< Jeremia 11 >

1 Detta är det ord som kom till Jeremia från HERREN; han sade:
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá:
2 "Hören detta förbunds ord, och talen till Juda män och till Jerusalems invånare;
“Fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí o sì sọ wọ́n fún àwọn ènìyàn Juda, àti gbogbo àwọn tó ń gbé ni Jerusalẹmu.
3 säg till dem: Så säger HERREN, Israels Gud: Förbannad vare den man som icke hör detta förbunds ord,
Sọ fún wọn wí pé èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ègbé ni fún ẹni náà tí kò pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí mọ́.
4 det som jag bjöd edra fader på den tid då jag förde dem ut ur Egyptens land, den smältugnen, i det jag sade: Hören min röst och gören detta, alldeles såsom jag bjuder eder, så skolen I vara mitt folk, och jag skall vara eder Gud,
Àwọn májẹ̀mú tí mo pàṣẹ fún àwọn baba ńlá yín, nígbà tí mo mú wọn jáde láti Ejibiti, láti inú iná alágbẹ̀dẹ wá.’ Mo wí pé, ‘Ẹ gbọ́ tèmi, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín. Ẹ̀yin ó sì jẹ́ ènìyàn mi, Èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
5 på det att jag må hålla den ed som jag har svurit edra fäder: att giva dem ett land som flyter av mjölk och honung, såsom ock nu har skett." Och jag svarade och sade: "Ja, amen, HERRE."
Nígbà náà ni Èmi ó sì mú ìlérí tí mo búra fún àwọn baba ńlá yín ṣẹ; láti fún wọn ní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin,’ ilẹ̀ tí ẹ ní lónìí.” Mo sì dáhùn wí pé, “Àmín, Olúwa.”
6 Och HERREN sade till mig: Predika allt detta i Juda städer och på gatorna i Jerusalem och säg: Hören detta förbunds ord och gören efter dem.
Olúwa wí fún mi pé, “Kéde gbogbo ọ̀rọ̀ yìí ní àwọn ìlú Juda àti ní gbogbo òpópónà ìgboro Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí ẹ sì se wọn.
7 Ty både på den dag då jag förde edra fäder ut ur Egyptens land och sedan ända till denna dag har jag varnat dem, ja, titt och ofta har jag varnat dem och sagt: "Hören min röst";
Láti ìgbà tí mo ti mú àwọn baba yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá títí di òní, mo kìlọ̀ fún wọn lọ́pọ̀ ìgbà wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi.”
8 men de ville icke höra eller böja sitt öra därtill, utan vandrade var och en i sitt onda hjärtas hårdhet. Därför lät jag ock komma över dem allt vad jag hade sagt i det förbund som jag bjöd dem hålla, men som de dock icke höllo.
Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kọbi ara sí i dípò èyí wọ́n tẹ̀síwájú ni agídí ọkàn wọn. Mo sì mú gbogbo ègún inú májẹ̀mú tí mo ti ṣèlérí, tí mo sì ti pàṣẹ fún wọn láti tẹ̀lé, tí wọn kò tẹ̀lé wa sórí wọn.’”
9 Och HERREN sade till mig: Jag vet huru Juda män och Jerusalems invånare hava sammansvurit sig.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Ọ̀tẹ̀ kan wà láàrín àwọn ará Juda àti àwọn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.
10 De hava vänt tillbaka till sina förfäders missgärningar, deras som icke ville höra mina ord. Själva hava de så följt efter andra gudar och tjänat dem. Ja, Israels hus och Juda hus hava brutit det förbund som jag slöt med deras fäder.
Wọ́n ti padà sí ìdí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn tí wọn kọ̀ láti tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n ti tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti sìn wọ́n. Ilé Israẹli àti ilé Juda ti ba májẹ̀mú tí mo dá pẹ̀lú àwọn baba ńlá wọn jẹ́.
11 Därför säger HERREN så: Se, jag skall låta en olycka komma över dem, som de icke skola kunna undkomma; och när de då ropa till mig, skall jag icke höra dem.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi yóò mu ibi tí wọn kò ní le è yẹ̀ wá sórí wọn, bí wọ́n tilẹ̀ ké pè mí èmi kì yóò fetí sí igbe wọn.
12 Och om så Juda städer och Jerusalems invånare gå bort och ropa till de gudar åt vilka de pläga tända offereld, så skola dessa alls icke kunna frälsa dem i deras olyckas tid.
Àwọn ìlú Juda àti àwọn ará Jerusalẹmu yóò lọ kégbe sí àwọn òrìṣà tí wọ́n ń sun tùràrí sí; àwọn òrìṣà náà kò ní ràn wọ́n lọ́wọ́ ní ìgbà tí ìpọ́njú náà bá dé.
13 Ty så många som dina städer äro, så många hava dina gudar blivit, du Juda; och så många som gatorna äro i Jerusalem, så många altaren haven I satt upp åt skändlighetsguden: altaren till att tända offereld åt Baal.
Ìwọ Juda, bí iye àwọn ìlú rẹ, bẹ́ẹ̀ iye àwọn òrìṣà rẹ; bẹ́ẹ̀ ni iye pẹpẹ tí ẹ̀yin ti tẹ́ fún sísun tùràrí Baali ohun ìtìjú n nì ṣe pọ̀ bí iye òpópónà tí ó wà ní Jerusalẹmu.’
14 Så må du nu icke bedja för detta folk eller frambära någon klagan och förbön för dem; ty jag vill icke höra, när de ropa till mig för sin olyckas skull.
“Má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn, nítorí pé, Èmi kì yóò dẹtí sí wọn nígbà tí wọ́n bá ké pè mí ní ìgbà ìpọ́njú.
15 Vad har min älskade att göra i mitt hus, då hon, ja, hela hopen, övar sådan skändlighet? Kan heligt kött komma såsom offer från dig? När du får bedriva din ondska, då fröjdar du dig ju.
“Kí ni olùfẹ́ mi ní í ṣe ní tẹmpili mi, bí òun àti àwọn mìíràn ṣe ń hu oríṣìíríṣìí ìwà àrékérekè? Ǹjẹ́ ẹran tí a yà sọ́tọ̀ lè mú ìjìyà kúrò lórí rẹ̀? Nígbà tí ó bá ń ṣe iṣẹ́ búburú rẹ̀, nígbà náà jẹ́ kí inú rẹ̀ kí ó dùn.”
16 "Ett grönskande olivträd, prytt med sköna frukter", så kallade HERREN dig; men nu har han med stort och väldigt dån tänt upp en eld omkring det trädet, så att dess grenar fördärvas.
Olúwa pè ọ́ ní igi olifi pẹ̀lú èso rẹ tí ó dára ní ojú. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìjì líle ọ̀wọ́-iná ni yóò sun ún tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ yóò sì di gígé kúrò.
17 Ja, HERREN Sebaot, han som planterade dig, har beslutit olycka över dig, för den ondskas skull som Israels och Juda hus hava bedrivit till att förtörna mig, i det att de hava tänt offereld åt Baal.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó dá ọ ti kéde ibi sí ọ, nítorí ilé Israẹli àti Juda ti ṣe ohun ibi, wọ́n sì ti mú inú bí mi, wọ́n ti ru ìbínú mi sókè nípa sísun tùràrí si Baali.
18 HERREN kungjorde det för mig, så att jag fick veta det; ja, du lät mig se vad de förehade.
Nítorí Olúwa fi ọ̀tẹ̀ wọn hàn mí mo mọ̀ ọ́n; nítorí ní àsìkò náà ó fi ohun tí wọ́n ń ṣe hàn mí.
19 Själv var jag såsom ett menlöst lamm som föres bort till att slaktas; jag visste ej att de förehade anslag mot mig: "Låt oss fördärva trädet med dess frukt, låt oss utrota honom ur de levandes land, så att man icke mer kommer ihåg hans namn."
Mo ti dàbí ọ̀dọ́-àgùntàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí a mú lọ fún pípa; n kò mọ̀ pé wọ́n ti gbìmọ̀ búburú sí mi wí pé: “Jẹ́ kí a run igi àti èso rẹ̀; jẹ́ kí a gé e kúrò ní orí ilẹ̀ alààyè, kí a má lè rántí orúkọ rẹ̀ mọ́.”
20 Men HERREN Sebaot är en rättfärdig domare, som prövar njurar och hjärta. Så låt mig då få se din hämnd på dem, ty för dig har jag lagt fram min sak.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, tí ó ń ṣe ìdájọ́ òdodo, tí ó ń ṣe àyẹ̀wò ẹ̀mí àti ọkàn, jẹ́ kí n rí ẹ̀san rẹ lórí wọn; nítorí ìwọ ni mo fi ọ̀rọ̀ mi lé lọ́wọ́.
21 Därför säger HERREN så om Anatots män, dem som stå efter ditt liv och säga: "Profetera icke i HERRENS namn, om du icke vill dö för vår hand"
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ọlọ́run sọ nípa àwọn arákùnrin Anatoti tí wọ́n ń lépa ẹ̀mí rẹ̀, tí wọ́n ń wí pé, ‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìwọ ó kú láti ọwọ́ wa.’
22 ja, därför säger HERREN Sebaot så: Se, jag skall hemsöka dem; deras unga män skola dö genom svärd, deras söner och döttrar skola dö genom hunger.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ pé, ‘Èmi yóò fì ìyà jẹ wọ́n, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn yóò tipasẹ̀ idà kú, ìyàn yóò pa àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
23 Och intet skall bliva kvar av dem; ty jag skall låta olycka drabba Anatots män, när deras hemsökelses år kommer.
Kò ní ṣẹ́kù ohunkóhun sílẹ̀ fún wọn nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí àwọn ènìyàn Anatoti ní ọdún ìbẹ̀wò wọn.’”

< Jeremia 11 >