< Hosea 14 >
1 Vänd om, o Israel, till HERREN, din Gud; ty genom din missgärning har du kommit på fall.
Yípadà ìwọ Israẹli sí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ló fa ìparun rẹ!
2 Tagen med eder böneord, och vänden så åter till HERREN; sägen till honom: "Skaffa bort all missgärning, och tag fram goda håvor, så vilja vi hembära dig våra läppars offer, såsom man offrar tjurar.
Ẹ gba ọ̀rọ̀ Olúwa gbọ́, kí ẹ sì yípadà sí Olúwa. Ẹ sọ fún un pé, “Darí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá kí o sì fi oore-ọ̀fẹ́ gbà wá, kí àwa kí ó lè fi ètè wa sán an fún ọ
3 Hos Assur skola vi ej mer söka vår frälsning, vi skola icke vidare stiga till häst. våra händers verk skola vi icke mer kalla för vår Gud. Ty hos dig är det som den faderlöse undfår barmhärtighet."
Asiria kò le gbà wá là; a kò ní í gorí ẹṣin ogun. A kò sì ní tún sọ ọ́ mọ́ láé, ‘Àwọn ni òrìṣà wa’ sí àwọn ohun tí ó fi ọwọ́ wa ṣe; nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ ni àwọn aláìní baba tí ń rí àánú.”
4 Ja, deras avfällighet vill jag hela, jag vill bevisa dem kärlek av hjärtat, ty min vrede har vänt sig ifrån dem.
“Èmi wo àgàbàgebè wọn sàn, Èmi ó sì fẹ́ràn wọn, lọ́fẹ̀ẹ́, nítorí ìbínú mi ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn.
5 Jag skall bliva för Israel såsom dagg, han skall blomstra såsom en lilja, och såsom Libanons skog skall han skjuta rötter.
Èmi o dàbí ìrì sí Israẹli, wọn o sì yọ ìtànná bi ewéko lílì. Bi kedari ti Lebanoni yóò si ta gbòǹgbò.
6 Telningar skola utgå från honom, han skall bliva lik ett olivträd i fägring och doft skall han sprida såsom Libanon.
Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ẹ̀ka rẹ̀ yóò dàgbà, dídán ẹwà yóò rẹ̀ dànù bí igi olifi. Òórùn rẹ yóò sì dàbí igi kedari ti Lebanoni.
7 De som bo i hans skugga skola åter få odla säd och skola grönska såsom vinträd; hans namn skall vara såsom Libanons vin.
Àwọn ènìyàn yóò tún padà gbé lábẹ́ òjijì rẹ̀. Yóò rúwé bi ọkà. Yóò sì yọ ìtànná bi àjàrà, òórùn rẹ yóò dàbí ti wáìnì Lebanoni.
8 Men vad har jag då mer att skaffa med avgudarna, du Efraim! Jag själv vill ju giva bönhörelse och se till honom. Ja, lik en grönskande cypress vill jag bliva; hos mig skall finnas frukt att hämta för dig.
Ìwọ Efraimu, kín ló tún kù tí mo ní ṣe pẹ̀lú ère òrìṣà? Èmi ó dá a lóhùn, èmi ó sì ṣe ìtọ́jú rẹ. Mo dàbí igi junifa tó ń fi gbogbo ìgbà tutù, èso tí ìwọ ń so si ń wá láti ọ̀dọ̀ mi.”
9 Den som är vis, han akte härpå; den som är förståndig, han besinne detta. Ty HERRENS vägar äro rätta, och på dem vandra de rättfärdiga, men överträdarna komma där på fall.
Ta ni ọlọ́gbọ́n? Òun yóò mòye àwọn nǹkan wọ̀nyí. Ta a ní ó mọ̀? Òun yóò ní ìmọ̀ wọn. Títọ́ ni ọ̀nà Olúwa àwọn olódodo si ń rìn nínú wọn, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ni yóò kọsẹ̀ nínú wọn.