< 2 Mosebok 32 >
1 Men när folket såg att Mose dröjde att komma ned från berget, församlade de sig omkring Aron och sade till honom: "Upp, gör oss en gud som kan gå framför oss; ty vi veta icke vad som har vederfarits denne Mose, honom som förde oss upp ur Egyptens land."
Nígbà tí àwọn ènìyàn rí i pé Mose pẹ́ kí ó tó sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè wá, wọn péjọ yí Aaroni ká, wọ́n sì wí pé, “Wá, dá òrìṣà tí yóò máa ṣáájú wa fún wa. Bí ó ṣe ti Mose tí ó mú wa jáde láti Ejibiti wá, àwa kò mọ́ ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí i.”
2 Då sade Aron till dem: "Tagen guldringarna ut ur öronen på edra hustrur, edra söner och edra döttrar, och bären dem till mig.
Aaroni dá wọn lóhùn pé, “Ẹ bọ́ òrùka wúrà tí ó wà ní etí àwọn ìyàwó yín, tí àwọn ọmọkùnrin yín, àti tí àwọn ọmọbìnrin yín, kí ẹ sì mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi.”
3 Då tog allt folket av sig guldringarna som de hade i öronen, och de buro dem till Aron;
Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ènìyàn bọ́ òrùka etí wọn, wọn sì kó wọn wá fún Aaroni.
4 och han tog emot guldet av dem och formade det med en mejsel och gjorde därav en gjuten kalv. Och de sade: "Detta är din Gud, Israel, han som har fört dig upp ur Egyptens land."
Ó sì gbà wọ́n ní ọwọ́ wọn, ó sì fi ṣe ohun ọnà fínfín, ó sì dà á ní àwòrán ẹgbọrọ màlúù. Nígbà náà ni wọn wí pé, “Israẹli, wọ̀nyí ni òrìṣà, ti ó mú un yín jáde wá láti Ejibiti.”
5 När Aron såg detta, byggde han ett altare åt honom. Och Aron lät utropa och säga: "I morgon bliver en HERRENS högtid."
Nígbà ti Aaroni rí èyí, ó kọ́ pẹpẹ kan níwájú ẹgbọrọ màlúù náà, ó sì kéde pé, “Lọ́la ni àjọyọ̀ sí Olúwa.”
6 Dagen därefter stodo de bittida upp och offrade brännoffer och buro fram tackoffer, och folket satte sig ned till att äta och dricka, och därpå stodo de upp till att leka.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn dìde ní kùtùkùtù ọjọ́ kejì, wọ́n sì rú ẹbọ sísun, wọ́n sì mú ẹbọ àlàáfíà wá. Lẹ́yìn náà wọ́n jókòó láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì dìde láti ṣeré.
7 Då sade HERREN till Mose: "Gå ditned, ty ditt folk, som du har fört upp ur Egyptens land, har tagit sig till, vad fördärvligt är.
Olúwa sì wí fún Mose pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ, nítorí àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ mú gòkè wá láti Ejibiti, wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀.
8 De hava redan vikit av ifrån den väg som jag bjöd dem gå; de hava gjort sig en gjuten kalv. Den hava de tillbett, åt den hava de offrat, och sagt: 'Detta är din Gud, Israel, han som har fört dig upp ur Egyptens land."
Wọ́n ti yí kánkán kúrò nípa ọ̀nà tí mo ti mo pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì ti dá ère ẹgbọrọ màlúù fún ara wọn. Wọ́n ti foríbalẹ̀ fún un, wọ́n sì ti rú ẹbọ sí i, wọ́n sì ti sọ pé, ‘Israẹli wọ̀nyí ní òrìṣà tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá.’”
9 Och HERREN sade ytterligare till Mose: "Jag ser att detta folk är ett hårdnackat folk.
Olúwa wí fún Mose pé, “Èmi ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, wọ́n sì jẹ́ ọlọ́rùn líle ènìyàn.
10 Så låt mig nu vara, på det att min vrede må brinna mot dem, och på det att jag må förgöra dem; dig vill jag sedan göra till ett stort folk."
Ǹjẹ́ nísinsin yìí fi mí sílẹ̀, nítorí kí ìbínú mi lè gbóná sí wọn, kí Èmi sì lè pa wọ́n run. Nígbà náà ni Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá.”
11 Men Mose bönföll inför HERREN, sin Gud, och sade: "HERRE, varför skulle din vrede brinna mot ditt folk, som du med stor kraft och stark hand har fört ut ur Egyptens land?
Ṣùgbọ́n Mose kígbe fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ó wí pé, “Olúwa, èéṣe tí ìbínú rẹ yóò ṣe gbóná sí àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ mú jáde láti Ejibiti wá pẹ̀lú agbára ńlá àti ọwọ́ agbára?
12 Varför skulle egyptierna få säga: 'Till deras olycka har han fört dem ut, till att dräpa dem bland bergen och förgöra dem från jorden'? Vänd dig ifrån din vredes glöd, och ångra det onda du nu har i sinnet mot ditt folk.
Èéṣe tí àwọn ará Ejibiti yóò ṣe wí pé, ‘Nítorí ibi ni ó ṣe mọ̀ ọ́n mọ̀ mú wọn jáde, láti pa wọ́n ní orí òkè àti láti gbá wọn kúrò lórí ayé’? Yípadà kúrò nínú ìbínú rẹ tí ó múná, yí ọkàn padà, kí o má sì ṣe mú ìparun wá sórí àwọn ènìyàn rẹ.
13 Tänk på Abraham, Isak och Israel, dina tjänare, åt vilka du med ed vid dig själv har givit det löftet: 'Jag skall göra eder säd talrik såsom stjärnorna på himmelen, och hela det land som jag har talat om skall jag giva åt eder säd, och de skola få det till evärdlig arvedel.'"
Rántí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, ẹni tí ìwọ búra fún fúnra rẹ̀, ‘Tí o wí fún wọn pé, Èmi yóò mú irú-ọmọ rẹ pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, Èmi yóò sì fún irú-ọmọ rẹ ní gbogbo ilẹ̀ tí mo ti pinnu fún wọn, yóò sì jẹ́ ogún ìní wọn láéláé.’”
14 Då ångrade HERREN det onda som han hade hotat att göra mot sitt folk.
Nígbà náà ni Olúwa dáwọ́ ìbínú rẹ̀ dúró, kò sì mú ìparun náà tí ó sọ wá sórí àwọn ènìyàn rẹ̀ mọ́.
15 Och Mose vände sig om och steg ned från berget, och han hade med sig vittnesbördets två tavlor. Och på tavlornas båda sidor var skrivet både på den ena sidan och på den andra var skrivet.
Mose sì yípadà, ó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà pẹ̀lú òkúta wàláà ẹ̀rí méjì ní ọwọ́ rẹ̀. Wọ́n kọ ìwé síhà méjèèjì, iwájú àti ẹ̀yin.
16 Och tavlorna voro gjorda av Gud, och skriften var Guds skrift, inristad på tavlorna.
Iṣẹ́ Ọlọ́run sì ni wàláà náà; ìkọ̀wé náà jẹ́ ìkọ̀wé Ọlọ́run, a fín in sára àwọn òkúta wàláà náà.
17 När Josua nu hörde huru folket skriade, sade han till Mose: "Krigsrop höres i lägret."
Nígbà tí Joṣua gbọ́ ariwo àwọn ènìyàn tí wọ́n ń kígbe, ó sọ fún Mose pé, “Ariwo ogun wà nínú àgọ́.”
18 Men han svarade: "Det är varken segerrop som höres, ej heller är det ett ropande såsom efter nederlag; det är sång jag hör."
Mose dáhùn pé, “Kì í ṣe ariwo fún ìṣẹ́gun, kì í ṣe ariwo fún aṣẹ́gun; ohùn àwọn tí ń kọrin ni mo gbọ́.”
19 När sedan Mose kom närmare lägret och fick se kalven och dansen, upptändes hans vrede, och han kastade tavlorna ifrån sig och slog sönder dem nedanför berget.
Nígbà tí Mose dé àgọ́, ó sì rí ẹgbọrọ màlúù náà àti ijó, ìbínú rẹ gbóná, ó sì sọ wàláà ọwọ́ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ ní ìsàlẹ̀ òkè náà.
20 Sedan tog han kalven som de hade gjort, och brände den i eld och krossade den till stoft; detta strödde han i vattnet och gav det åt Israels barn att dricka.
Ó sì gbé ẹgbọrọ màlúù tí wọ́n ṣe, ó sì fi iná jó wọn; ó sì lọ̀ wọ́n kúnná, ó dà á sínú omi, ó sì mú àwọn ọmọ Israẹli mu ún.
21 Och Mose sade till Aron: "Vad har folket gjort dig, eftersom du har kommit dem att begå en så stor synd?"
Mose sọ fún Aaroni pé, “Kí ni àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe sí ọ, tí ìwọ ṣe mú wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ ńlá yìí?”
22 Aron svarade: "Min herres vrede må icke upptändas; du vet själv att detta folk är ont.
Aaroni dáhùn wí pé, “Má ṣe bínú olúwa mi. Ìwọ mọ bí àwọn ènìyàn yìí ṣe burú tó.
23 De sade till mig: 'Gör oss en gud som kan gå framför oss; ty vi veta icke vad som har vederfarits denne Mose, honom som förde oss upp ur Egyptens land.'
Wọ́n sọ fún mi pé, ‘Ṣe òrìṣà fún wa, tí yóò máa ṣáájú wa. Bí ó ṣe ti Mose ẹni tí ó mú wa jáde láti Ejibiti wá àwa kò mọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí i.’
24 Då sade jag till dem: 'Den som har guld tage det av sig'; och de gåvo det åt mig. Och jag kastade det i elden, och så kom kalven till."
Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún wọn pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó ní òrùka wúrà, kí ó bọ́ ọ wá.’ Nígbà náà ni wọ́n fún mi ní wúrà, mo sì jù ú sínú iná, a sì fi ṣe ẹgbọrọ màlúù yìí!”
25 Då nu Mose såg att folket var lössläppt, eftersom Aron, till skadeglädje för deras fiender, hade släppt dem lösa,
Mose rí pé àwọn ènìyàn náà kò ṣe ṣàkóso àti pé Aaroni ti sọ wọ́n di aláìlákóṣo láàrín àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wọn.
26 ställde han sig i porten till lägret och ropade: "Var och en som hör HERREN till komme hit till mig." Då församlade sig till honom alla Levi barn.
Bẹ́ẹ̀ ni Mose dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó sì wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá wà fún Olúwa, kí ó wá sí ọ̀dọ̀ mi.” Gbogbo àwọn ará Lefi sì péjọ yí i ká.
27 Och han sade till dem: "Så säger HERREN, Israels Gud: Var och en binde sitt svärd vid sin länd. Gån så igenom lägret, fram och tillbaka, från den ena porten till den andra, Och dräpen vem I finnen, vore det också broder eller vän eller frände.
Nígbà náà ni ó sọ fún wọn pé, “Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, wí pé, ‘Kí olúkúlùkù ọkùnrin kí ó kọ idà rẹ̀ sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Ẹ lọ padà, kí ẹ jà láti àgọ́ kan dé òmíràn, olúkúlùkù kí ó pa arákùnrin rẹ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ àti aládùúgbò rẹ.’”
28 Och Levi barn gjorde såsom Mose hade sagt; och på den dagen föllo av folket vid pass tre tusen män.
Àwọn ará Lefi ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ṣe pàṣẹ, àti ní ọjọ́ náà àwọn tí ó kú tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ènìyàn.
29 Och Mose sade: "Eftersom I nu haven stått emot edra egna söner och bröder, mån I i dag taga handfyllning till HERRENS tjänst, för att välsignelse i dag må komma över eder."
Nígbà náà ni Mose wí pé, “Ẹ ti ya ara yín sọ́tọ̀ fún Olúwa lónìí, nítorí ìwọ ti dìde sí àwọn ọmọ rẹ àti arákùnrin rẹ, ó sì ti bùkún fún ọ lónìí.”
30 Dagen därefter sade Mose till folket: "I haven begått en stor synd. Jag vill nu stiga upp till HERREN och se till, om jag kan bringa försoning för eder synd."
Ní ọjọ́ kejì Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ̀yin ti dá ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí èmi yóò gòkè lọ bá Olúwa; bóyá èmi lè ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yín.”
31 Och Mose gick tillbaka till HERREN och sade: "Ack, detta folk har begått en stor synd; de hava gjort sig en gud av guld.
Bẹ́ẹ̀ ni Mose padà tọ Olúwa lọ, ó sì wí pé, “Yé, kí ni ẹ̀ṣẹ̀ ńlá tí àwọn ènìyàn ti dá yìí! Wọ́n ti ṣe òrìṣà wúrà fún ara wọn.
32 Men förlåt dem nu deras synd; varom icke, så utplåna mig ur boken som du skriver i."
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, jọ̀wọ́ dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n ṣùgbọ́n tí kò bá sì ṣe bẹ́ẹ̀, pa orúkọ mi rẹ́ kúrò nínú ìwé tí ìwọ ti kọ.”
33 Men HERREN svarade Mose: "Den som har syndat mot mig, honom skall jag utplåna ur min bok.
Olúwa dá Mose lóhùn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi, Èmi yóò pa á rẹ́ kúrò nínú ìwé mi.
34 Gå nu och för folket dit jag har sagt dig; se, min ängel skall gå framför dig. Men när min hemsökelses dag kommer, skall jag på dem hemsöka deras synd."
Ǹjẹ́ nísinsin yìí lọ, máa darí àwọn ènìyàn yìí lọ sí ibi ti mo sọ, angẹli mi yóò sì máa lọ ṣáájú yín. Ìgbà ń bọ̀ fún mi tì Èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò, Èmi yóò fi yà jẹ wọ́n fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
35 Så straffade HERREN folket, därför att de hade gjort kalven, den som Aron gjorde.
Olúwa sì yọ àwọn ènìyàn náà lẹ́nu, pẹ̀lú ààrùn nítorí ohun tí wọ́n ṣe ní ti ẹgbọrọ màlúù tí Aaroni ṣe.