< Jeremia 51 >

1 Så säger HERREN: Se, jag skall uppväcka mot Babel och mot Leb-Kamais inbyggare en fördärvares ande.
Ohùn ti Olúwa wí nìyìí: “Wò ó èmi yóò ru afẹ́fẹ́ apanirun sókè sí Babeli àti àwọn ènìyàn Lebikamai,
2 Och jag skall sända främlingar mot Babel, och de skola kasta det med kastskovlar och ödelägga dess land. Ja, från alla sidor skola de komma emot det på olyckans dag.
Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli láti fẹ́ ẹ, tí yóò sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di òfo; wọn yóò takò ó ní gbogbo ọ̀nà ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.
3 Skyttar skola spänna sina bågar mot dem som där spänna båge, och mot dem som där yvas i pansar. Skonen icke dess unga män, given hela dess här till spillo.
Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀, jáde tàbí kí ó di ìhámọ́ra rẹ̀. Má ṣe dá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sí; pátápátá ni kí o pa àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
4 Dödsslagna män skola då falla i kaldéernas land och genomborrade man på dess gator.
Gbogbo wọn ni yóò ṣubú ní Babeli, tí wọn yóò sì fi ara pa yánnayànna ní òpópónà.
5 Ty Israel och Juda äro icke änkor som hava blivit övergivna av sin Gud, av HERREN Sebaot, därför att deras land var fullt av skuld mot Israels Helige.
Nítorí pé Juda àti Israẹli ni Ọlọ́run wọn tí í ṣe Olúwa àwọn ọmọ-ogun, kò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọn kún fún kìkì ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Israẹli.
6 Flyn ut ur Babel; må var och en söka rädda sitt liv, så att I icke förgås genom dess missgärning. Ty detta är för HERREN en hämndens tid, då han vill vedergälla det vad det har gjort.
“Sá kúrò ní Babeli! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Àsìkò àti gbẹ̀san Olúwa ni èyí; yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.
7 Babel var i HERRENS hand en gyllene kalk som gjorde hela jorden drucken. Av dess vin drucko folken, och så blevo folken såsom vanvettiga.
Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa; ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí. Gbogbo orílẹ̀-èdè mu ọtí rẹ̀, wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.
8 Men plötsligt är nu Babel fallet och krossat. Jämren eder över henne, hämten balsam för hennes plåga, om hon till äventyrs kan helas.
Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́. Ẹ hu fun un! Ẹ mú ìkunra fún ìrora rẹ, bóyá yóò le wo ọ́ sàn.
9 "Ja, vi hava sökt hela Babel, men hon har icke kunnat helas; låt oss lämna henne och gå var och en till sitt land. Ty hennes straffdom räcker upp till himmelen och når allt upp till skyarna.
“‘À bá ti wo Babeli sàn, ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀, kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè, ó ga àní títí dé òfúrufú.’
10 HERREN har låtit vår rätt gå fram; kom, låt oss förtälja i Sion HERRENS, vår Guds, verk."
“‘Olúwa ti dá wa láre, wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Sioni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa ti ṣe.’
11 Vässen pilarna, fatten sköldarna. HERREN har uppväckt de mediska konungarnas ande; ty hans tankar äro vända mot Babel till att fördärva det. Ja, HERRENS hämnd är här, hämnden för hans tempel.
“Ṣe ọfà rẹ ní mímú, mú àpáta! Olúwa ti ru ọba Media sókè, nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Babeli run. Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
12 Resen upp ett baner mot Babels murar, hållen sträng vakt, ställen ut väktare, läggen bakhåll; ty HERREN har fattat sitt beslut, och han gör vad han har talat mot Babels invånare.
Gbé àsíá sókè sí odi Babeli! Ẹ ṣe àwọn ọmọ-ogun gírí, ẹ pín àwọn olùṣọ́ káàkiri, ẹ ṣètò àwọn tí yóò sá pamọ́ Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde, òfin rẹ̀ sí àwọn ará Babeli.
13 Du som bor vid stora vatten och är så rik på skatter, din ände har nu kommit, din vinningslystnads mått är fyllt.
Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀, tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé, àní àsìkò láti ké ọ kúrò!
14 HERREN Sebaot har svurit vid sig själv: sannerligen, om jag än har uppfyllt dig med människor så talrika som gräshoppor, så skall man dock få upphäva skördeskri över dig.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀, Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú, wọn yóò yọ ayọ̀, ìṣẹ́gun lórí rẹ.
15 Han har gjort jorden genom sin kraft, han har berett jordens krets genom sin vishet, och genom sitt förstånd har han utspänt himmelen.
“Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀, o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.
16 När han vill låta höra sin röst, då brusa himmelens vatten, då låter han regnskyar stiga upp från jordens ända; han låter ljungeldar komma med regn och för vinden ut ur dess förvaringsrum.
Nígbà tí ará omi ọ̀run hó ó mú kí òfúrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.
17 Såsom dårar stå då alla människor där och begripa intet; guldsmederna komma då alla på skam med sina beläten, ty deras gjutna beläten äro lögn, och ingen ande är i dem.
“Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ tí kò sì ní ìmọ̀, olúkúlùkù alágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀. Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn; wọn kò ní èémí nínú.
18 De äro fåfänglighet, en tillverkning att le åt; när hemsökelsen kommer över dem, måste de förgås.
Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà, nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn ó ṣègbé.
19 Men sådan är icke han som är Jakobs del; nej, det är han som har skapat allt, och särskilt sin arvedels stam. HERREN Sebaot är hans namn.
Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí; nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo, àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
20 Du var min hammare, mitt stridsvapen; med dig krossade jag folk, med dig fördärvade jag riken.
“Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi, ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀-èdè túútúú, èmi ó bà àwọn ilé ọba jẹ́.
21 Med dig krossade jag häst och ryttare; med dig krossade jag vagn och körsven.
Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀; èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lú èmi ó pa awakọ̀,
22 Med dig krossade jag man och kvinna; med dig krossade jag gammal och ung; med dig krossade jag yngling och jungfru.
pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin, pẹ̀lú rẹ, mo pa àgbàlagbà àti ọmọdé, pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.
23 Med dig krossade jag herden och hans hjord; med dig krossade jag åkermannen och hans oxpar; med dig krossade jag ståthållare och landshövding.
Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn, àti agbo àgùntàn rẹ̀ túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ àgbẹ̀ àti àjàgà màlúù túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ túútúú.
24 Men nu skall jag vedergälla Babel och alla Kaldeens inbyggare allt det onda som de hava förövat mot Sion, inför edra ögon, säger HERREN.
“Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,” ni Olúwa wí.
25 Se, jag skall vända mig mot dig, du fördärvets berg, säger HERREN, du som fördärvade hela jorden; och jag skall uträcka min hand mot dig och vältra dig ned från klipporna och göra dig till ett förbränt berg,
“Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun ìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,” ni Olúwa wí. “Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ, èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta, Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.
26 så att man icke av dig skall kunna taga vare sig hörnsten eller grundsten, utan du skall bliva en ödemark för evärdlig tid, säger HERREN.
A kò ní mú òkúta kankan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbí fún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò di ahoro títí ayé,” ní Olúwa wí.
27 Resen upp ett baner på jorden, stöten i basun ibland folken, invigen folk till strid mot det, båden upp mot det riken, både Ararats, Minnis och Askenas', tillsätten hövdingar mot det, dragen ditupp med hästar som likna borstiga gräshoppor.
“Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà! Fọn ìpè láàrín àwọn orílẹ̀-èdè! Sọ àwọn orílẹ̀-èdè di mímọ́ sórí rẹ̀, pe àwọn ìjọba yìí láti dojúkọ ọ́: Ararati, Minini àti Aṣkenasi. Yan olùdarí ogun láti kọlù ú, rán àwọn ẹṣin sí i bí ọ̀pọ̀ eṣú.
28 Invigen folk till strid mot det: Mediens konungar, dess ståthållare och alla dess landshövdingar, och hela det land som lyder under deras välde.
Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀, àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ ọba lé lórí.
29 Då darrar jorden och bävar, ty nu fullbordas vad HERREN tänkte mot Babel: att han ville göra Babels land till en ödemark, där ingen skulle bo.
Ilẹ̀ wárìrì síyìn-ín sọ́hùn-ún, nítorí pé ète Olúwa, sí Babeli dúró, láti ba ilẹ̀ Babeli jẹ́ lọ́nà tí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.
30 Babels hjältar upphöra att strida, de sitta stilla i sina fästen; deras styrka har försvunnit, de hava blivit såsom kvinnor. Man har tänt eld på dess boningar; dess bommar äro sönderbrutna.
Gbogbo àwọn jagunjagun Babeli tó dáwọ́ ìjà dúró sínú àgọ́ wọn. Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin. Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun, gbogbo irin ẹnu-ọ̀nà wọn ti di fífọ́.
31 Löparna löpa mot varandra, den ene budbäraren korsar den andres väg, med bud till konungen i Babel om att hela hans stad år intagen,
Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn láti sọ fún ọba Babeli pé gbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.
32 att vadställena äro besatta och dammarna förbrända i eld och krigsmännen gripna av skräck.
Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́ ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”
33 Ty så säger HERREN Sebaot, Israels Gud: Dottern Babel är såsom en tröskplats, när man just har trampat till den; ännu en liten tid, och skördetiden kommer för henne.
Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí: “Ọmọbìnrin Babeli dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”
34 Uppätit mig och förgjort mig har han, Nebukadressar, konungen i Babel. Han har gjort mig till ett tomt kärl; lik en drake har han uppslukat mig, han har fyllt sin buk med mina läckerheter och drivit mig bort.
“Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run, ó ti mú kí ìdààmú bá wa, ó ti sọ wá di àgbá òfìfo. Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì. Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀, lẹ́yìn náà ni ó pọ̀ wá jáde.
35 "Den orätt mig har skett och det som har vederfarits mitt kött, det komme över Babel", så må Sions invånare säga; och "Mitt blod komme över Kaldeens inbyggare", så må Jerusalem säga.
Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,” èyí tí àwọn ibùgbé Sioni wí. “Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogbo àwọn tí ń gbé Babeli,” ni Jerusalẹmu wí.
36 Därför säger HERREN så: Se, jag skall utföra din sak och utkräva din hämnd. Jag skall låta dess hav sina bort och dess brunn uttorka,
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lórí ohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san, èmi yóò mú kí omi Òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.
37 och Babel skall bliva en stenhop, en boning för schakaler, ett föremål för häpnad och begabberi, så att ingen kan bo där.
Babeli yóò parun pátápátá, yóò sì di ihò àwọn akátá, ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.
38 Alla ryta de nu såsom lejon; de skria såsom lejonungar.
Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù bí ọmọ kìnnìún.
39 Men när de äro som mest upptända, skall jag tillreda åt dem ett gästabud; jag skall göra dem druckna, så att de jubla. Så skola de somna in i en evig sömn, ur vilken de aldrig skola uppvakna, säger HERREN.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè, èmi yóò ṣe àsè fún wọn, èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó tí wọn yóò máa kọ fun ẹ̀rín, lẹ́yìn náà, wọn yóò sun oorun, wọn kì yóò jí,” ni Olúwa wí.
40 Jag skall föra dem ned till att slaktas såsom lamm, likasom vädurar och bockar.
“Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.
41 Huru har icke Sesak blivit intaget och hon som var hela jordens berömmelse erövrad! Huru har icke Babel blivit ett föremål för häpnad bland folken!
“Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé. Irú ìpayà wo ni yóò bá Babeli láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!
42 Havet steg upp över Babel; av dess brusande böljor blev det övertäckt.
Òkun yóò ru borí Babeli, gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Babeli.
43 Så blev av dess städer en ödemark, ett torrt land och en hedmark, ett land där ingen bor, och där intet människobarn går fram.
Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro, ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.
44 Ja, jag skall hemsöka Bel i Babel och taga ut ur hans gap vad han har slukat; och folken skola icke mer strömma till honom. Babels murar skola ock falla.
Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli àti pé èmi yóò jẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì. Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò jùmọ̀ sàn lọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ mọ́. Ní òótọ́ odi Babeli yóò sì wó.
45 Dragen ut därifrån, mitt folk; må var och en söka rädda sitt liv undan HERRENS vredes glöd.
“Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn mi! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Sá fún ìbínú ńlá Olúwa.
46 Varen icke försagda i edra hjärtan, och frukten icke för de olycksbud som höras i landet, om än ett olycksbud kommer det ena året och sedan nästa år ett nytt olycksbud, och om än våld råder på jorden och härskare står mot härskare.
Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú tàbí kí o bẹ̀rù nígbà tí a bá gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa; àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí, òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipá ní ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.
47 Se, därför skola dagar komma, då jag skall hemsöka Babels beläten, och då hela dess land skall stå med skam och alla skola falla slagna därinne.
Nítorí ìgbà náà yóò wá dandan nígbà tí èmi yóò fi ìyà jẹ àwọn òrìṣà Babeli; gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó dójútì gbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárín rẹ̀.
48 Då skola himmel och jord jubla över Babel, de och allt vad i dem är, då nu förhärjarna komma över det norrifrån, säger HERREN.
Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn, yóò sì kọrin lórí Babeli: nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,” ni Olúwa wí.
49 Ja, I slagna av Israel, också Babel måste falla, likasom för Babel människor föllo slagna över hela jorden.
“Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli, gẹ́gẹ́ bí àwọn ti a pa ní gbogbo ayé nítorí Babeli.
50 I som haven lyckats rädda eder undan svärdet, gån åstad, stannen icke. Kommen ihåg HERREN, i fjärran land, och tänken på Jerusalem.
Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró. Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè, ẹ sì jẹ́ kí Jerusalẹmu wá sí ọkàn yín.”
51 Vi stå här med skam, ja vi måste höra smädelse; blygsel höljer vårt ansikte, ty främlingar hava kastat sig över vad heligt som fanns i HERRENS hus.
“Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn: ìtìjú ti bò wá lójú nítorí àwọn àjèjì wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”
52 Se, därför skola dagar komma, säger HERREN, då jag skall hemsöka dess beläten, och då slagna män skola jämra sig i hela dess land.
“Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fínfín rẹ̀, àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa kérora já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀.
53 Om Babel än stege upp till himmelen, och om det gjorde sin befästning än så hög och stark så skulle dock förhärjare ifrån mig komma över det, säger HERREN.
Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run, bí ó sì ṣe ìlú olódi ní òkè agbára rẹ, síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,” ní Olúwa wí.
54 Klagorop höras från Babel, och stort brak från kaldéernas land.
“Ìró igbe láti Babeli, àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kaldea!
55 Ty HERREN förhärjar Babel och gör slut på det stora larmet därinne. Och deras böljor brusa såsom stora vatten; dånet av dem ljuder högt.
Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ, ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀; àwọn ọ̀tá wọn sì ń hó bi omi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.
56 Ty över det, över Babel, kommer en förhärjare, och dess hjältar tagas till fånga, deras bågar brytas sönder. Se, HERREN är en vedergällningens Gud; han lönar till fullo.
Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀, àní sórí Babeli; a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn: nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa, yóò san án nítòótọ́.
57 Ja, jag skall göra dess furstar druckna, så ock dess visa män, dess ståthållare, dess landshövdingar och dess hjältar, och de skola somna in i en evig sömn, ur vilken de aldrig skola uppvakna, säger konungen, han vilkens namn är HERREN Sebaot.
Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí, àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀ àti àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀, wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,” ní ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
58 Så säger HERREN Sebaot: Det vida Babels murar skola i grund omstörtas, och dess höga portar skola brännas upp i eld. Så möda sig folken för det som skall bliva till intet, och folkslagen arbeta sig trötta för det som skall förbrännas av elden.
Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Odi Babeli gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátápátá, ẹnu-bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun: tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán, àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná, tí àárẹ̀ sì mú wọn.”
59 Detta är vad profeten Jeremia bjöd Seraja, son till Neria, son till Mahaseja, när denne begav sig till Babel med Sidkia, Juda konung, i hans fjärde regeringsår. Seraja var nämligen den som hade bestyret med lägerplatserna.
Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó.
60 Och Jeremia tecknade i en och samma bok upp alla de olyckor som skulle komma över Babel, allt detta som nu är skrivet om Babel.
Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli.
61 Jeremia sade till Seraja: "När du kommer till Babel, så se till, att du läser upp allt detta.
Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “Nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
62 Och du skall säga: 'HERRE, du har själv talat om denna ort att du vill fördärva den, så att ingen mer skall bo där, varken någon människa eller något djur; ty den skall vara en ödemark för evärdlig tid.'
Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’
63 Och när du har läst upp boken till slut, så bind en sten vid den och kasta den ut i Frat,
Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate.
64 och säg: 'På detta sätt skall Babel sjunka ned och icke mer komma upp, för den olyckas skull som jag skall låta komma över det, mitt under deras ävlan.'" Så långt Jeremias ord.
Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’” Títí dé ìhín ni ọ̀rọ̀ Jeremiah.

< Jeremia 51 >