< 2 Samuel 1 >
1 Saul'un ölümünden sonra Amalekliler'e karşı kazandığı zaferden dönen Davut Ziklak'ta iki gün kaldı.
Lẹ́yìn ikú Saulu, Dafidi ti ibi tí ó ti ṣẹ́gun àwọn ará Amaleki bọ̀, ó sì dúró ní Siklagi ní ọjọ́ méjì.
2 Üçüncü gün, Saul'un ordugahından giysileri yırtılmış, başı toz toprak içinde bir adam geldi. Adam Davut'a yaklaşınca önünde yere kapandı.
Ní ọjọ́ kẹta, ọkùnrin kan dé láti ibi ibùdó Saulu, pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ tí ó ti ya; àti erùpẹ̀ ní orí rẹ̀. Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ Dafidi, ó wólẹ̀ fún un láti bu ọlá fún un.
3 Davut, “Nereden geliyorsun?” diye sordu. Adam, “İsrail ordugahından kaçıp kurtuldum” dedi.
Dafidi sì béèrè pé, “Ibo ni ìwọ ti wá?” “Èmi sá láti ibùdó àwọn ọmọ Israẹli.”
4 Davut, “Ne oldu? Bana anlat” dedi. Adam askerlerin savaş alanından kaçtığını, birçoğunun düşüp öldüğünü, Saul'la oğlu Yonatan'ın da ölüler arasında olduğunu anlattı.
Dafidi béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” “Sọ fún mi.” Ó wí pé, “Àwọn ọkùnrin náà sá láti ojú ogun. Ọ̀pọ̀ wọn ṣubú, wọ́n sì kú. Saulu àti ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Jonatani sì kú pẹ̀lú.”
5 Davut, kendisine haberi veren genç adama, “Saul'la oğlu Yonatan'ın öldüğünü nereden biliyorsun?” diye sordu.
Nígbà náà, ní Dafidi sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Báwo ni o ṣe mọ̀ pé Saulu àti ọmọkùnrin rẹ̀ Jonatani ti kú.”
6 Genç adam şöyle yanıtladı: “Bir rastlantı sonucu Gilboa Dağı'ndaydım. Saul mızrağına dayanmıştı. Atlılarla savaş arabaları ona doğru yaklaşıyordu.
Ọ̀dọ́mọkùnrin náà sọ pé, “Mo wà ní orí òkè Gilboa níbẹ̀ ni Saulu fi ara tí ọkọ̀ rẹ̀, àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin sì ń lépa rẹ̀.
7 Saul arkasına dönüp beni görünce seslendi. Ben de, ‘Buyrun, buradayım’ dedim.
Nígbà tí ó wò yíká, tí ó rí mí, ó pè mi, mo sì wí pé, ‘Kí ni mo lè ṣe?’
8 “Saul, ‘Sen kimsin?’ diye sordu. “‘Ben bir Amalekli'yim’ diye yanıtladım.
“Ó bi mí wí pé, ‘Ta ni ìwọ?’ “Mo dáhùn pé, ‘Ará a Amaleki.’
9 “Saul, ‘Ne olur üstüme var ve beni öldür!’ dedi, ‘Çünkü çektiğim acılardan kurtulmak istiyorum.’
“Nígbà náà ó wí fún mi pé, ‘Dúró lórí ì mi kí o sì pa mí! Èmi wà nínú ìrora ikú, ṣùgbọ́n mo wà láààyè.’
10 Bu yüzden varıp onu öldürdüm. Çünkü yere düştükten sonra yaşayamayacağını biliyordum. Başındaki taçla kolundaki bileziği aldım ve onları buraya, efendime getirdim.”
“Nígbà náà, mo dúró lórí i rẹ̀, mo sì pa á nítorí mo mọ̀ wí pé, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣubú, kò le è yè mọ́. Mo sì mú adé tí ó wà lórí rẹ̀, idẹ tí ó wà ní apá a rẹ̀, mo sì kó wọn wá síbí fún olúwa mi.”
11 Bunun üzerine Davut'la yanındakiler giysilerini yırttılar.
Nígbà náà ni, Dafidi àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, di aṣọ wọn mú, wọ́n sì fà á ya.
12 Kılıçtan geçirilen Saul, oğlu Yonatan ve RAB'bin halkı olan İsrailliler için akşama dek yas tutup ağladılar, oruç tuttular.
Wọ́n ṣọ̀fọ̀, wọ́n sì sọkún, wọ́n sì gbààwẹ̀ títí di ìrọ̀lẹ́ fún Saulu àti ọmọ rẹ̀ Jonatani àti fún àwọn ọmọ-ogun Olúwa, àti fún àwọn ilé Israẹli, nítorí wọ́n ti ṣubú nípa idà.
13 Davut, kendisine haber getiren genç adama, “Nerelisin?” diye sordu. Adam, “Ben yabancıyım, bir Amalekli'nin oğluyum” dedi.
Dafidi sọ fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Níbo ni ó ti wá?” O dáhùn pé, “Ọmọ àlejò ni mo jẹ́, ará Amaleki.”
14 Davut, “RAB'bin meshettiği kişiye el kaldırıp onu yok etmekten korkmadın mı?” diye sordu.
Dafidi béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ kò fi bẹ̀rù láti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè láti fi pa ẹni àmì òróró Olúwa?”
15 Sonra adamlarından birini çağırıp, “Git, öldür onu!” diye buyurdu. Böylece adam Amalekli'yi vurup öldürdü.
Nígbà náà Dafidi pe ọ̀kan nínú ọkùnrin, ó sì wí pé, “Lọ, gbé e lulẹ̀!” Nígbà náà ó gbé e lulẹ̀, ó sì kú.
16 Davut Amalekli'ye, “Kanından sen kendin sorumlusun” demişti, “Çünkü ‘RAB'bin meshettiği kişiyi ben öldürdüm’ demekle kendine karşı ağzınla tanıklıkta bulundun.”
Nítorí Dafidi wí fún un pé, “Ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò wà lórí ara rẹ, nítorí ẹnu ara rẹ ni o fi sọ pé, ‘Mo pa ẹni àmì òróró Olúwa.’”
17 Davut Saul'la oğlu Yonatan için ağıt yaktı.
Dafidi sì fi orin ọ̀fọ̀ yìí ṣọ̀fọ̀ lórí Saulu àti lórí Jonatani ọmọ rẹ̀,
18 Sonra Yaşar Kitabı'nda yazılan Yay adındaki ağıtın Yahuda halkına öğretilmesini buyurdu:
Ó sì pàṣẹ pé kí a kọ́ àwọn ọkùnrin Juda ní orin arò yìí tí ó jẹ́ ti ọrun (a kọ ọ́ sí inú ìwé Jaṣari):
19 “Ey İsrail, senin yüceliğin yüksek tepelerinde yok oldu! Güçlüler nasıl da yere serildi!
“Ògo rẹ, Israẹli ni a pa ní òkè gíga rẹ. Wò bí àwọn alágbára ṣe ń ṣubú!
20 Haberi ne Gat'a duyurun, Ne de Aşkelon sokaklarında yayın. Öyle ki, ne Filistliler'in kızları sevinsin, Ne de sünnetsizlerin kızları coşsun.
“Ẹ má ṣe sọ ọ́ ní Gati, ẹ má ṣe kéde rẹ̀ ní òpópónà Aṣkeloni, kí àwọn ọmọbìnrin Filistini má bá à yọ̀, kí àwọn ọmọbìnrin aláìkọlà má ba à dunnú.
21 Ey Gilboa dağları, Üzerinize ne çiy ne de yağmur düşsün. Ürün veren tarlalarınız olmasın. Çünkü güçlünün kalkanı, Bir daha yağ sürülmeyecek olan Saul'un kalkanı Orada bir yana atıldı!
“Ẹ̀yin òkè Gilboa, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe rí ìrì tàbí òjò, tàbí oko tí ó mú èso ọrẹ wá. Nítorí ibẹ̀ ni asà alágbára ti ṣègbé, asà Saulu, bí ẹni pé a kò fi òróró yàn án.
22 Yonatan'ın yayı yere serilmişlerin kanından, Yiğitlerin bedenlerinden hiç geri çekilmedi. Saul'un kılıcı hiç boşa savrulmadı.
“Ọrun Jonatani kì í padà bẹ́ẹ̀ ni idà Saulu kì í padà lásán, láì kan ẹ̀jẹ̀ àwọn tí a pa, àti ẹran àwọn alágbára.
23 Saul'la Yonatan tatlı ve sevimliydiler, Yaşamda da ölümde de ayrılmadılar. Kartallardan daha çevik, Aslanlardan daha güçlüydüler.
Saulu àti Jonatani— ní ọjọ́ ayé, wọ́n fẹ́ràn ara, wọn sì dùn, ní ikú, wọn kò sì yà ara wọ́n. Wọ́n yára ju idì lọ, wọ́n lágbára ju kìnnìún lọ.
24 Ey İsrail kızları! Sizi al renkli, süslü giysilerle donatan, Giysinizi altın süslerle bezeyen Saul için ağlayın!
“Ẹ̀yin ọmọbìnrin Israẹli, ẹ sọkún lórí Saulu, ẹni tí ó fi aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára wọ̀ yín, ẹni tí ó fi wúrà sí ara aṣọ yín.
25 Güçlüler nasıl da yere serildi savaşta! Yonatan senin yüksek tepelerinde ölü yatıyor.
“Wò ó bí alágbára ti ṣubú ní ojú ogun! Jonatani, ìwọ tí a pa ní òkè gíga.
26 Senin için üzgünüm, kardeşim Yonatan. Benim için çok değerliydin. Sevgin kadın sevgisinden daha üstündü.
Ọkàn mi gbọgbẹ́ fún ọ Jonatani arákùnrin mi; ìwọ ṣọ̀wọ́n fún mi. Ìfẹ́ rẹ sí mi jẹ́ ìyanu, ó jẹ́ ìyanu ju ti obìnrin lọ.
27 Güçlüler nasıl da yere serildi! Savaş silahları yok oldu!”
“Wò ó bí alágbára ti ṣubú! Ohun ìjà sì ti ṣègbé!”