< Psaltaren 69 >

1 För sångmästaren, efter "Liljor"; av David. Fräls mig, Gud; ty vattnen tränga mig inpå livet.
Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi. Gbà mí, Ọlọ́run, nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
2 Jag har sjunkit ned i djup dy, där ingen botten är; jag har kommit i djupa vatten, och svallet vill fördränka mig.
Mo ń rì nínú irà jíjìn, níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé. Mo ti wá sínú omi jíjìn; ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
3 Jag har ropat mig trött, min strupe är förtorkad; mina ögon försmäkta av förbidan efter min Gud.
Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́; ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú, nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
4 Flera än håren på mitt huvud äro de som hata mig utan sak; många äro de som vilja förgöra mig, de som äro mina fiender utan skäl; vad jag icke har rövat, det måste jag gälda.
Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí wọ́n ju irun orí mi lọ, púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí, àwọn tí ń wá láti pa mí run. A fi ipá mú mi láti san ohun tí èmi kò jí.
5 Du, o Gud, känner min dårskap, och mina skulder äro icke förborgade för dig.
Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run; ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
6 Låt icke i mig dem komma på skam, som förbida dig, Herre, HERRE Sebaot; Låt icke i mig dem varda till blygd, som söka dig, du Israels Gud.
Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun; má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi, Ọlọ́run Israẹli.
7 Ty för din skull bär jag smälek, för din skull höljer blygsel mitt ansikte;
Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn, ìtìjú sì bo ojú mi.
8 främmande har jag blivit för mina bröder och en främling för min moders barn.
Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi; àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
9 Ty nitälskan för ditt hus har förtärt mig, och dina smädares smädelser hava fallit över mig.
nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run, àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
10 Jag grät, ja, min själ grät under fasta, men det blev mig till smälek.
Nígbà tí mo sọkún tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
11 Jag klädde mig i sorgdräkt, men jag blev för dem ett ordspråk.
nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà, àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
12 Om mig tassla de, när de sitta i porten; i dryckeslag göra de visor om mig.
Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi, mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
13 Men jag kommer med min bön till dig, HERRE, i behaglig tid, genom din stora nåd, o Gud; svara mig i din frälsande trofasthet.
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa, ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ, dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
14 Rädda mig ur dyn, så att jag icke sjunker ned; låt mig bliva räddad från dem som hata mig och från de djupa vattnen.
Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀, má ṣe jẹ́ kí n rì; gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, kúrò nínú ibú omi.
15 Låt icke vattensvallet fördränka mig eller djupet uppsluka mig; och låt ej graven tillsluta sitt gap över mig.
Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
16 Svara mig, HERRE, ty god är din nåd; vänd dig till mig efter din stora barmhärtighet.
Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ; nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
17 Fördölj icke ditt ansikte för din tjänare, ty jag är i nöd; skynda att svara mig.
Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ: yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
18 Kom till min själ och förlossa henne; befria mig för mina fienders skull.
Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là; rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
19 Du känner min smälek, min skam och blygd; du ser alla mina ovänner.
Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá; gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
20 Smälek har krossat mitt hjärta, så att jag är vanmäktig; jag väntade på medlidande, men där var intet, och på tröstare, men jag fann ingen.
Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́; mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí, mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
21 De gåvo mig galla att äta, och ättika att dricka, i min törst.
Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi, àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
22 Må deras bord framför dem bliva till en snara och till ett giller, bäst de gå där säkra;
Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
23 må deras ögon förmörkas, så att de icke se; gör deras länder vacklande alltid.
Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran, kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
24 Gjut ut över dem din ogunst, och låt din vredes glöd hinna upp dem.
Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn; kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
25 Deras gård blive öde, ingen må finnas, som bor i deras hyddor,
Kí ibùjókòó wọn di ahoro; kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
26 eftersom de förfölja dem som du själv har slagit och orda om huru de plågas, som du har stungit.
Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù, àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
27 Låt dem gå från missgärning till missgärning, och låt dem icke komma till din rättfärdighet.
Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
28 Må de utplånas ur de levandes bok och icke varda uppskrivna bland de rättfärdiga.
Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
29 Men mig som är betryckt och plågad, mig skall din frälsning, o Gud, beskydda.
Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí, Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
30 Jag vill lova Guds namn med sång och upphöja honom med tacksägelse.
Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
31 Det skall behaga HERREN bättre än någon tjur, något offerdjur med horn och klövar.
Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
32 När de ödmjuka se det, skola de glädja sig; I som söken Gud, edra hjärtan skola leva.
Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀: ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
33 Ty HERREN lyssnar till de fattiga och föraktar icke sina fångna.
Olúwa, gbọ́ ti aláìní, kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
34 Honom love himmelen och jorden, havet och allt vad som rör sig däri.
Kí ọ̀run àti ayé yìn ín, òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
35 Ty Gud skall frälsa Sion, han skall bygga upp Juda städer; man skall bo i dem och besitta landet.
nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́. Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
36 Hans tjänares barn skola få det till arvedel, och de som älska hans namn skola bo däri.
àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀, àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.

< Psaltaren 69 >