< 2 Samuel 6 >

1 Davut İsrail'deki bütün seçme adamları topladı. Sayıları otuz bin kişiydi.
Dafidi sì tún kó gbogbo àwọn akọni ọkùnrin ní Israẹli jọ, wọ́n sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún.
2 Böylece Davut'la ordusu, sandığın üzerindeki Keruvlar arasında taht kuran Her Şeye Egemen RAB'bin adıyla anılan Tanrı'nın Sandığı'nı getirmek için Baale-Yahuda'ya gittiler.
Dafidi sì dìde, ó sì lọ àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ́ lọ́dọ̀ rẹ́, láti Baalahi ní Juda wá, láti mú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run tí ibẹ̀ wá, èyí tí a ń pe orúkọ rẹ̀ ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó jókòó láàrín àwọn kérúbù.
3 Tanrı'nın Sandığı'nı Avinadav'ın tepedeki evinden alıp yeni bir arabaya koydular. Tanrı'nın Sandığı'nı taşıyan yeni arabayı Avinadav'ın oğulları Uzza'yla Ahyo sürüyordu. Ahyo sandığın önünden yürüyordu.
Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà gun kẹ̀kẹ́ tuntun kan, wọ́n sì mú un láti ilé Abinadabu wá, èyí tí ó wà ní Gibeah: Ussa àti Ahio, àwọn ọmọ Abinadabu sì ń dá kẹ̀kẹ́ tuntun náà.
4
Wọ́n sì mú un láti ilé Abinadabu jáde wá, tí ó wà ní Gibeah, pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, Ahio sì ń rìn níwájú àpótí ẹ̀rí náà.
5 Bu arada Davut'la bütün İsrail halkı da RAB'bin önünde lir, çenk, tef, çıngırak ve ziller eşliğinde ezgiler okuyarak var güçleriyle bu olayı kutluyorlardı.
Dafidi àti gbogbo ilé Israẹli sì ṣiré níwájú Olúwa lára gbogbo onírúurú ohun èlò orin tí a fi igi arère ṣe àti lára ìlù haapu, ní ara tambori, sisitirumu àti lára kimbali.
6 Nakon'un harman yerine vardıklarında öküzler tökezledi. Bu nedenle Uzza elini uzatıp Tanrı'nın Sandığı'nı tuttu.
Nígbà tí wọ́n dé sí ilẹ̀ ìpakà Nakoni, Ussa sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, ó sì dìímú, nítorí tí màlúù kọsẹ̀.
7 RAB Tanrı saygısızca davranan Uzza'ya öfkelenerek onu orada yere çaldı. Uzza Tanrı'nın Sandığı'nın yanında öldü.
Ìbínú Olúwa sì ru sí Ussa; Ọlọ́run sì pa á níbẹ̀ nítorí ìṣísẹ̀ rẹ̀; níbẹ̀ ni ó sì kù ní ẹ̀bá àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.
8 Davut, RAB'bin Uzza'yı cezalandırmasına öfkelendi. O günden bu yana oraya Peres-Uzza denilir.
Inú Dafidi sì bàjẹ́ nítorí tí Olúwa gé Ussa kúrò, ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Peresi-Usa títí ó fi di òní yìí.
9 Davut o gün RAB'den korkarak, “RAB'bin Sandığı nasıl olur da bana gelir?” diye düşündü.
Dafidi sì bẹ̀rù Olúwa ní ọjọ́ náà, ó sì wí pé, “Àpótí ẹ̀rí Olúwa yóò ti ṣe tọ̀ mí wá?”
10 RAB'bin Sandığı'nı Davut Kenti'ne götürmek istemedi. Bunun yerine sandığı Gatlı Ovet-Edom'un evine götürdü.
Dafidi kò sì fẹ́ mú àpótí ẹ̀rí Olúwa sọ́dọ̀ rẹ̀ sí ìlú Dafidi; ṣùgbọ́n Dafidi sì mú un yà sí ilé Obedi-Edomu ará Gitti.
11 RAB'bin Sandığı Gatlı Ovet-Edom'un evinde üç ay kaldı. RAB Ovet-Edom'u ve bütün ailesini kutsadı.
Àpótí ẹ̀rí Olúwa sì gbé ní ilé Obedi-Edomu ará Gitti ní oṣù mẹ́ta; Olúwa sì bùkún fún Obedi-Edomu, àti gbogbo ilé rẹ̀.
12 “Tanrı'nın Sandığı'ndan ötürü RAB Ovet-Edom'un ailesini ve ona ait her şeyi kutsadı” diye Kral Davut'a bildirildi. Böylece Davut gidip Tanrı'nın Sandığı'nı Ovet-Edom'un evinden Davut Kenti'ne sevinçle getirdi.
A sì rò fún Dafidi ọba pé, “Olúwa ti bùkún fún ilé Obedi-Edomu, àti gbogbo èyí tí í ṣe tirẹ̀, nítorí àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.” Dafidi sì lọ, ó sì mú àpótí ẹ̀rí náà gòkè láti ilé Obedi-Edomu wá sí ìlú Dafidi pẹ̀lú ayọ̀.
13 RAB'bin Sandığı'nı taşıyanlar altı adım atınca, Davut bir boğayla besili bir dana kurban etti.
Ó sì ṣe nígbà tí àwọn ènìyàn tí ó ru àpótí ẹ̀rí Olúwa bá sì ṣí ẹsẹ̀ mẹ́fà, òun a sì fi màlúù àti ẹran àbọ́pa rú ẹbọ.
14 Keten efod kuşanmış Davut, RAB'bin önünde var gücüyle oynuyordu.
Dafidi sì fi gbogbo agbára rẹ̀ jó níwájú Olúwa; Dafidi sì wọ efodu ọ̀gbọ̀.
15 Davut'la bütün İsrail halkı, sevinç naraları ve boru sesi eşliğinde RAB'bin Sandığı'nı getiriyorlardı.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti gbogbo ilé Israẹli sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá, pẹ̀lú ìhó ayọ̀, àti pẹ̀lú ìró ìpè.
16 RAB'bin Sandığı Davut Kenti'ne varınca, Saul'un kızı Mikal pencereden baktı. RAB'bin önünde oynayıp zıplayan Kral Davut'u görünce, onu küçümsedi.
Bí àpótí ẹ̀rí Olúwa sì ti wọ ìlú Dafidi wá; Mikali ọmọbìnrin Saulu sì wo láti ojú fèrèsé, ó sì rí Dafidi ọba ń fò sókè ó sì ń jó níwájú Olúwa; òun sì kẹ́gàn rẹ̀ ní ọkàn rẹ̀.
17 RAB'bin Sandığı'nı getirip Davut'un bu amaçla kurduğu çadırın içindeki yerine koydular. Davut RAB'be yakmalık sunular ve esenlik sunuları sundu.
Wọ́n sì mú àpótí ẹ̀rí Olúwa náà wá, wọ́n sì gbé e kalẹ̀ sípò rẹ̀ láàrín àgọ́ náà tí Dafidi pa fún un. Dafidi sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ìrẹ́pọ̀ níwájú Olúwa.
18 Yakmalık sunuları ve esenlik sunularını sunmayı bitirince, Her Şeye Egemen RAB'bin adıyla halkı kutsadı.
Dafidi sì parí ìṣe ẹbọ sísun àti ẹbọ ìrẹ́pọ̀ náà, ó sì súre fún àwọn ènìyàn náà ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
19 Ardından kadın erkek herkese, bütün İsrail topluluğuna birer somun ekmekle birer hurma ve üzüm pestili dağıttı. Sonra herkes evine döndü.
Ó sì pín fún gbogbo àwọn ènìyàn náà, àní fún gbogbo ọ̀pọ̀ ènìyàn Israẹli, àti ọkùnrin àti obìnrin; fún olúkúlùkù ìṣù àkàrà kan àti ekìrí ẹran kan, àti àkàrà díndín kan. Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì túká lọ, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀.
20 Davut ailesini kutsamak için eve döndüğünde, Saul'un kızı Mikal onu karşılamaya çıktı. Davut'a şöyle dedi: “İsrail Kralı bugün ne güzel bir ün kazandırdı kendine! Değersiz biri gibi, kullarının cariyeleri önünde soyundun.”
Dafidi sì yípadà láti súre fún àwọn ará ilé rẹ̀, Mikali ọmọbìnrin Saulu sì jáde láti wá pàdé Dafidi, ó sì wí pé, “Báwo ni ọba Israẹli ṣe ṣe ara rẹ̀ lógo bẹ́ẹ̀ lónìí, tí ó bọ́ ara rẹ̀ sílẹ̀ lónìí lójú àwọn ìránṣẹ́bìnrin àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn lásán tí ń bọ́ra rẹ̀ sílẹ̀.”
21 Davut, “Baban ve bütün soyu yerine beni seçen ve halkı İsrail'e önder atayan RAB'bin önünde oynadım!” diye karşılık verdi, “Evet, RAB'bin önünde oynayacağım.
Dafidi sì wí fún Mikali pé, “Níwájú Olúwa ni, ẹni tí ó yàn mí fẹ́ ju baba rẹ lọ, àti ju gbogbo ìdílé rẹ lọ, láti fi èmi ṣe olórí àwọn ènìyàn Olúwa, àní lórí Israẹli, èmi ó sì súre níwájú Olúwa.
22 Üstelik kendimi bundan daha da küçük düşüreceğim, hiçe sayacağım. Ama sözünü ettiğin o cariyeler beni onurlandıracaklar.”
Èmi ó sì tún rẹ ara mi sílẹ̀ jú bẹ́ẹ̀ lọ, èmi ó sì ṣe aláìníyìn lójú ara mi, àti lójú àwọn ìránṣẹ́bìnrin náà ti ìwọ wí, lọ́dọ̀ wọn náà ni èmi ó sì ní ògo.”
23 Saul'un kızı Mikal'ın ölene dek çocuğu olmadı.
Mikali ọmọbìnrin Saulu kò sì bí ọmọ, títí o fi di ọjọ́ ikú rẹ̀ nítorí tí ó sọ̀rọ̀-òdì yìí sí Dafidi.

< 2 Samuel 6 >