< 1 Samuel 2 >
1 Hanna şöyle dua etti: “Yüreğim RAB'de bulduğum sevinçle coşuyor; Gücümü yükselten RAB'dir. Düşmanlarımın karşısında övünüyor, Kurtarışınla seviniyorum!
Hana sì gbàdúrà pé, “Ọkàn mi yọ̀ sí Olúwa; ìwo agbára mi ni a sì gbé sókè sí Olúwa. Ẹnu mi sì gbòòrò lórí àwọn ọ̀tá mi, nítorí ti èmi yọ̀ ni ìgbàlà rẹ̀.
2 Kutsallıkta RAB'bin benzeri yok, Evet, senin gibisi yok, ya RAB! Tanrımız gibi dayanak yok.
“Kò sí ẹni tí ó mọ́ bi Olúwa; kò sí ẹlòmíràn bí kò ṣe ìwọ; kò sì sí àpáta bi Ọlọ́run wa.
3 Artık büyük konuşmayın, Ağzınızdan küstahça sözler çıkmasın. Çünkü RAB her şeyi bilen Tanrı'dır; O'dur davranışları tartan.
“Má ṣe halẹ̀; má ṣe jẹ́ kí ìgbéraga ti ẹnu yín jáde nítorí pé Ọlọ́run olùmọ̀ ni Olúwa, láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá ni a ti ń wọn ìwà.
4 Güçlülerin yayları kırılır; Güçsüzlerse güçle donatılır.
“Ọ̀run àwọn alágbára ti ṣẹ́, àwọn tí ó ṣe aláìlera ni a fi agbára dì ní àmùrè.
5 Toklar yiyecek uğruna gündelikçi olur, Açlar doyurulur. Kısır kadın yedi çocuk doğururken, Çok çocuklu kadın kimsesiz kalır.
Àwọn tí ó yọ̀ fún oúnjẹ ti fi ara wọn ṣe alágbàṣe, àwọn tí ebi ń pa kò sì ṣe aláìní. Tó bẹ́ẹ̀ tí àgàn fi bí méje. Ẹni tí ó bímọ púpọ̀ sì di aláìlágbára.
6 RAB öldürür de diriltir de, Ölüler diyarına indirir ve çıkarır. (Sheol )
“Olúwa pa ó sì sọ di ààyè; ó mú sọ̀kalẹ̀ lọ sí isà òkú, ó sì gbé dìde. (Sheol )
7 O kimini yoksul, kimini varsıl kılar; Kimini alçaltır, kimini yükseltir.
Olúwa sọ di tálákà; ó sì sọ di ọlọ́rọ̀; ó rẹ̀ sílẹ̀, ó sì gbé sókè.
8 Düşkünü yerden kaldırır, Yoksulu çöplükten çıkarır; Soylularla oturtsun Ve kendilerine onur tahtını miras olarak bağışlasın diye. Çünkü yeryüzünün temelleri RAB'bindir, O dünyayı onların üzerine kurmuştur.
Ó gbé tálákà sókè láti inú erùpẹ̀ wá, ó gbé alágbe sókè láti orí òkìtì eérú wá, láti mú wọn jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé, láti mu wọn jogún ìtẹ́ ògo, “Nítorí pé ọ̀wọ́n ayé ti Olúwa ni, ó sì ti gbé ayé ka orí wọn.
9 RAB sadık kullarının adımlarını korur, Ama kötüler karanlıkta susturulur. Çünkü güçle zafere ulaşamaz insan.
Yóò pa ẹsẹ̀ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ mọ́, àwọn ènìyàn búburú ni yóò dákẹ́ ní òkùnkùn. “Nípa agbára kò sí ọkùnrin tí yóò borí.
10 RAB'be karşı gelenler paramparça olacak, RAB onlara karşı gökleri gürletecek, Bütün dünyayı yargılayacak, Kralını güçle donatacak, Meshettiği kralın gücünü yükseltecek.”
A ó fọ́ àwọn ọ̀tá Olúwa túútúú; láti ọ̀run wá ni yóò sán àrá sí wọn; Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ òpin ayé. “Yóò fi agbára fún ọba rẹ̀, yóò si gbé ìwo ẹni àmì òróró rẹ̀ sókè.”
11 Sonra Elkana Rama'ya, evine döndü. Küçük Samuel ise Kâhin Eli'nin gözetiminde RAB'bin hizmetinde kaldı.
Elkana sì lọ sí Rama, sí ilé rẹ̀, ọmọ náà sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún Olúwa níwájú Eli àlùfáà.
12 Eli'nin oğulları değersiz kişilerdi. RAB'bi ve kâhinlerin halkla ilgili kurallarını önemsemiyorlardı. Biri sunduğu kurbanın etini haşlarken, kâhinin hizmetkârı elinde üç dişli büyük bir çatalla gelir,
Àwọn ọmọ Eli sì jẹ́ ọmọ Beliali; wọn kò mọ Olúwa.
Iṣẹ́ àwọn àlùfáà pẹ̀lú àwọn ènìyàn ni pé nígbà tí ẹnìkan bá ṣe ìrúbọ, ìránṣẹ́ àlùfáà á dé, nígbà tí ẹran náà bá ń hó lórí iná, pẹ̀lú ọ̀pá-ẹran náà oníga mẹ́ta ní ọwọ́ rẹ̀.
14 çatalı kap, tencere, tava ya da kazana daldırırdı. Çatalla çıkarılan her şey kâhin için ayırılırdı. Şilo'ya gelen İsrailliler'in hepsine böyle davranırlardı.
Òun a sì fi gún inú apẹ, tàbí àgé tàbí ọpọ́n, tàbí ìkòkò, gbogbo èyí tí ọ̀pá-ẹran oníga náà bá mú wá sí òkè, àlùfáà á mú un fún ara rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń ṣe sí gbogbo Israẹli tí ó wá sí ibẹ̀ ní Ṣilo.
15 Üstelik kurbanın yağları yakılmadan önce, kâhinin hizmetkârı gelip kurban sunan adama, “Kâhine kızartmalık et ver. Senden haşlanmış et değil, çiğ et alacak” derdi.
Pẹ̀lú, kí wọn tó sun ọ̀rá náà, ìránṣẹ́ àlùfáà á dé, á sì wí fún ọkùnrin tí ó ń ṣe ìrúbọ pé, “Fi ẹran fún mi láti sun fún àlùfáà; nítorí tí kì yóò gba ẹran sísè lọ́wọ́ rẹ, bí kò ṣe tútù.”
16 Kurban sunan, “Önce hayvanın yağları yakılmalı, sonra dilediğin kadar al” diyecek olsa, hizmetkâr, “Hayır, şimdi vereceksin, yoksa zorla alırım” diye karşılık verirdi.
Bí ọkùnrin náà bá sì wí fún un pé, “Jẹ́ kí wọn ó sun ọ̀rá náà nísinsin yìí, kí o sì mú iyekíye tí ọkàn rẹ̀ bá fẹ́,” nígbà náà ni yóò dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n kí ìwọ ó fi í fún mi nísinsin yìí, bí kó ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó fi agbára gbà á.”
17 Gençlerin RAB'be karşı işledikleri günah çok büyüktü; çünkü RAB'be sunulan sunuları küçümsüyorlardı.
Ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì tóbi gidigidi níwájú Olúwa: nítorí tí àwọn ènìyàn kórìíra ẹbọ Olúwa.
18 Bu arada genç Samuel, keten efod giymiş, RAB'bin önünde hizmet ediyordu.
Ṣùgbọ́n Samuẹli ń ṣe ìránṣẹ́ níwájú Olúwa, ọmọdé, ti a wọ̀ ní efodu ọ̀gbọ̀.
19 Yıllık kurbanı sunmak için annesi her yıl kocasıyla birlikte oraya gider, diktiği cüppeyi oğluna getirirdi.
Pẹ̀lúpẹ̀lú, ìyá rẹ̀ máa ń dá aṣọ ìlekè péńpé fún un, a sì máa mú wá fún un lọ́dọọdún, nígbà tí ó bá bá ọkọ rẹ̀ gòkè wá láti ṣe ìrúbọ ọdún.
20 Kâhin Eli de, Elkana ile karısına iyi dilekte bulunarak, “Dilediği ve RAB'be adadığı çocuğun yerine RAB sana bu kadından başka çocuklar versin” derdi. Bundan sonra evlerine dönerlerdi.
Eli súre fún Elkana àti aya rẹ̀ pé, “Kí Olúwa fún ọ ní irú-ọmọ láti ara obìnrin yìí wá, nítorí ẹ̀bùn tí ó béèrè tí ó sì tún fún Olúwa.” Wọ́n sì lọ sí ilé wọn.
21 RAB'bin lütfuna eren Hanna gebe kalıp üç erkek, iki kız daha doğurdu. Küçük Samuel ise RAB'bin hizmetinde büyüdü.
Olúwa si bojú wo Hana, ó sì lóyún, ó bí ọmọkùnrin mẹ́ta àti ọmọbìnrin méjì. Samuẹli ọmọ náà sì ń dàgbà níwájú Olúwa.
22 Eli artık çok yaşlanmıştı. Oğullarının İsrailliler'e bütün yaptıklarını, Buluşma Çadırı'nın girişinde görevli kadınlarla düşüp kalktıklarını duymuştu.
Eli sì di arúgbó gidigidi, ó sì gbọ́ gbogbo èyí ti àwọn ọmọ rẹ̀ ṣe sí gbogbo Israẹli; àti bi wọ́n ti máa ń bá àwọn obìnrin sùn, tí wọ́n máa ń péjọ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ.
23 Onlara, “Neden böyle şeyler yapıyorsunuz?” dedi, “Yaptığınız kötülükleri herkesten işitiyorum.
Ó sì wí fún wọn pé, kí ni ó ti ri “Èétirí tí èmi fi ń gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ sí yín? Nítorí tí èmi ń gbọ́ iṣẹ́ búburú yín láti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn.
24 Olmaz bu, oğullarım! RAB'bin halkı arasında yayıldığını duyduğum haber iyi değil.
Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí kì ṣe ìròyìn rere èmi gbọ́; ẹ̀yin mú ènìyàn Olúwa dẹ́ṣẹ̀.
25 İnsan insana karşı günah işlerse, Tanrı onun için aracılık eder. Ama RAB'be karşı günah işleyeni kim savunacak?” Ne var ki, onlar babalarının sözünü dinlemediler. Çünkü RAB onları öldürmek istiyordu.
Bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì, onídàájọ́ yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀: ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí Olúwa, ta ni yóò bẹ̀bẹ̀ fún un?” Wọn kò sì fi etí sí ohùn baba wọn, nítorí tí Olúwa ń fẹ́ pa wọ́n.
26 Bu arada giderek büyüyen genç Samuel RAB'bin de halkın da beğenisini kazanmaktaydı.
Ọmọ náà Samuẹli ń dàgbà, ó sì rí ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa, àti ènìyàn pẹ̀lú.
27 O sıralarda bir Tanrı adamı Eli'ye gelip şöyle dedi: “RAB diyor ki, ‘Atan ve soyu Mısır'da firavunun halkına kölelik ederken kendimi onlara açıkça göstermedim mi?
Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ Eli wá, ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Olúwa wí, ‘Èmi fi ara mi hàn ní gbangba fún ilé baba rẹ, nígbà tí wọ́n ń bẹ ní Ejibiti nínú ilé Farao.
28 Sunağıma çıkması, buhur yakıp önümde efod giymesi için bütün İsrail oymakları arasından yalnız atanı kendime kâhin seçtim. Üstelik İsrailliler'in yakılan bütün sunularını da atanın soyuna verdim.
Èmi sì yàn án kúrò láàrín gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti jẹ́ àlùfáà mi, láti rú ẹbọ lórí pẹpẹ mi, láti fi tùràrí jóná, láti wọ efodu níwájú mi, èmi sì fi gbogbo ẹbọ tí ọmọ Israẹli máa ń fi iná sun fún ìdílé baba rẹ̀.
29 Öyleyse neden konutum için buyurduğum kurbanı ve sunuyu küçümsüyorsunuz? Halkım İsrail'in sunduğu bütün sunuların en iyi kısımlarıyla kendinizi semirterek neden oğullarını benden daha çok önemsiyorsun?’
Èéha ṣe tí ẹ̀yin fi tàpá sí ẹbọ àti ọrẹ mi, tí mo pàṣẹ ní ibùjókòó mi, ìwọ sì bu ọlá fún àwọn ọmọ rẹ jù mí lọ, tí ẹ sì fi gbogbo àṣàyàn ẹbọ Israẹli àwọn ènìyàn mi mú ara yín sanra.’
30 “Bu nedenle İsrail'in Tanrısı RAB şöyle diyor: ‘Gerçekten, ailen ve atanın soyu sonsuza dek bana hizmet edecekler demiştim.’ Ama şimdi RAB şöyle buyuruyor: ‘Bu benden uzak olsun! Beni onurlandıranı ben de onurlandırırım. Ama beni saymayan küçük düşürülecek.
“Nítorí náà Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí pé, ‘Èmi ti wí nítòótọ́ pé, ilé rẹ àti ilé baba rẹ, yóò máa rìn níwájú mi títí.’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa wí pé, ‘Kí á má rí i! Àwọn tí ó bú ọlá fún mi ni èmi yóò bu ọlá fún, àti àwọn tí kò kà mí sí ni a ó sì ṣe aláìkàsí.
31 Soyundan hiç kimsenin yaşlanacak kadar yaşamaması için senin ve atanın soyunun gücünü kıracağım günler yaklaşıyor.
Kíyèsi i, àwọn ọjọ́ ń bọ̀ tí èmi ó gé agbára rẹ kúrò, àti agbára baba rẹ, tí kì yóò sí arúgbó kan nínú ilé rẹ.
32 İsrail'e yapılacak bütün iyiliğe karşın, sen konutumda sıkıntı göreceksin. Artık soyundan hiç kimse yaşlanacak kadar yaşamayacak.
Ìwọ yóò rí wàhálà ti Àgọ́, nínú gbogbo ọlá tí Ọlọ́run yóò fi fún Israẹli; kì yóò sí arúgbó kan nínú ilé rẹ láéláé.
33 Sunağımdan bütün soyunu yok edeceğim, yalnız bir kişiyi esirgeyeceğim. Gözleri ağlamaktan kör olacak, yüreği yanacak. Ama soyundan gelenlerin hepsi kılıçla ölecekler.
Ọkùnrin tí ó jẹ́ tìrẹ, tí èmi kì yóò gé kúrò ní ibi pẹpẹ mi ni a ó dá sí láti sọkún yọ lójú àti láti banújẹ́. Ṣùgbọ́n gbogbo irú-ọmọ ilé rẹ̀ ni a ó fi idà pa ní ààbọ̀ ọjọ́ wọn.
34 İki oğlun Hofni ile Pinehas'ın başına gelecek olay senin için bir belirti olacak: İkisi de aynı gün ölecek.
“‘Kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ọmọ ọkùnrin rẹ̀ méjèèjì, Hofini àti Finehasi, yóò jẹ́ àmì fún ọ—àwọn méjèèjì yóò kú ní ọjọ́ kan náà.
35 İsteklerimi ve amaçlarımı yerine getirecek güvenilir bir kâhin çıkaracağım kendime. Onun soyunu sürdüreceğim; o da meshettiğim kişinin önünde sürekli hizmet edecek.
Èmi yóò dìde fún ara mi láti gbé àlùfáà olódodo dìde fún ara mi, ẹni tí yóò ṣe gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó wà ní ọkàn mi àti inú mi. Èmi yóò fi ẹsẹ̀ ilé rẹ̀ múlẹ̀ gbọningbọnin òun yóò sì ṣe òjíṣẹ́ níwájú ẹni òróró mi ní ọjọ́ gbogbo.
36 Ailenden sağ kalan herkes bir parça gümüş ve bir somun ekmek için gelip ona boyun eğecek ve, Ne olur, karın tokluğuna beni herhangi bir kâhinlik görevine ata! diye yalvaracak.’”
Nígbà náà olúkúlùkù ẹnikẹ́ni tí ó bá kù ní ìdílé yín, yóò jáde wá yóò sì foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀ nítorí ẹyọ fàdákà àti nítorí èépá àkàrà àti ẹ̀bẹ̀ pé, “Jọ̀wọ́ yàn mí sí ọ̀kan nínú iṣẹ́ àwọn àlùfáà, kí èmi kí ó le máa rí oúnjẹ jẹ.”’”