< Mika 2 >

1 Ve dessa som tänka ut vad fördärvligt är och bereda vad ont är på sina läger, och som sätta det i verket, så snart morgonen gryr, allenast det står i deras makt;
Ègbé ni fún àwọn tí ń gbèrò àìṣedéédéé tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ibi lórí ibùsùn wọn! Nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́, wọn yóò gbé e jáde nítorí ó wà ní agbára wọn láti ṣe é.
2 dessa som hava begärelse till sin nästas åkrar och röva dem, eller till hans hus och tillägna sig dem; dessa som öva våld mot både människor och hus, mot både ägare och egendom!
Wọ́n sì ń ṣe ojúkòkòrò oko, wọ́n sì fi agbára wọn gbà wọ́n, àti àwọn ilé, wọ́n sì gbà wọ́n. Wọ́n sì ni ènìyàn àti ilẹ̀ rẹ̀ lára àní ènìyàn àti ohun ìní rẹ̀.
3 Därför säger HERREN så: Se, jag tänker ut mot detta släkte vad ont är; och I skolen icke kunna draga eder hals därur, ej heller skolen I sedan gå så stolta, ty det bliver en ond tid.
Nítorí náà, Olúwa wí pé: “Èmi ń gbèrò ibi sí àwọn ìdílé wọ̀nyí, nínú èyí tí wọn kì yóò le è gba ara wọn là. Ìwọ kì yóò sì lè máa rìn ní ìgbéraga mọ́, nítorí yóò jẹ́ àkókò ibi.
4 På den dagen skall man stämma upp en visa över eder och sjunga en sorgesång; man skall säga: »Det är ute med oss, vi äro förstörda i grund! Mitt folks arvslott bliver nu given åt en annan. Ja i sanning, den ryckes ifrån mig, och åt avfällingar utskiftas våra åkrar.»
Ní ọjọ́ náà ni ẹnìkan yóò pa òwe kan sí yín; wọn yóò sì pohùnréré ẹkún kíkorò pé: ‘Ní kíkó a ti kó wọn tán; Olúwa ti pín ohun ìní àwọn ènìyàn mi; Ó ti mú un kúrò lọ́dọ̀ mi! Ó fi oko wa lé àwọn ọlọ̀tẹ̀ lọ́wọ́.’”
5 Så sker det att hos dig icke mer finnes någon som får spänna mätsnöre över en lott i HERRENS församling.
Nítorí náà, ìwọ kò ní ní ẹnìkankan tí yóò ta okùn nínú ìjọ Olúwa, tí yóò pín ilẹ̀ nípa ìbò.
6 »Hören då upp att predika», så är deras predikan; »om sådant får man icke predika; det är ju ingen ände på smädelser!»
“Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀,” ni àwọn wòlíì wọn wí. “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀ nípa nǹkan wọ̀nyí; kí ìtìjú má ṣe le bá wa.”
7 Är detta ett tillbörligt tal, du Jakobs hus? Har då HERREN varit snar till vrede? Hava hans gärningar visat något sådant? Äro icke fastmer mina ord milda mot den som vandrar redligt?
Ṣé kí á sọ ọ́, ìwọ ilé Jakọbu: “Ǹjẹ́ ẹ̀mí Olúwa ha ń bínú bí? Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ ha nìwọ̀nyí?” “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ mi kò ha ń ṣe rere fún ẹni tí ń rìn déédé bí?
8 Men nu sedan en tid uppreser sig mitt folk såsom en fiende. I sliten manteln bort ifrån kläderna på människor som trygga gå sin väg fram och ej vilja veta av strid.
Láìpẹ́ àwọn ènìyàn mi dìde bí ọ̀tá sí mi. Ìwọ bọ́ aṣọ ọlọ́rọ̀ kúrò lára àwọn tí ń kọjá lọ ní àìléwu, bí àwọn ẹni tí ó padà bọ̀ láti ojú ogun.
9 Mitt folks kvinnor driven I ut från de hem där de hade sin lust; deras barn beröven I för alltid den berömmelse de hade av mig.
Ẹ̀yin sì lé obìnrin àwọn ènìyàn mi kúrò nínú ilé ayọ̀ wọn, ẹ̀yin sì ti gba ògo mi, kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ wọn láéláé.
10 Stån upp och gån eder väg! Här skolen I icke hava någon vilostad, för eder orenhets skull, som drager i fördärv, ja, i gruvligt fördärv.
Ẹ dìde, kí ẹ sì máa lọ! Nítorí èyí kì í ṣe ibi ìsinmi yín, nítorí tí a ti sọ ọ́ di àìmọ́ yóò pa yín run, àní ìparun kíkorò.
11 Om någon som fore med munväder och falskhet sade i sin lögnaktighet: »Jag vill predika för dig om vin och starka drycker» -- det vore en predikare för detta folk!
Tí òpùrọ́ àti ẹlẹ́tàn bá wà tí wọ́n sì wí pé, ‘Èmi yóò sọtẹ́lẹ̀ fún ọ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wáìnì àti ọtí líle,’ òun ni yóò tilẹ̀ ṣe wòlíì àwọn ènìyàn wọ̀nyí!
12 Jag vill församla dig, Jakob, ja, hela ditt folk. Jag vill hämta tillhopa Israels kvarlevor, jag vill föra dem tillsammans såsom fåren till fållan, såsom en hjord till dess betesmark, så att där uppstår ett gny av människor.
“Èmi yóò kó gbogbo yín jọ, ìwọ Jakọbu; Èmi yóò gbá ìyókù Israẹli jọ. Èmi yóò kó wọn jọ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú agbo ẹran, gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nínú agbo wọn, ibẹ̀ yóò sì pariwo nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.
13 En vägbrytare drager ut framför dem; de bryta sig igenom och tåga fram, genom porten vandra de ut. Deras konung tågar framför dem, HERREN går i spetsen för dem.
Ẹni tí ó ń fọ ọ̀nà yóò lọ sókè níwájú wọn; wọn yóò fọ láti ẹnu ibodè, wọn yóò sì jáde lọ. Àwọn ọba wọn yóò sì kọjá lọ níwájú wọn, Olúwa ni yóò sì ṣe olórí wọn.”

< Mika 2 >