< Jesaja 37 >

1 Då nu konung Hiskia hörde detta, rev han sönder sina kläder och höljde sig i sorgdräkt och gick in i HERRENS hus.
Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara rẹ̀, ó sì wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
2 Och överhovmästaren Eljakim och sekreteraren Sebna och de äldste bland prästerna sände han, höljda i sorgdräkt, till profeten Jesaja, Amos' son.
Òun sì rán Eliakimu alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti aṣíwájú àwọn àlùfáà, gbogbo wọn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
3 Och de sade till denne: "Så säger Hiskia: En nödens, tuktans och smälekens dag är denne dag, ty fostren hava väl kommit fram till födseln, men kraft att föda finnes icke.
Wọ́n sọ fún un pé, “Báyìí ni Hesekiah wí, ọjọ́ òní jẹ́ ọjọ́ ìbànújẹ́, ìbáwí àti ẹ̀gàn gẹ́gẹ́ bí ìgbà ìbí àwọn ọmọdé tí kò sì ṣí agbára láti bí wọn.
4 Kanhända skall HERREN, din Gud, höra Rab-Sakes ord, med vilka hans herre, konungen i Assyrien, har sänt honom till att smäda den levande Guden, så att han straffar honom för dessa ord som han, HERREN, din Gud, har hört. Så bed nu en bön för den kvarleva som ännu finnes."
Ó lè jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ọ̀gágun ẹni tí ọ̀gá rẹ̀ ọba Asiria ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣe ẹlẹ́yà, àti pé òun ni yóò bá a wí nítorí àwọn ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n sì wà láààyè.”
5 När nu konung Hiskias tjänare kommo till Jesaja,
Nígbà tí àwọn ìjòyè ọba Hesekiah dé ọ̀dọ̀ Isaiah,
6 sade Jesaja till dem: "Så skolen I säga till eder herre: Så säger HERREN: Frukta icke för de ord som du har hört, dem, med vilka den assyriske konungens tjänare hava hädat mig.
Isaiah sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ fún ọ̀gá yín pé, ‘Ohun tí Olúwa sọ nìyìí. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba Asiria tí ó wà nínú ìdè ti fi sọ̀rọ̀-òdì sí mi.
7 Se, jag skall låta en sådan ande komma in i honom, att han på grund av ett rykte som han skall få höra vänder tillbaka till sitt land; och jag skall låta honom falla för svärd i hans eget land."
Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò fi ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé bí o bá ti gbọ́ ìròyìn kan, òun yóò padà sí orílẹ̀-èdè rẹ̀, níbẹ̀ ni n ó sì ti jẹ́ kí wọn ké e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’”
8 Och Rab-Sake vände tillbaka och fann den assyriske konungen upptagen med att belägra Libna; ty han hade hört, att han hade brutit upp från Lakis.
Nígbà tí ọ̀gágun gbọ́ pé ọba Asiria ti fi Lakiṣi sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn, ó sì bá ọba tí ń bá Libina jà.
9 Men när Sanherib fick höra sägas om Tirhaka, konungen i Etiopien, att denne hade dragit ut för att strida mot honom, skickade han, så snart han hörde detta, sändebud till Hiskia och sade:
Ní àkókò yìí Sennakeribu gbọ́ ìròyìn kan pé Tirakah ará Kuṣi ọba Ejibiti ń jáde bọ̀ wá bá òun jà. Nígbà tí ó gbọ́ èyí, ó rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí,
10 "Så skolen I säga till Hiskia, Juda konung: Låt icke din Gud, som du förtröstar på, bedraga dig, i det att du tänker: 'Jerusalem skall icke bliva givet i den assyriske konungens hand.'
“Ẹ sọ fún Hesekiah ọba Juda pé: Má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tàn ọ́ jẹ nígbà tí ó sọ pé, ‘A kì yóò jọ̀wọ́ Jerusalẹmu fún ọba Asiria.’
11 Du har ju hört, vad konungarna i Assyrien hava gjort med alla andra länder, huru de hava givit dem till spillo. Och du skulle nu bliva räddad!
Dájúdájú, ìwọ ti gbọ́ ohun tí ọba Asiria ti ṣe sí àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó pa wọ́n run pátápátá. Ǹjẹ́ a ó ha dá ọ nídè bí?
12 Hava väl de folk, som mina fäder fördärvade, Gosan, Haran, Resef och Edens barn i Telassar, blivit räddade av sina gudar?
Ǹjẹ́ àwọn òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí àwọn baba ńlá mi parun ha gbà wọ́n sílẹ̀ bí àwọn òrìṣà Gosani, Harani, Reṣefu àti àwọn ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari?
13 Var är Hamats konung och Arpads konung och konungen över Sefarvaims stad, över Hena och Iva?"
Níbo ni ọba Hamati wà, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi tàbí Hena tàbí Iffa?”
14 När Hiskia hade mottagit brevet av sändebuden och läst det, gick han upp i HERRENS hus, och där bredde Hiskia ut det inför HERRENS ansikte.
Hesekiah gba ìwé náà lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ ó sì kà á. Lẹ́yìn náà ni ó gòkè lọ sí tẹmpili Olúwa ó sì tẹ́ ìwé náà sílẹ̀ níwájú Olúwa.
15 Och Hiskia bad till HERREN och sade:
Hesekiah sì gbàdúrà sí Olúwa:
16 "HERRE Sebaot, Israels Gud, du som tronar på keruberna, du allena är Gud, den som råder över alla riken på jorden; du har gjort himmel och jord.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli, tí ó gúnwà láàrín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí i gbogbo ìjọba orílẹ̀ ayé. Ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
17 HERRE, böj ditt öra härtill och hör; HERRE, öppna dina ögon och se. Ja, hör alla Sanheribs ord, det budskap, varmed han har smädat den levande Guden.
Tẹ́tí sílẹ̀, ìwọ Olúwa, kí o gbọ́, ya ojú rẹ, Ìwọ Olúwa, kí o rí i; tẹ́tí sí gbogbo ọ̀rọ̀ tí Sennakeribu rán láti fi àbùkù kan Ọlọ́run alààyè.
18 Det är sant, HERRE, att konungarna i Assyrien hava förött alla länder såsom ock sitt eget land.
“Òtítọ́ ni Olúwa pé àwọn ọba Asiria ti sọ àwọn ènìyàn àti ilẹ̀ wọn di asán.
19 Och de hava kastat deras gudar i elden; ty dessa voro inga gudar, utan verk av människohänder, trä och sten; därför kunde de förgöra dem.
Wọ́n ti da àwọn òrìṣà wọn sínú iná wọ́n sì ti pa wọ́n run, nítorí àwọn wọ̀nyí kì í ṣe ọlọ́run bí kò ṣe igi àti òkúta lásán, tí a ti ọwọ́ ènìyàn ṣe.
20 Men fräls oss nu, HERRE, vår Gud, ur hans hand, så att alla riken på jorden förnimma, att du, HERRE, är den ende."
Nísinsin yìí, ìwọ Olúwa, Ọlọ́run wa, gbà wá lọ́wọ́ rẹ̀, tí ó fi jẹ́ pé gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé yóò fi mọ̀ pé Ìwọ, Ìwọ nìkan, Olúwa ni Ọlọ́run.”
21 Då sände Jesaja, Amos' son, bud till Hiskia och lät säga: "Så säger HERREN, Israels Gud, jag, till vilken du har bett angående Sanherib, konungen i Assyrien:
Lẹ́yìn náà Isaiah ọmọ Amosi rán iṣẹ́ kan sí Hesekiah: “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ pé, nítorí pé ìwọ ti gbàdúrà sí mi nípa Sennakeribu ọba Asiria,
22 Detta är det ord, som HERREN har talat om honom: Hon föraktar dig och bespottar dig, jungfrun dottern Sion; hon skakar huvudet efter dig, dottern Jerusalem.
èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀: “Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni ti kẹ́gàn rẹ, ó sì ti fi ọ ṣe ẹlẹ́yà. Ọmọbìnrin Jerusalẹmu ti mi orí rẹ̀ bí ó ti ń sálọ.
23 Vem har du smädat och hädat, och mot vem har du upphävt din röst? Alltför högt har du upplyft dina ögon -- ja, mot Israels Helige.
Ta ni ìwọ ti bú tí ìwọ sì ti sọ̀rọ̀-òdì sí? Sí ta ní ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí o sì gbé ojú rẹ sókè ní ìgbéraga? Sí Ẹni Mímọ́ Israẹli!
24 Genom dina tjänare smädade du HERREN, när du sade: 'Med mina många vagnar drog jag upp på bergens höjder, längst upp på Libanon; jag högg ned dess höga cedrar och väldiga cypresser; jag trängde fram till dess översta höjder, dess frodigaste skog;
Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ, ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa. Tì wọ sì wí pé, ‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá, sí ibi gíga jùlọ Lebanoni. Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀, àti ààyò igi firi rẹ̀. Èmi ti dé ibi rẹ̀ tí ó ga jùlọ, igbó rẹ̀ tí ó dára jùlọ.
25 jag grävde brunnar och drack ut vatten, och med min fot uttorkade jag alla Egyptens strömmar.'
Èmi ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì mo sì mu omi ní ibẹ̀, pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi Èmi ti gbẹ́ gbogbo omi àwọn odò Ejibiti.’
26 Har du icke hört, att jag för länge sedan beredde detta? Av ålder bestämde jag ju så; och nu har jag fört det fram: du fick makt att ödelägga befästa städer till grusade stenhopar.
“Ṣé o kò tí ì gbọ́? Tipẹ́tipẹ́ ni mo ti fìdí rẹ̀ mulẹ̀. Láti ìgbà pípẹ́ ni mo ti ṣètò rẹ̀; ní àkókò yìí ni mo mú wá sí ìmúṣẹ, pé o ti sọ àwọn ìlú olódi di àkójọpọ̀ àwọn òkúta.
27 Deras invånare blevo maktlösa, de förfärades och stodo med skam. Det gick dem såsom gräset på marken och gröna örter, såsom det som växer på taken, och säd, som förgås, förrän strået har vuxit upp.
Àwọn ènìyàn, tí agbára ti wọ̀ lẹ́wù, ni wọ́n banújẹ́ tí a sì dójútì. Wọ́n dàbí ohun ọ̀gbìn nínú pápá, gẹ́gẹ́ bí ọ̀jẹ̀lẹ̀ èhíhù tuntun, gẹ́gẹ́ bí i koríko tí ó ń hù lórí òrùlé, tí ó jóná kí ó tó dàgbàsókè.
28 Om du sitter eller går ut eller går in, så vet jag det, och huru du rasar mot mig.
“Ṣùgbọ́n mo mọ ibi tí o wà àti ìgbà tí o wá tí o sì lọ àti bí inú rẹ ṣe ru sí mi.
29 Men då du nu så rasar mot mig och då ditt övermod har nått till mina öron, skall jag sätta min krok i din näsa och mitt betsel i din mun och föra dig tillbaka samma väg, som du har kommit på.
Nítorí pé inú rẹ ru sí mi àti nítorí pé orí kunkun rẹ ti dé etí ìgbọ́ mi, Èmi yóò fi ìwọ̀ mi sí ọ ní imú, àti ìjẹ mi sí ọ lẹ́nu, èmi yóò sì jẹ́ kí o padà láti ọ̀nà tí o gbà wá.
30 Och detta skall för dig vara tecknet: man skall detta år äta, vad som växer upp av spillsäd, och nästa år självvuxen säd, men det tredje året skolen I få så och skörda och plantera vingårdar och äta deras frukt.
“Èyí ni yóò ṣe àmì fún ọ, ìwọ Hesekiah: “Ní ọdún yìí, ìwọ yóò jẹ ohun tí ó hù fúnra rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó jáde láti ara rẹ. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, ẹ gbìn kí ẹ sì kórè, ẹ gbin ọgbà àjàrà kí ẹ sì jẹ èso wọn.
31 Och den räddade skaran av Juda hus, som bliver kvar, skall åter skjuta rot nedtill och bära frukt upptill.
Lẹ́ẹ̀kan sí i, àṣẹ́kù láti ilé Juda yóò ta gbòǹgbò nísàlẹ̀ yóò sì ṣo èso lókè.
32 Ty från Jerusalem skall utgå en kvarleva, en räddad skara från Sions berg. HERREN Sebaots nitälskan skall göra detta.
Nítorí láti Jerusalẹmu ni àwọn àṣẹ́kù yóò ti wá, àti láti òkè Sioni ni ikọ̀ àwọn tí ó sálà. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.
33 Därför säger HERREN så om konungen i Assyrien: Han skall icke komma in i denna stad och icke skjuta någon pil ditin; han skall icke mot den föra fram någon sköld eller kasta upp någon vall mot den.
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọba Asiria, “Òun kì yóò wọ ìlú yìí wá tàbí ta ẹyọ ọfà kan níhìn-ín Òun kì yóò wá síwájú rẹ pẹ̀lú asà tàbí kí ó kó dágunró sílẹ̀ fún un.
34 Samma väg han kom skall han vända tillbaka, och in i denna stad skall han icke komma, säger HERREN.
Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá náà ni yóò padà lọ; òun kì yóò wọ inú ìlú yìí,” ni Olúwa wí.
35 Ty jag skall beskärma och frälsa denna stad för min tjänare Davids skull."
“Èmi yóò dáàbò bo ìlú yìí èmi ó sì gbà á là, nítorí mi àti nítorí Dafidi ìránṣẹ́ mi!”
36 Och HERRENS ängel gick ut och slog i assyriernas läger ett hundra åttiofem tusen man; och när man bittida följande morgon kom ut, fick man se döda kroppar ligga där överallt.
Lẹ́yìn náà ni angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ó lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní i ibùdó àwọn Asiria. Nígbà tí àwọn ènìyàn yìí jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì gbogbo wọn ti dòkú!
37 Då bröt Sanherib, konungen i Assyrien, upp och tågade tillbaka; och han stannade sedan i Nineve.
Nítorí náà Sennakeribu ọba Asiria fọ́ bùdó ó sì pẹsẹ̀dà. Òun sì padà sí Ninefe, ó sì dúró síbẹ̀.
38 Men när han en gång tillbad i sin gud Nisroks tempel, blev han dräpt med svärd av sina söner Adrammelek och Sareser; därefter flydde dessa undan till Ararats land. Och hans son Esarhaddon blev konung efter honom.
Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń jọ́sìn nínú tẹmpili Nisroki òrìṣà rẹ̀, àwọn ọmọ rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati. Bẹ́ẹ̀ ni Esarhadoni ọmọ rẹ̀ sì gba ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.

< Jesaja 37 >