< Psaltaren 62 >
1 För sångmästaren, till Jedutun; en psalm av David. Allenast hos Gud söker min själ sin ro; från honom kommer min frälsning.
Fún adarí orin. Fun Jedutuni. Saamu Dafidi. Nínú Ọlọ́run nìkan ni ọkàn mi ti rí ìsinmi; ìgbàlà mi ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá.
2 Allenast han är min klippa och min frälsning, min borg, jag skall ej mycket vackla.
Òun nìkan ní àpáta mi àti ìgbàlà mi; Òun ni ààbò mi, a kì yóò sí mi ní ipò padà.
3 Huru länge viljen I rasa mot denne man, samfällt slå honom ned, såsom vore han en lutande vägg, en sönderbräckt mur?
Ẹ̀yin ó ti máa kọ́lú ènìyàn kan pẹ́ tó? Gbogbo yín ni ó fẹ́ pa á, bí ògiri tí ó fẹ́ yẹ̀, àti bí ọgbà tí ń wó lọ?
4 De rådslå allenast om att stöta honom ned från hans höjd, de hava behag till lögn; med munnen välsigna de, men i sitt innersta förbanna de. (Sela)
Kìkì èrò wọn ni láti bì ṣubú kúrò nínú ọlá rẹ̀; inú wọn dùn sí irọ́. Wọ́n ń fi ẹnu wọn súre, ṣùgbọ́n wọ́n ń gégùn ún nínú ọkàn wọn. (Sela)
5 Allenast i Gud må du hava din ro, min själ; ty från honom kommer mitt hopp.
Nínú Ọlọ́run nìkan ni ìsinmi wà, ìwọ Ọlọ́run mi. Ìrètí mi wá láti ọ̀dọ̀ rẹ.
6 Allenast han är min klippa och min frälsning, min borg, jag skall icke vackla.
Òun nìkan ní àpáta àti ìgbàlà mi; Òun ni ààbò mi, a kì yóò ṣí mi ní ipò.
7 Hos Gud är min frälsning och min ära; min starka klippa, min tillflykt har jag i Gud.
Ìgbàlà mi àti ògo mi dúró nínú Ọlọ́run; Òun ní àpáta ńlá mi, àti ààbò mi.
8 Förtrösta på honom alltid, du folk; utgjuten för honom edra hjärtan. Gud är vår tillflykt. (Sela)
Gbẹ́kẹ̀lé ní gbogbo ìgbà, ẹ̀yin ènìyàn; tú ọkàn rẹ jáde sí i, nítorí Ọlọ́run ni ààbò wa.
9 Allenast ett intet äro människors barn, myndiga herrar fåfänglighet; i vågskålen äro de för lätta, mindre än intet äro de allasammans.
Nítòótọ́, asán ni àwọn ọmọ ènìyàn, èké sì ni àwọn olóyè, wọ́n gòkè nínú ìwọ̀n, lápapọ̀ wọ́n jẹ́ èémí.
10 Förliten eder icke på orätt vinning, sätten icke ett fåfängligt hopp till rov: om ock eder rikedom växer, så akten icke därpå.
Má ṣe gbẹ́kẹ̀lé ìnilára, tàbí gbéraga nínú olè jíjà, nítòótọ́ bí ọrọ̀ rẹ̀ ń pọ̀ sí i, má ṣe gbẹ́kẹ̀ rẹ lé wọn.
11 En gång har Gud sagt det, ja, två gånger har jag hört det, att hos Gud är makten;
Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ lẹ́ẹ̀kejì, ni mo gbọ́ èyí pé, “Ti Ọlọ́run ni agbára,
12 och hos dig, Herre, är nåd. Ty du vedergäller var och en efter hans gärningar.
pẹ̀lúpẹ̀lú, Olúwa, tìrẹ ni àánú; nítorí tí ìwọ san án fún olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.”