< Jeremia 32 >

1 Detta är det ord som från HERREN kom till Jeremia i Sidkias, Juda konungs, tionde regeringsår, vilket var Nebukadressars adertonde regeringsår.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọdún kẹwàá Sedekiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kejìdínlógún ti Nebukadnessari.
2 Vid den tiden belägrade den babyloniske konungens här Jerusalem, och profeten Jeremia låg då fången i fängelsegården i Juda konungs hus.
Àwọn ogun ọba Babeli ìgbà náà há Jerusalẹmu mọ́. A sì sé wòlíì Jeremiah mọ́ inú túbú tí wọ́n ń ṣọ́ ní àgbàlá ilé ọba Juda.
3 Ty Sidkia, Juda konung, hade låtit spärra in honom, i det han sade: »Huru djärves du profetera och säga: 'Så säger HERREN: Se, jag skall giva denna stad i de babyloniske konungens hand, och han skall intaga den.
Nítorí Sedekiah ọba Juda ti há a mọ́lé síbẹ̀; pé, “Kí ló dé tí ìwọ fi ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀? Tí o sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Èmi ń bọ̀ wá fi ìlú yìí fún ọba Babeli, tí yóò sì gbà á.
4 Och Sidkia, Juda konung, skall icke undkomma kaldéernas hand, utan skall förvisso bliva given i den babyloniske konungens hand, så att han nödgas muntligen tala med honom och stå inför honom, öga mot öga.
Sedekiah ọba Juda kò lè bọ́ lọ́wọ́ àwọn Kaldea, ṣùgbọ́n à ó mú fún ọba Babeli, yóò sì bá sọ̀rọ̀ ní ojúkojú; yóò sì rí pẹ̀lú ojú rẹ̀.
5 Och Sidkia skall av honom föras till Babel och skall förbliva där, till dess jag ser till honom, säger HERREN. När I striden mot kaldéerna, skolen I icke hava någon framgång.»
Yóò mú Sedekiah lọ sí Babeli tí yóò wà títí èmi yóò fi bẹ̀ ọ́ wò ni Olúwa wí. Tí ẹ̀yin bá bá àwọn ará Kaldea jà, ẹ̀yin kì yóò borí wọn.’”
6 Och Jeremia sade: »HERRENS ord kom till mig; han sade:
Jeremiah wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
7 Se, Hanamel, din farbroder Sallums son, skall komma till dig och säga: 'Köp du min åker i Anatot, ty du har såsom bördeman rätt att köpa den.'»
Hanameli ọmọkùnrin Ṣallumu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ yóò tọ̀ ọ́ wá pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti; nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹni tó súnmọ́ wọn, ẹ̀tọ́ àti ìṣe rẹ ní láti rà á.’
8 Och Hanamel, min farbroders son, kom till mig i fängelsegården, såsom HERREN hade sagt, och sade till mig: »Köp min åker i Anatot, i Benjamins land, ty du har arvsrätt därtill och är bördeman; så köp den då åt dig.» Då förstod jag att det var HERRENS ord
“Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ, Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi tọ̀ mí wá ní àgbàlá túbú wí pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti tí ó wà ní ilẹ̀ Benjamini, èyí tí ó jẹ́ pé ẹ̀tọ́ rẹ ni láti gbà á àti láti ni, rà á fún ara rẹ.’ “Nígbà náà ni èmi mọ̀ wí pé ọ̀rọ̀ Olúwa ni èyí.
9 och köpte åkern av Hanamel, min farbroders son, i Anatot, och vägde upp penningarna åt honom, sjutton siklar silver.
Bẹ́ẹ̀ ni; èmi ra pápá náà ní Anatoti láti ọwọ́ Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi. Mo sì wọn ìwọ̀n ṣékélì àti fàdákà mẹ́tàdínlógún fún un.
10 Jag skrev ett köpebrev och förseglade det och tillkallade vittnen och vägde upp penningarna på en våg.
Mo fọwọ́ sínú ìwé, mo sì dì í pa. Mo pe ẹlẹ́rìí sí i, mo sì wọn fàdákà náà lórí òsùwọ̀n.
11 Och jag tog köpebrevet, såväl det förseglade, som innehöll avtalet och de särskilda bestämmelserna, som ock det öppna brevet,
Mo mú ìwé tí mo fi rà á, èyí tí a di pa nípa àṣẹ àti òfin wa, àti èyí tí a kò lẹ̀.
12 och gav köpebrevet åt Baruk, son till Neria, son till Mahaseja, i närvaro av min frände Hanamel och de vittnen som hade underskrivit köpebrevet, och alla andra judar som voro tillstädes i fängelsegården.
Èmi sì fi èyí fún Baruku, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, ní ojú Hanameli, ọmọ ẹ̀gbọ́n mi àti níwájú àwọn ẹlẹ́rìí tí ó ti fi ọwọ́ sí ìwé àti ní ojú àwọn Júù gbogbo tí wọ́n jókòó ní àgbàlá ilé túbú.
13 Och jag bjöd Baruk, i deras närvaro, och sade:
“Ní ojú wọn ni èmi ti pàṣẹ fún Baruku pé,
14 Så säger HERREN Sebaot, Israels Gud: Tag du dessa brev, både detta förseglade köpebrev och detta öppna brev, och lägg dem i ett lerkärl, för att de må vara i behåll för lång tid.
èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; mú àwọn ìwé tí a fi rà á wọ̀nyí, àti èyí tí a lẹ̀ àti èyí tí a kò lẹ̀, kí o wá gbé wọn sínú ìkòkò amọ̀, kí wọn ó lè wà ní ọjọ́ púpọ̀.
15 Ty så säger HERREN Sebaot, Israels Gud: Ännu en gång skall man komma att i detta land köpa hus och åkrar och vingårdar.»
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; àwọn ilẹ̀, pápá àti ọgbà àjàrà ni à ó tún rà padà nílẹ̀ yìí.
16 Och sedan jag hade givit köpebrevet åt Baruk, Nerias son, bad jag till HERREN och sade:
“Lẹ́yìn tí mo ti fi ìwé rírà náà fún Baruku ọmọkùnrin Neriah, mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé:
17 »Ack Herre, HERRE, du är ju den som har gjort himmel och jord genom din stora kraft och din uträckta arm. Intet är så underbart att du icke skulle förmå det,
“Háà! Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí o dá ọ̀run àti ayé pẹ̀lú títóbi agbára rẹ àti gbogbo ọ̀rọ̀ apá rẹ. Kò sí ohun tí ó ṣòro fún ọ láti ṣe.
18 du som gör nåd med tusenden och vedergäller fädernas missgärning i deras barns sköte efter dem; du store och väldige Gud, vilkens namn är HERREN Sebaot;
O fi ìfẹ́ hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n o gbé ìyà ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba lé àwọn ọmọ lẹ́yìn wọn. Ọlọ́run títóbi àti alágbára, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ.
19 du som är stor i råd och mäktig i gärningar; du vilkens ögon äro öppna över människobarnens alla vägar, så att du giver åt var och en efter hans vägar och efter hans gärningars frukt;
Títóbi ni ìgbìmọ̀, àti alágbára ní í ṣe, ojú rẹ̀ ṣì sí gbogbo ọ̀nà àwọn ọmọ ènìyàn; láti fi fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ ọ̀nà rẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí èso iṣẹ́ rẹ̀.
20 du som gjorde tecken och under i Egyptens land, och som har gjort sådana intill denna dag, både i Israel och bland andra människor, och som har gjort dig ett namn, som är detsamma än i dag.
O ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá ní Ejibiti. O sì ń ṣe é títí di òní ní Israẹli àti lára ọmọ ènìyàn tí ó sì ti gba òkìkí tí ó jẹ́ tìrẹ.
21 Du förde ditt folk Israel ut ur Egyptens land med tecken och under, med stark hand och uträckt arm, och genom stor förskräckelse.
O kó àwọn Israẹli ènìyàn rẹ jáde láti Ejibiti pẹ̀lú iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu nínú ọwọ́ agbára àti nína apá rẹ pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá.
22 Och du gav dem detta land, som du med ed hade lovat deras fäder att giva dem, ett land som flyter av mjölk och honung.
Ìwọ fún wọn nílẹ̀ yìí, èyí tí o ti ṣèlérí fún àwọn baba ńlá wọn; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
23 Och de kommo och togo det i besittning, men de ville icke höra din röst och vandrade icke efter din lag; de gjorde intet av det du hade bjudit dem att göra. Därför lät du all denna olycka vederfaras dem.
Wọ́n wá, wọ́n sì gba ilẹ̀ náà ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ tàbí tẹ̀lé òfin rẹ. Wọn kò ṣe ohun tí o pàṣẹ fún wọn, nítorí náà ìwọ mú àwọn ibi yìí wá sórí wọn.
24 Se, belägringsvallarna gå redan så långt fram mot staden, att man kan intaga den och genom svärd, hungersnöd och pest är staden given i de kaldeiska belägrarnas hand. Vad du hotade med, det har skett, och du har det nu inför dina ögon.
“Wò ó, bí àwọn ìdọ̀tí ṣe kórajọ láti gba ìlú. Nítorí idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, sì fi ìlú lé ọwọ́ àwọn ará Kaldea tí ń gbóguntì wọ́n. Ohun tí ìwọ sọ ṣẹ gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i.
25 Och likväl, fastän staden är given i kaldéernas hand, sade du, Herre HERRE, till mig: 'Köp du åkern för penningar, och tag vittnen därpå'!»
Síbẹ̀ a ó fi ìlú náà fún àwọn ará Babeli, ìwọ Olúwa Olódùmarè sọ fún mi pé, ‘Ra pápá náà pẹ̀lú owó fàdákà, kí o sì pe ẹlẹ́rìí.’”
26 Och HERRENS ord kom till Jeremia han sade: Se,
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá pé:
27 jag är HERREN, allt kötts Gud; skulle något vara så underbart att jag icke förmådde det?
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run gbogbo ẹran-ara. Ǹjẹ́ ohun kan ha a ṣòro fún mi bí?
28 Därför säger HERREN så: Se, jag vill giva denna stad i kaldéernas och Nebukadressars, den babyloniske konungens, hand, och han skall intaga den.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí, Èmi ṣetán láti fi ìlú yìí fún àwọn ará Kaldea àti fún Nebukadnessari ọba Babeli ẹni tí yóò kó o.
29 Och kaldéerna, som belägra denna stad, skola komma och tända eld på staden och bränna upp den, tillika med de hus på vilkas tak man har tänt offereld åt Baal och utgjutit drickoffer åt andra gudar, till att förtörna mig.
Àwọn ará Kaldea tí ó ń gbógun tí ìlú yóò wọ ìlú. Wọn ó sì fi iná sí ìlú; wọn ó jó o palẹ̀ pẹ̀lú ilé tí àwọn ènìyàn ti ń mú mi bínú, tí wọ́n ń rú ẹbọ tùràrí lórí pẹpẹ fún Baali tiwọn sì ń da ẹbọ ohun mímu fún àwọn ọlọ́run mìíràn.
30 Ty allt ifrån sin ungdom hava Israels barn och Juda barn allenast gjort vad ont är i mina ögon; ja, Israels barn hava med sina händers verk berett mig allenast förtörnelse, säger HERREN.
“Àwọn ènìyàn Israẹli àti Juda kò ṣe ohun kankan bí kò ṣe ibi lójú mi láti ìgbà èwe wọn. Nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti fi kìkì iṣẹ́ ọwọ́ wọ́n mú mi bínú ni Olúwa wí.
31 Ty allt ifrån den dag då denna stad byggdes ända till nu har den uppväckt min vrede och förtörnelse, så att jag måste förkasta den från mitt ansikte,
Láti ọjọ́ tí wọ́n ti kọ́ ọ, títí di àkókò yìí ni ìlú yìí ti jẹ́ ohun ìbínú àti ìyọnu fún mi tó bẹ́ẹ̀ tí èmi yóò fà á tu kúrò níwájú mi.
32 för all den ondskas skull som Israels barn och Juda barn med sina konungar, furstar, präster och profeter, både Juda män och Jerusalems invånare, hava bedrivit, till att förtörna mig.
Àwọn ènìyàn Israẹli àti àwọn ènìyàn Juda ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ìbàjẹ́ tí wọ́n ṣe. Àwọn Israẹli, ọba wọn àti gbogbo ìjòyè, àlùfáà àti wòlíì, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu.
33 De vände ryggen till mig och icke ansiktet; och fastän de titt och ofta blevo varnade, ville de icke höra och taga emot tuktan.
Wọ́n kọ ẹ̀yìn sí mi, wọ́n sì yí ojú wọn padà. Èmi kọ wọ́n, síbẹ̀ wọn kò fetísílẹ̀ láti gbọ́ ẹ̀kọ́ tàbí kọbi ara sí ìwà ìbàjẹ́.
34 De satte upp sina styggelser i det hus som är uppkallat efter mitt namn och orenade det så;
Wọ́n kó òrìṣà ìríra wọn jọ sí inú ilé tí wọ́n fi orúkọ mi pè, wọ́n sì ṣọ́ di àìmọ́.
35 och Baalshöjderna i Hinnoms sons dal byggde de upp, för att där offra sina söner och döttrar åt Molok, fastän jag aldrig hade bjudit dem att göra sådan styggelse eller ens tänkt mig något sådant; och så förledde de Juda till synd.
Wọ́n kọ́ ibi gíga fún Baali ní àfonífojì Hinnomu láti fi ọmọ wọn ọkùnrin àti obìnrin rú ẹbọ sí Moleki. Èmi kò pàṣẹ, fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò wá sí ọkàn mi pé kí wọ́n ṣe ohun ìríra wọ̀nyí tí ó sì mú Juda dẹ́ṣẹ̀.
36 Men så säger nu HERREN, Israels Gud, om denna stad, som I menen vara genom svärd, hungersnöd och pest given i den babyloniske konungens hand:
“Ìwọ ń sọ̀rọ̀ nípa ti ìlú yìí pé, ‘Pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn ni à ó fi wọ́n fún ọba Babeli,’ ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ nìyìí,
37 Se, jag skall församla dem ur alla de länder till vilka jag i min vrede och harm och stora förtörnelse har fördrivit dem, och jag skall föra dem tillbaka till denna plats och låta dem bo bär i trygghet.
Èmi ó kó wọn jọ láti gbogbo ilẹ̀ tí mo ti lé wọn kúrò ní ìgbà ìbínú àti ìkáàánú ńlá mi. Èmi yóò mú wọn padà wá sí ilẹ̀ yìí; èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó máa gbé láìléwu.
38 Och de skola vara mitt folk, och jag skall vara deras Gud.
Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
39 Och jag skall giva dem alla ett och samma hjärta och lära dem en och samma väg, så att de frukta mig beständigt; för att det må gå dem väl, och deras barn efter dem.
Èmi ó fún wọn ní ọkàn kan àti ìṣe kí wọn kí ó lè máa bẹ̀rù mi fún rere wọn àti fún rere àwọn ọmọ wọn tí ó tẹ̀lé wọn.
40 Och jag skall sluta med dem ett evigt förbund, så att jag icke upp hör att följa dem och göra dem gott; och min fruktan skall jag ingiva i deras hjärtan, så att de icke vika av ifrån mig.
Èmi ò bá wọn dá májẹ̀mú ayérayé, èmi kò ní dúró láti ṣe rere fún wọn, Èmi ó sì jẹ́ kí wọ́n bẹ̀rù mi, wọn kì yóò sì padà lẹ́yìn mi.
41 Och jag skall hava min fröjd i att göra dem gott, och skall plantera dem i detta land med trofasthet, av allt mitt hjärta och all min själ.
Lóòtítọ́, èmi ó yọ̀ nípa ṣíṣe wọ́n ní rere, èmi ó sì fi dá wọn lójú nípa gbígbìn wọ́n sí ilẹ̀ yìí tọkàntọkàn mi.
42 Ty så säger HERREN: Likasom jag har låtit all denna stora olycka komma över detta folk, så skall jag ock låta allt det goda som jag lovade dem komma dem till del.
“Nítorí báyìí ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú gbogbo ibi ńlá yìí wá sórí àwọn ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó mú gbogbo rere tí èmi ti sọ nípa tiwọn wá sórí wọn.
43 Och man skall komma att köpa åkrar i detta land, om vilket I sägen att det är en ödemark, där varken människor eller djur kunna bo, och att det är givet i kaldéernas hand.
Lẹ́ẹ̀kan sí i, pápá yóò di rírà ní ilẹ̀ yìí tí ìwọ ti sọ pé, ‘Ohun òfò ni tí kò bá sí ọkùnrin tàbí àwọn ẹran, nítorí tí a ti fi fún àwọn ará Babeli.’
44 Ja, åkrar skall man köpa för penningar, och man skall skriva och försegla köpebrev och tillkalla vittnen i Benjamins land, i Jerusalems omnejd och i Juda städer, både i Bergsbygdens och i Låglandets och i Sydlandets städer; ty jag skall åter upprätta dem, säger HERREN.
Wọn ó fi owó fàdákà ra oko, wọn yóò fi ọwọ́ sí ìwé, wọn ó dí pa pẹ̀lú ẹlẹ́rìí láti ilẹ̀ Benjamini àti ní ìlú kéékèèké tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda àti ní ìlú àwọn ìlú orí òkè, àti ni àwọn ẹsẹ̀ òkè, àti ní gúúsù, èmi ó mú ìgbèkùn wọn padà wá, ni Olúwa wí.”

< Jeremia 32 >