< Ordspråksboken 8 >

1 Hör, visheten ropar, och förståndet höjer sin röst.
Ǹjẹ́ ọgbọ́n kò ha ń kígbe síta? Òye kò ha ń gbé ohùn rẹ sókè?
2 Uppe på höjderna står hon, vid vägen, där stigarna mötas.
Ní ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ní ìkóríta, ní ó dúró;
3 Invid portarna, vid ingången till staden där man träder in genom dörrarna, höjer hon sitt rop:
ní ẹgbẹ́ ibodè tí ó wọ ìlú, ní ẹnu ibodè ni ó ń kígbe sókè:
4 Till eder, I man, vill jag ropa, och min röst skall utgå till människors barn.
“Sí i yín ẹ̀yin ènìyàn, ní mo ń kígbe pè; mo gbé ohun mi sókè sí gbogbo ènìyàn.
5 Lären klokhet, I fåkunnige, och I dårar, lären förstånd.
Ẹ̀yin aláìmọ̀kan, ẹ kọ́gbọ́n; ẹ̀yin aṣiwèrè, ẹ gba òye.
6 Hören, ty om höga ting vill jag tala, och mina läppar skola upplåta sig till att säga vad rätt är.
Ẹ gbọ́, nítorí tí èmi ó sọ̀rọ̀ ohun iyebíye; Èmí ṣí ètè mi láti sọ ohun tí ó tọ́,
7 Ja, sanning skall min mun tala, en styggelse för mina läppar är ogudaktighet.
ẹnu mi ń sọ ohun tí í ṣe òtítọ́, nítorí ètè mi kórìíra ibi.
8 Rättfärdiga äro alla min muns ord; i dem finnes intet falskt eller vrångt.
Gbogbo ọ̀rọ̀ ẹnu mi ni ó tọ́, kò sí èyí tí ó jẹ́ ẹ̀tàn tàbí àyídáyidà níbẹ̀.
9 De äro alla sanna för den förståndige och rätta för dem som hava funnit kunskap.
Fún olóye gbogbo rẹ̀ ni ó tọ̀nà; wọ́n jẹ́ aláìlẹ́gàn fún gbogbo ẹni tí ó ní ìmọ̀.
10 Så tagen emot min tuktan hellre än silver, och kunskap hellre än utvalt guld.
Yan ẹ̀kọ́ mi dípò fàdákà, ìmọ̀ dípò o wúrà àṣàyàn,
11 Ty visheten är bättre än pärlor; allt vad härligt som finnes går ej upp emot henne.
nítorí ọgbọ́n ṣe iyebíye jù iyùn lọ, kò sí ohun tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ tí a sì le fiwé e.
12 Jag, visheten, är förtrogen med klokheten, och jag råder över eftertänksam insikt.
“Èmi, ọgbọ́n ń gbé pẹ̀lú òye; mo ní ìmọ̀ àti ọgbọ́n-inú.
13 Att frukta HERREN är att hata det onda; ja, högfärd, högmod, en ond vandel och en ränkfull mun, det hatar jag.
Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìkórìíra ibi mo kórìíra ìgbéraga àti agídí, ìwà ibi àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
14 Hos mig finnes råd och utväg; jag är förstånd, hos mig är makt.
Ìmọ̀ràn àti ọgbọ́n tí ó yè kooro jẹ́ tèmi mo ní òye àti agbára.
15 Genom mig regera konungarna och stadga furstarna vad rätt är.
Nípasẹ̀ mi ni ọba ń ṣàkóso tí àwọn aláṣẹ sì ń ṣe òfin tí ó dára.
16 Genom mig härska härskarna och hövdingarna, ja, alla domare på jorden.
Nípasẹ̀ mi àwọn ọmọ-aládé ń ṣàkóso, àti gbogbo ọlọ́lá tí ń ṣàkóso ilẹ̀ ayé.
17 Jag älskar dem som älska mig, och de som söka mig, de finna mig.
Mo fẹ́ràn àwọn tí ó fẹ́ràn mi, àwọn tí ó sì wá mi rí mi.
18 Rikedom och ära vinnas hos mig, ädla skatter och rättfärdighet.
Lọ́dọ̀ mi ni ọrọ̀ àti ọlá wà, ọrọ̀ tí í tọ́jọ́ àti ìgbéga rere.
19 Min frukt är bättre än guld, ja, finaste guld och den vinning jag skänker bättre än utvalt silver.
Èso mi dára ju wúrà dáradára lọ; ohun tí mò ń mú wá ju àṣàyàn fàdákà lọ.
20 På rättfärdighetens väg går jag fram, mitt på det rättas stigar,
Mò ń rìn ní ọ̀nà òdodo, ní ojú ọ̀nà òtítọ́,
21 till att giva dem som älska mig en rik arvedel och till att fylla deras förrådshus.
mò ń fi ọrọ̀ fún gbogbo àwọn tí ó fẹ́ràn mi mo sì ń mú kí ilé ìṣúra wọn kún.
22 HERREN skapade mig såsom sitt förstlingsverk, i urminnes tid, innan han gjorde något annat.
“Èmi ni Olúwa kọ́kọ́ dá nínú iṣẹ́ rẹ̀. Ṣáájú àwọn iṣẹ́ rẹ̀ àtijọ́;
23 Från evighet är jag insatt, från begynnelsen, ända ifrån jordens urtidsdagar.
a ti yàn mí láti ayérayé, láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, kí ayé tó bẹ̀rẹ̀.
24 Innan djupen voro till, blev jag född, innan källor ännu funnos, fyllda med vatten
Nígbà tí kò tí ì sí Òkun, ni a ti bí mi, nígbà tí kò tí ì sí ìsun tí ó ní omi nínú;
25 Förrän bergens grund var lagd, förrän höjderna funnos, blev jag född,
kí a tó fi àwọn òkè sí ipò wọn, ṣáájú àwọn òkè ni a ti bí mi,
26 när han ännu icke hade skapat land och mark, ej ens det första av jordkretsens stoft.
kí ó tó dá ilẹ̀ ayé tàbí àwọn oko rẹ̀ tàbí èyíkéyìí nínú eruku ayé.
27 När han beredde himmelen, var jag tillstädes, när han spände ett valv över djupet,
Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn, nígbà tí ó fi òsùwọ̀n àyíká sórí ibú omi,
28 när han fäste skyarna i höjden, när djupets källor bröto fram med makt,
nígbà tí ó ṣẹ̀dá òfúrufú lókè tí ó sì fi orísun ibú omi sí ipò rẹ̀ láì le è yẹsẹ̀,
29 när han satte för havet dess gräns, så att vattnet icke skulle överträda hans befallning, när han fastställde jordens grundvalar --
nígbà tí ó ṣe ààlà fún omi Òkun kí omi má ba à kọjá ààlà àṣẹ rẹ̀, àti nígbà tí ó pààlà ìpìlẹ̀ ayé.
30 då fostrades jag såsom ett barn hos honom, då hade jag dag efter dag min lust och min lek inför hans ansikte beständigt;
Nígbà náà èmi ni gbẹ́nàgbẹ́nà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ mo kún fún inú dídùn lójoojúmọ́, mo ń yọ̀ nígbà gbogbo níwájú rẹ̀.
31 jag hade min lek på hans jordkrets och min lust bland människors barn.
Mo ń yọ̀ nínú gbogbo àgbáyé tí ó dá mo sì ní inú dídùn sí àwọn ọmọ ènìyàn.
32 Så hören mig nu, I barn, ty saliga äro de som hålla mina vägar.
“Nítorí náà báyìí, ẹ̀yin ọmọ mi, ìbùkún ni fún àwọn tí ó pa ọ̀nà mi mọ́.
33 Hören tuktan, så att I bliven visa, ja, låten henne icke fara.
Fetí sí ìtọ́sọ́nà mi kí o sì gbọ́n; má ṣe pa á tì sápá kan.
34 Säll är den människa som hör mig, så att hon vakar vid mina dörrar dag efter dag och håller vakt vid dörrposterna i mina portar.
Ìbùkún ni fún ẹni tí ó fetísílẹ̀ sí mi, tí ń ṣọ́nà ní ẹnu-ọ̀nà mi lójoojúmọ́, tí ń dúró ní ẹnu-ọ̀nà mi.
35 Ty den som finner mig, han finner livet och undfår nåd från HERREN.
Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi rí ìyè ó sì rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ Olúwa.
36 Men den som går miste om mig han skadar sig själv; alla de som hata mig, de älska döden.
Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti rí ń pa ara rẹ̀ lára gbogbo ẹni tí ó kórìíra mi fẹ́ ikú.”

< Ordspråksboken 8 >