< Josua 23 >

1 En lång tid härefter, när HERREN hade låtit Israel få ro för alla dess fiender runt omkring, och då Josua var gammal och kommen till hög ålder,
Lẹ́yìn ọjọ́ pípẹ́, nígbà tí Olúwa sì ti fún Israẹli ní ìsinmi kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká, nígbà náà Joṣua sì ti di arúgbó.
2 kallade han till sig hela Israel, dess äldste, dess huvudmän, dess domare och tillsyningsmän och sade till dem: »Jag är nu gammal och kommen till hög ålder.
Ó sì pe gbogbo Israẹli jọ: àgbàgbà wọn, olórí wọn, adájọ́ àti àwọn ìjòyè, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti pọ̀ ní ọdún èmi ti di arúgbó.
3 Och I haven själva sett allt vad HERREN, eder Gud, gjorde med alla dessa folk, när I drogen härin, ty HERREN eder Gud, stridde själv för eder.
Ẹ̀yin tìkára yín sì ti rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí nítorí yín, Olúwa Ọlọ́run yín ni ó jà fún yín.
4 Se, dessa folk som ännu äro kvar har jag genom lottkastning fördelat åt eder till arvedel, efter edra stammar, allt ifrån Jordan intill Stora havet västerut, för att icke nämna alla de folk jag har utrotat.
Ẹ rántí bí mo ṣe pín ogún ìní fún àwọn ẹ̀yà yín ní ilẹ̀ orílẹ̀-èdè gbogbo tí ó kù; àwọn orílẹ̀-èdè tí mo ti ṣẹ́gun ní àárín Jordani àti Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
5 Och HERREN, eder Gud, skall själv driva dem undan för eder och förjaga dem för eder, så att I skolen taga deras land i besittning, såsom HERREN, eder Gud, har lovat eder.
Olúwa Ọlọ́run yín fúnra rẹ̀ yóò lé wọn jáde kúrò ní ọ̀nà yín, yóò sì tì wọ́n jáde ní iwájú yín, ẹ̀yin yóò sì gba ilẹ̀ ìní wọn, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún yín.
6 Men varen I nu ståndaktiga i att hålla och göra allt vad som är föreskrivet i Moses lagbok, så att I icke viken av därifrån vare sig till höger eller till vänster,
“Ẹ jẹ́ alágbára gidigidi, kí ẹ sì ṣọ́ra láti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun tí a kọ sí inú ìwé òfin Mose, láìyí padà sí ọ̀tún tàbí sí òsì.
7 och icke träden i gemenskap med dessa folk som ännu äro kvar här jämte eder, ej heller nämnen deras gudars namn eller svärjen vid dem eller tjänen och tillbedjen dem.
Ẹ má ṣe ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ṣẹ́kù láàrín yín; ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà wọn tàbí kí ẹ fi wọ́n búra. Ẹ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n tàbí ki ẹ tẹríba fún wọn.
8 Nej, till HERREN, eder Gud, skolen I hålla eder, såsom I haven gjort ända till denna dag,
Ṣùgbọ́n ẹ di Olúwa Ọlọ́run yín mú ṣinṣin gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ń ṣe tẹ́lẹ̀ títí di àkókò yìí.
9 varför ock HERREN har fördrivit för eder stora och mäktiga folk, så att ingen har kunnat stå eder emot ända till denna dag.
“Olúwa ti lé àwọn orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára kúrò níwájú yín; títí di òní yìí kò sí ẹnìkan tí ó le dojúkọ yín.
10 En enda man bland eder jagade tusen framför sig, ty HERREN, eder Gud, stridde själv för eder, såsom han hade lovat eder.
Ọ̀kan nínú yín lé ẹgbẹ̀rún ọ̀tá, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín jà fún yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí.
11 Så haven nu noga akt på eder själva, så att I älsken HERREN, eder Gud.
Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ ṣọ́ra gidigidi láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín.
12 Ty om I vänden eder bort ifrån honom, och hållen eder till återstoden av dessa folk som ännu äro kvar här jämte eder, och befrynden eder med dem, så att I träden i gemenskap med dem och de med eder,
“Ṣùgbọ́n bí ẹ bá yí padà, tí ẹ sì gba ìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú àwọn tó ṣẹ́kù lára àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù láàrín yín, tí ẹ sì ń fọmọ fún ara yín ní ìyàwó, tí ẹ sì bá wọn ní àjọṣepọ̀.
13 då mån I förvisso veta att HERREN, eder Gud, icke mer skall fördriva dessa folk undan för eder, utan de skola bliva eder till en snara och ett giller och bliva ett gissel för edra sidor och taggar i edra ögon, till dess I bliven utrotade ur detta goda land, som HERREN, eder Gud, har givit eder.
Nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ dájú pé Olúwa Ọlọ́run yín kì yóò lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde mọ́ kúrò níwájú yín. Dípò èyí, wọn yóò jẹ́ ìkẹ́kùn àti tàkúté fún un yín, pàṣán ní ẹ̀yin yín àti ẹ̀gún ní ojú yín, títí ẹ ó fi ṣègbé kúrò ní ilẹ̀ dáradára yí, èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fi fún yín.
14 Se, jag går nu all världens väg. Så besinnen då av allt edert hjärta och av all eder själ att intet har uteblivit av allt det goda som HERREN, eder Gud, har lovat angående eder; det har allt gått i fullbordan för eder, intet därav har uteblivit.
“Nísinsin yìí èmi ti fẹ́ máa lọ sí ibi tí àwọn àgbà ń rè. Ẹ mọ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti àyà yín pé, kò sí ohun kan tí ó kùnà nínú àwọn ìlérí rere gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín. Gbogbo ìlérí tó ti ṣe kò sí ọ̀kan tí ó kùnà.
15 Men likasom allt det goda som HERREN, eder Gud, lovade eder har kommit över eder, så skall ock HERREN låta allt det onda komma över eder, till dess han har förgjort eder ur detta goda land, som HERREN, eder Gud, har givit eder.
Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí ìlérí dáradára gbogbo ti Olúwa Ọlọ́run yín ti wá sí ìmúṣẹ, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò mú ibi gbogbo tí ó ti kìlọ̀ wá sí orí yín, títí yóò fi pa yín run kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.
16 Om I nämligen överträden HERRENS, eder Guds, förbund, det som han har stadgat för eder, och gån åstad och tjänen andra gudar och tillbedjen dem, så skall HERRENS vrede upptändas mot eder, och I skolen med hast bliva utrotade ur det goda land som han har givit eder.»
Bí ẹ bá sẹ̀ sí májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín, èyí tí ó pàṣẹ fún un yín, tí ẹ bá sì lọ tí ẹ sì sin àwọn òrìṣà tí ẹ sì tẹ orí ba fún wọn, ìbínú gbígbóná Olúwa yóò wá sórí i yín, ẹ̀yin yóò sì ṣègbé kíákíá kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.”

< Josua 23 >