< 1 Şamuelin 17 >

1 Filiştinaaşe dəv'ə haa'asdemee g'oşun sav'u, Yahudayne Soko eyhene şahareeqa qavayle. Sokoyneyiy Azeka eyhene şaharbışde yı'q'nee Efes-Dammimee manbışe g'oşun ulyoozarasın ciga ha'a.
Filistini kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ fún ogun ní Soko ti Juda. Wọ́n pàgọ́ sí Efesi-Damimu, láàrín Soko àti Aseka,
2 Şauluy İzrailybı sabı Ela eyhene q'adaalil g'oşun ulyoozarasın ciga hı'ı, Filiştinaaşika dəv'ə vukkeesva manbışde ögee ulyoozar.
Saulu àti àwọn ọmọ Israẹli wọ́n kò ara wọ́n jọ pọ̀, wọ́n sì pàgọ́ ní àfonífojì Ela, wọ́n sì gbé ogun wọn sókè ní ọ̀nà láti pàdé àwọn Filistini.
3 Filiştinar sa tepal, İzrailybıb manisa tepal ulyobzur vuxha. Manbışde yı'q'nee q'adaal ıxha.
Àwọn Filistini sì wà ní orí òkè kan àwọn ọmọ Israẹli sì wà ní orí òkè mìíràn, àfonífojì sì wà láàrín wọn.
4 Gatne şahareençena Golyat donana sa yugra siç'ekkvana Filiştinaaşde g'oşuneençe ögeeqa qığeç'e. Mana yixhne xılekkumneyiy sayid sa ç'umne axtıvalee ıxha.
Ọ̀gágun tí a ń pè ní Goliati, tí ó jẹ́ ará Gati, ó wá láti ibùdó Filistini. Ó ga ní ìgbọ̀nwọ́ mẹ́fà àti ìnà ìka kan ní ìbú.
5 Mang'une vuk'lel tuncıke hı'iyn dəbilga ıxha, tanalqad xhone aazır şekelyne yı'q'valeedın zireh ali'ı ıxha.
Ó ní àṣíborí idẹ ní orí rẹ̀, ó sì wọ ẹ̀wù tí a fi idẹ pẹlẹbẹ ṣe, ìwọ̀n ẹ̀wù náà sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ṣékélì idẹ.
6 Mang'une g'elybışiled tuncuke hı'iyn zireh givatxın, mang'un yı'q'əlid mizrag ıxha.
Òun sì wọ ìhámọ́ra idẹ sí ẹsẹ̀ rẹ̀ àti àpáta idẹ kan láàrín ẹ̀yìn rẹ̀.
7 Mang'une nizeyn cık'rı qexhvane xhanayn arğacın dal xhinne xətta ıxha, mançin yivayke hı'iyn sivıd yixhıd vəş şekelyne yı'qvalee ıxha. Mang'un g'alxan haqqanar cule ögil əlyhəə ıxha.
Ọ̀pá ọ̀kọ̀ rẹ̀ rí bí apásá ìhunṣọ, orí ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì wọn ẹgbẹ̀ta kilogiramu méje irin, ẹni tí ó ru asà ogun rẹ̀ lọ ṣáájú u rẹ̀.
8 Golyat gipk'ınne İzrailybışde ögilqa qığeç'u, ts'ir haa'a-haa'a eyhen: – Nişisne şu qığeepç'ı, dəv'ə haa'asne? Zı Filiştinğançena, şunab Şaulun g'ular dişde vob? Vuşde yı'q'neençe sa insan g'əyxə, hasre mana zasqa giç'ecen.
Goliati dìde, ó sì kígbe sí ogun Israẹli pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi jáde wá, tí ẹ ṣe tò fún ogun? Ṣé èmi kì í ṣe Filistini ni, àbí ẹ̀yin kì í ṣe ìránṣẹ́ Saulu? Yan ọkùnrin kan kí o sì jẹ́ kí ó sọ̀kalẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
9 Zaka siç'ekkvamee, mang'usse zı gik'as əxee, manke şi vuşun g'ular vuxhes. De'eş, zı ğamxha, zı mana gik'veene, şu yişin g'ular vuxhes, şi eyhençika şu gyuv'ur oza qeepxhes.
Tí òhun bá sì le jà tí ó sì pa mí, àwa yóò di ẹrú u yín, ṣùgbọ́n tí èmi bá lè ṣẹ́gun rẹ̀ tí mo sì pa á, ẹ̀yin yóò di ẹrú u wa, ẹ̀yin yóò sì máa sìn wá.”
10 Filiştinğançeng'vee meed eyhen: – G'iyna zı İzrailybışilqa cuvab ayhe! Zaka qığeç'u saç'ikkvasda vuşde yı'q'neençe insan g'əyxe.
Nígbà náà Filistini náà wí pé, “Èmi fi ìjà lọ ogun Israẹli ní òní! Ẹ mú ọkùnrin kan wá kí ẹ sì jẹ́ kí a bá ara wa jà.”
11 Filiştinğançeng'vee eyhen g'ayxhı, Şaulur cukan İzrailybıb çiçis üvxüyxə, manbı geeb qəvəyq'ən.
Nígbà tí Saulu àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Filistini, ìdààmú bá wọn.
12 Davud Yahudayne Bet-Lexem şahareençene Yesseyna dix ıxha. Yessey Efratbışda sa ıxha. Mang'uqa molyuyre dix ıxha. Şaulne gahıl Yessey q'əs qıxha ıxha.
Nísinsin yìí Dafidi jẹ́ ọmọ ará Efrata kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jese, tí ó wá láti Bẹtilẹhẹmu ní Juda, Jese ní ọmọ mẹ́jọ, ní àsìkò Saulu ó ti darúgbó ẹni ọdún púpọ̀.
13 Mang'una xərna xhebiyre dix Şauluka qihna dəv'eeqaniy apk'ın. Mang'une dəv'eeqa apk'ınne dixbışin dobı inbıniy vod: ts'erriyna Eliav, q'ör'esda Avinadav, xhebır'esdar Şamma.
Àwọn ọmọ Jese mẹ́tẹ̀ẹ̀ta tí ó ti dàgbà bá Saulu lọ sí ojú ogun, èyí àkọ́bí ni Eliabu, èyí èkejì ni Abinadabu, èyí ẹ̀kẹta sì ní Ṣamma.
14 Davud Yesseyna nekke k'ınna dix ıxha. Dixbışin çak'ınbı, xhebırsana Şauluqa qihna avayk'an.
Dafidi ni ó kéré jù nínú wọn. Àwọn àgbà mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì tẹ̀lé Saulu,
15 Davudur dekkın syuru uxhiyxhan ha'ava, Şaulusqa Bet-Lexemqa hark'ın qarayle ıxha.
ṣùgbọ́n Dafidi padà lẹ́yìn Saulu, láti máa tọ́jú àgùntàn baba rẹ̀ ní Bẹtilẹhẹmu.
16 Filiştinğançena Golyat, yoqts'al yiğna exhaliy-miç'eer İzrailybışisqa qığeç'u, manbışilqa cuvab ayhe ıxha.
Fún ogójì ọjọ́, Filistini wá síwájú ní àràárọ̀ àti ní ìrọ̀lẹ́ wọ́n sì fi ara wọn hàn.
17 Yiğbışde sa yiğıl Yesseyee cune duxayk'le Davuduk'le eyhen: – Həşde yits'ıble kokayiy sa maşuk' qootsune sukuna alyapt'ı, g'oşun ulyobzurne cigeeqa yiğne çocaaşisqa zaara hoora.
Nísinsin yìí Jese wí fún ọmọ rẹ̀ Dafidi pé, “Mú ìwọ̀n efa àti àgbàdo yíyan àti ìṣù àkàrà mẹ́wàá lọ fún àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ kí o sì súré lọ sí ibùdó o wọn.
18 Manbışde xərıng'usub yits'ıble guru nissenna alept'e. Çocaaşilir alycaxve, manbı nəxübiyva zas xabar able.
Kí o sì mú wàrà mẹ́wàá yìí lọ́wọ́ fún adarí ogun tiwọn. Wo bí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ ṣe wà kí o sì padà wá fún mi ní àmì ìdánilójú láti ọ̀dọ̀ wọn.
19 Yiğın çocar Şaulukayiy mang'une insanaaşika sacigee Ela eyhene q'adaalil, Filiştinaaşika dəv'ə haa'a vob.
Wọ́n wà pẹ̀lú Saulu àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli ní àfonífojì Ela, wọ́n bá àwọn Filistini jà.”
20 Davud miç'eer çakra suğotsu, cun vəq'əbı menne çobanılqa g'alya'a. Qiyğar mana, Yesseyee uvhuyn xhinne, karbı alyaat'u, ayk'anna. Mana g'oşun ulyobzurne cigeeqa qarı hirxhıling'a, g'oşun dəv'ə haa'asde cigeeqa axtıne seseka giviyk'an g'ooce.
Ní àárọ̀ kùtùkùtù Dafidi fi agbo ẹran rẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn olùtọ́jú, ó di ẹrù, ó sì mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n gẹ́gẹ́ bí Jese ti sọ fún un. Ó dé ibùdó bí àwọn ọmọ-ogun ti ń lọ láti dúró ní ipò wọn ní ojú ogun, wọ́n hó ìhó ogun.
21 İzrailybıyiy Filiştinar sanasanbışde ögee ulyozar haa'a.
Israẹli àti Filistini lọ sí ojú ìjà wọ́n da ojú ìjà kọ ara wọn.
22 Davudee, vucee adıyn karbı g'oşuneene g'aravulyçilqa g'ali'ı, g'oşun gipk'ınne cigeeqa çocaaşis xoşgelydiy haa'asva g'adayxhvan.
Dafidi sì kó ẹrù rẹ̀ ti àwọn olùtọ́jú ohun èlò, ó sì sálọ sí ojú ogun ó sì kí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
23 Davudee çocaaşika gaf haa'ang'a, Filiştinaaşine Gat şahareençena Golyat donana sa yugra siç'ekkvana hiqa qığeç'u, meed ögiylin xhinne cuvabbı ayhe. Mang'vee eyhenbı Davuduk'le g'iyxhenbı.
Bí ó ṣe ń bá wọn sọ̀rọ̀, Goliati akíkanjú Filistini tí ó wá láti Gati bọ́ sí iwájú ní ojú ogun, ó sì kígbe fún ìpèníjà, Dafidi sì gbọ́.
24 Gırgın İzrailybıcab mana insan g'acumee it'umba qəpq'ı'n heebaxa vuxha.
Nígbà tí àwọn Israẹli rí ọkùnrin náà, gbogbo wọn sì sá fún un ní ìbẹ̀rù bojo.
25 Manbışe eyhe ıxha: – Şok'le mana ögilqa qığeç'una insan g'eceye? Mana İzraililqa cuvab ahas qığeç'u. Mana gik'una insan paççahee geed karnana ha'as, mang'us yişir heylesda, mang'une dekkına xizanıb İzrailyne nalok'bışike g'attivxhan haa'asda.
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin Israẹli wí pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò rí i bí ọkùnrin yìí ṣe ń jáde wá? Ó jáde wá láti pe Israẹli níjà. Ọba yóò fún ọkùnrin tí ó bá pa á ní ọrọ̀ púpọ̀. Yóò tún fi ọmọ rẹ̀ obìnrin fún un ní ìyàwó, yóò sì sọ ilé e baba rẹ̀ di òmìnira kúrò nínú sísan owó orí ní Israẹli.”
26 Davudee cune k'ane ulyobzurne insanaaşike qiyghanan: – İna Filiştinğançena gik'uyne, İzrail tesseriyvalike g'attivxhan hav'uyne insanıs hucooy'e heles? İna sunnat hidi'ına Filiştinğançena vuşuna eyxhe, Vorne Allahne g'oşunbışilqa cuvab ayhe?
Dafidi béèrè lọ́wọ́ ọkùnrin tí ó dúró ní ẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Kí ni a yóò ṣe fún ọkùnrin náà tí ó bá pa Filistini yìí, tí ó sì mú ẹ̀gàn kúrò lára Israẹli? Ta ni aláìkọlà Filistini tí ó jẹ́ wí pé yóò máa gan ogun Ọlọ́run alààyè?”
27 Milletın, mana gik'uyne insanık hucooyiy ha'asva, sayid eyhen.
Wọ́n tún sọ fún un ohun tí wọ́n ti ń sọ, wọ́n sì wí pé, “Èyí ni ohun tí wọn yóò ṣe fún ọkùnrin tí ó bá pa á.”
28 Davud insanaaşika yuşan ha'amee, mang'vee eyhenbı xərne çocuk'le, Eliavık'le g'iyxhe. Mançike çocus qəl vuxha qiyghanan: – Nişisne ğu inyaqa arı? Çoleena yişda sa-q'öble vəq'ə, ğu şavulqane g'alepçı? Zak'le ats'an, ğucar ğu xərra ıkkekka ıxhayke, yiğne yik'eençed yugun karbı ılğı'də ıxhayke, ğu inyaqa dəv'əyqa ilyakkas arı.
Nígbà tí Eliabu ẹ̀gbọ́n Dafidi gbọ́ nígbà tí ó ń bá ọkùnrin yìí sọ̀rọ̀, ó bínú sí i, ó sì wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi sọ̀kalẹ̀ wá síbí? Àti pé ta ni ìwọ fi àwọn àgùntàn kékeré tókù ṣọ́ ní aginjù? Èmi mọ ìgbéraga rẹ, àti búburú ọkàn rẹ: ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá nìkan láti wòran ogun.”
29 Davudee eyhen: – Nya'a, zı hucoona hı'ı? Nya'a, zas yuşan ha'asırne dexhes?
Dafidi wí pé, “Kí ni mo ṣe nísinsin yìí? Ǹjẹ́ mo lè sọ̀rọ̀ bí?”
30 Davud çocuke merıng'ulqa sak'ı, mançinacab gaf haa'a giyğal, milletınıd ögiylin xhinne mang'us alidghıniy qele.
Ó sì yípadà sí ẹlòmíràn, ó sì ń sọ̀rọ̀ kan náà, ọkùnrin náà sì dáhùn bí ti ẹni ìṣáájú.
31 Davudee yuşan ha'anbı g'ayxhinbışe, mang'un cuvab Şaululqa hixhar ha'a. Şauleeyir mana cusqa qoyt'al.
Àwọn ènìyàn gbọ́ ohun tí Dafidi sọ wọ́n sọ fún Saulu, Saulu sì ránṣẹ́ sí i.
32 Davudee Şauluk'le eyhen: – Hasre mane insanıl-alla şavaacad aq'va havaxan hıma'acen. Zı, yiğna g'ul, hark'ın mang'uka səyxəsda.
Dafidi sọ fún Saulu pé, “Kí ẹnikẹ́ni má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí Filistini yìí, ìránṣẹ́ rẹ yóò lọ láti bá a jà.”
33 Şaulee Davuduk'le eyhen: – Vasse mane Filiştinğançeng'uka saç'ikkvas əxəs deş, ğu uşax vod, manamee k'ırranang'ançile otç'u dəv'əbışee siç'ekkvana vor.
Saulu sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò tó láti jáde lọ pàdé ogun Filistini yìí àti láti bá a jà; ọmọdé ni ìwọ, òun sì ti ń jagun láti ìgbà èwe rẹ̀ wá.”
34 Davudee Şauluk'le eyhen: – Zı dekkın syuru uxhiyxhana'asniy haykanna. Şirın, syoyun abı syuruneençe urg avqu əlyhəəmee,
Ṣùgbọ́n Dafidi sọ fún Saulu pé, “Ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ti ń tọ́jú agbo àgùntàn baba rẹ̀. Nígbà tí kìnnìún tàbí àmọ̀tẹ́kùn bá wá láti wá gbé àgùntàn láti inú igbó.
35 zı mançiqar qihna gyurxhu mançileğana kar ı'xı' ghalençe urg g'ooşenaniy. Mane həyvanaaşina sa zalqa g'opk'uluyng'amee, zı mana həyvan gardanılyne xhayıke avqu mana gyook'ananiy.
Mo sá tẹ̀lé e, mo lù ú, mo sì gba àgùntàn náà kúrò lẹ́nu rẹ̀. Nígbà tí ó kọjú sí mi, mo fi irun rẹ̀ gbá a mú, mo sì lù ú mo sì pa á.
36 Zı, yiğne g'ulee, şirıd, syoyub gyuvk'una. Mana sunnat hidi'ına Filiştinğançenar mançina sa xhinne ixhes, mang'vee Vorne Allahne g'oşunulqa cuvab avhuva.
Ìránṣẹ́ rẹ ti pa kìnnìún àti àmọ̀tẹ́kùn, aláìkọlà Filistini yìí yóò jẹ́ ọ̀kan lára wọn, nítorí ó ti pe ogun Ọlọ́run alààyè ní ìjà.
37 Şirneyiy syoyune ghalençe zı g'attixhan hı'iyne Rəbbee, Filiştinğançeng'uner xılençe g'attixhan ha'asda. Şaulee Davuduk'le eyhen: – Hak'ne, Rəbb Vuc vaka ixhecen!
Olúwa tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìhàlẹ̀ kìnnìún àti ti ìhàlẹ̀ àmọ̀tẹ́kùn yóò gbà mí kúrò lọ́wọ́ Filistini yìí.” Saulu wí fún Dafidi pé, “Lọ kí Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
38 Şaulee cun silahbı Davuduk qa'a. Vuk'lelqa tuncuna dəbilga giviyxhe, tanalqad zirehbı alya'a.
Saulu fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ wọ Dafidi, ó wọ̀ ọ́ ní aṣọ ìhámọ́ra ogun, ó sì fi ìbòrí idẹ kan bò ó ní orí.
39 Davudee mane zirehıl ooğançe g'ılınc qı'ı iykar. Mankilqamee mang'vee silah iykar hı'iyn deşdiy. Qiyğa Davudee Şauluk'le eyhen: – Zasse man karbı ali'ı iykaras əxə deş. Zı həşdilqamee məxdın karbı ali'iynbıcad deşdiy. Davudee manbı tanale g'eşşenbı.
Dafidi si di idà rẹ̀ mọ́ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní rìn káàkiri nítorí wí pé kò mọ́ ọ lára. Ó sọ fún Saulu pé, “Èmi kò le wọ èyí lọ, kò mọ́ mi lára.” Ó sì bọ́ wọn kúrò.
40 Qiyğa xılyaqa əsaa alyaat'u, arageençe cusda xhoble hamavarna g'ayeb g'əvxü, manbıd q'oç'eeqa k'i'ı xılene sapandıka mana Filiştinğançeng'usqa qexhe.
Nígbà náà, ó sì mú ọ̀pá rẹ̀ lọ́wọ́, ó ṣá òkúta dídán márùn-ún létí odò, ó kó wọn sí àpò olùṣọ́-àgùntàn tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kànnàkànnà, ó sì súnmọ́ Filistini náà.
41 Filiştinğançenar cune g'alxan haqqang'uka mane gahıl Davudne suralqa q'öö eyxhe.
Lákòókò yìí, Filistini pẹ̀lú ẹni tí ń gbé ìhámọ́ra ààbò wà níwájú rẹ̀, ó ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ Dafidi.
42 Filiştinğançeng'uk'le Davud ç'ərəne danbışika, aq'vayle uftanra, mek'vra g'acumee, mana mang'uqa ooğançe-avqa ilyakka.
Nígbà tí Filistini náà sì wo Dafidi láti òkè délẹ̀, ó sì rí i wí pé ọmọ kékeré kùnrin ni, ó pọ́n ó sì lẹ́wà lójú, ó sì kẹ́gàn an rẹ̀.
43 Mang'vee Davuduk'le eyhen: – Nya'a, zı vas xvaane vob, ğu zalqa t'at'aaka ı'qqə? Filiştinğançeng'vee cone allahaaşika Davudus bed-düə hav'u eyhen:
Ó sì wí fún Dafidi pé, “Ṣé ajá ni mí ni? Tí o fi tọ̀ mí wá pẹ̀lú ọ̀pá?” Filistini sì fi Dafidi bú pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.
44 – Zasqana qora, zı yiğne ç'urunuke xəəne şit'yaaşisiy, çolane həyvanaaşis heles.
Filistini náà sì wí Dafidi pé, “Wá níbí, èmi yóò fi ẹran-ara rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run jẹ àti fún àwọn ẹranko tí ó wà nínú igbó!”
45 Davudeeme Filiştinğançeng'uk'le eyhen: – Ğu zalqa g'ılıncıka, nizeyka, mizragıka qöö, zımee valqa ğu hokuyne İzrailyne g'oşunbışde Allahne, Xəəne G'oşunbışde Rəbbine doyuka q'öö.
Dafidi sì wí fún Filistini pé, “Ìwọ dojú ìjà kọ mí pẹ̀lú idà, ọ̀kọ̀ àti ọfà, ṣùgbọ́n èmi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ pẹ̀lú orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli tí ìwọ tí gàn.
46 G'iyna Rəbbee ğu yizde xılyaqa qeles, zınar ğu gik'asda. Zı yiğna vuk'ul tanake curaa'asda. G'iyna Filiştinaaşde g'oşunbışin leşbı, zı xəəne şit'yaaşisiy çolane həyvanaaşis heles. Mançile qiyğa gırgıne dyunyeyk'lecad ats'axhxhesın İzrailee Allah vorna.
Lónìí yìí ni Olúwa yóò fi ọ́ lé mi lọ́wọ́, èmi yóò sì pa ọ́, èmi yóò sì gé orí rẹ. Lónìí èmi yóò fi òkú ogun Filistini fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko igbó, gbogbo ayé yóò sì mọ̀ pé Ọlọ́run wà ní Israẹli.
47 İnyaqa sabıyne gırgıng'uk'lecad ats'axhxhesın, Rəbbee g'ılıncıkayiy nizeyka deş g'attivxhan haa'a, ina Rəbbina dəv'ə vobna, Mang'veeyib şu yişde xılyaqa qevles.
Gbogbo àwọn tí ó péjọ níbí ni yóò mọ̀ pé kì í ṣe nípa ọ̀kọ̀ tàbí idà ni Olúwa fi ń gbàlà; ogun náà ti Olúwa ni, yóò sì fi gbogbo yín lé ọwọ́ wa.”
48 Filiştinğançena Davudne ögeeqa qığeç'esva, mang'usqana qöömee, Davud zaara ı'ğiykır Filiştinaaşde g'oşunbışde suralqana g'adayxhvan.
Bí Filistini ṣe súnmọ́ iwájú láti pàdé e rẹ̀. Dafidi yára sáré sí òun náà láti pàdé e rẹ̀.
49 Davudee q'oç'eeqa xıl k'eççu g'aye alyabat'a, qiyğab sapandeeqa gyuvxhu avhu, Filiştinğançeng'une ligaylek'ena üvxüyxə. G'aye qipxhırmee mang'une ligayna bark'v havayq'ar, vucur aqvakkena ç'iyelqa qukkyoyk'al.
Dafidi ti ọwọ́ sí àpò rẹ̀, ó sì mú òkúta jáde wá ó sì fì í, ó sì jù ú sí ọ̀kọ́kán iwájú orí Filistini. Òkúta náà sì wọ̀ ọ́ níwájú orí, ó sì ṣubú ó sì dojúbolẹ̀ ní orí ilẹ̀.
50 Davud Filiştinğançeng'ule sapandıkayiy g'ayeyka ğamexhe. Davudne xılee g'ılıncıd eyxhe deş, mang'vee Filiştinğançena ı'xı' gek'ana.
Dafidi yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí Filistini pẹ̀lú kànnàkànnà àti òkúta, láìsí idà ní ọwọ́ rẹ̀, ó lu Filistini, ó sì pa á.
51 Davud g'adarxhun Filiştinğançeng'une k'ane ulyoyzar. Filiştinğançeng'un g'ılınc qığayşu mana gik'u, qiyğab vuk'ul tanıke curaa'a. Filiştinaaşik'le cona yugra siç'ekkvana qik'u g'acumee, manbı heebaxanbı.
Dafidi sì sáré ó sì dúró lórí rẹ̀. Ó sì mú idà Filistini, ó sì fà á yọ nínú àkọ̀ ọ rẹ̀. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti pa á tan, ó sì gé orí rẹ̀ pẹ̀lú idà. Nígbà tí àwọn ará Filistini rí i wí pé akọni wọn ti kú, wọ́n yípadà wọ́n sì sálọ.
52 İzrailiniy Yahudayn g'oşunbıd ts'irbı ha'a manbışiqa qihna gyadak'va. Manbışe Filiştinar Gateeqa ikkəəne cigeeqamee, Ekronne akkabışisqamee g'e'eebaşenbı. Gateeqayiy Ekronqa əlyhəəna Şaarayimna yəqvolle Filiştinaaşin gyapt'ıynbı opt'ul-opxul vuxha.
Nígbà náà, àwọn ọkùnrin Israẹli àti ti Juda súnmọ́ iwájú pẹ̀lú ariwo, wọ́n sì lépa àwọn ará Filistini dé ẹnu ibodè Gati àti títí dé ẹnu ibodè Ekroni. Àwọn tí ó kú wà káàkiri ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà Ṣaaraimu àti títí dé ọ̀nà Gati àti Ekroni.
53 İzrailybı Filiştinaaşiqab qihna gyapk'ı, mançe sapk'ılıyle qiyğa manbışin g'oşunbı ulyozzuriyn cigabı q'əra qa'a.
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli sì padà láti máa lé àwọn ará Filistini, wọ́n sì ba ibùdó wọn jẹ́.
54 Davudee Golyatna vuk'ul alyapt'ı İyerusalimqa qavayle. Filiştinğançeng'un g'ılıncmee adı, Davudne çadıreeqa giyxhe.
Dafidi gé orí Filistini ó sì gbé e wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó àwọn ohun ìjà Filistini sínú àgọ́ tirẹ̀.
55 Şauluk'le Davud Filiştinğançeng'usqa qığəə g'acumee, mang'vee g'oşunbışde xərıng'uke, Avnerıke, qiyghanan: – Avner, ina cehil şavna dixne? Avneree eyhen: – Paççah, geer qa'ana, ats'a deş.
Bí Saulu sì ti wo Dafidi bí ó ṣe ń jáde lọ pàdé Filistini, ó wí fún Abneri, olórí àwọn ológun rẹ̀ pé, “Abneri, ọmọ ta ni ọmọdékùnrin yìí?” Abneri dáhùn pe, “Bí ọkàn rẹ̀ ti ń bẹ ní ààyè, ọba èmi kò mọ̀.”
56 Paççahee eyhen: – Ats'axhxhelan, mana cehil şavna dixiy.
Ọba sì wí pé, “Wádìí ọmọ ẹni tí ọmọdékùnrin náà ń ṣe.”
57 Davud Golyat gik'u qöömee, Avneree mana qort'ul, Şaulusqa ıkkekka. Filiştinğançeng'una vuk'ulyub mang'une xıleecab vooxhe.
Kété tí ó dé láti ibi tí ó ti lọ pa Filistini, Abneri sì mú u wá síwájú Saulu, orí Filistini sì wà ní ọwọ́ Dafidi.
58 Şaulee mang'uke qiyghanan: – Cehil, ğu şavna dixne? Davudee «Yiğne Bet-Lexemğançene g'uluna, Yesseyna dix vornava» alidghıniy qele.
Saulu béèrè pé, “Ọmọdékùnrin, ọmọ ta ni ọ́?” Dafidi dáhùn pé, “Èmi ni ọmọ ìránṣẹ́ rẹ Jese ti Bẹtilẹhẹmu.”

< 1 Şamuelin 17 >