< Jakobsbrevet 5 >

1 Hören nu, I rike: Gråten och jämren eder över det elände som skall komma över eder.
Ẹ wá nísinsin yìí, ẹ̀yin ọlọ́rọ̀, ẹ máa sọkún kí ẹ sì máa pohùnréré ẹkún nítorí òsì tí ó ń bọ̀ wá ta yín.
2 Eder rikedom multnar bort, och edra kläder frätas sönder av mal;
Ọrọ̀ yín díbàjẹ́, kòkòrò sì ti jẹ aṣọ yín.
3 edert guld och silver förrostar, och rosten därpå skall vara eder till ett vittnesbörd och skall såsom en eld förtära edert kött. I haven samlat eder skatter i de yttersta dagarna.
Wúrà òun fàdákà yín díbàjẹ́; ìbàjẹ́ wọn ni yóò sì ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, tí yóò sì jẹ ẹran-ara yín bí iná. Ẹ̀yin tí kó ìṣúra jọ de ọjọ́ ìkẹyìn.
4 Se, den lön I haven förhållit arbetarna som hava avbärgat edra åkrar, den ropar över eder, och skördemännens rop hava kommit fram till Herren Sebaots öron.
Kíyèsi i, ọ̀yà àwọn alágbàṣe tí wọ́n ti ṣe ìkórè oko yín, èyí tí ẹ kò san, ń ké rara; àti igbe àwọn tí ó ṣe ìkórè sì ti wọ inú etí Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
5 I haven levat i kräslighet på jorden och gjort eder goda dagar; I haven gött eder av hjärtans lust "på eder slaktedag".
Ẹ̀yin ti jẹ adùn ní ayé, ẹ̀yin sì ti fi ara yín fún ayé jíjẹ; ẹ̀yin ti mú ara yín sanra de ọjọ́ pípa.
6 I haven dömt den rättfärdige skyldig och haven dräpt honom; han står eder icke emot.
Ẹ̀yin ti dá ẹ̀bi fún olódodo, ẹ sì ti pa á; ẹni tí kò kọ ojú ìjà sí yín.
7 Så biden nu tåligt, mina bröder, intill Herrens tillkommelse. I sen huru åkermannen väntar på jordens dyrbara frukt och tåligt bidar efter den, till dess att den har fått höstregn och vårregn.
Nítorí náà ará, ẹ mú sùúrù títí di ìpadà wá Olúwa. Kíyèsi i, àgbẹ̀ a máa retí èso iyebíye ti ilẹ̀, a sì mú sùúrù dè é, títí di ìgbà àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò.
8 Ja, biden ock I tåligt, och styrken edra hjärtan; ty Herrens tillkommelse är nära.
Ẹ̀yin pẹ̀lú, ẹ mú sùúrù; ẹ fi ọkàn yín balẹ̀, nítorí ìpadà wá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀.
9 Sucken icke mot varandra, mina bröder, på det att I icke mån bliva dömda. Se, domaren står för dörren.
Ẹ má ṣe kùn sí ọmọnìkejì yín, ará, kí a má ba à dá a yín lẹ́bi: kíyèsi i, onídàájọ́ dúró ní ẹnu ìlẹ̀kùn.
10 Mina bröder, tagen profeterna, som talade i Herrens namn, till edert föredöme i att uthärda lidande och visa tålamod.
Ará mi, ẹ fi àwọn wòlíì tí ó ti ń sọ̀rọ̀ ní orúkọ Olúwa ṣe àpẹẹrẹ ìyà jíjẹ, àti sùúrù.
11 Vi prisa ju dem saliga, som hava varit ståndaktiga. Om Jobs ståndaktighet haven I hört, och I haven sett vilken utgång Herren beredde; ty Herren är nåderik och barmhärtig.
Sá à wò ó, àwa a máa ka àwọn tí ó fi ara dà ìyà sí ẹni ìbùkún. Ẹ̀yin ti gbọ́ ti sùúrù Jobu, ẹ̀yin sì rí ìgbẹ̀yìn tí Olúwa ṣe; pé Olúwa kún fún ìyọ́nú, ó sì ní àánú.
12 Men framför allt, mina bröder, svärjen icke, varken vid himmelen eller vid jorden, ej heller vid något annat, utan låten edert "ja" vara "ja", och edert "nej" vara "nej", så att I icke hemfallen under dom.
Ṣùgbọ́n ju ohun gbogbo lọ, ará mi, ẹ má ṣe ìbúra, ìbá à ṣe fífi ọ̀run búra, tàbí ilẹ̀, tàbí ìbúra-kíbúra mìíràn. Ṣùgbọ́n jẹ́ kí “Bẹ́ẹ̀ ni” yín jẹ́ bẹ́ẹ̀ ni; àti “Bẹ́ẹ̀ kọ́” yín jẹ́ bẹ́ẹ̀ kọ́; kí ẹ má ba à bọ́ sínú ẹ̀bi.
13 Får någon bland eder utstå lidande, så må han bedja.
Inú ẹnikẹ́ni ha bàjẹ́ nínú yín bí? Jẹ́ kí ó gbàdúrà. Inú ẹnikẹ́ni ha dùn? Jẹ́ kí ó kọrin mímọ́.
14 Är någon glad, så må han sjunga lovsånger. Är någon bland eder sjuk, må han då kalla till sig församlingens äldste; och dessa må bedja över honom och i Herrens namn smörja honom med olja.
Ẹnikẹ́ni ha ṣe àìsàn nínú yín bí? Kí ó pe àwọn àgbà ìjọ, kí wọ́n sì gbàdúrà sórí rẹ̀, kí wọn fi òróró kùn ún ní orúkọ Olúwa.
15 Och trons bön skall hjälpa den sjuke, och Herren skall låta honom stå upp igen; och om han har begått synder, skall detta bliva honom förlåtet.
Àdúrà ìgbàgbọ́ yóò sì gba aláìsàn náà là, Olúwa yóò sì gbé e dìde; bí ó bá sì ṣe pé ó ti dẹ́ṣẹ̀, a ó dáríjì í.
16 Bekännen alltså edra synder för varandra, och bedjen för varandra, på det att I mån bliva botade. Mycket förmår en rättfärdig mans bön, när den bedes med kraft.
Ẹ jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ yín fún ara yín, kí ẹ sì máa gbàdúrà fún ara yín, kí a lè mú yín láradá. Iṣẹ́ tí àdúrà olódodo ń ṣe ní agbára púpọ̀.
17 Elias var en människa, med samma natur som vi. Han bad en bön att det icke skulle regna, och det regnade icke på jorden under tre år och sex månader;
Ènìyàn bí àwa ni Elijah, ó gbàdúrà gidigidi pé kí òjò kí ó má ṣe rọ̀, òjò kò sì rọ̀ sórí ilẹ̀ fún ọdún mẹ́ta òun oṣù mẹ́fà.
18 åter bad han, och då gav himmelen regn, och jorden bar sin frukt.
Ó sì tún gbàdúrà, ọ̀run sì tún rọ̀jò, ilẹ̀ sì so èso rẹ̀ jáde.
19 Mina bröder, om någon bland eder har farit vilse från sanningen, och någon omvänder honom,
Ará, bí ẹnikẹ́ni nínú yín bá ṣìnà kúrò nínú òtítọ́, tí ẹni kan sì yí i padà;
20 så mån I veta att den som omvänder en syndare från hans villoväg, han frälsar hans själ från döden och överskyler en myckenhet av synder.
jẹ́ kí ó mọ̀ pé, ẹni tí ó bá yí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan padà kúrò nínú ìṣìnà rẹ̀, yóò gba ọkàn kan là kúrò lọ́wọ́ ikú, yóò sì bo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́lẹ̀.

< Jakobsbrevet 5 >