< Hesekiel 11 >

1 Och en andekraft lyfte upp mig och förde mig till östra porten på HERRENS hus, den som vetter åt öster. Där fick jag se tjugufem män stå vid ingången till porten; och jag såg bland dem Jaasanja, Assurs son, och Pelatja, Benajas son, som voro furstar i folket.
Ẹ̀mí sì gbé mi sókè, ó mú mi lọ sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa èyí tó dojúkọ ìlà-oòrùn. Ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà yìí ni àwọn ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n wá, mo rí Jaaṣaniah ọmọ Assuri àti Pelatiah ọmọ Benaiah, tí wọ́n jẹ́ ìjòyè àwọn ènìyàn.
2 Och han sade till mig: "Du människobarn, det är dessa män som tänka ut vad fördärvligt är och råda till vad ont är, här i staden;
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gbé ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.
3 det är de som säga: 'Hus byggas icke upp så snart. Här är grytan, och vi äro köttet.
Wọ́n ní, ‘Kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.
4 Profetera därför mot dem, ja, profetera, du människobarn."
Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀.”
5 Då föll HERRENS Ande över mig, han sade till mig: "Säg: Så säger HERREN: Sådant sägen I, I av Israels hus, och edra hjärtans tankar känner jag väl.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, ohun tí ẹ ń sọ nìyìí, ilé Israẹli, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.
6 Många ligga genom eder slagna här i staden; I haven uppfyllt dess gator med slagna.
Ẹ̀yin ti sọ òkú yín di púpọ̀ nínú ìlú yìí, òkú sì ti kún gbogbo ìgboro rẹ̀.
7 Därför säger Herren, HERREN så: De slagna vilkas fall I haven vållat i staden, de äro köttet, och den är grytan; men eder själva skall man föra bort ur den.
“Torí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, àwọn òkú tí ẹ fọn sílẹ̀ sí àárín yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n èmi yóò le yín jáde níbẹ̀.
8 I frukten för svärd, och svärd skall jag ock låta komma över eder, säger Herren, HERREN.
Ẹ bẹ̀rù idà, èmi yóò sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Jag skall föra eder bort härifrån och giva eder i främlingars hand; och jag skall hålla dom över eder.
Èmi yóò lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, èmi yóò sì fà yín lé àjèjì lọ́wọ́, èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
10 För svärd skolen I falla; vid Israels gräns skall jag döma eder. Och I skolen förnimma att jag är HERREN.
Nípa idà ni ẹ̀yin yóò ṣubú, èmi yóò sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
11 Staden skall icke vara en gryta för eder, och I skolen icke vara köttet i den; nej, vid Israels gräns skall jag döma eder.
Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli.
12 Då skolen I förnimma att jag är HERREN, I som icke haven vandrat efter mina stadgar och icke haven gjort efter mina rätter, utan haven gjort efter de hednafolks rätter, som bo runt omkring eder."
Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ̀yin kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀-èdè tó yí yín ká.”
13 Medan jag så profeterade, hade Pelatja, Benajas son, uppgivit andan. Då föll jag ned på mitt ansikte och ropade med hög röst och sade: "Ack, Herre, HERRE, vill du då alldeles göra ände på kvarlevan av Israel?"
Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pelatiah ọmọ Benaiah kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ṣé ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli run pátápátá ni?”
14 Och HERRENS ord kom till mig; han sade:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé,
15 "Du människobarn, dina bröder, ja, dina bröder dina nära fränder och hela Israels hus, alla de till vilka Jerusalems invånare säga: 'Hållen eder borta från HERREN; det är åt oss som landet har blivit givet till besittning' --
“Ọmọ ènìyàn, àwọn arákùnrin rẹ, àní àwọn ará rẹ, àwọn ọkùnrin nínú ìbátan rẹ, àti gbogbo ilé Israẹli pátápátá, ni àwọn ará Jerusalẹmu ti wí fún pé, ‘Ẹ jìnnà sí Olúwa, àwa ni a fi ilẹ̀ yìí fún yín ní ìní.’
16 om dem skall du alltså säga: Så säger Herren, HERREN: Ja, väl har jag fört dem långt bort ibland folken och förstrött dem i länderna, och med nöd har jag varit för dem en helgedom i de länder dit de hava kommit;
“Nítorí náà, sọ fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fọ́n wọn káàkiri orílẹ̀-èdè, síbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, èmi yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún wọn níbi tí wọ́n lọ.’
17 men därför skall du nu säga: Så säger Herren, HERREN: Jag skall församla eder ifrån folkslagen och hämta eder tillhopa från de länder dit I haven blivit förströdda, och skall giva eder Israels land.
“Nítorí náà, wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò kó wọn jọ kúrò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí mo fọ́n wọn ká sí, Èmi yóò sì fún wọn ní ilẹ̀ Israẹli padà.’
18 Och när de hava kommit dit, skola de skaffa bort därifrån alla de skändliga och styggeliga avgudar som nu finnas där.
“Wọn yóò padà síbẹ̀, wọn yóò sì mú gbogbo àwòrán ìríra rẹ̀ àti ìbọ̀rìṣà rẹ̀ kúrò.
19 Och jag skall giva dem alla ett och samma hjärta, och en ny ande skall jag låta komma i deras bröst; jag skall taga bort stenhjärtat ur deras kropp och giva dem ett hjärta av kött,
Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.
20 så att de vandra efter mina stadgar och hålla mina rätter och göra efter dem, och de skola vara mitt folk, och jag skall vara deras Gud.
Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
21 Men de vilkas hjärtan efterfölja de skändliga och styggeliga avgudarnas hjärtan, deras gärningar skall jag låta komma över deras huvuden, säger Herren, HERREN."
Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sí orí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.”
22 Och keruberna, följda av hjulen, lyfte sina vingar, och Israels Guds härlighet vilade ovanpå dem.
Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lókè orí wọn.
23 Och HERRENS härlighet höjde sig och lämnade staden och stannade på berget öster om staden.
Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrín ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà-oòrùn ìlú náà.
24 Men mig hade en andekraft lyft upp och fört bort till de fångna i Kaldeen, så hade skett i synen, genom Guds Ande. Sedan försvann för mig den syn jag hade fått se.
Lẹ́yìn náà, Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi wá sí Kaldea lójú ìran, nípa ti Ẹ̀mí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ àwọn ti ìgbèkùn. Bẹ́ẹ̀ ni ìran tí mo rí lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi,
25 Och jag talade till de fångna alla de ord som HERREN hade uppenbarat för mig.
mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn.

< Hesekiel 11 >