< Domarboken 11 >

1 Gileaditen Jefta var en tapper stridsman, men han var son till en sköka; och Jeftas fader var Gilead.
Jefta ará Gileadi jẹ́ akọni jagunjagun. Gileadi ni baba rẹ̀; ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ jẹ́ panṣágà.
2 Nu födde ock Gileads hustru honom söner; och när dessa hans hustrus söner hade växt upp, drevo de ut Jefta och sade till honom: »Du skall icke taga arv i vår faders hus, ty du är son till en kvinna som icke är hans hustru.»
Ìyàwó Gileadi sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un, nígbà tí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí dàgbà, wọ́n rán Jefta jáde kúrò nílé, wọ́n wí pé, “Ìwọ kì yóò ní ogún kankan ní ìdílé wa, nítorí pé ìwọ jẹ́ ọmọ obìnrin mìíràn.”
3 Då flydde Jefta bort ifrån sina bröder och bosatte sig i landet Tob; där sällade sig löst folk till Jefta och gjorde strövtåg med honom.
Jefta sì sá kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì pàgọ́ sí ilẹ̀ Tobu, ó sì ń gbé níbẹ̀, níbẹ̀ ni àwọn ènìyàn kan ti ń tẹ òfin lójú parapọ̀ láti máa tẹ̀lé e kiri.
4 Någon tid därefter gåvo Ammons barn sig i strid med Israel.
Ní àsìkò kan, nígbà tí àwọn ará Ammoni dìde ogun sí àwọn Israẹli,
5 Men när Ammons barn gåvo sig i strid med Israel, gingo de äldste i Gilead åstad för att hämta Jefta från landet Tob
Ó sì ṣe nígbà tí àwọn Ammoni bá Israẹli jagun, àwọn àgbàgbà Gileadi tọ Jefta lọ láti pè é wá láti ilẹ̀ Tobu.
6 Och de sade till Jefta: »Kom och bliv vår anförare, så vilja vi strida mot Ammons barn.»
Wọ́n wí fún Jefta wí pé, “Wá kí o sì jẹ́ olórí ogun wa kí a lè kọjú ogun sí àwọn ará Ammoni.”
7 Men Jefta svarade de äldste i Gilead: »I haven ju hatat mig och drivit mig ut ur min faders hus. Huru kunnen I då nu, när I ären i nöd, komma till mig?»
Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Ṣé kì í ṣe pé ẹ kórìíra mi tí ẹ sì lé mi kúrò ní ilé baba mi? Kí ló dé tí ẹ fi tọ̀ mí wá báyìí nígbà tí ẹ wà nínú wàhálà?”
8 De äldste i Gilead sade till Jefta: »Just därför hava vi nu kommit tillbaka till dig, och du måste gå med oss och strida mot Ammons barn; ty du skall bliva hövding över oss, alla Gileads inbyggare.»
Àwọn àgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Nítorí rẹ̀ ni àwa fi yípadà sí ọ báyìí: tẹ̀lé wa, kí a lè dojú ìjà kọ àwọn ará Ammoni, ìwọ yóò sì jẹ olórí wa àti gbogbo àwa tí ń gbé ní Gileadi.”
9 Jefta svarade de äldste i Gilead: »Om I nu fören mig tillbaka för att strida mot Ammons barn och HERREN giver dem i mitt våld, så vill jag ock sedan vara eder hövding.»
Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Bí ẹ̀yin bá mú mi padà láti bá àwọn ará Ammoni jà àti tí Olúwa bá fi wọ́n lé mi lọ́wọ́: ṣe èmi yóò jẹ́ olórí yín nítòótọ́?”
10 Då sade de äldste i Gilead till Jefta: »HERREN höre vårt avtal. Förvisso skola vi låta det bliva så om du har sagt.»
Àwọn àgbàgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Àwa fi Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí: àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá wí.”
11 Så gick då Jefta med de äldste i Gilead, och folket satte honom till hövding och anförare över sig. Och Jefta uttalade inför HERREN i Mispa allt vad han hade sagt.
Jefta sì tẹ̀lé àwọn àgbàgbà Gileadi lọ, àwọn ènìyàn náà sì fi ṣe olórí àti ọ̀gágun wọn. Jefta sì tún sọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ níwájú Olúwa ní Mispa.
12 Och Jefta skickade sändebud till Ammons barns konung och lät säga: »Vad har du med mig att göra, eftersom du har kommit emot mig och angripit mitt land?»
Jefta sì rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba àwọn ará Ammoni pé, “Kí ni ẹ̀sùn tí o ní sí wa láti fi kàn wá tí ìwọ fi dojú ìjà kọ ilẹ̀ wa?”
13 Då svarade Ammons barns konung Jeftas sändebud: »När Israel drog upp från Egypten, togo de ju mitt land från Arnon ända till Jabbok och till Jordan; så giv mig nu detta tillbaka i godo.»
Ọba àwọn Ammoni dá àwọn oníṣẹ́ Jefta lóhùn pé, “Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli jáde ti Ejibiti wá. Wọ́n gba ilẹ̀ mi láti Arnoni dé Jabbok, àní dé Jordani, nítorí náà dá wọn padà lọ ní àlàáfíà àti ní pẹ̀lẹ́ kùtù.”
14 Åter skickade Jefta sändebud till Ammons barns konung
Jefta sì tún ránṣẹ́ padà sí ọba àwọn ará Ammoni
15 och lät säga till honom: »Så säger Jefta: Israel har icke tagit något land vare sig från Moab eller från Ammons barn.
ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Jefta wí: àwọn ọmọ Israẹli kò gba ilẹ̀ Moabu tàbí ilẹ̀ àwọn ará Ammoni.
16 Ty när de drogo upp från Egypten och Israel hade tågat genom öknen ända till Röda havet och sedan kommit till Kades,
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde kúrò ní Ejibiti àwọn ọmọ Israẹli la aginjù kọjá lọ sí ọ̀nà Òkun Pupa wọ́n sì lọ sí Kadeṣi.
17 skickade Israel sändebud till konungen i Edom och lät säga: 'Låt mig tåga genom ditt land.' Men konungen i Edom hörde icke därpå. De skickade ock till konungen i Moab, men denne ville icke heller Då stannade Israel i Kades.
Nígbà náà Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba Edomu pé, ‘Gbà fún wa láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kọjá,’ ṣùgbọ́n ọba Edomu kò fetí sí wọn. Wọ́n tún ránṣẹ́ sí ọba Moabu bákan náà òun náà kọ̀. Nítorí náà Israẹli dúró sí Kadeṣi.
18 Därefter tågade de genom öknen och gingo omkring Edoms land och Moabs land och kommo öster om Moabs land och lägrade sig på andra sidan Arnon; de kommo icke in på Moabs område, ty Arnon är Moabs gräns.
“Wọ́n rin aginjù kọjá, wọ́n pẹ́ àwọn ilẹ̀ Edomu àti ti Moabu sílẹ̀, nígbà tí wọ́n gba apá ìlà-oòrùn Moabu, wọ́n sì tẹ̀dó sí apá kejì Arnoni. Wọn kò wọ ilẹ̀ Moabu, nítorí pé ààlà rẹ̀ ni Arnoni wà.
19 Sedan skickade Israel sändebud till Sihon, amoréernas konung, konungen i Hesbon; och Israel lät säga till honom: 'Låt oss genom ditt land tåga dit vi skola.'
“Nígbà náà ni Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ń ṣe àkóso ní Heṣboni, wọ́n sì wí fún un pé, ‘Jẹ́ kí a la ilẹ̀ rẹ kọjá lọ sí ibùgbé wa.’
20 Men Sihon litade icke på Israel och lät dem icke tåga genom sitt land, utan församlade allt sitt folk, och de lägrade sig i Jahas; där in- lät han sig i strid med Israel.
Ṣùgbọ́n Sihoni kò gba Israẹli gbọ́ (kò fọkàn tán an) láti jẹ́ kí ó kọjá. Ó kó gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ jọ, ó sì tẹ̀dó sí Jahisa láti bá Israẹli jagun.
21 Men HERREN, Israels Gud, gav Sihon och allt hans folk i Israels hand, så att de slogo dem; och Israel intog hela amoréernas land, ty dessa bodde då i detta land.
“Olúwa Ọlọ́run Israẹli sì fi Sihoni àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lé Israẹli lọ́wọ́, wọ́n sì ṣẹ́gun wọn. Israẹli sì gba gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Amori tí wọ́n ń gbé ní agbègbè náà,
22 De intogo hela amoréernas område, från Arnon ända till Jabbok, och från öknen ända till Jordan.
wọ́n gbà gbogbo agbègbè àwọn ará Amori, láti Arnoni tí ó fi dé Jabbok, àti láti aginjù dé Jordani.
23 Och nu, då HERREN, Israels Gud, har fördrivit amoréerna för sitt folk Israel, skulle du taga deras land i besittning!
“Wàyí o, nígbà tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti lé àwọn ará Amori kúrò níwájú àwọn ènìyàn rẹ̀; Israẹli, ẹ̀tọ́ wo ni ẹ ní láti gba ilẹ̀ náà?
24 Är det icke så: vad din gud Kemos giver dig till besittning, det tager du i besittning? Så taga ock vi, närhelst HERREN, vår Gud, fördriver ett folk för oss, deras land i besittning.
Ǹjẹ́ ìwọ kì yóò ha gba èyí tí Kemoṣi òrìṣà rẹ fi fún ọ? Bákan náà àwa yóò gba èyíkéyìí tí Olúwa Ọlọ́run wa fi fún wa.
25 Menar du att du är så mycket förmer än Balak, Sippors sons konungen i Moab? Han dristade ju icke att inlåta sig i tvist med Israel eller giva sig i strid med dem.
Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu lọ? Ǹjẹ́ òun ha ṣe gbólóhùn asọ̀ pẹ̀lú Israẹli bí? Tàbí òun dojú ìjà kọ wọ́n rí bí?
26 När Israel nu i tre hundra år har bott i Hesbon och underlydande orter, i Aror och underlydande orter och i alla städer på båda sidor om Arnon, varför haven I då under hela den tiden icke tagit detta ifrån oss?
Fún ọ̀ọ́dúnrún ọdún ni Israẹli fi ṣe àtìpó ní Heṣboni, Aroeri àti àwọn ìgbèríko àti àwọn ìlú tí ó yí Arnoni ká. Èéṣe tí ìwọ kò fi gbà wọ́n padà ní àsìkò náà?
27 Jag har icke försyndat mig mot dig, men du gör illa mot mig, då du nu överfaller mig. HERREN, domaren, må i dag döma mellan Israels barn och Ammons barn.»
Èmi kọ́ ni ó ṣẹ̀ ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ ni ó ṣẹ̀ mí nípa kíkógun tọ̀ mí wá. Jẹ́ kí Olúwa olùdájọ́, ṣe ìdájọ́ lónìí láàrín àwọn ọmọ Israẹli àti àwọn ará Ammoni.”
28 Men Ammons barns konung hörde icke på vad Jefta lät säga honom genom sändebuden.
Ṣùgbọ́n ọba àwọn Ammoni kò fetí sí iṣẹ́ tí Jefta rán sí i.
29 Då kom HERRENS Ande över Jefta; och han tågade genom Gilead och Manasse och tågade så genom Mispe i Gilead, och från Mispe i Gilead tågade han fram mot Ammons barn.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jefta òun sì la Gileadi àti Manase kọjá. Ó la Mispa àti Gileadi kọjá láti ibẹ̀, ó tẹ̀síwájú láti bá àwọn ará Ammoni jà.
30 Och Jefta gjorde ett löfte åt HERREN och sade: »Om du giver Ammons barn i min hand,
Jefta sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí ìwọ bá fi àwọn ará Ammoni lé mi lọ́wọ́,
31 så lovar jag att vadhelst som ur dörrarna till mitt hus går ut emot mig, när jag välbehållen kommer tillbaka från Ammons barn, det skall höra HERREN till, och det skall jag offra till brännoffer.»
yóò sì ṣe, ohunkóhun tí ó bá jáde láti ẹnu-ọ̀nà ilé mi láti wá pàdé mi, nígbà tí èmi bá ń padà bọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ammoni ní àlàáfíà, yóò jẹ́ ti Olúwa, èmi yóò sì fi rú ẹbọ bí ọrẹ ẹbọ sísun.”
32 Så drog nu Jefta åstad mot Ammons barn för att strida mot dem; och HERREN gav dem i hans hand.
Jefta sì jáde lọ láti bá àwọn ará Ammoni jagun, Olúwa sì fi wọ́n lé e lọ́wọ́.
33 Och han tillfogade dem ett mycket stort nederlag och intog landet från Aroer ända till fram emot Minnit, tjugu städer, och ända till Abel-Keramim. Alltså blevo Ammons barn kuvade under Israels barn.
Òun sì ṣẹ́gun wọn, ó sì pa wọ́n ní à pa tán láti Aroeri títí dé agbègbè Minniti, ó jẹ́ ogún ìlú, títí dé Abeli-Keramimu. Báyìí ni Israẹli ti ṣẹ́gun àwọn ará Ammoni.
34 När sedan Jefta kom hem till sitt hus i Mispa, då gick hans dotter ut emot honom med pukor och dans. Och hon var hans enda barn, han hade utom henne varken son eller dotter.
Nígbà tí Jefta padà sí ilé rẹ̀ ní Mispa, wò ó, ọmọ rẹ̀ obìnrin ń jáde bọ̀ wá pàdé rẹ̀ pẹ̀lú timbrili àti ijó. Òun ni ọmọ kan ṣoṣo tí ó ní: kò ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn yàtọ̀ sí òun nìkan.
35 I detsamma han nu fick se henne, rev han sönder sina kläder och ropade: »Ve mig, min dotter, du kommer mig att sjunka till jorden, du drager olycka över mig! Ty jag har öppnat min mun inför HERREN till ett löfte och kan icke taga mitt ord tillbaka.»
Ní ìgbà tí ó rí i ó fa aṣọ rẹ̀ ya ní ìbànújẹ́, ó sì ké wí pé, “Háà! Ọ̀dọ́mọbìnrin mi, ìwọ fún mi ní ìbànújẹ́ ọkàn ìwọ sì rẹ̀ mí sílẹ̀ gidigidi, nítorí pé èmi ti ya ẹnu mi sí Olúwa ní ẹ̀jẹ́, èmi kò sì le sẹ́ ẹ̀jẹ́ mi.”
36 Hon svarade honom: »Min fader, har du öppnat din mun inför HERREN, så gör med mig enligt din muns tal, eftersom HERREN nu har skaffat dig hämnd på dina fiender, Ammons barn.»
Ọmọ náà sì dáhùn pé, “Baba mi bí ìwọ bá ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa, ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ, ní báyìí tí Olúwa ti gba ẹ̀san fún ọ lára àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ará Ammoni.
37 Och hon sade ytterligare till sin fader: »Uppfyll dock denna min begäran: unna mig två månader, så att jag får gå åstad ned på bergen och begråta min jungfrudom med mina väninnor.
Ṣùgbọ́n yọ̀ǹda ìbéèrè kan yìí fún mi, gbà mí láààyè oṣù méjì láti rìn ká orí àwọn òkè, kí n sọkún pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ mi torí mo jẹ́ wúńdíá tí n kò sì ní lè ṣe ìgbéyàwó.”
38 Han svarade: »Du får gå åstad.» Och han tillstadde henne att vara borta i två månader. Då gick hon åstad med sina väninnor och begrät sin jungfrudom på bergen.
Jefta dá lóhùn pé, “Ìwọ lè lọ.” Ó sì gbà á láààyè láti lọ fún oṣù méjì. Òun àti àwọn ọmọbìnrin yòókù lọ sí orí àwọn òkè, wọ́n sọkún nítorí pé kì yóò lè ṣe ìgbéyàwó.
39 Men efter två månader vände hon tillbaka till sin fader, och han förfor då med henne efter det löfte han hade gjort. Och hon hade icke känt någon man.
Lẹ́yìn oṣù méjì náà, ó padà tọ baba rẹ̀ wá òun sì ṣe sí i bí ẹ̀jẹ́ tí ó ti jẹ́. Ọmọ náà sì jẹ́ wúńdíá tí kò mọ ọkùnrin rí. Èyí sì bẹ̀rẹ̀ àṣà kan ní Israẹli
40 Sedan blev det en sedvänja i Israel att Israels döttrar år efter år gingo åstad för att lovprisa gileaditen Jeftas dotter, under fyra dagar vart år.
wí pé ní ọjọ́ mẹ́rin láàrín ọdún àwọn obìnrin Israẹli a máa lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti ṣe ìrántí ọmọbìnrin Jefta ti Gileadi.

< Domarboken 11 >