní àárín rẹ, tí ó sì ba ara rẹ̀ jẹ́ nípa ṣíṣe àwọn ère.
4 Döktüğün kan yüzünden suçlu bulundun, yaptığın putlarla kirlendin. Böylece günlerin yaklaştı, yıllarının sonuna ulaştın. Bu yüzden seni uluslara alay konusu edeceğim, bütün ülkelerin gözünde seni gülünç duruma düşüreceğim.
Ìwọ ti jẹ̀bi nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀, àti pé àwọn ère tí ó ṣe tí bà ọ́ jẹ́. Ìwọ tí mú ọjọ́ rẹ súnmọ́ tòsí, ìparí àwọn ọdún rẹ sì ti dé. Nítorí náà èmi yóò fi ọ ṣe ohun ẹ̀gàn lójú àwọn orílẹ̀-èdè àti ohun ẹ̀sín lójú gbogbo ìlú.
5 Ey adı kötüye çıkmış, kargaşa dolu kent, yakındakiler de uzaktakiler de seninle alay edecekler.
Àwọn tí ó wà ní tòsí àti àwọn tí ó jìnnà sí ọ, yóò fi ọ ṣe ẹlẹ́yà, ìwọ ìlú ẹlẹ́gàn, tí ó kún fún làálàá.
6 “‘İşte içindeki her İsrail önderi yetkisini kullanarak kan döküyor.
“‘Wo bí ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli tí ó wà nínú yín ti ń lo agbára rẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀.
7 Senin içinde anneye, babaya kötü davrandılar, yabancıya baskı yaptılar, öksüze, dul kadına haksızlık ettiler.
Nínú rẹ wọn ti hùwà sí baba àti ìyá pẹ̀lú ìfojú tínrín; nínú rẹ wọn ti ni àwọn àlejò lára, wọn sì hùwàkiwà sí aláìní baba àti opó.
8 Benim kutsal eşyalarıma saygısızlık ettin, Şabat günlerimi hiçe saydın.
Ìwọ tí kọ àwọn ohun mímọ́ mi sílẹ̀, ìwọ sì ti lo ọjọ́ ìsinmi mi ní ìlòkulò.
9 Kan dökmek için iftira edenler, dağlarda putlara kurban edilen hayvanları yiyenler, kendilerini şehvete kaptıranlar senin içinde yaşıyor.
Nínú rẹ ni àwọn ayannijẹ ènìyàn pinnu láti tàjẹ̀ sílẹ̀; nínú rẹ ní àwọn tí ó ń jẹun ní orí òkè ojúbọ òrìṣà, wọn sì hùwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.
10 Babalarının karılarıyla yatanlar, âdet gören dinsel açıdan kirli kadınlarla cinsel ilişki kuranlar senin içinde yaşıyor.
Nínú rẹ ní àwọn ti kò bu ọlá fún àwọn àkéte baba wọn; nínú rẹ ni àwọn tí o ń bá àwọn obìnrin lò nígbà tí wọ́n ń ṣe àkókò lọ́wọ́, ní àsìkò tí a ka wọn sì aláìmọ́.
11 Senin içinde kimi komşusunun karısıyla iğrenç şeyler yaptı; kimi utanmadan gelinini kirletti; kimi öz kızkardeşiyle ilişki kurdu.
Nínú rẹ ọkùnrin kan ti dá ẹ̀ṣẹ̀ ìríra pẹ̀lú aya aládùúgbò rẹ̀, òmíràn bá ìyàwó ọmọ rẹ̀ jẹ́, òmíràn sì bá arábìnrin rẹ̀ lòpọ̀ èyí tí í ṣe ọbàkan rẹ̀.
12 Senin içinde kan dökmek için rüşvet aldılar. Faiz aldın, tefecilik yaptın, zorbalıkla komşularından haksız kazanç sağladın. Beni unuttun. Egemen RAB böyle diyor.
Nínú rẹ àwọn ènìyàn gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀; ìwọ gba èlé ìlọ́po láti mú aláìṣòótọ́ jèrè láti ara aládùúgbò rẹ nípa ìrẹ́jẹ. Ìwọ sì ti gbàgbé èmi; ni Olúwa Olódùmarè wí.
13 “‘Edindiğiniz haksız kazançtan, içinizde döktüğünüz kandan ötürü ellerimi birbirine vuracağım.
“‘Èmi yóò kúkú pàtẹ́wọ́ lórí èrè àìmọ̀ tí ìwọ ti jẹ, àti lórí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀ ní àárín yín.
14 Sizinle uğraşacağım gün cesaretiniz kalacak mı? Elleriniz güçlü olabilecek mi? Bunu ben RAB söylüyorum ve dediğimi yapacağım.
Ọkàn rẹ le gbà á, tàbí ọwọ́ rẹ lè le, ní ọjọ́ tí èmi yóò bá ọ ṣé? Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, Èmi yóò sì ṣe é.
15 Sizi uluslar arasına dağıtıp ülkelere süreceğim. Sizdeki ruhsal kirliliğe son vereceğim.
Èmi yóò tú yin ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò fọ́n ọ ká sí àwọn ìlú; èmi yóò sì fi òpin sí àìmọ́ rẹ.
16 Ulusların gözünde aşağılanacak ve benim RAB olduğumu anlayacaksınız.’”
Nígbà tí a ó bà ọ́ jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
17 RAB bana şöyle seslendi:
Nígbà náà ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
18 “İnsanoğlu, İsrail halkı benim için cüruf gibi oldu. Hepsi potada tunç, kalay, demir, kurşundur; gümüşün cürufudur.
“Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ti di ìdàrọ́ sí mi; gbogbo wọn jẹ́ bàbà, idẹ, irin àti òjé ti a fi sínú iná ìléru. Wọn jẹ́ ìdàrọ́ ti fàdákà.
19 Bundan ötürü Egemen RAB şöyle diyor: ‘Hepiniz cüruf gibi olduğunuz için sizi Yeruşalim'in ortasına toplayacağım.
Nítorí náà èyí yìí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí tí ìwọ ti di ìdàrọ́, èmi yóò kó yín jọ sí Jerusalẹmu.
20 Eritmek için ateşi üfleyerek gümüşü, tuncu, demiri, kurşunu, kalayı nasıl potaya atıyorlarsa, ben de öfkemle, kızgınlığımla sizi toplayacak, kentin ortasına koyup eriteceğim.
Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe ń kó fàdákà, bàbà, irin, òjé àti idẹ jọ sínú iná ìléru láti fi iná yọ́ ọ, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò kó ọ jọ ní ìbínú àti ìrunú mi, èmi yóò sì fi ọ sì àárín ìlú, èmi yóò sì yọ́ ọ. Níbẹ̀ ní ìwọ yóò sì ti yọ́.
21 Sizi toplayacak, öfkemin ateşini üzerinize üfleyeceğim; siz de kentin içinde eriyip yok olacaksınız.
Èmi yóò kó yín jọ, èmi o sì fín iná ìbínú mi si yin lára, ẹ o si di yíyọ́ láàrín rẹ̀.
22 Gümüş potada nasıl erirse, siz de kentin içinde öyle eriyeceksiniz. O zaman üzerinize kızgınlığını dökenin ben, RAB olduğumu anlayacaksınız.’”
Bí a ti ń yọ́ fàdákà nínú iná ìléru bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní ìwọ yóò ṣe yọ́ nínú rẹ̀, ìwọ yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi Olúwa ti tú ìbínú mi sórí rẹ.’”
23 RAB bana şöyle seslendi:
Lẹ́ẹ̀kan sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
24 “İnsanoğlu, ülkeye de ki, ‘Sen öfke günü temizlenmemiş, üzerine yağmur yağmamış bir ülkesin.’
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilẹ̀ náà, ‘Ìwọ ní ilẹ̀ tí kò gbá mọ́, ti kò sì rọ òjò tàbí ìrì ní àkókò ìbínú.’
25 Önderleri kükreyen, avını parçalayan aslan gibi orada düzen kurdular. Canlara kıydılar, hazineler, değerli nesneler aldılar, birçok kadını dul bıraktılar.
Ìdìtẹ̀ sì wà láàrín àwọn ọmọ-aládé inú rẹ̀, tó dàbí bíbú kìnnìún tó ń fà ẹran ya, wọ́n ń ba àwọn ènìyàn jẹ́, wọ́n ń kó ìṣúra àti àwọn ohun iyebíye wọ́n sì ń sọ púpọ̀ di opó nínú rẹ̀.
26 Kâhinleri yasamı hiçe saydılar, kutsal eşyalarımı kirlettiler, kutsalla bayağı arasındaki ayrımı yapmadılar, kirliyle temiz arasındaki farkı öğretmediler, Şabat günlerimden gözlerini çevirdiler. Kutsallığımı önemsemediler.
Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti rú òfin mi, wọn si ti sọ ohun mímọ́ mi di àìlọ́wọ̀: wọn kò fi ìyàtọ̀ sáàrín ohun mímọ́ àti àìlọ́wọ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fi ìyàtọ̀ hàn láàrín ohun àìmọ́, àti mímọ́, wọn sì ti fi ojú wọn pamọ́ kúrò ní ọjọ́ ìsinmi mi, mó sì dí ẹni àìlọ́wọ̀ láàrín wọn.
27 Yöneticileri avını parçalayan kurt gibidir. Haksız kazanç elde etmek için kan döküyor, canlara kıyıyorlar.
Àwọn ọmọ-aládé àárín rẹ̀ dàbí ìkookò ti ń ṣọdẹ, láti tàjẹ̀ sílẹ̀, láti pa ọkàn run, láti jèrè àìṣòótọ́.
28 Peygamberleri uydurma görümlerle, yalan fal açarak bu suçları gizlediler; ben RAB konuşmadığım halde, ‘Egemen RAB şöyle diyor’ diyorlar.
Àti àwọn wòlíì rẹ́ ti ṣẹ̀tàn sí wọn, wọn ń rì ìran asán, wọn sì ń fọ àfọ̀ṣẹ èké sí wọn, wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí,’ nígbà tí ó ṣépè Olúwa kò sọ̀rọ̀.
29 Ülke halkı baskı uyguladı, soygunculuk etti. Düşküne, yoksula baskı yaptı, yabancıya haksız yere kötü davrandı.
Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, tí lo ìwà ìninilára, wọn sì já olè, wọn sì ni àwọn tálákà àti aláìní lára; nítòótọ́, wọn tí ní àlejò lára láìnídìí. Kò sì ṣí ìdájọ́ òdodo.
30 “İçlerinde duvarı örecek, gedikte durup önümde ülkeyi savunacak, onu yerle bir etmemi engelleyecek bir adam aradım, ama hiç kimseyi bulmadım.
“Èmi si wá ẹnìkan láàrín wọn, tí ìbá tún odi náà mọ́, tí ìbá dúró ní ibi tí ó ya náà níwájú mi fún ilẹ̀ náà, kí èmi má bá à parun: ṣùgbọ́n èmi kò rí ẹnìkan.
31 Bunun için öfkemi üzerlerine boşaltacak, kızgınlığımla onları yakıp yok edeceğim. Yaptıklarını kendi başlarına getireceğim.” Egemen RAB böyle diyor.
Nítorí náà ni mo ṣe da ìbínú mi sí wọn lórí, mo ti fi iná ìbínú mi run wọn, mo si ti fi ọ̀nà wọn gbẹ̀san lórí ara wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.”

< Hezekiel 22 >