< Nehemja 4 >

1 När nu Sanballat hörde att vi höllo på att bygga upp muren, vredgades han och blev högeligen förtörnad. Och han bespottade judarna
Nígbà tí Sanballati gbọ́ pé àwa ń tún odi náà mọ, ó bínú, ó sì bínú púpọ̀. Ó fi àwọn ará Júù ṣe ẹlẹ́yà,
2 och talade så inför sina bröder och inför Samariens krigsfolk: "Vad är det dessa vanmäktiga judar göra? Skall man låta dem hållas? Skola de få offra? Skola de kanhända i sinom tid fullborda sitt verk? Skola de kunna giva liv åt stenarna i grushögarna, där de ligga förbrända?"
ó sọ níwájú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ àti níwájú àwọn ọmọ-ogun Samaria pé, “Kí ni àwọn aláìlera Júù wọ̀nyí ń ṣe yìí? Ṣé wọn yóò mú odi wọn padà ni? Ṣé wọn yóò rú ẹbọ ni? Ṣé wọn yóò parí i rẹ̀ lóòjọ́ ni bí? Ṣé wọ́n lè mú òkúta tí a ti sun láti inú òkìtì padà bọ̀ sípò tí ó jóná bí wọ́n ṣe wà?”
3 Och ammoniten Tobia, som stod bredvid honom sade: "Huru de än bygga, skall dock en räv komma deras stenmur att rämna, blott han hoppar upp på den."
Tobiah ará Ammoni, ẹni tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, wí pé, “Ohun tí wọ́n ń mọ—bí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ lásán bá gùn ún sókè, yóò fọ́ odi òkúta wọn lulẹ̀!”
4 Hör, vår Gud, huru föraktade vi äro. Låt deras smädelser falla tillbaka på deras egna huvuden. Ja, låt dem bliva utplundrade i ett land dit de föras såsom fångar.
Gbọ́ ti wa, Ọlọ́run wa, nítorí àwa di ẹni ẹ̀gàn. Dá ẹ̀gàn wọn padà sórí ara wọn. Kí o sì fi wọ́n fún ìkógun ní ilẹ̀ ìgbèkùn.
5 Överskyl icke deras missgärningar, och låt deras synd icke varda utplånad ur din åsyn, eftersom de hava varit de byggande till förargelse.
Má ṣe bo ẹ̀bi wọn tàbí wẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wọn nù kúrò níwájú rẹ, nítorí wọ́n mú ọ bínú níwájú àwọn ọ̀mọ̀lé.
6 Och vi byggde på muren, och hela muren blev hopfogad till sin halva höjd; och folket arbetade med gott mod.
Bẹ́ẹ̀ ni àwa mọ odi náà títí gbogbo rẹ̀ fi dé ìdajì gíga rẹ̀, nítorí àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an wọn.
7 Men när Sanballat och Tobia och araberna, ammoniterna och asdoditerna hörde att man alltjämt höll på med att laga upp Jerusalems murar, och att rämnorna begynte igentäppas, då blevo de mycket vreda.
Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati, Tobiah, àwọn ará Arabia, ará Ammoni, àti àwọn ènìyàn Aṣdodu gbọ́ pé àtúnṣe odi Jerusalẹmu ti ga dé òkè àti pé a ti mọ àwọn ibi tí ó yá dí, inú bí wọn gidigidi.
8 Och de sammansvuro sig allasammans att gå åstad och angripa Jerusalem och störa folket i deras arbete.
Gbogbo wọn jọ gbìmọ̀ pọ̀ láti wá bá Jerusalẹmu jà àti láti dìde wàhálà sí í.
9 Då bådo vi till vår Gud; och vi läto hålla vakt mot dem både dag och natt för att skydda oss mot dem.
Ṣùgbọ́n àwa gbàdúrà sí Ọlọ́run wa, a sì yan olùṣọ́ ọ̀sán àti ti òru láti kojú ìhàlẹ̀ yìí.
10 Men judarna sade: "Bärarnas kraft sviker, och gruset är alltför mycket; vi förmå icke mer att bygga på muren."
Lákòókò yìí, àwọn ènìyàn Juda wí pé, “Agbára àwọn òṣìṣẹ́ ti dínkù, àlàpà púpọ̀ ni ó wà tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi le è mọ odi náà.”
11 Våra ovänner åter sade: "Innan de få veta eller se något, skola vi stå mitt ibland dem och dräpa dem; så skola vi göra slut på arbetet."
Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ọ̀tá wa wí pé, “Kí wọn tó mọ̀ tàbí kí wọn tó rí wa, àwa yóò ti dé àárín wọn, a ó sì pa wọ́n, a ó sì dá iṣẹ́ náà dúró.”
12 När nu de judar som bodde i deras grannskap kommo och från alla håll uppmanade oss, väl tio gånger, att vi skulle draga oss tillbaka till dem,
Nígbà náà ni àwọn Júù tí ó ń gbé ní ẹ̀gbẹ́ wọn wá sọ fún wa ní ìgbà mẹ́wàá pé, “Ibikíbi tí ẹ̀yin bá padà sí, wọn yóò kọlù wá.”
13 då ställde jag upp folket i de lägsta och mest öppna delarna av staden bakom muren; jag ställde upp dem efter släkter, med sina svärd, spjut och bågar.
Nítorí náà mo dá ènìyàn díẹ̀ dúró níbi tí ó rẹlẹ̀ jù lẹ́yìn odi ní ibi gbangba, mo fi wọ́n síbẹ̀ nípa àwọn ìdílé wọn, pẹ̀lú àwọn idà wọn, àwọn ọ̀kọ̀ wọn àti àwọn ọrun wọn.
14 Och sedan jag hade besett allt, stod jag upp och sade till ädlingarna och föreståndarna och det övriga folket: "Frukten icke för dem; tänken på Herren, den store och fruktansvärde, och striden för edra bröder, edra söner och döttrar, edra hustrur och edra hus."
Lẹ́yìn ìgbà tí mo wo àwọn nǹkan yíká, mo dìde mo sì wí fún àwọn ọlọ́lá àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù u wọn. Ẹ rántí Olúwa, ẹni tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, kí ẹ sì jà fún àwọn arákùnrin yín, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, àwọn ìyàwó yín àti àwọn ilé yín.”
15 Sedan våra fiender sålunda hade fått förnimma att saken var oss bekant, och att Gud hade gjort deras råd om intet, kunde vi alla vända tillbaka till muren, var och en till sitt arbete.
Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ pé àwa ti mọ èrò wọn àti wí pé Ọlọ́run ti bà á jẹ́, gbogbo wa padà sí ibi odi, ẹnìkọ̀ọ̀kan sí ibi iṣẹ́ tirẹ̀.
16 Från den dagen var ena hälften av mina tjänare sysselsatt med arbetet, under det att andra hälften stod väpnad med sina spjut, sköldar, bågar och pansar, medan furstarna stodo bakom hela Juda hus.
Láti ọjọ́ náà lọ, ìdajì àwọn ènìyàn ń ṣe iṣẹ́ náà, nígbà tí àwọn ìdajì tókù múra pẹ̀lú ọ̀kọ̀, asà, ọrun àti ìhámọ́ra. Àwọn ìjòyè sì pín ara wọn sẹ́yìn gbogbo ènìyàn Juda.
17 De som byggde på muren och de som lassade på och buro bördor gjorde sitt arbete med den ena handen, och med den andra höllo de vapnet.
Àwọn ẹni tí ó ń mọ odi. Àwọn tí ń ru àwọn ohun èlò ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú ọwọ́ kan, wọ́n sì fi ọwọ́ kejì di ohun ìjà mú,
18 Och de som byggde hade var och en sitt svärd bundet vid sin länd, under det att de byggde; och bredvid mig stod en basunblåsare.
olúkúlùkù àwọn ọ̀mọ̀lé fi idà wọn sí ẹ̀gbẹ́ wọn bí wọ́n ṣe ń ṣiṣẹ́. Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí ń fọn ìpè dúró pẹ̀lú mi.
19 Jag hade nämligen sagt till ädlingarna och föreståndarna och det övriga folket: "Arbetet är stort och vidsträckt, och vi äro spridda över muren, långt ifrån varandra.
Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Iṣẹ́ náà fẹ̀ ó sì pọ̀, a sì ti jìnnà sí ara wa púpọ̀ lórí odi.
20 Där I nu hören basunen ljuda, dit skolen I församla eder till oss; vår Gud skall strida för oss."
Níbikíbi tí ẹ bá ti gbọ́ ohùn ìpè, ẹ da ara pọ̀ mọ́ wa níbẹ̀. Ọlọ́run wa yóò jà fún wa!”
21 Så gjorde ock vi vårt arbete, under det att hälften av folket stod väpnad med sina spjut från morgonrodnadens uppgång, till dess att stjärnorna kommo fram.
Bẹ́ẹ̀ ni àwa ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú àwọn ìdajì ènìyàn tí ó di ọ̀kọ̀ mú, láti òwúrọ̀ kùtùkùtù títí di ìgbà tí ìràwọ̀ yóò fi yọ.
22 Vid samma tid sade jag ock till folket att var och en med sin tjänare skulle stanna över natten inne i Jerusalem, så att vi om natten kunna hava dem till vakt och om dagen till arbete.
Ní ìgbà náà mo tún sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Jẹ́ kí olúkúlùkù ènìyàn àti olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ dúró ní Jerusalẹmu ní òru, nítorí kí wọn le jẹ́ ẹ̀ṣọ́ fún wa ní òru, kí wọn sì le ṣe iṣẹ́ ní ọ̀sán.”
23 Och varken jag eller mina bröder eller mina tjänare eller de som gjorde vakt hos mig lade av kläderna; vapnen höllos av var och en för lika nödvändiga som vatten.
Bẹ́ẹ̀ ni èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi àti àwọn ẹ̀ṣọ́ tí ó wà pẹ̀lú mi kò bọ́ aṣọ wa, olúkúlùkù wa ní ohun ìjà tirẹ̀, kódà nígbà tí wọ́n bá ń lọ pọn omi.

< Nehemja 4 >