< Psaltaren 116 >

1 Jag har HERREN kär, ty han hör min röst och mina böner.
Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
2 Ja, han har böjt sitt öra till mig; i hela mitt liv skall jag åkalla honom.
Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
3 Dödens band omvärvde mig, och dödsrikets ångest grep mig; jag kom i nöd och bedrövelse. (Sheol h7585)
Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
4 Men jag åkallade HERRENS namn: »Ack HERRE, rädda min själ.»
Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
5 HERREN är nådig och rättfärdig, vår Gud är barmhärtig.
Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
6 HERREN bevarar de enfaldiga; jag var i elände, och han frälste mig.
Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
7 Vänd nu åter till din ro, min själ, ty HERREN har gjort väl mot dig.
Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
8 Ja, du har räddat min själ från döden, mitt öga från tårar, min fot ifrån fall;
Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
9 jag skall få vandra inför HERREN i de levandes land.
nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
10 Jag tror, ty därför talar jag, jag som var storligen plågad,
Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
11 jag som måste säga i min ångest: »Alla människor äro lögnaktiga.»
Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
12 Huru skall jag vedergälla HERREN alla hans välgärningar mot mig?
Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
13 Jag vill taga frälsningens bägare och åkalla HERRENS namn.
Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
14 Jag vill infria åt HERREN mina löften, ja, i hela hans folks åsyn.
Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Dyrt aktad i HERRENS ögon är hans frommas död.
Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
16 Ack HERRE, jag är ju din tjänare, jag är din tjänare, din tjänarinnas son; du har lossat mina band.
Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
17 Dig vill jag offra lovets offer, och HERRENS namn vill jag åkalla.
Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
18 Jag vill infria åt HERREN mina löften, ja, i hela hans folks åsyn,
Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
19 i gårdarna till HERRENS hus, mitt i dig, Jerusalem. Halleluja!
nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.

< Psaltaren 116 >