< Job 20 >
1 Därefter tog Sofar från Naama till orda och sade:
Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé,
2 På sådant tal giva mina tankar mig ett svar, än mer, då jag nu är så upprörd i mitt inre.
“Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn, àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.
3 Smädlig tillrättavisning måste jag höra, och man svarar mig med munväder på förståndigt tal.
Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye mi sì dá mi lóhùn.
4 Vet du då icke att så har varit från evig tid, från den stund då människor sattes på jorden:
“Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́, láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,
5 att de ogudaktigas jubel varar helt kort och den gudlöses glädje ett ögonblick?
pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni, àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?
6 Om än hans förhävelse stiger upp till himmelen och hans huvud når intill molnen,
Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run, ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;
7 Så förgås han dock för alltid och aktas lik sin träck; de som sågo honom måste fråga: »Var är han?»
ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀; àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’
8 Lik en dröm flyger han bort, och ingen finner honom mer; han förjagas såsom en syn om natten.
Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i, àní a ó lé e lọ bi ìran òru.
9 Det öga som såg honom ser honom icke åter, och hans plats får ej skåda honom mer.
Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.
10 Hans barn måste gottgöra hans skulder till de arma, hans händer återbära hans vinning.
Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà, ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.
11 Bäst ungdomskraften fyller hans ben, skall den ligga i stoftet med honom.
Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀, tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.
12 Om än ondskan smakar ljuvligt i hans mun, så att han gömmer den under sin tunga,
“Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀, bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,
13 är rädd om den och ej vill gå miste därom, utan håller den förvarad inom sin gom,
bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀, tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,
14 så förvandlas denna kost i hans inre, bliver huggormsetter i hans liv.
ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà, ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;
15 Den rikedom han har slukat måste han utspy; av Gud drives den ut ur hans buk.
Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde; Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.
16 Ja, huggormsgift kommer han att dricka, av etterormens tunga bliver han dräpt.
Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú; ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.
17 Ingen bäck får vederkvicka hans syn, ingen ström med flöden av honung och gräddmjölk.
Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì, ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.
18 Sitt fördärv måste han återbära, han får ej njuta därav; hans fröjd svarar ej mot den rikedom han har vunnit.
Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì; gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.
19 Ty mot de arma övade han våld och lät dem ligga där; han rev till sig hus som han ej kan hålla vid makt.
Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti pẹ̀yìndà si wọ́n; nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.
20 Han visste ej av någon ro för sin buk, men han skall icke rädda sig med sina skatter.
“Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀, kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.
21 Intet slapp undan hans glupskhet, därför äger och hans lycka intet bestånd.
Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀; nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.
22 Mitt i hans överflöd påkommer honom nöd, och envar eländig vänder då mot honom sin hand.
Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a; àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.
23 Ja, så måste ske, för att hans buk må bliva fylld; sin vredes glöd skall Gud sända över honom och låta den tränga såsom ett regn in i hans kropp.
Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun, Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́, yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.
24 Om han flyr undan för vapen av järn, så genomborras han av kopparbågens skott.
Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn; ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.
25 När han då drager i pilen och den kommer ut ur hans rygg, när den ljungande udden kommer fram ur hans galla, då falla dödsfasorna över honom.
O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára; idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá. Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;
26 Idel mörker är förvarat åt hans skatter; till mat gives honom eld som brinner utan pust, den förtär vad som är kvar i hans hydda.
òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀. Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.
27 Himmelen lägger hans missgärning i dagen, och jorden reser sig upp emot honom.
Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn, ayé yóò sì dìde dúró sí i.
28 Vad som har samlats i hans hus far åter sin kos, likt förrinnande vatten, på vredens dag.
Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.
29 Sådan lott får en ogudaktig människa av Gud, sådan arvedel har av Gud blivit bestämd åt henne.
Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”