< Jeremia 12 >
1 HERRE, om jag vill gå till rätta med dig, så behåller du dock rätten. Likväl måste jag tala med dig om vad rätt är. Varför går det de ogudaktiga så väl? Varför hava alla trolösa så god lycka?
Olúwa, olódodo ni ọ́ nígbàkígbà, nígbà tí mo mú ẹjọ́ kan tọ̀ ọ́ wá. Síbẹ̀ èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀ nípa òdodo rẹ. Èéṣe tí ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú fi ń ṣe déédé? Èéṣe tí gbogbo àwọn aláìṣòdodo sì ń gbé ní ìrọ̀rùn?
2 Du planterar dem, och de slå rot; de växa och bära frukt. Nära är du i deras mun, men fjärran är du från deras innersta.
Ó ti gbìn wọ́n, wọ́n sì ti fi egbò múlẹ̀, wọ́n dàgbà wọ́n sì so èso. Gbogbo ìgbà ni ó wà ní ètè wọn, o jìnnà sí ọkàn wọn.
3 Men du, HERRE, känner mig; du ser mig och prövar huru mitt hjärta är mot dig. Ryck dem bort såsom får till att slaktas, och invig dem till en dödens dag.
Síbẹ̀ o mọ̀ mí ní Olúwa, o ti rí mi o sì ti dán èrò mi nípa rẹ wò. Wọ, wọ́n lọ bí àgùntàn tí a fẹ́ pa. Yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ọjọ́ pípa.
4 Huru länge skall landet ligga sörjande och gräset på marken allestädes förtorka, så att både fyrfotadjur och fåglar förgås för inbyggarnas ondskas skull, under det att dessa säga: »Han skall icke se vår undergång»
Yóò ti pẹ́ tó tí ọ̀gbẹlẹ̀ yóò fi wà, tí gbogbo ewéko igbó sì ń rọ? Nítorí àwọn ènìyàn búburú ni ó ń gbé ibẹ̀. Àwọn ẹranko àti àwọn ẹyẹ ti ṣègbé, pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ènìyàn ń sọ pé, “Kò lè rí ohun tó ṣẹlẹ̀ sí wa.”
5 Om du icke orkar löpa i kapp med fotgängare, huru vill du då taga upp tävlan med hästar? Och om du nu känner dig trygg i ett fredligt land, huru skall det gå dig bland Jordanbygdens snår?
Bí ìwọ bá ń bá ẹlẹ́ṣẹ̀ sáré, tí àárẹ̀ sì mú ọ, báwo ni ìwọ yóò ṣe bá ẹṣin díje? Bí ìwọ bá kọsẹ̀ ní ilẹ̀ àlàáfíà, bí ìwọ bá ní ìgbẹ́kẹ̀lé, kí ni ìwọ ó ṣe nínú ẹkùn odò Jordani?
6 Se, till och med dina bröder och din faders hus äro ju trolösa mot dig; till och med dessa ropa med full hals bakom din rygg. Du må icke tro på dem, om de ock tala vänligt till dig.
Àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn ìdílé ti dà ọ́, kódà wọ́n ti kẹ̀yìn sí ọ, wọ́n ti hó lé ọ lórí. Má ṣe gbà wọ́n gbọ́ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ń sọ̀rọ̀ rẹ dáradára.
7 Jag har övergivit mitt hus, förskjutit min arvedel; det som var kärast för min själ lämnade jag i fiendehand.
Èmi yóò kọ ilé mi sílẹ̀, èmi yóò fi ìní mi sílẹ̀. Èmi yóò fi ẹni tí mo fẹ́ lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.
8 Hon som är min arvedel blev mot mig såsom ett lejon i skogen; hon har höjt sin röst mot mig, därför har jag fattat hat till henne.
Ogún mi ti rí sí mi bí i kìnnìún nínú igbó. Ó ń bú ramúramù mọ́ mi; nítorí náà mo kórìíra rẹ̀.
9 Skall min arvedel vara mot mig såsom en brokig rovfågel -- då må ock rovfåglar komma emot henne från alla sidor. Upp, samlen tillhopa alla markens djur, och låten dem komma för att äta!
Ogún mi kò ha ti rí sí mi bí ẹyẹ kannakánná tí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ dòyì ka, tí wọ́n sì kọjú ìjà sí i? Ẹ lọ, kí ẹ sì kó gbogbo ẹranko igbó jọ, ẹ mú wọn wá jẹ.
10 Herdar i mängd fördärva min vingård och förtrampa min åker; de göra min sköna åker till en öde öken. Man gör den till en ödemark;
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùṣọ́-àgùntàn ni yóò sì ba ọgbà àjàrà mi jẹ́, tí wọn yóò sì tẹ oko mi mọ́lẹ̀; wọ́n ó sọ oko dídára mi di ibi tí a ń da ìdọ̀tí sí.
11 sörjande och öde ligger den framför mig. Hela landet ödelägges, ty ingen finnes, som vill akta på.
A ó sọ ọ́ di aṣálẹ̀ ilẹ̀ tí kò wúlò níwájú mi, gbogbo ilẹ̀ ni yóò di ahoro nítorí kò sí ẹnìkankan tí yóò náání.
12 Över alla höjder i öknen rycka förhärjare fram, ja, HERRENS svärd förtär allt, från den ena ändan av landet till den andra; intet kött kan finna räddning.
Gbogbo ibi gíga tí ó wà nínú aṣálẹ̀ ni àwọn apanirun ti gorí, nítorí idà Olúwa yóò pa láti ìkangun kìn-ín-ní dé ìkangun èkejì ilẹ̀ náà; kò sí àlàáfíà fún gbogbo alààyè.
13 De hava sått vete, men skördat tistel; de hava mödat sig fåfängt. Ja, I skolen komma på skam med eder gröda för HERRENS glödande vredes skull.
Àlìkámà ni wọn yóò gbìn, ṣùgbọ́n ẹ̀gún ni wọn yóò ká, wọn yóò fi ara wọn ṣe wàhálà, ṣùgbọ́n òfo ni èrè wọn. Kí ojú kí ó tì yín nítorí èrè yín, nítorí ìbínú gbígbóná Olúwa.
14 Så säger HERREN om alla de onda grannar som förgripa sig på den arvedel jag har givit åt mitt folk Israel: Se, jag skall rycka dem bort ur deras land, och Juda hus skall jag rycka undan ifrån dem.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ní ti gbogbo àwọn aládùúgbò mi búburú tí wọ́n gbẹ́sẹ̀ lé ogún tí mo fún àwọn ènìyàn Israẹli mi, Èmi yóò fà wọ́n tu kúrò lórí ilẹ̀ wọn, èmi yóò fa ìdílé Juda tu kúrò ní àárín wọn.
15 Men därefter, sedan jag har ryckt dem bort, skall jag åter förbarma mig över dem och låta dem komma tillbaka, var och en till sin arvedel och var och en till sitt land.
Ṣùgbọ́n tí mo bá fà wọ́n tu tán, Èmi yóò padà yọ́nú sí wọn. Èmi yóò sì padà fún oníkálùkù ní ogún ìní rẹ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ ìní oníkálùkù.
16 Om de då rätt lära sig mitt folks vägar, så att de svärja vid mitt namn: »Så sant HERREN lever», likasom de förut lärde mitt folk att svärja vid Baal, då skola de bliva upprättade mitt ibland mitt folk.
Bí wọ́n bá sì kọ ìwà àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì fi orúkọ mi búra wí pé, ‘Níwọ̀n bí Olúwa ń bẹ láààyè,’ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti kọ́ àwọn ènìyàn mi láti fi Baali búra, nígbà náà ni a ó gbé wọn ró láàrín àwọn ènìyàn mi.
17 Men om de icke vilja höra, så skall jag alldeles bortrycka och förgöra det folket, säger HERREN.
Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kan kò bá gbọ́, Èmi yóò fà á tu pátápátá, èmi yóò sì pa wọ́n run,” ni Olúwa wí.