< Hezekiel 21 >

1 RAB bana şöyle seslendi:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
2 “Ey insanoğlu, yüzünü Yeruşalim'e çevir, kutsal yerlerine karşı konuş, İsrail ülkesine karşı peygamberlik et.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí ìhà Jerusalẹmu, kí o sì wàásù lòdì sí ibi mímọ́. Sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí ilẹ̀ Israẹli.
3 Ona de ki, ‘RAB şöyle diyor: Ben sana karşıyım! Kılıcımı kınından çıkaracak, içindeki doğru kişiyi de kötü kişiyi de kesip yok edeceğim.
Kí ó sì sọ fún un pe, ‘Èyí yìí ni Olúwa wí, Èmi lòdì sí ọ. Èmi yóò fa idà mi yọ kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀, Èmi yóò sì ké olódodo àti ènìyàn búburú kúrò ni àárín yín.
4 Doğru kişiyi de kötü kişiyi de kesip yok etmek için kılıcım kınından çıkacak ve güneyden kuzeye herkese karşı olacak.
Nítorí pé, èmi yóò ké olódodo àti olùṣe búburú kúrò, idà mi yóò jáde láti inú àkọ̀ rẹ̀ lòdì sí gbogbo ènìyàn láti gúúsù títí dé àríwá.
5 Böylece herkes kılıcını kınından çıkaranın ben RAB olduğumu anlayacak. Onu bir daha yerine koymayacağım.’
Nígbà náà gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti yọ idà mi kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀; kì yóò sì padà sínú rẹ̀ mọ́.’
6 “Sen, ey insanoğlu, inle! Onların gözü önünde ezik bir yürekle acı acı inle!
“Nítorí náà, mí ìmí ẹ̀dùn ìwọ ọmọ ènìyàn! Mí ìmí ẹ̀dùn pẹ̀lú ọkàn ìbànújẹ́ àti ẹ̀dùn ọkàn kíkorò ní iwájú wọn.
7 Sana, ‘Neden böyle inliyorsun?’ diye sorduklarında, ‘Yakında duyulacak haberden ötürü’ diye yanıtlayacaksın. ‘Her yürek eriyecek, her el gevşeyecek, her ruh baygın düşecek, her dizin bağı çözülecek. Evet, haber duyulacak! Bu kesinlikle yerine gelecek.’ Egemen RAB böyle diyor.”
Bí wọ́n bá sì bi ọ́, wí pé, ‘Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń mí ìmí ẹ̀dùn?’ Ìwọ yóò wí pé, ‘Nítorí ìròyìn tí ó ń bẹ. Gbogbo ọkàn ni yóò yọ́, gbogbo ọwọ́ ni yóò sì di aláìlera; gbogbo ọkàn ní yóò dákú, gbogbo eékún ni yóò sì di aláìlera bí omi?’ Ó ń bọ̀! Yóò sì wa sí ìmúṣẹ dandan, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
8 RAB bana şöyle seslendi:
Ọ̀rọ̀ Olúwa si tún tọ̀ mí wá pé:
9 “İnsanoğlu, peygamberlik et ve de ki, ‘Rab şöyle diyor: “‘Kılıç, kılıç, Bilendi, cilalandı.
“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ wí pé, èyí yìí ní Olúwa wí pé, “‘Idà kan, idà kan, tí a pọ́n, tí a sì dán pẹ̀lú,
10 Öldürmek için bilendi, Şimşek gibi çaksın diye cilalandı. Nasıl sevinebiliriz? Kılıç oğlumun asasını sıradan bir sopa gibi küçümsedi.
a pọ́n láti pa ènìyàn púpọ̀, a dán an láti máa kọ mọ̀nà! “‘Àwa o ha máa ṣe àríyá ọ̀gọ ọmọ mi? Idà gán gbogbo irú igi bẹ́ẹ̀.
11 Kılıç kullanılmak için Cilalanmaya verildi; Öldürenin eline verilsin diye bilenip cilalandı.
“‘Idà ní a yàn láti pọ́n, kí ó lè ṣe é gbámú; a pọ́n ọn, a sì dán an, ó ṣetán fún ọwọ́ àwọn apani.
12 İnsanoğlu, bağır, haykır! Çünkü bu kılıç halkıma karşı; Bütün İsrail önderlerine karşı. Onlar halkımla birlikte kılıca teslim edildiler. Bunun için bağrını döv.
Sọkún síta, kí ó sì pohùnréré ẹ̀kún, ọmọ ènìyàn, nítorí yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi; yóò wá sórí gbogbo ọmọ-aládé Israẹli ìbẹ̀rù ńlá yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi nítorí idà náà; nítorí náà lu oókan àyà rẹ.
13 “‘Deneme kuşkusuz gelecek. Kılıcın küçümsediği asa varlığını sürdüremezse ne olur? Böyle diyor Egemen RAB.’
“‘Ìdánwò yóò dé dandan. Tí ọ̀pá aládé Juda èyí tí idà kẹ́gàn, kò bá tẹ̀síwájú mọ́ ń kọ́? Ni Olúwa Olódùmarè wí.’
14 “Sen, ey insanoğlu, peygamberlik et, el çırp. Bırak kılıç iki, üç kez vursun. Bu öldüren bir kılıçtır, Çok sayıda insan kıran, İnsanı her yandan saran kılıçtır.
“Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́. Jẹ́ kí idà lu ara wọn lẹ́ẹ̀méjì, kódà ní ẹ̀ẹ̀mẹta. Ó jẹ́ idà fún ìpànìyàn idà fún ìpànìyàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀, tí yóò sé wọn mọ́ níhìn-ín àti lọ́hùnnún.
15 Yürekleri erisin, Tökezleyip düşenler çok olsun diye Bütün kapılarında öldürmek için Görevlendirdim kılıcı. Ah, kılıç şimşek gibi parladı, Öldürmek için bilendi.
Kí ọkàn kí ó lè yọ́ kí àwọn tí ó ṣubú le pọ̀, mo ti gbé idà sí gbogbo bodè fún ìparun. Háà! A mú kí ó kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná, a gbá a mú fún ìparun.
16 Ey kılıç, sağa, sonra sola savrul, Ağzın nereye dönerse, oraya savrul!
Ìwọ idà, jà sí ọ̀tún kí o sì jà sí òsì lọ ibikíbi tí ẹnu rẹ bá dojúkọ.
17 Ben de elimi çırpacağım Ve öfkem dinecek. Bunu ben RAB söylüyorum.”
Èmi gan an yóò pàtẹ́wọ́ ìbínú mi yóò sì rẹlẹ̀. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀.”
18 RAB bana şöyle seslendi:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
19 “İnsanoğlu, Babil Kralı'nın kılıcı gelsin diye iki yol belirle; ikisi de aynı ülkeden başlamalı. Kent yolunun başladığı yere bir işaret koy.
“Ọmọ ènìyàn la ọ̀nà méjì fún idà ọba Babeli láti gbà, kí méjèèjì bẹ̀rẹ̀ láti ìlú kan náà. Ṣe àmì sí ìkóríta ọ̀nà tí ó lọ sí ìlú náà.
20 Ammonlular'ın Rabba Kenti'ne ya da Yahuda'ya ve surlarla çevrili Yeruşalim'e ilerlesin diye kılıç için yol belirle.
La ọ̀nà kan fún idà láti wá kọlu Rabba ti àwọn ará Ammoni kí òmíràn kọlu Juda, kí ó sì kọlu Jerusalẹmu ìlú olódi.
21 Çünkü Babil Kralı iki yolun ayrıldığı, yolların çatallaştığı yerde fala bakmak için duracak. Okları silkeleyecek, aile putlarına danışacak, kurban edilen bir hayvanın ciğerine bakacak.
Nítorí ọba Babeli yóò dúró ni ìyànà ní ojú ọ̀nà, ní ìkóríta, láti máa lo àfọ̀ṣẹ. Yóò fi ọfà di ìbò, yóò béèrè lọ́wọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀, òun yóò ṣe àyẹ̀wò ẹ̀dọ̀.
22 Kütük yerleştirmek, öldür buyruğunu vermek, savaş naraları atmak, kapılara kütük yerleştirmek, toprak rampalar oluşturmak, kuşatma duvarları yapmak için sağ elinde Yeruşalim'i gösteren ok olacak.
Nínú ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni ìbò Jerusalẹmu yóò ti wá, ní ibi tí yóò ti gbé afárá kalẹ̀, láti pàṣẹ fún àwọn apànìyàn, láti mú ki wọn hó ìhó ogun láti gbé òòlù dí ẹnu-ọ̀nà ibodè, láti mọ odi, àti láti kọ́ ilé ìṣọ́.
23 Onunla ant içerek antlaşma yapanlar fala yanlış bakıldığını sanacak. Ama kral suçlarını anımsatıp onları tutsak alacak.
Àfọ̀ṣẹ náà yóò dàbí àmì èké sí àwọn tí ó ti búra ìtẹríba fún un, ṣùgbọ́n òun yóò ran wọn létí ẹbí wọn yóò sì mú wọn lọ sí ìgbèkùn.
24 “Bundan ötürü Egemen RAB şöyle diyor: ‘Madem suçlarınızı, isyanlarınızı anımsattırdınız, bütün uygulamalarınızda günahlarınızı açığa çıkardınız, madem bütün bunları yaptınız, siz de tutsak alınıp götürüleceksiniz.
“Nítorí náà èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí ti ẹ̀yin ti mú ẹ̀bi yín wá sí ìrántí nípa ìṣọ̀tẹ̀ ní gbangba, ní ṣíṣe àfihàn àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nínú gbogbo ohun tí ó ṣe, nítorí tí ẹ̀yin ti ṣe èyí, a yóò mú yín ní ìgbèkùn.
25 “‘Sen, ey saygısız, kötü İsrail önderi, günün yaklaştı, sonunda yargı günün geldi.
“‘Ìwọ aláìmọ́ àti ẹni búburú ọmọ-aládé Israẹli, ẹni ti ọjọ́ rẹ̀ ti dé, ẹni tí àsìkò ìjìyà rẹ̀ ti dé góńgó,
26 Egemen RAB şöyle diyor: Sarığı çıkar, tacı kaldır. Artık eskisi gibi olmayacak. Alçakgönüllü yükseltilecek, gururlu alçaltılacak.
èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, tú ìwérí kúrò kí o sì gbé adé kúrò. Kò ní rí bí ti tẹ́lẹ̀, ẹni ìgbéga ni a yóò sì rẹ̀ sílẹ̀.
27 Yıkım! Yıkım! Kenti yerle bir edeceğim! Hak sahibi gelinceye dek onarılmayacak. Kenti ona vereceğim.’
Ìparun! Ìparun! Èmi yóò ṣé e ni ìparun! Kì yóò padà bọ̀ sípò bí kò ṣe pé tí ó bá wá sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ní ẹ̀tọ́ láti ni in; òun ni èmi yóò fi fún.’
28 “Sen, ey insanoğlu, peygamberlik et ve de ki, ‘Aşağılayıcı sözler söyleyen Ammonlular için Egemen RAB şöyle diyor: “‘Kılıç, kılıç, Öldürmek için kınından çekilmiş, Yok etmek için, Şimşek gibi parlamak için cilalanmış!
“Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nípa àwọn ará Ammoni àti àbùkù wọn: “‘Idà kan idà kan tí á fa yọ fún ìpànìyàn tí a dán láti fi ènìyàn ṣòfò àti láti kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná!
29 Size ilişkin görümler aldatıcıdır, Açılan fal yalandır. Öldürülecek kötülerin enseleri üzerine Yerleştirileceksin, ey kılıç! Onların günü yaklaştı, Sonunda yargı günleri geldi.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a rí èké nípa yín àti àfọ̀ṣẹ èké nípa yín a yóò gbé e lé àwọn ọrùn ènìyàn búburú ti a ó pa, àwọn tí ọjọ́ wọn ti dé, àwọn tí ọjọ́ ìjìyà wọn ti dé góńgó.
30 Kılıç kınına koyulsun! Yaratıldığınız yerde, Atalarınızın ülkesinde Yargılayacağım sizi.
“‘Dá idà padà sínú àkọ̀ rẹ̀. Níbi tí a gbé ṣẹ̀dá yín, ní ibi tí ẹ̀yin ti ṣẹ̀ wá.
31 Öfkemi üzerinize dökeceğim, Kızgınlığımı üzerinize üfleyeceğim; Acımasız adamların, Yakıp yok etmekte usta kişilerin eline Teslim edeceğim sizi.
Níbẹ̀ ni èmi yóò ti ṣe ìdájọ́ yín, èmi o sì fi èémí ìbínú gbígbóná mi bá yín jà.
32 Ateşe yakıt olacaksınız, Kanınız ülkenizin ortasında dökülecek, Bir daha anılmayacaksınız. Çünkü bunu ben RAB söylüyorum.’”
Ẹ̀yin yóò jẹ́ èpò fún iná náà, a yóò ta ẹ̀jẹ̀ yin sórí ilẹ̀ yín, a kì yóò rántí yín mọ́; nítorí Èmi Olúwa ní ó ti wí bẹ́ẹ̀.’”

< Hezekiel 21 >