< Lukas 15 >

1 Och till honom kom allt vad publikaner och syndare hette för att höra honom.
Gbogbo àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sì súnmọ́ ọn láti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.
2 Men fariséerna och de skriftlärde knorrade och sade: "Denne tager emot syndare och äter med dem."
Àti àwọn Farisi àti àwọn akọ̀wé ń kùn pé, “Ọkùnrin yìí ń gba ẹlẹ́ṣẹ̀, ó sì ń bá wọn jẹun.”
3 Då framställde han för dem denna liknelse; han sade:
Ó sì pa òwe yìí fún wọn, pé,
4 "Om ibland eder finnes en man som har hundra får, och han förlorar ett av dem, lämnar han icke då de nittionio i öknen och går och söker efter det förlorade, till dess han finner det?
“Ọkùnrin wo ni nínú yín, tí ó ní ọgọ́rùn-ún àgùntàn, bí ó bá sọ ọ̀kan nù nínú wọn, tí kì yóò fi mọ́kàndínlọ́gọ́rùn-ún yokù sílẹ̀ ni ijù tí kì yóò sì tọ ipasẹ̀ èyí tí ó nù lọ, títí yóò fi rí i?
5 Och när han har funnit det, lägger han det på sina axlar med glädje.
Nígbà tí ó bá sì rí i tán, yóò gbé e lé èjìká rẹ̀ pẹ̀lú ayọ̀.
6 Och när han kommer hem, kallar han tillhopa sina vänner och grannar och säger till dem: 'Glädjens med mig, ty jag har funnit mitt får, som var förlorat.'
Nígbà tí ó bá sì dé ilé yóò pe àwọn ọ̀rẹ́ àti aládùúgbò rẹ̀ jọ, yóò sì wí fún wọn pé, ‘Ẹ bá mí yọ̀; nítorí tí mo ti rí àgùntàn mi tí ó nù.’
7 Jag säger eder att likaså bliver mer glädje i himmelen över en enda syndare som gör bättring, än över nittionio rättfärdiga som ingen bättring behöva.
Mo wí fún yín, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ayọ̀ yóò wà ní ọ̀run lórí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan tí ó ronúpìwàdà, ju lórí olóòtítọ́ mọ́kàndínlọ́gọ́rùn-ún lọ, tí kò nílò ìrònúpìwàdà.
8 Eller om en kvinna har tio silverpenningar, och hon tappar bort en av dem, tänder hon icke då upp ljus och sopar huset och söker noga, till dess hon finner den?
“Tàbí obìnrin wo ni ó ní owó fàdákà mẹ́wàá bí ó bá sọ ọ̀kan nù, tí kì yóò tan fìtílà, kí ó fi gbá ilé, kí ó sì wá a gidigidi títí yóò fi rí i?
9 Och när hon har funnit den, kallar hon tillhopa sina väninnor och grannkvinnor och säger: 'Glädjens med mig, ty jag har funnit den penning som jag hade tappat bort.'
Nígbà tí ó sì rí i, ó pe àwọn ọ̀rẹ́ àti àwọn aládùúgbò rẹ̀ jọ, ó wí pé, ‘Ẹ bá mi yọ̀; nítorí mo rí owó fàdákà tí mo ti sọnù.’
10 Likaså, säger jag eder, bliver glädje hos Guds änglar över en enda syndare som gör bättring.
Mo wí fún yín, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ayọ̀ ń bẹ níwájú àwọn angẹli Ọlọ́run lórí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan tí ó ronúpìwàdà.”
11 Ytterligare sade han: "En man hade två söner.
Ó sì wí pé ọkùnrin kan ní ọmọ méjì:
12 Och den yngre av dem sade till fadern: 'Fader, giv mig den del av förmögenheten, som faller på min lott.' Då skiftade han sina ägodelar mellan dem.
“Èyí àbúrò nínú wọn wí fún baba rẹ̀ pé, ‘Baba, fún mi ní ìní tí ó kàn mí.’ Ó sì pín ohun ìní rẹ̀ fún wọn.
13 Och icke lång tid därefter lade den yngre sonen allt sitt tillhopa och for långt bort till ett främmande land. Där levde han i utsvävningar och förfor så sin förmögenhet.
“Kò sì tó ọjọ́ mélòó kan lẹ́yìn náà, èyí àbúrò kó ohun gbogbo tí ó ní jọ, ó sì mú ọ̀nà àjò rẹ̀ pọ̀n lọ sí ilẹ̀ òkèrè, níbẹ̀ ni ó sì gbé fi ìwà wọ̀bìà ná ohun ìní rẹ̀ ní ìnákúnàá.
14 Men sedan han hade slösat bort allt, kom en svär hungersnöd över det landet, och han begynte lida nöd.
Nígbà tí ó sì ba gbogbo rẹ̀ jẹ́ tan, ìyàn ńlá wá mú ní ilẹ̀ náà; ó sì bẹ̀rẹ̀ sí di aláìní.
15 Då gick han bort och gav sig under en man där i landet, och denne sände honom ut på sina marker för att vakta svin.
Ó sì fi ara rẹ sọfà fun ọ̀kan lára àwọn ọmọ ìlú náà; òun sì rán an lọ sí oko rẹ̀ láti tọ́jú ẹlẹ́dẹ̀.
16 Och han åstundade att få fylla sin buk med de fröskidor som svinen åto; men ingen gav honom något.
Ayọ̀ ni ìbá fi jẹ oúnjẹ tí àwọn ẹlẹ́dẹ̀ ń jẹ ní àjẹyó, ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni kò sì fi fún un.
17 Då kom han till besinning och sade: 'Huru många legodrängar hos min fader hava icke bröd i överflöd, medan jag har förgås av hunger!
“Ṣùgbọ́n nígbà tí ojú rẹ̀ wálẹ̀, ó ní ‘Mélòó mélòó àwọn alágbàṣe baba mí ni ó ní oúnjẹ àjẹyó, àti àjẹtì, èmi sì ń kú fún ebi níhìn-ín.
18 Jag vill stå upp och gå till min fader och säga till honom: Fader, jag har syndat mot himmelen och inför dig;
Èmi ó dìde, èmi ó sì tọ baba mi lọ, èmi ó sì wí fún un pé, Baba, èmí ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ̀run, àti níwájú rẹ,
19 jag är icke mer värd att kallas din son. Låt mig bliva såsom en av dina legodrängar.'
èmi kò sì yẹ, ní ẹni tí à bá pè ní ọmọ rẹ mọ́; fi mí ṣe ọ̀kan nínú àwọn alágbàṣe rẹ.’
20 Så stod han upp och gick till sin fader. Och medan han ännu var långt borta, fick hans fader se honom och ömkade sig över honom och skyndade emot honom och föll honom om halsen och kysste honom innerligt.
Ó sì dìde, ó sì tọ baba rẹ̀ lọ. “Ṣùgbọ́n nígbà tí ó sì wà ní òkèrè, baba rẹ̀ rí i, àánú ṣe é, ó sì súré, ó rọ̀ mọ́ ọn ní ọrùn, ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
21 Men sonen sade till honom: 'Fader, jag har syndat mot himmelen och inför dig; jag är icke mer värd att kallas din son.'
“Ọmọ náà sì wí fún un pé, Baba, èmi ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ̀run, àti níwájú rẹ, èmi kò yẹ ní ẹni tí à bá pè ní ọmọ rẹ mọ́!
22 Då sade fadern till sina tjänare 'Skynden eder att taga fram den yppersta klädnaden och kläden honom i den, och sätten en ring på hans hand och skor på hans fötter.
“Ṣùgbọ́n baba náà wí fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, Ẹ mú ààyò aṣọ wá kánkán, kí ẹ sì fi wọ̀ ọ́; ẹ sì fi òrùka bọ̀ ọ́ lọ́wọ́, àti bàtà sí ẹsẹ̀ rẹ̀:
23 Och hämten den gödda kalven och slakten den, så vilja vi äta och gör oss glada.
Ẹ sì mú ẹgbọrọ màlúù àbọ́pa wá, kí ẹ sì pa á, kí a máa ṣe àríyá.
24 Ty denne min son var död, men har fått liv igen; han var förlorad men är återfunnen.' Och de begynte göra sig glada.
Nítorí ọmọ mi yìí ti kú, ó sì tún yè, ó ti nù, a sì rí i. Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àríyá.
25 Men hans äldre son var ute på marken. När denne nu vände tillbaka och hade kommit nära huset fick han höra spel och dans.
“Ṣùgbọ́n ọmọ rẹ̀ èyí ẹ̀gbọ́n ti wà ní oko: bí ó sì ti ń bọ̀, tí ó súnmọ́ etí ilé, ó gbọ́ orin àti ijó.
26 Då kallade han till sig en av tjänarna och frågade vad detta kunde betyda.
Ó sì pe ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ wọn, ó béèrè, kín ni a mọ nǹkan wọ̀nyí sí?
27 Denne svarade honom: 'Din broder har kommit hem; och då nu din fader har fått honom välbehållen tillbaka, har han låtit slakta den gödda kalven.'
Ó sì wí fún un pé, ‘Arákùnrin rẹ dé, baba rẹ sì pa ẹgbọrọ màlúù àbọ́pa, nítorí tí ó rí i padà ní àlàáfíà àti ní ìlera.’
28 Då blev han vred och ville icke gå in. Hans fader gick då ut och talade vanligt med honom.
“Ó sì bínú, ó sì kọ̀ láti wọlé; baba rẹ̀ sì jáde, ó sì wá í ṣìpẹ̀ fún un.
29 Men han svarade och sade till sin fader: 'Se, i så många år har jag nu tjänat dig, och aldrig har jag överträtt något ditt bud; och lik väl har du åt mig aldrig givit ens en killing, för att jag skulle kunna göra mig glad med mina vänner.
Ó sì dáhùn ó wí fún baba rẹ̀ pé, ‘Wò ó, láti ọdún mélòó wọ̀nyí ni èmi ti ń sìn ọ́, èmi kò sì rú òfin rẹ rí, ìwọ kò sì tí ì fi ọmọ ewúrẹ́ kan fún mi, láti fi bá àwọn ọ̀rẹ́ mi ṣe àríyá.
30 Men när denne din son, som har förtärt dina ägodelar tillsammans med skökor, nu har kommit tillbaka, så har du för honom låtit slakta den gödda kalven.'
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọmọ rẹ yìí dé, ẹni tí ó fi panṣágà fi ọrọ̀ rẹ̀ ṣòfò, ìwọ sì ti pa ẹgbọrọ màlúù àbọ́pa fún un.’
31 Då sade han till honom: 'Min son, du är alltid hos mig, och all mitt är ditt.
“Ó sì wí fún un pé, ‘Ọmọ, nígbà gbogbo ni ìwọ ń bẹ lọ́dọ̀ mi, ohun gbogbo tí mo sì ní, tìrẹ ni.
32 Men nu måste vi fröjda oss och vara glada; ty denne din broder var död, men har fått liv igen, han var förlorad, men är återfunnen.'"
Ó yẹ kí a ṣe àríyá kí a sì yọ̀: nítorí arákùnrin rẹ yìí ti kú, ó sì tún yè; ó ti nù, a sì rí i.’”

< Lukas 15 >