< 3 Mosebok 24 >
1 Och HERREN talade till Mose och sade:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Bjud Israels barn att bära till dig ren olja, av stötta oliver, till ljusstaken, så att lamporna dagligen kunna sättas upp.
“Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli láti mú òróró tí ó mọ́ tí a fún láti ara olifi wá láti fi tan iná, kí fìtílà lè máa jò láì kú.
3 Utanför den förlåt som hänger framför vittnesbördet, i uppenbarelsetältet, skall Aron beständigt sköta den, från aftonen till morgonen, inför HERRENS ansikte. Detta skall vara en evärdlig stadga för eder från släkte till släkte.
Lẹ́yìn aṣọ ìkélé ti ibi àpótí ẹ̀rí tí ó wà ní inú àgọ́ ìpàdé, ni kí Aaroni ti tan iná náà níwájú Olúwa, láti ìrọ̀lẹ́ di àárọ̀ lójoojúmọ́. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀.
4 Lamporna på den gyllene ljusstaken skall han beständigt sköta inför HERRENS ansikte.
Àwọn Àtùpà tí wọ́n wà lórí ojúlówó ọ̀pá fìtílà tí a fi wúrà ṣe níwájú Olúwa ni kí ó máa jó lójoojúmọ́.
5 Och du skall taga fint mjöl och därav baka tolv kakor; var kaka skall innehålla två tiondedels efa.
“Mú ìyẹ̀fun dáradára, kí o sì ṣe ìṣù àkàrà méjìlá, kí o lo ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) fún ìṣù kọ̀ọ̀kan.
6 Och du skall lägga upp dem i två rader, sex i var rad, på det gyllene bordet inför HERRENS ansikte.
Tò wọ́n sí ọ̀nà ìlà méjì, mẹ́fà mẹ́fà ní ìlà kọ̀ọ̀kan lórí tábìlì tí a fi ojúlówó wúrà bọ̀. Èyí tí ó wà níwájú Olúwa.
7 Och på vardera raden skall du lägga ren rökelse, för att denna må utgöra själva altaroffret av bröden, ett eldsoffer åt HERREN.
Ẹ fi ojúlówó tùràrí sí ọnà kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ìpín ìrántí láti dípò àkàrà, àti láti jẹ ẹbọ sísun sí Olúwa.
8 Sabbatsdag efter sabbatsdag skall man beständigt lägga upp dem inför HERRENS ansikte: en gärd av Israels barn, till ett evigt förbund.
Àkàrà yìí ni kí ẹ gbé wá síwájú Olúwa nígbàkígbà, lọ́ṣọ̀ọ̀ṣẹ̀, nítorí tí àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí májẹ̀mú ayérayé.
9 De skola tillhöra Aron och hans söner och skola ätas av dem på en helig plats, ty de äro högheliga och äro hans evärdliga rätt av HERRENS eldsoffer.
Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ló ni í. Wọ́n gbọdọ̀ jẹ ẹ́ ní ibi mímọ́ torí pé ó jẹ́ ipa tí ó mọ́ jùlọ ti ìpín wọn ojoojúmọ́ nínú ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa.”
10 Och en man som var son till en israelitisk kvinna, men till fader hade en egyptisk man, gick ut bland Israels barn; och den israelitiska kvinnans son och en israelitisk man kommo i träta med varandra i lägret.
Ọmọkùnrin kan wà tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọ Israẹli baba rẹ̀ sì jẹ́ ará Ejibiti. Ó jáde lọ láàrín àwọn ọmọ Israẹli, ìjà sì ṣẹlẹ̀ nínú àgọ́ láàrín òun àti ọmọ Israẹli kan.
11 Och den israelitiska kvinnans son smädade Namnet och hädade. Då förde de honom fram till Mose. Och hans moder hette Selomit, dotter till Dibri, av Dans stam.
Ọmọkùnrin arábìnrin Israẹli náà sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa pẹ̀lú èpè, wọ́n sì mú un tọ Mose wá. (Orúkọ ìyá rẹ̀ ní Ṣelomiti, ọmọbìnrin Debiri, ti ẹ̀yà Dani.)
12 Och de satte honom i förvar, för att de skulle få hans dom bestämd efter HERRENS befallning.
Wọ́n fi í sínú túbú kí Olúwa to sọ ohun tí wọn yóò ṣe fún wọn.
13 Och HERREN talade till Mose och sade:
Olúwa sì sọ fún Mose pé,
14 För ut hädaren utanför lägret; sedan må alla som hörde det lägga sina händer på hans huvud, och må så hela menigheten stena honom.
“Mú asọ̀rọ̀-òdì náà jáde wá sẹ́yìn àgọ́, kí gbogbo àwọn tí ó gbọ́ pé ó ṣépè gbé ọwọ́ wọn lórí ọkùnrin náà láti fihàn pé ó jẹ̀bi. Lẹ́yìn náà ni kí gbogbo àpéjọpọ̀, sọ ọ́ ní òkúta pa.
15 Och till Israels barn skall du tala och säga: Om någon hädar sin Gud, kommer han att bära på synd.
Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Bí ẹnikẹ́ni bá ṣépè lé Ọlọ́run rẹ̀, yóò jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
16 Och den som smädar HERRENS namn skall straffas med döden; hela menigheten skall stena honom. Evad det är en främling eller en inföding som smädar Namnet, skall han dödas.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa ni kí ẹ pa, kí gbogbo àpéjọpọ̀ sọ ọ́ ní òkúta pa, yálà àlejò ni tàbí ọmọ bíbí Israẹli, bí ó bá ti sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa, pípa ni kí ẹ pa á.
17 Om någon slår ihjäl någon människa, skall han straffas med döden;
“‘Ẹni tí ó bá gba ẹ̀mí ènìyàn pípa ni kí ẹ pa á.
18 och den som slår ihjäl ett boskapsdjur skall ersätta det: liv för liv.
Ẹni tí ó bá gba ẹ̀mí ẹran ọ̀sìn ẹlòmíràn, kí ó dá a padà—ẹ̀mí dípò ẹ̀mí.
19 Och om någon vållar att hans nästa får ett lyte, så skall man göra mot honom såsom han själv har gjort:
Bí ẹnìkan bá pa ẹnìkejì rẹ̀ lára, ohunkóhun tí ó ṣe ni kí ẹ ṣe sí i.
20 bruten lem för bruten lem, öga för öga, tand för tand; samma lyte han har vållat att en annan fick skall han själv få.
Ẹ̀yà fún ẹ̀yà, ojú fún ojú, eyín fún eyín; bí òun ti ṣe àbùkù sí ara ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni kí a ṣe sí i.
21 Den som slår ihjäl ett boskapsdjur skall ersätta det, och den som slår ihjäl en människa skall dödas.
Ẹni tí ó bá sì lu ẹran pa, kí ó sán an padà; ẹni tí ó bá sì lu ènìyàn pa, a ó pa á.
22 En och samma lag skall gälla för eder, den skall gälla lika väl för främlingen som för infödingen; ty jag är HERREN, eder Gud.
Òfin kan náà ló wà fún àlejò àti fún ọmọ Israẹli. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
23 Och Mose talade detta till Israels barn; och de förde ut hädaren utanför lägret och stenade honom. Alltså gjorde Israels barn såsom HERREN hade bjudit Mose. Se Vittnesbördet i Ordförkl. Se Herren i Ordförkl.
Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì mú asọ̀rọ̀-òdì náà lọ sí ẹ̀yìn àgọ́, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa. Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose.