< Domarboken 6 >
1 Men när Israels barn gjorde vad ont var i HERRENS ögon, gav HERREN dem i Midjans hand, i sju år.
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́ fún ọdún méje.
2 Och Midjans hand blev Israel så övermäktig, att Israels barn till skydd mot Midjan gjorde sig de hålor som nu äro att se i bergen, så ock grottorna och bergfästena.
Agbára àwọn ará Midiani sì pọ̀ púpọ̀ lórí àwọn Israẹli, wọ́n sì hùwà ipá sí wọn, nítorí ìdí èyí, àwọn Israẹli sálọ sí àwọn orí òkè, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn nínú ihò àpáta, àti nínú ọ̀gbun àti ní ibi agbára nínú àpáta.
3 Så ofta israeliterna hade sått, drogo midjaniterna, amalekiterna och österlänningarna upp emot dem
Ní ìgbàkúgbà tí àwọn ọmọ Israẹli bá ti gbin ọ̀gbìn wọn, àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti àwọn ará ìlà-oòrùn mìíràn yóò wá láti bá wọn jà.
4 och lägrade sig där och överföllo dem och fördärvade landets gröda ända fram emot Gasa; de lämnade inga livsmedel kvar i Israel, inga får, oxar eller åsnor.
Wọn yóò tẹ̀dó sí orí ilẹ̀ náà, wọn a sì bá irúgbìn wọ̀nyí jẹ́ títí dé Gasa, wọn kì í sì í fi ohun alààyè kankan sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, kì bá à ṣe àgùntàn, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
5 Ty de drogo ditupp med sin boskap och sina tält och kommo så talrika som gräshoppor; de själva och deras kameler voro oräkneliga. Och de föllo in i landet för att fördärva det.
Wọn a máa wá pẹ̀lú ohun ọ̀sìn wọn àti àwọn àgọ́ wọn, wọn a sì dàbí eṣú nítorí i púpọ̀ wọn. Ènìyàn kò sì lè ka iye àwọn ènìyàn náà bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìbákasẹ, wọ́n pọ̀ dé bi pé wọn kò ṣe é kà ní iye, wọn a bo ilẹ̀ náà wọn a sì jẹ ẹ́ run.
6 Så kom Israel i stort elände genom Midjan; då ropade Israels barn till HERREN.
Àwọn ará Midiani sì pọ́n àwọn ọmọ Israẹli lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòṣì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
7 Och när Israels barn ropade till HERREN för Midjans skull,
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Midiani.
8 sände HERREN en profet till Israels barn. Denne sade till dem: »Så säger HERREN, Israels Gud: Jag själv har fört eder upp ur Egypten och hämtat eder ut ur träldomshuset.
Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: mo mú yín gòkè ti Ejibiti wá, láti oko ẹrú.
9 Jag har räddat eder från egyptiernas hand och från alla edra förtryckares hand; jag har förjagat dem för eder och givit eder deras land.
Mo gbà yín kúrò nínú agbára Ejibiti àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
10 Och jag sade till eder: Jag är HERREN, eder Gud; I skolen icke frukta de gudar som dyrkas av amoréerna, i vilkas land I bon. Men I villen icke höra min röst.
Mo wí fún un yín pé, ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín; ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé.’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́rọ̀ sí ohun tí mo sọ.”
11 Och HERRENS ängel kom och satte sig under terebinten vid Ofra, som tillhörde abiesriten Joas; dennes son Gideon höll då på att klappa ut vete i vinpressen, för att bärga det undan Midjan.
Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù Ofira èyí ti ṣe ti Joaṣi ará Abieseri, níbi tí Gideoni ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọntí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Midiani.
12 För honom uppenbarade sig nu HERRENS ängel och sade till honom: »HERREN är med dig, du tappre stridsman.»
Nígbà tí angẹli Olúwa fi ara han Gideoni, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”
13 Gideon svarade honom: »Ack min herre, om HERREN är med oss, varför har då allt detta kommit över oss? Och var äro alla hans under, om vilka våra fäder hava förtäljt för oss och sagt: 'Se, HERREN har fört oss upp ur Egypten'? Nu har ju HERREN förskjutit oss och givit oss i Midjans våld.»
Gideoni dáhùn pé, “Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, ‘Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá?’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́.”
14 Då vände sig HERREN till honom och sade: »Gå åstad i denna din kraft och fräls Israel ur Midjans våld; se, jag har sänt dig.»
Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Israẹli sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Midiani. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”
15 Han svarade honom: »Ack Herre, varmed kan jag frälsa Israel? Min ätt är ju den oansenligaste i Manasse, och jag själv den ringaste i min faders hus.»
Gideoni sì dáhùn pé, “Yéè olúwa mi, ọ̀nà wo ni èmi yóò fi gba Israẹli là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Manase, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé baba mi.”
16 HERREN sade till honom: »Jag vill vara med dig, så att du skall slå Midjan, såsom voro det en enda man.»
Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Midiani láì ku ẹnìkankan.”
17 Men han svarade honom: »Om jag har funnit nåd för dina ögon, så låt mig få ett tecken att det är du som talar med mig.
Gideoni sì dáhùn pé, nísinsin yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.
18 Gå icke bort härifrån, förrän jag har kommit tillbaka till dig och hämtat ut min offergåva och lagt fram den för dig.» Han sade: »Jag vill stanna, till dess du kommer igen.»
Jọ̀wọ́ má ṣe kúrò níbí títí èmi yóò fi mú ọrẹ wá fún ọ kí n sì gbé e sí iwájú rẹ. Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò dúró títí ìwọ yóò fi dé.”
19 Då gick Gideon in och tillredde en killing, så ock osyrat bröd av en efa mjöl; därefter lade han köttet i en korg och hällde spadet i en kruka; sedan bar han ut det till honom under terebinten och satte fram det.
Gideoni sì yára wọ ilé lọ, ó sì pa ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan, wọ́n sì sè é, ó sì mú ìyẹ̀fun efa kan, ó fi ṣe àkàrà aláìwú. Ó gbé ẹran náà sínú agbọ̀n, ṣùgbọ́n ó fi ọbẹ̀ rẹ̀ sínú ìkòkò, ó gbé wọn jáde tọ angẹli náà wá bí ọrẹ lábẹ́ igi óákù.
20 Men Guds ängel sade till honom: Tag köttet och det osyrade brödet, och lägg det på berghällen där, och gjut spadet däröver.» Och han gjorde så.
Angẹli Ọlọ́run náà sì wí fún un pé, “Gbé ẹran náà àti àkàrà àìwú náà, sí orí àpáta yìí, kí o sì da omi ọbẹ̀ rẹ̀ sí orí rẹ̀.” Gideoni sì ṣe bẹ́ẹ̀.
21 Och HERRENS ängel räckte ut staven som han hade i sin hand och rörde med dess ända vid köttet och det osyrade brödet; då kom eld ut ur klippan och förtärde köttet och det osyrade brödet; och därvid försvann HERRENS ängel ur hans åsyn.
Angẹli Olúwa sì fi orí ọ̀pá tí ó wà ní ọwọ́ rẹ̀ kan ẹran àti àkàrà àìwú náà. Iná sì jáde láti inú àpáta, ó sì jó ẹran àti àkàrà náà, kò sì rí angẹli náà mọ́.
22 Då såg Gideon att det var HERRENS ängel. Och Gideon sade: »Ve mig, Herre, HERRE, eftersom jag nu har sett HERRENS ängel ansikte mot ansikte!»
Nígbà tí Gideoni sì ti mọ̀ dájúdájú pé angẹli Olúwa ni, ó ké wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Mo ti rí angẹli Olúwa ní ojúkorojú!”
23 Men HERREN sade till honom: »Frid vare med dig, frukta icke; du skall icke dö.»
Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Àlàáfíà! Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ kì yóò kùú.”
24 Då byggde Gideon där ett altare åt HERREN och kallade det HERREN är frid; det finnes kvar ännu i dag i det abiesritiska Ofra.
Báyìí ni Gideoni mọ pẹpẹ kan fún Olúwa níbẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní “Àlàáfíà ni Olúwa.” Ó sì wà ní Ofira ti Abieseri títí di òní.
25 Den natten sade HERREN till honom: »Tag den tjur som tillhör din fader och den andra sjuåriga tjuren. Riv sedan ned det Baalsaltare som tillhör din fader, och hugg sönder Aseran som står därinvid.
Ní òru ọjọ́ náà Olúwa wí fún un pé, mú akọ màlúù baba rẹ, àní akọ màlúù kejì ọlọ́dún méje. Wó pẹpẹ Baali baba rẹ lulẹ̀, kí o sì bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ lulẹ̀.
26 Bygg därefter upp ett altare åt HERREN, din Gud, överst på denna fasta plats, och uppför det på övligt sätt; tag så den andra tjuren och offra den till brännoffer på styckena av Aseran som du har huggit sönder.»
Lẹ́yìn èyí kí o wá mọ pẹpẹ èyí tí ó yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ lórí òkè yìí. Kí o sì mú akọ màlúù kejì, kí o sì mú igi ère òrìṣà Aṣerah tí ìwọ bẹ́ lulẹ̀ rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
27 Då tog Gideon tio av sina tjänare med sig och gjorde såsom HERREN sade sagt till honom. Men eftersom han fruktade att göra det om dagen, av rädsla för sin faders hus och för männen i staden, gjorde han det om natten.
Gideoni mú mẹ́wàá nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún un ṣùgbọ́n, nítorí ó bẹ̀rù àwọn ará ilé baba rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ìlú náà kò ṣe é ní ọ̀sán, òru ni ó ṣe.
28 Bittida följande morgon fingo mannen i staden se att Baals altare låg nedbrutet, att Aseran därinvid var sönderhuggen, och att den andra tjuren hade blivit offrad såsom brännoffer på det nyuppbyggda altaret.
Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ kejì mọ́, tí àwọn ènìyàn ìlú náà jí, wọ́n rí i pé àti fọ́ pẹpẹ Baali àti pé a ti bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, a sì ti fi akọ màlúù kejì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ.
29 Då sade de till varandra: »Vem har gjort detta?» Och när de frågade och gjorde efterforskningar, fingo de veta att Gideon, Joas' son, hade gjort det.
Àwọn ènìyàn ìlú náà bi ara wọn wí pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Lẹ́yìn tí wọn fi ara balẹ̀ ṣe ìwádìí, wọ́n gbọ́ wí pé, “Gideoni ọmọ Joaṣi ni ó ṣe é.”
30 Då sade männen i staden till Joas: »För din son hitut, han måste dö; ty han har brutit ned Baals altare, och han har ock huggit sönder Aseran som stod därinvid.»
Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì wí fún Joaṣi wí pé, “Mú ọmọ rẹ jáde wá. Ó ní láti kú nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali lulẹ̀ ó sì ti ké ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀bá rẹ̀ lulẹ̀.”
31 Men Joas svarade alla som stodo omkring honom: »Viljen I utföra Baals sak, viljen I komma honom till hjälp? Den som vill utföra hans sak, han skall bliva dödad innan nästa morgon. Är han Gud, så utföre han själv sin sak, eftersom denne har brutit ned hans altare.
Ṣùgbọ́n Joaṣi bi àwọn èrò tí wọ́n fi ìbínú dúró tì í wí pé, “Ẹ̀yin yóò ha gbìjà Baali bí? Ẹ̀yin yóò ha gbà á sílẹ̀ bí? Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbìjà rẹ̀ kíkú ni olúwa rẹ̀ yóò kú ní òwúrọ̀. Bí Baali bá ṣe Ọlọ́run nítòótọ́ yóò jà fún ara rẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá wó pẹpẹ rẹ̀ lulẹ̀.”
32 Härav kallade man honom då Jerubbaal, i det man sade: »Baal utföre sin sak mot honom, eftersom han har brutit ned hans altare.»
Fún ìdí èyí ní ọjọ́ náà wọ́n pe Gideoni ní “Jerubbaali” wí pé, “Jẹ́ kí Baali bá a jà,” nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali.
33 Och midjaniterna, amalekiterna och österlänningarna hade alla tillhopa församlat sig och gått över floden och lägrat sig i Jisreels dal.
Láìpẹ́ jọjọ, àwọn ogun àwọn Midiani, ti àwọn Amaleki àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà-oòrùn yòókù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jordani wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jesreeli.
34 Men Gideon hade blivit beklädd med HERRENS Andes kraft; han stötte i basun, och abiesriterna församlade sig och följde efter honom.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gideoni, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Abieseri láti tẹ̀lé òun.
35 Och han sände omkring budbärare i hela Manasse, så att ock de övriga församlade sig och följde efter honom; likaledes sände han budbärare till Aser, Sebulon och Naftali, och dessa drogo då också upp, de andra till mötes.
Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Manase já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Aṣeri, Sebuluni àti Naftali gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.
36 Och Gideon sade till Gud: »Om du verkligen vill genom min hand frälsa Israel, såsom du har lovat,
Gideoni wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—
37 så se nu här: jag lägger denna avklippta ull på tröskplatsen; ifall dagg kommer allenast på ullen, under det att marken eljest överallt förbliver torr, då vet jag att du genom min hand skall frälsa Israel, såsom du har lovat.»
kíyèsi, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá sẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yòókù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”
38 Och det skedde så, ty när han bittida dagen därefter kramade ur ullen, kunde han av den pressa ut så mycket dagg, att en hel skål blev full med vatten.
Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gideoni jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì fún irun àgùntàn náà, ọpọ́n omi kan sì kún.
39 Men Gideon sade till Gud: »Må din vrede icke upptändas mot mig, därför att jag talar ännu en enda gång. Låt mig få försöka blott en gång till med ullen: gör nu så, att allenast ullen förbliver torr, under det att dagg kommer eljest överallt på marken.»
Gideoni sì tún wí fún Ọlọ́run pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan sí i. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”
40 Och Gud gjorde så den natten; allenast ullen var torr, men eljest hade dagg kommit överallt på marken. Hebr jareb.
Ní òru náà Ọlọ́run ṣe bẹ́ẹ̀, awọ irun àgùntàn nìkan ni ó gbẹ; gbogbo ilẹ̀ yòókù sì tutù nítorí ìrì.