< Jeremia 5 >

1 Gån omkring på gatorna i Jerusalem, och sen till och given akt; söken på dess torg om I finnen någon, om där är någon som gör rätt och beflitar sig om sanning; då vill jag förlåta staden.
“Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
2 Men säga de än: »Så sant HERREN lever», så svärja de dock falskt.
Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
3 HERRE, är det ej sanning dina ögon söka? Du slog dem, men de kände ingen sveda. Du förgjorde dem, men de ville ej taga emot tuktan. De gjorde sina pannor hårdare än sten, de ville icke omvända sig.
Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
4 Då tänkte jag: »Detta är allenast de ringa i folket; de äro dåraktiga, ty de känna icke HERRENS väg, sin Guds rätt.
Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
5 Jag vill nu gå till de stora och tala med dem; de måste ju känna HERRENS väg, sin Guds rätt.» Men ock dessa hade alla brutit sönder oket och slitit av banden.
Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
6 Därför bliva de slagna av lejonet från skogen och fördärvade av vargen från hedmarken; pantern lurar vid deras städer, och envar som vågar sig ut därifrån bliver ihjälriven. Ty många äro deras överträdelser och talrika deras avfällighetssynder.
Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
7 Huru skulle jag då kunna förlåta dig? Dina barn hava ju övergivit mig och svurit vid gudar som icke äro gudar. Jag gav dem allt till fyllest, men de blevo mig otrogna och samlade sig i skaror till skökohuset.
“Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
8 De likna välfödda, ystra hästar; de vrenskas var och en efter sin nästas hustru.
Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
9 Skulle jag icke för sådant hemsöka dem? säger HERREN. Och skulle icke min själ hämnas på ett sådant folk som detta är?
Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
10 Stormen då hennes murar och för stören dem, dock utan att alldeles göra ände på henne. Riven bort hennes vinrankor, de äro ju icke HERRENS.
“Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
11 Ty både Israels hus och Juda hus hava varit mycket trolösa mot mig, säger HERREN.
Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
12 De hava förnekat HERREN och sagt: »Han betyder intet. Olycka skall icke komma över oss, svärd och hunger skola vi icke se.
Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
13 Men profeterna skola försvinna såsom en vind, och han som säges tala är icke i dem; dem själva skall det så gå.»
Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
14 Därför säger HERREN, härskarornas Gud: Eftersom I fören ett sådant tal, se, därför skall jag göra mina ord i din mun till en eld, och detta folk till ved, och elden skall förtära dem.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
15 Se, jag skall låta komma över eder, I av Israels hus, ett folk ifrån fjärran land, säger HERREN, ett starkt folk, ett urgammalt folk, ett folk vars tungomål du icke känner, och vars tal du icke förstår.
Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
16 Deras koger är en öppen grav; de äro allasammans hjältar.
Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
17 De skola förtära din skörd och ditt bröd, de skola förtära dina söner och döttrar, de skola förtära dina får och fäkreatur, de skola förtära dina vinträd och fikonträd. Dina befästa städer, som du förlitar dig på, dem skola de förstöra med svärd.
Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
18 Dock vill jag på den tiden, säger HERREN, icke alldeles göra ände på eder.
“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
19 Och om I då frågen: »Varför har HERREN, vår Gud, gjort oss allt detta?», så skall du svara dem: »Såsom I haven övergivit mig och tjänat främmande gudar i edert eget land, så skolen I nu få tjäna främlingar i ett land som icke är edert.»
Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
20 Förkunnen detta i Jakobs hus, kungören det i Juda och sägen:
“Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
21 Hör detta, du dåraktiga och oförståndiga folk, I som haven ögon, men icke sen, I som haven öron, men icke hören.
Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
22 Skullen I icke frukta mig, säger HERREN, skullen I icke bäva för mig, for mig som har satt stranden till en damm for havet, till en evärdlig gräns, som det icke kan överskrida, så att dess böljor, huru de än svalla, ändå intet förmå, och huru de än brusa, likväl icke kunna överskrida den?
Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
23 Men detta folk har ett gensträvigt och upproriskt hjärta; de hava avfallit och gått sin väg.
Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
24 De sade icke i sina hjärtan: »Låtom oss frukta HERREN, vår Gud, honom som giver regn i rätt tid, både höst och vår, och som ständigt beskär oss de bestämda skördeveckorna.»
Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
25 Edra missgärningar hava nu fört dessa i olag, och edra synder hava förhållit för eder detta goda.
Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
26 Ty bland mitt folk finnas ogudaktiga människor: de ligga i försåt, likasom fågelfängaren ligger på lur, de sätta ut giller till att fånga människor.
“Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
27 Såsom när en bur är full av fåglar, så äro deras hus fulla av svek. Därigenom hava de blivit så stora och rika; de hava blivit feta och skinande.
Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
28 För sina ogärningar veta de icke av någon gräns, de hålla icke rätten vid makt, icke den faderlöses rätt, till att främja den; och i den fattiges sak fälla de icke rätt dom.
wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
29 Skulle jag icke för sådant hemsöka dem? säger HERREN. Skulle icke min själ hämnas på ett sådant folk som detta är?
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
30 Förfärliga och gruvliga ting ske i landet.
“Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
31 Profeterna profetera lögn, och prästerna styra efter deras råd; och mitt folk vill så hava det. Men vad skolen I göra, när änden på detta kommer?
Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?

< Jeremia 5 >