< Jeremia 33 >
1 Och HERRENS ord kom till Jeremia för andra gången, medan han ännu var inspärrad i fängelsegården; han sade:
Nígbà tí Jeremiah wà nínú àgbàlá túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá lẹ́ẹ̀kejì:
2 Så säger HERREN, han som ock utför sitt verk, HERREN, som bereder det för att låta det komma till stånd, han vilkens namn är HERREN:
“Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹni tí ó dá ayé, Olúwa tí ó mọ ayé tí ó sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, Olúwa ni orúkọ rẹ̀:
3 Ropa till mig, så vill jag svara dig och förkunna för dig stora och förunderliga ting, som du icke känner.
‘Pè mí, èmi ó sì dá ọ lóhùn, èmi ó sì sọ ohun alágbára ńlá àti ọ̀pọ̀ ohun tí kò ṣe é wádìí tí ìwọ kò mọ̀ fún ọ.’
4 Ty så säger HERREN, Israels Gud, om husen i denna stad och om Juda konungars hus, som nu brytas ned för belägringsvallarna och värden:
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ nípa àwọn ilẹ̀ ìlú yìí àti ààfin àwọn ọba Juda tí ó ti wó lulẹ̀ nítorí àwọn ìdọ̀tí àti idà
5 Man har kommit hitin för att strida med kaldéerna, och man skall så fylla husen med döda kroppar av människor som jag har slagit i min vrede och förtörnelse, människor som genom all sin ondska hava vållat att jag har måst dölja mitt ansikte för denna stad.
nínú ìjà pẹ̀lú Kaldea: ‘Wọn yóò kún fún ọ̀pọ̀ òkú ọmọkùnrin tí èmi yóò pa nínú ìbínú àti nínú ìrunú mi. Èmi ó pa ojú mi mọ́ kúrò ní ìlú yìí nítorí gbogbo búburú wọn.
6 Dock, jag skall hela dess sår och skaffa läkedom och läka dem, och jag skall låta dem skåda frid och trygghet i överflöd.
“‘Wò ó, èmi ó mú ọ̀já àti oògùn ìmúláradá dì í; èmi ó wo àwọn ènìyàn mi sàn. Èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó jẹ ìgbádùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ àlàáfíà àti òtítọ́.
7 Och jag skall åter upprätta Juda och Israel och uppbygga dem, så att de bliva såsom förut.
Èmi ó mú Juda àti Israẹli kúrò nínú ìgbèkùn, èmi ó sì tún wọn kọ́ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe wà tẹ́lẹ̀.
8 Och jag skall rena dem från all missgärning varmed de hava syndat mot mig, och förlåta alla missgärningar genom vilka de hava syndat mot mig och avfallit från mig.
Èmi ó wẹ̀ wọ́n nù kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ti ṣẹ sí mi. Èmi ó sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àìṣedéédéé wọn sí mi jì wọ́n.
9 Och staden skall bliva mig till fröjd och berömmelse, och till lov och ära inför alla jordens folk, när de få höra allt det goda som jag gör med dem; och de skola förskräckas och darra vid åsynen av all den lycka och all den framgång som jag bereder henne.
Nígbà náà ni ìlú yìí ó fún mi ní òkìkí, ayọ̀, ìyìn àti ọlá níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé; tí wọ́n gbọ́ gbogbo rere tí èmi ṣe fún wọn. Wọn ó sì bẹ̀rù, wọn ó wárìrì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore àti àlàáfíà tí èmi pèsè fún wọn.’
10 Så säger HERREN: På denna plats, om vilken I sägen att den är så öde att varken människor eller djur kunna bo där, ja, här i Juda städer och på Jerusalems gator, som äro så ödelagda att inga människor, inga invånare, inga djur där finnas,
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ẹ̀yin yóò wí nípa ibí yìí pé, “Ó dahoro, láìsí ènìyàn tàbí ẹran.” Síbẹ̀ ní ìlú Juda àti ní òpópónà Jerusalẹmu tí ó dahoro, láìsí ẹni tó gbé ibẹ̀; ìbá à se ènìyàn tàbí ẹran, tí yóò gbọ́ lẹ́ẹ̀kan sí.
11 här skall man ännu en gång höra fröjderop och glädjerop, rop för brudgum och rop för brud, rop av människor som säga: »Tacken HERREN Sebaot, ty HERREN är god, ty hans nåd varar evinnerligen», och av människor som frambära lovoffer i HERRENS hus. Ty jag vill åter upprätta landet, så att det bliver såsom förut, säger HERREN.
Ariwo ayọ̀ àti inú dídùn, ohùn ìyàwó àti ti ọkọ ìyàwó àti ohùn àwọn tí ó ru ẹbọ ọpẹ́ wọn nílé Olúwa wí pé: “‘“Yin Olúwa àwọn ọmọ-ogun, nítorí Olúwa dára, ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé.” Nítorí èmi ó dá ìkólọ ilẹ̀ náà padà sí bí o ṣe wà tẹ́lẹ̀,’ ni Olúwa wí.
12 Så säger HERREN Sebaot: På denna plats, som nu är så öde att varken människor eller ens djur kunna bo här, ja ock i alla hithörande städer, här skola åter en gång finnas betesmarker där herdar kunna låta sina hjordar lägra sig.
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ní ilẹ̀ yìí tí ó ti dahoro láìsí ọkùnrin àti àwọn ẹran nínú gbogbo ìlú, kò ní sí pápá oko fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sinmi.
13 I Bergsbygdens, Låglandets och Sydlandets städer, i Benjamins land i Jerusalems omnejd och i andra Juda städer skola ännu en gång hjordar draga fram, förbi herdar som räkna dem, säger HERREN.
Ní ìlú òkè wọ̀n-ọn-nì, nínú ìlú àfonífojì, àti nínú ìlú ìhà gúúsù, àti ní ilẹ̀ ti Benjamini, ní ibi wọ̀n-ọn-nì tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda ni agbo àgùntàn yóò tún máa kọjá ní ọwọ́ ẹni tí ń kà wọ́n,’ ni Olúwa wí.
14 Se, dagar skola komma, säger HERREN, då jag skall uppfylla det löftesord som jag har talat om Israels hus och angående Juda hus.
“‘Àwọn ọjọ́ náà ń bọ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí èmi ó mú ìlérí rere tí mo ṣe fún ilé Israẹli àti ilé Juda ṣẹ.
15 I de dagarna och på den tiden skall jag låta en rättfärdig telning växa upp åt David. Han skall skaffa rätt och rättfärdighet på jorden.
“‘Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àti ní àkókò náà, Èmi ó gbé olódodo dìde láti ẹ̀ka Dafidi. Yóò ṣe ìdájọ́ àti ohun tí ó tọ́ ní ilẹ̀ náà.
16 I de dagarna skall Juda varda frälst och Jerusalem bo i trygghet; och man skall kalla det så: HERREN vår rättfärdighet.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Juda yóò di ẹni ìgbàlà. Jerusalẹmu yóò sì máa gbé láìséwu. Orúkọ yìí ni a ó máa pè é Olúwa wa olódodo.’
17 Ty så säger HERREN: Aldrig skall den tid komma, då icke en avkomling av David sitter på Israels hus' tron,
Nítorí báyìí ni Olúwa wí: ‘Dafidi kò ní kùnà láti rí ọkùnrin tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ ní ilé Israẹli.
18 aldrig den tid då icke en avkomling av de levitiska prästerna gör tjänst inför mig och alla dagar bär fram brännoffer och förbränner spisoffer och anställer slaktoffer.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà tí ó jẹ́ ọmọ Lefi kò ní kùnà láti ní ọkùnrin kan tí ó dúró níwájú mi ní gbogbo ìgbà láti rú ẹbọ sísun; ẹbọ jíjẹ àti láti pèsè ìrúbọ.’”
19 Och HERRENS ord kom till Jeremia; han sade:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá wí pé:
20 Så säger HERREN: Först när I gören om intet mitt förbund med dagen och mitt förbund med natten, så att det icke bliver dag och natt i rätt tid,
“Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Tí ìwọ bá lè dá májẹ̀mú mi ní òru tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀sán àti òru kò lè sí ní àkókò wọn mọ́.
21 först då skall mitt förbund med min tjänare David bliva om intet, så att icke längre en avkomling av honom sitter såsom konung på hans tron, och först då mitt förbund med de levitiska prästerna, som göra tjänst åt mig.
Nígbà náà ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú Dafidi ìránṣẹ́ mi àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi tí ó jẹ́ àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ níwájú mi lè bàjẹ́, tí Dafidi kò sì rí ẹni láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀.
22 Lika oräknelig som himmelens härskara är, och lika otalig som sanden är i havet, lika talrik skall jag låta min tjänare Davids säd bliva och lika många leviterna, som göra tjänst åt mig.
Èmi ó mú àwọn ọmọ lẹ́yìn Dafidi ìránṣẹ́ mi àti Lefi tí ó jẹ́ oníwàásù níwájú mi di bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, tí kò ṣe é kà àti bí iyẹ̀pẹ̀ ojú Òkun tí kò ṣe é wọ́n.’”
23 Och HERRENS ord kom till Jeremia; han sade:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
24 Har du icke märkt huru detta folk talar och säger: »De båda släkter som HERREN utvalde, dem har han förkastat»? Och så säga de föraktligt om mitt folk att det icke mer synes dem vara ett folk.
“Ǹjẹ́ ìwọ kò kíyèsi pé àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń sọ pé: ‘Olúwa ti kọ àwọn ọba méjèèjì tí ó yàn sílẹ̀’? Nítorí náà, ni wọ́n ti ṣe kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi. Wọn kò sì mọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè kan.
25 Men så säger HERREN: Om mitt förbund med dag och natt icke är beståndande, och om jag icke har stadgat en fast ordning för himmel och jord,
Báyìí ni Olúwa wí: ‘Bí èmi kò bá ti da májẹ̀mú mi pẹ̀lú ọ̀sán àti òru àti pẹ̀lú òfin ọ̀run àti ayé tí kò lè yẹ̀.
26 allenast då skall jag förkasta Jakobs och Davids, min tjänares, säd, så att jag icke mer av hans säd tager dem som skola råda över Abrahams, Isaks och Jakobs säd. Ty jag skall åter upprätta dem och förbarma mig över dem.
Nígbà náà ni èmi ó kọ ọmọ lẹ́yìn Jakọbu àti Dafidi ìránṣẹ́ mi tí èmi kò sì ní yan ọ̀kan nínú ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ́ alákòóso lórí àwọn ọmọ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu; nítorí èmi ó mú ìkólọ wọn padà; èmi ó sì ṣàánú fún wọn.’”