< Psaltaren 109 >
1 För sångmästaren; av David; en psalm. Min lovsångs Gud, tig icke.
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún, má ṣe dákẹ́,
2 Ty sin ogudaktiga mun, sin falska mun hava de upplåtit mot mig, de hava talat mot mig med lögnaktig tunga.
nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn ti ya ẹnu wọn sí mi wọ́n ti fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ sí mi.
3 Med hätska ord hava de omgivit mig, de hava begynt strid mot mig utan sak.
Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri; wọ́n bá mi jà láìnídìí
4 Till lön för min kärlek stå de mig emot, men jag beder allenast.
Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi, ṣùgbọ́n èmi ń gba àdúrà.
5 De hava bevisat mig ont för gott och hat för min kärlek.
Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi àti ìríra fún ìfẹ́ mi.
6 Låt en ogudaktig man träda upp emot honom, och låt en åklagare stå på hans högra sida.
Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ jẹ́ kí àwọn olùfisùn dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
7 När han kommer inför rätta, må han dömas skyldig, och hans bön vare synd.
Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́ kí àdúrà rẹ̀ kí ó lè di ìkọ̀sílẹ̀.
8 Blive hans dagar få, hans ämbete tage en annan.
Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú; kí ẹlòmíràn kí ó rọ́pò iṣẹ́ rẹ̀.
9 Varde hans barn faderlösa och hans hustru änka.
Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba kí aya rẹ̀ sì di opó.
10 Må hans barn alltid gå husvilla och tigga och söka sitt bröd fjärran ifrån ödelagda hem.
Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri kí wọn máa tọrọ oúnjẹ jìnnà sí ibi ahoro wọn.
11 Må ockraren få i sin snara allt vad han äger, och må främmande plundra hans gods.
Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní jẹ́ kí àlejò kí o kó èrè iṣẹ́ rẹ̀ lọ.
12 Må ingen finnas, som hyser misskund med honom, och ingen, som förbarmar sig över hans faderlösa.
Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un tàbí kí wọn káàánú lórí àwọn ọmọ rẹ̀ aláìní baba.
13 Hans framtid varde avskuren, i nästa led vare sådanas namn utplånat.
Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò kí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀.
14 Hans fäders missgärning varde ihågkommen inför HERREN, och hans moders synd varde icke utplånad.
Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí ó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ Olúwa. Má ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò.
15 Må den alltid stå inför HERRENS ögon; ja, sådana mäns åminnelse må utrotas från jorden.
Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwa kí ó lè gé ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
16 Ty han tänkte ju icke på att öva misskund, utan förföljde den som var betryckt och fattig och den vilkens hjärta var bedrövat, för att döda dem.
Nítorí kò rántí láti ṣàánú, ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíni sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú, kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
17 Han älskade förbannelse, och den kom över honom; han hade icke behag till välsignelse, och den blev fjärran ifrån honom.
Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀: bi inú rẹ̀ kò ti dùn si ìre, bẹ́ẹ̀ ni kí ó jìnnà sí.
18 Han klädde sig i förbannelse såsom i en klädnad, och såsom vatten trängde den in i hans liv och såsom olja in i hans ben.
Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù bẹ́ẹ̀ ni kí ó wá sí inú rẹ̀ bí omi.
19 Den varde honom såsom en mantel att hölja sig i, och såsom en gördel att alltid omgjorda sig med.
Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní ara, àti fún àmùrè tí ó fi gba ọ̀já nígbà gbogbo.
20 Detta vare mina motståndares lön från HERREN, och deras som tala ont mot min själ.
Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ Olúwa wá; àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọkàn mi.
21 Men du, HERRE, Herre, stå mig bi för ditt namn skull; god är ju din nåd, så må du då rädda mig.
Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa Olódùmarè, ṣe rere fún mi nítorí orúkọ rẹ. Nítorí tí àánú rẹ dára, ìwọ gbà mí.
22 Ty jag är betryckt och fattig, och mitt hjärta är genomborrat i mitt bröst.
Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí, àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
23 Såsom skuggan, när den förlänges, går jag bort; jag ryckes bort såsom en gräshoppssvärm.
Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́, mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.
24 Mina knän äro vacklande av fasta, och min kropp förlorar sitt hull.
Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà ẹran-ara mi sì gbẹ nítorí àìlera mi.
25 Till smälek har jag blivit inför dem; när de se mig, skaka de huvudet.
Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi; nígbà tí wọn wò mí, wọ́n gbọn orí wọn.
26 Hjälp mig, HERRE, min Gud; fräls mig efter din nåd;
Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
27 och må de förnimma att det är din hand, att du, HERRE, har gjort det.
Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí wí pé ìwọ, Olúwa, ni ó ṣe é.
28 Om de förbanna, så välsigna du; om de resa sig upp, så komme de på skam, men må din tjänare få glädja sig.
Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre, nígbà tí wọn bá dìde kí ojú kí ó tì wọ́n, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ yóò yọ̀.
29 Mina motståndare varde klädda i blygd och höljda i skam såsom i en mantel.
Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú kí á sì fi ìdàrúdàpọ̀ bọ̀ wọ́n lára bí ẹ̀wù.
30 Min mun skall storligen tacka HERREN; mitt ibland många vill jag lova honom.
Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin Olúwa gidigidi ní àárín ọ̀pọ̀ ènìyàn èmi yóò máa yìn ín.
31 Ty han står på den fattiges högra sida för att frälsa honom från dem som fördöma hans själ.
Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ń dá ọkàn rẹ̀ lẹ́bi.