< Jeremia 4 >
1 om du omvänder dig, Israel, säger HERREN, skall du få vända tillbaka till mig; och om du skaffar bort dina styggelser från min åsyn, skall du slippa vandra flyktig omkring.
“Tí ìwọ yóò bá yí padà, ìwọ Israẹli, padà tọ̀ mí wá,” ni Olúwa wí. “Tí ìwọ yóò bá sì mú ìríra rẹ kúrò níwájú mi, ìwọ kí ó sì rìn kiri.
2 Då skall du svärja i sanning, rätt och rättfärdighet: »Så sant HERREN lever», och hednafolken skola välsigna sig i honom och berömma sig av honom.
Tí ó bá jẹ́ lóòtítọ́ àti òdodo ni ìwọ búra. Nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè, nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò di alábùkún fún nípasẹ̀ rẹ, àti nínú rẹ̀ ni wọn yóò ṣògo.”
3 Ja, så säger HERREN till Juda män och till Jerusalem: Bryten eder ny mark, och sån ej bland törnen.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu: “Hú gbogbo ilẹ̀ tí ẹ kò lò rí, kí o má sì ṣe gbìn sáàrín ẹ̀gún.
4 Omskären eder åt HERREN; skaffen bort edert hjärtas förhud, I Juda män och I Jerusalems invånare. Eljest skall min vrede bryta fram såsom en eld och brinna så, att ingen kan utsläcka den, för edert onda väsendes skull.
Kọ ara rẹ ní ilà sí Olúwa, kọ ọkàn rẹ ní ilà, ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú mi yóò ru jáde yóò sì jó bí iná, nítorí ibi tí o ti ṣe kì yóò sí ẹni tí yóò pa á.
5 Förkunnen i Juda, kungören i Jerusalem och påbjuden, ja, stöten i basun i landet, ropen ut med hög röst och sägen: »Församlen eder och låt oss fly in i de befästa städerna.»
“Kéde ní Juda, kí o sì polongo ní Jerusalẹmu, kí o sì wí pé: ‘Fun fèrè káàkiri gbogbo ilẹ̀!’ Kí o sì kígbe: ‘Kó ara jọ pọ̀! Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi.’
6 Resen upp ett baner som visar åt Sion, bärgen edert gods och dröjen icke ty jag skall låta olycka komma från norr, med stor förstöring.
Fi àmì láti sálọ sí Sioni hàn, sálọ fún ààbò láìsí ìdádúró. Nítorí èmi ó mú àjálù láti àríwá wá, àní ìparun tí ó burú jọjọ.”
7 Ett lejon drager fram ur sitt snår och en folkfördärvare bryter upp, han går ut ur sin boning, för att göra ditt land till en ödemark; då bliva dina städer förstörda, så att ingen kan bo i dem.
Kìnnìún ti sá jáde láti inú ibùgbé rẹ̀, apanirun orílẹ̀-èdè sì ti jáde. Ó ti fi ààyè rẹ̀ sílẹ̀ láti ba ilẹ̀ rẹ̀ jẹ́. Ìlú rẹ yóò di ahoro láìsí olùgbé.
8 Så höljen eder nu i sorgdräkt, klagen och jämren eder, ty HERRENS vredes glöd upphör icke över oss.
Nítorí náà, gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀ káàánú kí o sì pohùnréré ẹkún, nítorí ìbínú ńlá Olúwa kò tí ì kúrò lórí wa.
9 På den tiden, säger HERREN, skall det vara förbi med konungens och furstarnas mod, och prästerna skola bliva förfärade och profeterna stå häpna.
“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí pé, “Àwọn ọba àti ìjòyè yóò pàdánù ẹ̀mí wọn, àwọn àlùfáà yóò wárìrì, àwọn wòlíì yóò sì fòyà.”
10 Men jag sade: »Ack Herre, HERRE, svårt bedrog du sannerligen detta folk och Jerusalem, då du sade: »Det skall gå eder väl.» Svärdet är ju nära att taga vårt liv.
Nígbà náà ni mo sì wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, báwo ni ìwọ ti ṣe tan àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti Jerusalẹmu jẹ nípa sísọ wí pé, ‘Ìwọ yóò wà ní àlàáfíà,’ nígbà tí o jẹ́ wí pé idà wà ní ọ̀fun wa.”
11 På den tiden skall det sägas om detta folk och om Jerusalem: En brännande vind från höjderna i öknen kommer emot dottern mitt folk, icke en sådan vind som passar, när man kastar säd eller rensar korn;
Nígbà náà ni a ó sọ fún Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn pé, “Ẹ̀fúùfù líle láti aṣálẹ̀ fẹ́ lu àwọn ènìyàn mi, kì í ṣe láti sọ di mímọ́.
12 nej, en våldsammare vind än som så låter jag komma. Ja, nu vill jag gå till rätta med dem!
Ẹ̀fúùfù líle tí ó wá láti ọ̀dọ̀ mi. Báyìí mo kéde ìdájọ́ mi lórí wọn.”
13 Se, såsom ett moln kommer han upp och såsom en stormvind äro hans vagnar; hans hästar äro snabbare än örnar, ve oss, vi äro förlorade!
Wò ó! O ń bọ̀ bí ìkùùkuu kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ sì wá bí ìjì líle ẹṣin rẹ̀ sì yára ju idì lọ. Ègbé ni fún wa àwa parun.
14 Så två nu ditt hjärta rent från ondska, Jerusalem, för att du må bliva frälst. Huru länge skola fördärvets tankar bo i ditt bröst?
Ìwọ Jerusalẹmu, mú búburú kúrò lọ́kàn rẹ kí o sì yè. Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò mú èrò búburú wà ní ọkàn rẹ?
15 Från Dan höres ju en budbärare ropa, och från Efraims bergsbygd en som bådar fördärv.
Ohùn kan sì ń kéde ní Dani o ń kókìkí ìparun láti orí òkè Efraimu wá.
16 Förkunnen för folken, ja, kungören över Jerusalem att en belägringshär kommer ifrån fjärran land och häver upp sitt rop mot Juda städer.
“Sọ èyí fún àwọn orílẹ̀-èdè, kéde rẹ̀ fún Jerusalẹmu pé: ‘Ọmọ-ogun ọ̀tá ń bọ̀ láti ilẹ̀ jíjìn wá wọ́n sì ń kígbe ogun láti dojúkọ ìlú Juda.
17 Såsom väktare kring ett åkerfält samla de sig runt omkring henne, därför att hon har varit gensträvig mot mig, säger HERREN.
Wọ́n yí i ká bí ìgbà tí àwọn ọkùnrin bá ń ṣọ́ pápá, nítorí pé ó ti dìtẹ̀ sí mi,’” ni Olúwa wí.
18 Ja, ditt eget leverne och dina egna varningar vålla dig detta; det är din ondskas frukt att det bliver dig så bittert, och att plågan träffar dig ända in i hjärtat.
“Ìwà rẹ àti ìṣe rẹ ló fa èyí bá ọ ìjìyà rẹ sì nìyìí. Báwo ló ti ṣe korò tó! Báwo ló ti ṣe gún ọkàn rẹ sí!”
19 I mitt innersta våndas jag, i mitt hjärtas djup. Mitt hjärta klagar i mig, jag kan icke tiga, ty basunljud hör du, min själ, och krigiskt härskri.
Háà! Ìrora mi, ìrora mi! Mo yí nínú ìrora. Háà, ìrora ọkàn mi! Ọkàn mi lù kìkì nínú mi, n kò le è dákẹ́. Nítorí mo ti gbọ́ ohùn ìpè, mo sì ti gbọ́ igbe ogun.
20 Olycka efter olycka ropas ut, ja, hela landet bliver förött; plötsligt bliva mina hyddor förödda, i ett ögonblick mina tält.
Ìparun ń gorí ìparun; gbogbo ilẹ̀ náà sì ṣubú sínú ìparun lọ́gán ni a wó àwọn àgọ́ mi, tí ó jẹ́ ohun ààbò mi níṣẹ́jú kan.
21 Huru länge skall jag se stridsbaneret och höra basunljud?
Yóò ti pẹ́ tó, tí èmi yóò rí ogun tí èmi yóò sì gbọ́ ìró fèrè?
22 Ja, mitt folk är oförnuftigt, de vilja ej veta av mig. De äro dåraktiga barn och hava intet förstånd. Visa äro de till att göra vad ont är, men att göra vad gott är förstå de ej.
“Aṣiwèrè ni àwọn ènìyàn mi; wọn kò mọ̀ mí. Wọ́n jẹ́ aláìgbọ́n ọmọ; wọ́n sì jẹ́ aláìlóye. Wọ́n mọ ibi ni ṣíṣe; wọn kò mọ bí a ti í ṣe rere.”
23 Jag såg på jorden, och se, den var öde och tom, och upp mot himmelen, och där lyste intet ljus.
Mo bojú wo ayé, ó sì wà ní júujùu, ó sì ṣófo àti ní ọ̀run, ìmọ́lẹ̀ wọn kò sì ṣí.
24 Jag såg på bergen, och se, de bävade, och alla höjder vacklade.
Mo wo àwọn òkè ńlá, wọ́n wárìrì; gbogbo òkè kéékèèké mì jẹ̀jẹ̀.
25 Jag såg mig om, och då fanns där ingen människa, och alla himmelens fåglar hade flytt bort.
Mo wò yíká n kò rí ẹnìkan; gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ló ti fò lọ.
26 Jag såg mig om, och då var det bördiga landet en öken, och alla dess städer voro nedbrutna, för HERRENS ansikte, för hans vredes glöd,
Mo bojú wò, ilẹ̀ eléso, ó sì di aṣálẹ̀ gbogbo àwọn ìlú inú rẹ̀ sì ṣubú sínú ìparun níwájú Olúwa àti níwájú ríru ìbínú rẹ̀.
27 Ty så säger HERREN: Hela landet skall bliva en ödemark, om jag än ej alldeles vill göra ände därpå.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Gbogbo ìlú náà yóò sì di ahoro, síbẹ̀ èmi kì yóò pa á run pátápátá.
28 Därför sörjer jorden, och himmelen därovan kläder sig i sorgdräkt, därför att jag så har talat och beslutit och ej kan ångra det eller taga det tillbaka.
Nítorí náà, ayé yóò pohùnréré ẹkún àwọn ọ̀run lókè yóò ṣú òòkùn nítorí mo ti sọ, mo sì ti pète rẹ̀ mo ti pinnu, n kì yóò sì yí i padà.”
29 För larmet av ryttare och bågskyttar tager hela staden till flykten. Man giver sig in i skogssnåren och upp bland klipporna. Alla städer äro övergivna, ingen människa bor mer i dem.
Nípa ariwo àwọn ẹlẹ́ṣin àti àwọn tafàtafà gbogbo ìlú yóò sálọ. Ọ̀pọ̀ sálọ sínú igbó; ọ̀pọ̀ yóò sì gun orí àpáta lọ. Gbogbo ìlú náà sì di ahoro; kò sì ṣí ẹnìkan nínú rẹ̀.
30 Vad vill du göra i din förödelse? Om du än kläder dig i scharlakan, om du än pryder dig med gyllene smycken om du än söker förstora dina ögon genom smink, så gör du dig dock skön förgäves. Dina älskare förakta dig, ja, de stå efter ditt liv.
Kí ni ò ń ṣe, ìwọ tí o ti di ìjẹ tán? Ìwọ ìbá wọ ara rẹ ní aṣọ òdodo kí o sì fi wúrà ṣe ara rẹ lọ́ṣọ̀ọ́. Àwọn olólùfẹ́ rẹ kẹ́gàn rẹ; wọ́n sì ń lépa ẹ̀mí rẹ.
31 Ty jag hör rop såsom av en barnaföderska, nödrop såsom av en förstföderska. Det är dottern Sion som ropar; hon flämtar, hon räcker ut sina händer: »Ack, ve mig! I mördares våld försmäktar min själ.»
Mo gbọ́ ìró kan bí i igbe obìnrin tó ń rọbí, tí ó ń rọbí, ìrora bí i abiyamọ ọmọbìnrin Sioni tí ń pohùnréré ẹkún ara rẹ̀. Tí ó na ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì wí pé, “Kíyèsi i mo gbé, nítorí a ti fi ẹ̀mí mi lé àwọn apani lọ́wọ́.”