< Lukas 16 >
1 Han sade också till sina lärjungar: "En rik man hade en förvaltare som hos honom blev angiven för förskingring av hans ägodelar.
Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pẹ̀lú pé, “Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan wà, tí ó ní ìríjú kan; òun náà ni wọ́n fi sùn ún pé, ó ti ń fi ohun ìní rẹ̀ ṣòfò.
2 Då kallade han honom till sig och sade till honom: 'Vad är det jag hör om dig? Gör räkenskap för din förvaltning; ty du kan icke längre få vara förvaltare.'
Nígbà tí ó sì pè é, ó wí fún un pé, ‘Èéṣe tí èmi fi ń gbọ́ èyí sí ọ? Ṣírò iṣẹ́ ìríjú rẹ; nítorí ìwọ kò lè ṣe ìríjú mi mọ́.’
3 Men förvaltaren sade vid sig själv: 'Vad skall jag göra, då min herre nu tager ifrån mig förvaltningen? Gräva orkar jag icke; att tigga blyges jag för.
“Ìríjú náà sì wí nínú ara rẹ̀ pé, ‘Èwo ni èmi ó ṣe? Nítorí tí olúwa mi gba iṣẹ́ ìríjú lọ́wọ́ mi: èmi kò le ṣiṣẹ́ oko, bẹ́ẹ̀ ni ojú ń tì mí láti ṣagbe.
4 Dock, nu vet jag vad jag skall göra, för att man må upptaga mig i sina hus, när jag bliver avsatt ifrån förvaltningen.'
Mo mọ èyí tí èmi yóò ṣe, nígbà tí a bá mú mi kúrò níbi iṣẹ́ ìríjú, kí àwọn ènìyàn le gbà mí sínú ilé wọn.’
5 Och han kallade till sig sin herres gäldenärer, var och en särskilt. Och han frågade den förste: 'Huru mycket är du skyldig min herre?'
“Ó sì pe àwọn ajigbèsè olúwa rẹ̀ sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí fún èkínní pé, ‘Èló ni ìwọ jẹ olúwa mi?’
6 Han svarade: 'Hundra fat olja.' Då sade han till honom: 'Tag här ditt skuldebrev, och sätt dig nu strax ned och skriv femtio.'
“Ó sì wí pé, ‘Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún òsùwọ̀n òróró.’ “Ó sì wí fún un pé, ‘Mú ìwé rẹ, sì jókòó nísinsin yìí, kí o sì kọ àádọ́ta lé ní irinwó.’
7 Sedan frågade han en annan: 'och du, huru mycket är du skyldig?' Denne svarade: 'hundra tunnor vete.' Då sade han till honom: 'Tag här ditt skuldebrev och skriv åttio.'
“Nígbà náà ni ó sì bi ẹnìkejì pé, ‘Èló ni ìwọ jẹ?’ “Òun sì wí pé, ‘Ẹgbẹ̀rún òsùwọ̀n alikama.’ “Ó sì wí fún un pé, ‘Mú ìwé rẹ, kí o sì kọ ẹgbẹ̀rin.’
8 Och husbonden prisade den orättrådige förvaltaren för det att han hade handlat klokt. Ty denna tidsålders barn skicka sig klokare mot sitt släkte än ljusets barn. (aiōn )
“Olúwa rẹ̀ sì yin aláìṣòótọ́ ìríjú náà, nítorí tí ó fi ọgbọ́n ṣe é, àwọn ọmọ ayé yìí sá à gbọ́n ní ìran wọn ju àwọn ọmọ ìmọ́lẹ̀ lọ. (aiōn )
9 Och jag säger eder: Skaffen eder vänner medelst den orättrådige Mamons goda, för att de, när detta har tagit slut, må taga emot eder i de eviga hyddorna. (aiōnios )
Èmi sì wí fún yín, ẹ fi ọrọ̀ ayé yìí yan ọ̀rẹ́ fún ara yín pé, nígbà tí o ba lọ, kí wọn kí ó le gbà yín sí ibùjókòó wọn títí ayé. (aiōnios )
10 Den som är trogen i det minsta, han är ock trogen i vad mer är, och den som är orättrådig i det minsta, han är ock orättrådig i vad mer är.
“Ẹni tí ó bá ṣe olóòtítọ́ nínú ohun kínkínní, ó ṣe olóòtítọ́ ní púpọ̀ pẹ̀lú: ẹni tí ó bá sì ṣe aláìṣòótọ́ ní ohun kínkínní, ó ṣe aláìṣòótọ́ ní ohun púpọ̀ pẹ̀lú.
11 Haven I nu icke varit trogna, när det gällde den orättrådige Mamons goda, vem vill då betro eder det sannskyldiga goda?
Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin kò bá ti jẹ́ olóòtítọ́ nínú ọrọ̀ ayé yìí, ta ni yóò fi ọ̀rọ̀ tòótọ́ fún yín?
12 Och haven I icke varit trogna, när det gällde vad som tillhörde en annan, vem vill då giva eder det som hör eder till?
Bí ẹ̀yin kò bá sì ti jẹ́ olóòtítọ́ nínú ohun tí í ṣe ti ẹlòmíràn, ta ni yóò fún yín ní ohun tí í ṣe ti ẹ̀yin tìkára yín?
13 Ingen som tjänar kan tjäna två herrar; ty antingen kommer han då att hata den ene och älska den andre, eller kommer han att hålla sig till den förre och förakta den senare. I kunnen icke tjäna både Gud och Mamon."
“Kò sì í ẹnìkan tí ó lè sin ọ̀gá méjì. Òun yóò yà kórìíra ọ̀kan tí yóò fẹ́ràn èkejì, tàbí kí ó fi ara mọ́ ọ̀kan kí ó sì yan èkejì ní ìpọ̀sí. Ẹ̀yin kò lè sin Ọlọ́run àti owó papọ̀.”
14 Allt detta hörde nu fariséerna, som voro penningkära, och de drevo då gäck med honom.
Àwọn Farisi, tí wọ́n ní ojúkòkòrò sì gbọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, wọ́n sì yọ ṣùtì sí i.
15 Men han sade till dem: "I hören till dem som göra sig rättfärdiga inför människorna. Men Gud känner edra hjärtan; ty det som bland människor är högt är en styggelse inför Gud.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ni àwọn tí ń dá àre fún ara yín níwájú ènìyàn; ṣùgbọ́n Ọlọ́run mọ ọkàn yín, nítorí ohun ti a gbéga lójú ènìyàn, ìríra ni níwájú Ọlọ́run.
16 Lagen och profeterna hava haft sin tid intill Johannes. Sedan dess förkunnas evangelium om Guds rike, och var man vill storma ditin.
“Òfin àti àwọn wòlíì ń bẹ títí di ìgbà Johanu, Láti ìgbà náà wá ni a ti ń wàásù ìròyìn ayọ̀ ìjọba Ọlọ́run, olúkúlùkù sì ń fi ipá wọ inú rẹ̀.
17 Men snarare kunna himmel och jord förgås, än en enda prick av lagen kan falla bort.
Ṣùgbọ́n ó rọrùn fún ọ̀run òun ayé láti kọjá lọ, ju kí èyí tí ó kéré jù nínú òfin kí ó yẹ.
18 Var och en som skiljer sig från sin hustru och tager sig en annan hustru, han begår äktenskapsbrott. Och den som tager till hustru en kvinna som är skild från sin man, han begår äktenskapsbrott.
“Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì gbé ẹlòmíràn ní ìyàwó, ó ṣe panṣágà: ẹnikẹ́ni tí ó bá sì gbé, ẹni tí ọkọ rẹ̀ kọ̀sílẹ̀ ní ìyàwó náà, ó ṣe panṣágà.
19 Det var en rik man som klädde sig i purpur och fint linne och levde var dag i glädje och prakt.
“Ǹjẹ́ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan wà, tí ó ń wọ aṣọ elése àlùkò àti aṣọ àlà dáradára, a sì máa jẹ dídùndídùn lójoojúmọ́.
20 Men en fattig man, vid namn Lasarus, låg vid hans port, full av sår,
Alágbe kan sì wà tí à ń pè ní Lasaru, tí wọ́n máa ń gbé wá kalẹ̀ lẹ́bàá ọ̀nà ilé rẹ̀, ó kún fún ooju,
21 och åstundade att få stilla sin hunger med vad som kunde falla ifrån den rike mannens bord. Ja, det gick så långt att hundarna kommo och slickade hans sår.
Òun a sì máa fẹ́ kí a fi èérún tí ó ti orí tábìlì ọlọ́rọ̀ bọ́ sílẹ̀ bọ́ òun, àwọn ajá sì wá, wọ́n sì fá a ní ooju lá.
22 Så hände sig att den fattige dog och blev förd av änglarna till Abrahams sköte. Också den rike dog och blev begraven.
“Ó sì ṣe, alágbe kú, a sì ti ọwọ́ àwọn angẹli gbé e lọ sí oókan àyà Abrahamu: ọlọ́rọ̀ náà sì kú pẹ̀lú, a sì sin ín;
23 När han nu låg i dödsriket och plågades, lyfte han upp sina ögon och fick se Abraham långt borta och Lasarus i hans sköte. (Hadēs )
Ní ipò òkú ni ó gbé ojú rẹ̀ sókè, ó ń bẹ nínú ìjìyà oró, ó sì rí Abrahamu ní òkèrè, àti Lasaru ní oókan àyà rẹ̀. (Hadēs )
24 Då ropade han och sade: 'Fader Abraham, förbarma dig över mig, och sänd Lasarus att doppa det yttersta av sitt finger i vatten och svalka min tunga, ty jag pinas svårt i dessa lågor.'
Ó sì ké, ó wí pé, ‘Baba Abrahamu, ṣàánú fún mi, kí o sì rán Lasaru, kí ó tẹ orí ìka rẹ̀ bọ omi, kí ó sì fi tù mí ní ahọ́n; nítorí èmi ń joró nínú ọ̀wọ́n iná yìí.’
25 Men Abraham svarade: 'Min son kom ihåg att du, medan du levde, fick ut ditt goda och Lasarus däremot vad ont var; nu åter får han här hugnad, under det att du pinas.
“Ṣùgbọ́n Abrahamu wí pé, ‘Ọmọ, rántí pé, nígbà ayé rẹ, ìwọ ti gba ohun rere tìrẹ, àti Lasaru ohun búburú, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ara rọ̀ ọ́, ìwọ sì ń joró.
26 Och till allt detta kommer, att ett stort svalg är satt mellan oss och eder, för att de som vilja begiva sig över härifrån till eder icke skola kunna det, och för att ej heller någon därifrån skall kunna komma över till oss."
Àti pẹ̀lú gbogbo èyí, a gbé ọ̀gbun ńlá kan sí agbede-méjì àwa àti ẹ̀yin, kí àwọn tí ń fẹ́ má ba á le rékọjá láti ìhín lọ sọ́dọ̀ yín, kí ẹnikẹ́ni má sì le ti ọ̀hún rékọjá tọ̀ wá wá.’
27 Då sade han: 'Så beder jag dig då, fader, att du sänder honom till min faders hus,
“Ó sì wí pé, ‘Ǹjẹ́ mo bẹ̀ ọ́, baba, kí ìwọ kí ó rán Lasaru lọ sí ilé baba mi,
28 där jag har fem bröder, och låter honom varna dem, så att icke också de komma till detta pinorum.'
nítorí mo ní arákùnrin márùn-ún; kí ó lè rò fún wọn kí àwọn kí ó má ba á wá sí ibi oró yìí pẹ̀lú.’
29 Men Abraham sade: 'De hava Moses och profeterna; dem må de lyssna till.'
“Abrahamu sì wí fún un pé, ‘Wọ́n ní Mose àti àwọn wòlíì; kí wọn kí ó gbọ́ tiwọn.’
30 Han svarade: 'Nej, fader Abraham; men om någon kommer till dem från de döda, så skola de göra bättring.'
“Ó sì wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, Abrahamu baba; ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá ti inú òkú tọ̀ wọ́n lọ, wọn ó ronúpìwàdà.’
31 Då sade han till honom: 'Lyssna de icke till Moses och profeterna, så skola de icke heller låta övertyga sig, om någon uppstår från de döda.'"
“Ó sì wí fún un pé, ‘Bí wọn kò bá gbọ́ ti Mose àti ti àwọn wòlíì, a kì yóò yí wọn ní ọkàn padà bí ẹnìkan tilẹ̀ ti inú òkú dìde.’”