< Daniel 9 >
1 Medli Ahaşveroş oğlu Darius Kildan Kralı oldu. Krallığının birinci yılında ben Daniel, RAB'bin Peygamber Yeremya'ya bildirdiği sayının –Yeruşalim'in ıssız kalacağı yılların sayısının– yetmiş olduğunu Kutsal Yazılar'dan anladım.
Ní ọdún kìn-ín-ní Dariusi ọmọ Ahaswerusi, ẹni tí a bí ní Media, òun ló jẹ ọba lórí ìjọba Babeli.
Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, èmi Daniẹli fi iyè sí i láti inú ìwé, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí wòlíì Jeremiah, wá pé, àádọ́rin ọdún ni Jerusalẹmu yóò fi wà ní ahoro.
3 Bunun üzerine yüzümü Rab Tanrı'ya çevirdim. Duayla, yakarışla, oruçla O'na yalvardım; çul kuşanıp külde oturdum.
Nígbà náà, ni mo yípadà sí Olúwa Ọlọ́run, mo bẹ̀ ẹ́ pẹ̀lú àdúrà àti ẹ̀bẹ̀, pẹ̀lú àwẹ̀, aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú.
4 RAB Tanrım'a dua edip günahlarımızı itiraf ettim. Şöyle dedim: “Ya Rab, kendisini sevenlerle, buyruklarına uyanlarla yaptığı antlaşmaya bağlı kalan yüce ve görkemli Tanrı!
Mo gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run mi, mo sì jẹ́wọ́ wí pé: “Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó ní ìfẹ́ rẹ̀ àti àwọn tí ó ń pa àwọn òfin rẹ̀ mọ́.
5 Buyruklarından, ilkelerinden ayrılıp günah, suç işledik, kötülük yaptık, başkaldırdık.
Àwa ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú. Àwa ti hu ìwà búburú, a sì ti ṣe ọ̀tẹ̀, a ti yí padà kúrò nínú àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà rẹ̀.
6 Senin adına krallarımıza, önderlerimize, atalarımıza, ülkedeki bütün halka seslenen kulların peygamberleri dinlemedik.
Àwa kò fetí sí àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, ẹni tí ó sọ̀rọ̀ ní orúkọ rẹ sí àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé àti àwọn baba wa, àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà.
7 “Sen adaletlisin, ya Rab! Sadakatsizliğimiz yüzünden bizi uzak yakın ülkelere sürdün. Oralarda yaşayan biz Yahudiler, Yeruşalim halkı, İsrailliler bugün utanç içindeyiz.
“Olúwa ìwọ ni olódodo, ṣùgbọ́n báyìí ìtìjú dé bá àwọn ènìyàn Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu àti gbogbo Israẹli ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti fọ́n wa ká sí nítorí àìṣòótọ́ ọ wa sí ọ.
8 Evet, ya RAB, bizler, krallarımız, önderlerimiz, atalarımız sana karşı işlediğimiz günah yüzünden utanç içindeyiz.
Háà! Olúwa, àwa àti àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé, àti àwọn baba wa, ìtìjú dé bá wa nítorí àwa ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ.
9 Sana karşı geldiğimiz halde, sen acıyan, bağışlayan Tanrımız Rab'sin.
Olúwa Ọlọ́run wa ní àánú, ó sì ń dáríjì, bí àwa tilẹ̀ ti ṣe ọ̀tẹ̀ sí i;
10 Tanrımız RAB'bin sözüne kulak vermedik, kulları peygamberler aracılığıyla bize verdiği yasalara uymadık.
àwa kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, a kò sì pa àwọn òfin rẹ mọ́, èyí tí ó fún wa nípasẹ̀ àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
11 Bütün İsrail halkı yasanı çiğnedi, sırtını sana dönüp seni dinlemek istemedi. “Bu yüzden Tanrı kulu Musa'nın Yasası'nda yazılan lanet başımıza yağdı, içilen ant yerine geldi. Çünkü sana karşı günah işledik.
Gbogbo Israẹli ti ṣẹ̀ sí òfin rẹ, wọ́n ti yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, wọ́n kọ̀ láti ṣe ìgbọ́ràn sí ọ. “Nígbà náà ni ègún àti ìdájọ́ tí a kọ sílẹ̀ pẹ̀lú ìbúra nínú òfin Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run dà sórí i wa, nítorí tí àwa ti sẹ̀ sí ọ.
12 Üzerimize büyük yıkım getirerek bizim ve bizi yöneten önderlerimiz için söylediğin sözleri yerine getirdin. Yeruşalim'in başına gelen, göğün altındaki başka hiçbir kentin başına gelmemiştir.
Ìwọ ti mú ọ̀rọ̀ tí o sọ sí wa sẹ àti lórí àwọn alákòóso wa, nípa mímú kí ibi ńlá bá wa, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí lábẹ́ ọ̀run, bí ó ti ṣẹlẹ̀ sí Jerusalẹmu yìí.
13 Musa'nın Yasası'nda yazıldığı gibi, bütün bu yıkımlar başımıza geldi. Buna karşın, ey Tanrımız RAB, suçumuzdan dönüp senin gerçeklerine yönelerek lütfunu dilemedik.
Bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Mose bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ibi yìí ti dé bá wa, síbẹ̀ a kò bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run wa, nípa yíyí padà kí a kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wa kí a sì mọ òtítọ́ rẹ.
14 RAB üzerimize yıkım göndermekten caymadı. Çünkü Tanrımız RAB yaptığı her şeyde adildir. Bizse O'nun sözüne kulak vermedik.
Olúwa kò jáfara láti mú ibi náà wá sórí wa, nítorí olódodo ni Olúwa Ọlọ́run wa nínú u gbogbo ohun tí ó ń ṣe; síbẹ̀ àwa kò ṣe ìgbọ́ràn sí i.
15 “Ey Tanrımız Rab, sen halkını Mısır'dan güçlü elinle çıkardın ve bugün olduğu gibi ün kazandın. Bizse günah işledik, kötülük yaptık.
“Ní ìsinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, pẹ̀lú ọwọ́ agbára, tí ó fún ara rẹ̀ ní orúkọ tí ó wà títí di òní, a ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú.
16 Ya Rab, doğru işlerin uyarınca kentin Yeruşalim'den, kutsal dağından öfkeni, kızgınlığını kaldırmanı dilerim. Günahlarımız ve atalarımızın suçları yüzünden Yeruşalim de halkın da çevremizdekilerin tümüne alay konusu oldu.
Olúwa, ní ìbámu pẹ̀lú ìwà òdodo rẹ, yí ìbínú àti ìrunú rẹ padà kúrò ní Jerusalẹmu ìlú u rẹ, òkè mímọ́ rẹ. Ẹ̀ṣẹ̀ wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa ti mú Jerusalẹmu àti ènìyàn rẹ di ẹ̀gàn fún gbogbo àwọn tí ó yí wọn ká.
17 “Şimdi, ey Tanrımız, kulunun duasını, yakarışını işit. Adın uğruna, ya Rab, yüzünü viran tapınağına çevir.
“Nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, nítorí i tìrẹ Olúwa, fi ojú àánú wo ibi mímọ́ rẹ tí ó ti dahoro.
18 Ey Tanrım, kulak ver ve işit! Gözlerini aç, senin olan viran kenti gör. Doğruluğumuzdan değil, senin büyük merhametinden ötürü dilekte bulunuyoruz.
Tẹ́ etí rẹ sílẹ̀, Ọlọ́run, kí o gbọ́; ya ojú rẹ sílẹ̀, kí o sì wo ìdahoro ìlú tí a ń fi orúkọ rẹ pè. Àwa kò gbé ẹ̀bẹ̀ wa kalẹ̀ níwájú u rẹ nítorí pé a jẹ́ olódodo, bí kò ṣe nítorí àánú ńlá rẹ.
19 Ya Rab, dinle! Ya Rab, bağışla! İşit ve davran, ya Rab! Ey Tanrım, adının hatırı için gecikme! Çünkü kent ve halk senindir.”
Olúwa, fetísílẹ̀! Olúwa, dáríjì! Olúwa, gbọ́ kí o sì ṣe é! Nítorí i tìrẹ, Ọlọ́run mi, má ṣe pẹ́ títí, nítorí ìlú rẹ àti àwọn ènìyàn rẹ ń jẹ́ orúkọ mọ́ ọ lára.”
20 Ben daha konuşup dua ederken, günahımı ve halkım İsrail'in günahını açıkça kabul edip Tanrım'ın kutsal dağı için Tanrım RAB'be dilekte bulunurken,
Bí mo ṣe ń sọ̀rọ̀, tí mo sì ń gba àdúrà, tí mo ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi àti ẹ̀ṣẹ̀ àwọn Israẹli ènìyàn mi, tí mo sì ń mú ẹ̀bẹ̀ mi tọ Olúwa Ọlọ́run mi nítorí òkè mímọ́ rẹ.
21 daha dua ediyorken, önceden görümde gördüğüm adam –Cebrail– akşam sunusu saatinde hızla uçarak yanıma geldi.
Bí mo ṣe ń gba àdúrà náà lọ́wọ́, Gabrieli ọkùnrin tí mo rí nínú ìran ìṣáájú, yára kánkán wá sí ọ̀dọ̀ mi ní àkókò ẹbọ àṣálẹ́.
22 “Daniel, sana anlayış vermek için geldim” diye açıkladı,
Ó jẹ́ kí ó yé mi, ó sì wí fún mi pé, “Daniẹli, mo wá láti jẹ́ kí o mọ̀ kí o sì ní òye.
23 “Sen Tanrı'ya yalvarmaya başlar başlamaz, duan yanıtlandı; bunu bildirmeye geldim. Çünkü sen çok sevilen birisin. Bu nedenle sözün anlamını kavra ve görümü anla:
Bí o ṣe bẹ̀rẹ̀ sí nígbà àdúrà, a fún ọ ní ìdáhùn kan, èyí tí mo wá láti sọ fún ọ, nítorí ìwọ jẹ́ àyànfẹ́ gidigidi. Nítorí náà, gba ọ̀rọ̀ náà yẹ̀ wò kí ìran náà sì yé ọ:
24 “Başkaldırıyı ortadan kaldırmak, günaha son vermek, suçu bağışlatmak, sonsuza dek kalıcı doğruluğu sağlamak, görüm ve peygamberliği mühürlemek, En Kutsal'ı meshetmek için senin halkına ve kutsal kentine yetmiş hafta kadar zaman saptanmıştır.
“Àádọ́rin ọ̀sẹ̀ ni a pàṣẹ fún àwọn ènìyàn rẹ àti fún àwọn ìlú mímọ́ rẹ láti parí ìrékọjá, láti fi òpin sí ẹ̀ṣẹ̀, láti ṣe ètùtù sí ìwà búburú, láti mú òdodo títí ayé wá, láti ṣe èdìdì ìran àti wòlíì àti láti fi òróró yan Ibi Mímọ́ Jùlọ.
25 “Şunu bil ve anla: Yeruşalim'i yeniden kurmak için buyruğun verilmesinden, meshedilmiş olan önderin gelişine dek yedi hafta geçecek. Altmış iki hafta içinde Yeruşalim yeniden sokaklarla, hendeklerle kurulacak. Ancak bu sıkıntılı zamanlarda olacak.
“Nítorí náà, mọ èyí pé, láti ìgbà tí a ti gbé ọ̀rọ̀ náà jáde wí pé kí a tún Jerusalẹmu ṣe, kí a sì tún kọ́, títí dé ìgbà ọmọ-aládé, ẹni òróró náà, alákòóso wa yóò fi dé, ó jẹ́ ọ̀sẹ̀ méje àti ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó sì tún ìgboro àti yàrá rẹ̀ mọ, ṣùgbọ́n ní àkókò wàhálà ni.
26 Bu altmış iki hafta sonunda meshedilmiş olan öldürülecek ve onu destekleyen olmayacak. Gelecek önderin halkı, kenti ve kutsal yeri yerle bir edecek. Sonu tufanla olacak: Savaş sona dek sürecek. Yıkımların da olacağı kararlaştırıldı.
Lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó ké Ẹni òróró náà kúrò, kò sì ní ní ohun kan. Àwọn ènìyàn ọmọ-aládé náà tí yóò wá ni yóò pa ìlú náà àti ibi mímọ́ run. Òpin yóò dé bí ìkún omi, ogun yóò máa jà títí dé òpin, a sì ti pàṣẹ ìdahoro.
27 Gelecek önder birçoklarıyla bir haftalık sağlam bir antlaşma yapacak. Haftanın yarısı geçince, kurbanı da sunuyu da kaldıracak. Kararlaştırılan yıkım başına gelinceye dek yok edici önder tapınağın üst bölümüne yıkıcı iğrenç şeyler yerleştirecek.”
Yóò sì fi ìdí i májẹ̀mú kan múlẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún ọ̀sẹ̀ kan. Ní àárín ọ̀sẹ̀ ni yóò mú òpin bá ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ. Àti lórí apá kan ni yóò dà ìríra tí ó mú ìdahoro wá, títí tí òpin tí a ti pàṣẹ lórí asọnidahoro yóò fi padà fi dé bá a.”