< Hesekiel 5 >

1 Och du, människobarn, tag dig ett skarpt svärd och bruka det såsom rakkniv, och för det över ditt huvud och din haka; tag dig så en vågskål och dela det avrakade håret.
“Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
2 En tredjedel skall du bränna upp i eld mitt i staden, när belägringsdagarna hava gått till ända; en tredjedel skall du taga ut och slå den med svärdet där runt omkring; och en tredjedel skall du strö ut för vinden, och mitt svärd skall jag draga ut efter dem.
Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
3 Men några få strån skall du taga undan därifrån, och dem skall du knyta in i flikarna av din mantel.
Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
4 Och av dessa strån skall du återigen taga några och kasta dem i elden och bränna upp dem i eld. Härifrån skall en eld gå ut över hela Israels hus.
Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
5 Så säger Herren, HERREN: Detta år Jerusalem, som jag har satt mitt ibland hednafolken, med länder runt däromkring.
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
6 Men det var gensträvigt mot mina rätter på ett ännu ogudaktigare sätt än hednafolken, och var ännu mer gensträvigt mot mina stadgar än länderna runt däromkring; ty de förkastade mina rätter och vandrade icke efter mina stadgar.
Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
7 Därför säger Herren, HERREN så: Eftersom I haven rasat värre än hednafolken runt omkring eder, och icke haven vandrat efter mina stadgar och icke gjort efter mina rätter, ja, icke ens gjort efter de hednafolks rätter, som bo runt omkring eder,
“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
8 därför säger Herren, HERREN så: Se, fördenskull skall jag också komma över dig och skipa rätt mitt ibland dig inför hednafolkens ögon;
“Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
9 jag skall göra med dig vad jag aldrig förr har gjort, och sådant som jag aldrig mer vill göra, för alla dina styggelsers skull.
Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
10 Därför skola i dig föräldrar äta sina barn, och barn sina föräldrar; och jag skall skipa rätt i dig och strö ut för alla vindar allt som bliver kvar av dig.
Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
11 Ja, så sant jag lever, säger Herren, HERREN: sannerligen, därför att du har orenat min helgedom med alla dina skändligheter och alla dina styggelser, skall jag också utan skonsamhet vända bort mitt öga och icke hava någon misskund.
Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
12 En tredjedel av dig skall dö av pest och förgås av hunger i dig, en tredjedel skall falla för svärd runt omkring dig; och en tredjedel skall jag strö ut för alla vindar, och mitt svärd skall jag draga ut efter dem.
Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
13 Ja, min vrede skall få uttömma sig, och jag skall släcka min förtörnelse på dem och hämnas på dem; och när jag så uttömmer min förtörnelse på dem, skola de förnimma att jag, HERREN, har talat i min nitälskan.
“Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
14 Och jag skall låta dig bliva en ödemark och en smälek bland folken runt omkring dig, inför var mans ögon, som går där fram.
“Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
15 Ja, det skall bliva till smälek och hån, till varnagel och skräck för folken runt omkring dig, när jag så skipar rätt i dig med vrede och förtörnelse och förtörnelses tuktan. Jag, HERREN, har talat.
O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
16 När jag sänder bland dem hungerns onda pilar, som bliva till fördärv, ja, när jag sänder dessa till att fördärva eder och så låter eder hunger bliva allt värre, då skall jag förstöra för eder edert livsuppehälle.
Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
17 Jag skall sända över eder hungersnöd och vilddjur, som skola döda edra barn; och pest och blodsutgjutelse skall gå över dig, och svärd skall jag låta komma över dig. Jag, HERREN, har talat.
Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”

< Hesekiel 5 >