< Job 12 >
1 Därefter tog Job till orda och sade:
Jobu sì dáhùn, ó sì wí pé,
2 Ja, visst ären I det rätta folket, och med eder kommer visheten att dö ut!
“Kò sí àní àní níbẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni àwọn ènìyàn náà, ọgbọ́n yóò sì kú pẹ̀lú yín!
3 Dock, jämväl jag har förstånd så gott som I, icke står jag tillbaka för eder; ty vem är den som ej begriper slikt?
Ṣùgbọ́n èmi ní ìyè nínú gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin; èmi kò kéré sí i yín. Àní, ta ni kò mọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí?
4 Så måste jag då vara ett åtlöje för min vän, jag som fick svar, så snart jag ropade till Gud; man ler åt en som är rättfärdig och ostrafflig!
“Èmi dàbí ẹni tí a ń fi ṣe ẹlẹ́yà lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀, tí ó ké pe Ọlọ́run, tí ó sì dá a lóhùn, à ń fi olóòtítọ́ ẹni ìdúró ṣinṣin rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà!
5 Ja, med förakt ses olyckan av den som står säker; förakt väntar dem vilkas fötter vackla.
Ó rọrùn fún ènìyàn láti fi ìbànújẹ́ ẹlòmíràn ṣe ẹlẹ́yà gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ẹni tí ẹsẹ̀ wọn ṣetán láti yọ̀.
6 Men förhärjares hyddor åtnjuta frid, och trygghet få sådana som trotsa Gud, de som hava sin gud i sin hand.
Àgọ́ àwọn ìgárá ọlọ́ṣà wá láìní ìbẹ̀rù; àwọn tí ó sì ń mú Ọlọ́run bínú wà láìléwu, àwọn ẹni tí ó sì gbá òrìṣà mú ní ọwọ́ wọn.
7 Men fråga du boskapen, den må undervisa dig, och fåglarna under himmelen, de må upplysa dig;
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́, àti ẹyẹ ojú ọ̀run, wọn ó sì sọ fún ọ.
8 eller tala till jorden, hon må undervisa dig, fiskarna i havet må giva dig besked.
Tàbí ba ilẹ̀ ayé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ, àwọn ẹja inú òkun yóò sì sọ fún ọ.
9 Vem kan icke lära genom allt detta att det är HERRENS hand som har gjort det?
Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkan wọ̀nyí pé, ọwọ́ Olúwa ni ó ṣe nǹkan yìí?
10 I hans han är ju allt levandes själ och alla mänskliga varelsers anda.
Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyè gbogbo gbé wà, àti ẹ̀mí gbogbo aráyé.
11 Skall icke öra pröva orden, likasom munnen prövar matens smak?
Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí tàbí adùn ẹnu kì í sì í tọ́ oúnjẹ rẹ̀ wò bí?
12 Vishet tillkommer ju de gamle och förstånd dem som länge hava levat.
Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún, àti nínú gígùn ọjọ́ ni òye.
13 Hos Honom finnes vishet och makt, hos honom råd och förstånd.
“Ti Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára; òun ló ni ìmọ̀ àti òye.
14 Se, vad han river ned, det bygges ej upp; för den han spärrar inne kan ingen upplåta.
Kíyèsi i, ó bì wó, a kò sì lè gbe ró mọ́; Ó sé ènìyàn mọ́, kò sì sí ìtúsílẹ̀ kan.
15 Han håller vattnen tillbaka -- se, se då bliver där torrt, han släpper dem lösa, då fördärva de landet.
Kíyèsi i, ó dá àwọn omi dúró, wọ́n sì gbẹ; Ó sì rán wọn jáde, wọ́n sì ṣẹ̀ bo ilẹ̀ ayé yípo.
16 Hos honom är kraft och klokhet, den förvillade och förvillaren äro båda i hans hand.
Tìrẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun; ẹni tí ń ṣìnà àti ẹni tí ń mú ni ṣìnà, tirẹ̀ ni wọ́n ń ṣe.
17 Rådsherrar utblottar han, han för dem i landsflykt, och domare gör han till dårar.
Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòhò a sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.
18 Han upplöser konungars välde och sätter fångbälte om deras höfter.
Ó tú ìdè ọba ó sì fi àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já.
19 Präster utblottar han, han för dem i landsflykt, och de säkrast rotade kommer han på fall.
Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòhò ó sì tẹ orí àwọn alágbára ba.
20 Välbetrodda män berövar han målet och avhänder de äldste deras insikt.
Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò ó sì ra àwọn àgbàgbà ní iyè.
21 Han utgjuter förakt över furstar och lossar de starkes gördel.
Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́lá ó sì tú àmùrè àwọn alágbára.
22 Han blottar djupen, så att de ej höljas av mörker, dödsskuggan drager han fram i ljuset.
Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀.
23 Han låter folkslag växa till -- och förgör dem; han utvidgar deras gränser, men för dem sedan bort.
Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n; òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù.
24 Stamhövdingar i landet berövar han förståndet, han leder dem vilse i väglösa ödemarker.
Òun a gba òye àwọn olórí àwọn ènìyàn aráyé, a sì máa mú wọn rin kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí.
25 De famla i mörkret och hava intet ljus, han kommer dem att ragla såsom druckna.
Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀; òun a sì máa mú ìrìn ìsìn wọn bí ọ̀mùtí.