< Jesaja 66 >

1 Så säger HERREN: Himmelen är min tron, och jorden är min fotapall; vad för ett hus skullen I då kunna bygga åt mig, och vad för en plats skulle tjäna mig till vilostad?
Báyìí ni Olúwa wí: “Ọ̀run ni ìtẹ́ mi, ayé sì ni àpótí ìtìsẹ̀ mi. Níbo ni ilé tí ẹ ó kọ́ fún mi wà? Níbo ní ibi ìsinmi mi yóò gbé wà?
2 Min hand har ju gjort allt detta, och så har allt detta blivit till, säger HERREN. Men till den skådar jag ned, som är betryckt och har en förkrossad ande, och till den som fruktar för mitt ord.
Kì í ha á ṣe ọwọ́ mi ló tí ṣe nǹkan wọ̀nyí, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì wà?” ni Olúwa wí. “Eléyìí ni ẹni tí mo kà sí: ẹni náà tí ó rẹra rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì kẹ́dùn ní ọkàn rẹ̀, tí ó sì wárìrì sí ọ̀rọ̀ mi.
3 Den däremot, som slaktar sin offertjur, men ock är en mandråpare, den som offrar sitt lamm, men tillika krossar nacken på en hund, den som frambär ett spisoffer, men därvid frambär svinblod, den som offrar rökelse, men därunder hyllar en fåfänglig avgud -- likasom det lyster dessa att gå sina egna vägar och likasom deras själ har behag till deras styggelser,
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fi akọ màlúù rú ẹbọ ó dàbí ẹni tí ó pa ènìyàn kan àti ẹni tí ó bá fi ọ̀dọ́-àgùntàn kan tọrẹ, dàbí ẹni tí ó bẹ́ ajá kan lọ́rùn; ẹnikẹ́ni tí ó bá fi irúgbìn ìyẹ̀fun tọrẹ dàbí ẹni tí ó mú ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ wá, ẹni tí ó bá sì sun tùràrí ìrántí, dàbí ẹni tí ó súre fún òrìṣà. Wọ́n ti yan ipa ọ̀nà tì wọ́n, ọkàn wọn pẹ̀lú sì láyọ̀ nínú ohun ìríra wọn,
4 så lyster det ock mig att fara illa fram med dem och att låta förskräckelse komma över dem, eftersom ingen svarade, när jag kallade, och eftersom de icke hörde, när jag talade, utan gjorde, vad ont var i mina ögon, och hade sin lust i att göra, vad mig misshagligt var.
fún ìdí èyí ni èmi pẹ̀lú yóò ṣe fi ọwọ́ líle mú wọn n ó sì mú ohun tí wọ́n bẹ̀rù rẹ̀ wá sórí wọn. Nítorí nígbà tí mo pè, kò sí ẹni tí ó dáhùn, nígbà tí mo sọ̀rọ̀, ẹnikẹ́ni kò tẹ́tí sílẹ̀. Wọ́n ṣe ohun búburú ní ojú mi wọ́n sì yan ohun tí mo kórìíra rẹ̀.”
5 Hören HERRENS ord, I som frukten för hans ord. Edra bröder, som hata eder och stöta eder bort för mitt namns skull, de säga: »Må HERREN förhärliga sig, så att vi få se eder glädje.» Men de skola komma på skam.
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin tí ẹ ń wárìrì nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀: “Àwọn arákùnrin yín tí wọ́n kórìíra yín, tí wọ́n ta yín nù nítorí orúkọ mi, wí pé, ‘Jẹ́ kí a yin Olúwa lógo, kí a le rí ayọ̀ yín!’ Ṣùgbọ́n àwọn ni ojú yóò tì.
6 Hör, huru det larmar i staden, hör dånet i templet! Hör dånet, när HERREN vedergäller sina fiender, vad de hava gjort!
Gbọ́ rògbòdìyàn láti ìlú wá, gbọ́ ariwo náà láti tẹmpili wá! Ariwo tí Olúwa ní í ṣe tí ó ń san án fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí wọn.
7 Innan Sion har känt någon födslovånda, föder hon barnet; innan kval har kommit över henne, bliver hon förlöst med ett gossebarn.
“Kí ó tó lọ sí ìrọbí, ó ti bímọ; kí ó tó di pé ìrora dé bá a, ó ti bí ọmọkùnrin.
8 Vem har hört något sådant, vem har sett något dylikt? Kan då ett land komma till liv på en enda dag, eller kan ett folk födas i ett ögonblick, eftersom Sion födde fram sina barn, just då våndan begynte?
Ta ni ó ti gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí? Ta ni ó ti rí irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a le bí orílẹ̀-èdè kan níjọ́ kan tàbí kí orílẹ̀-èdè lalẹ̀hù ní ìṣẹ́jú kan? Síbẹ̀síbẹ̀ Sioni bẹ̀rẹ̀ rírọbí bẹ́ẹ̀ ni ó sì bí àwọn ọmọ rẹ̀.
9 Ja, ty skulle jag väl låta fostret bliva fullgånget, men icke giva kraft att föda fram det? säger HERREN. Eller skulle jag giva kraft att föda, men sedan hålla fostret tillbaka? säger din Gud.
Ǹjẹ́ èmi a ha máa mú wá sí ìrọbí kí èmi má sì mú ni bí?” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ èmi a ha máa ṣé ilé ọmọ nígbà tí mo ń mú ìbí wá?” Ni Ọlọ́run yín wí.
10 Glädjens med Jerusalem och fröjden eder över henne, alla I som haven henne kär; jublen högt med henne, alla I som haven sörjt över henne.
“Ẹ bá Jerusalẹmu yọ̀ kí inú yín kí ó sì dùn sí i, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn rẹ̀; ẹ yọ̀ gidigidi pẹ̀lú rẹ̀, gbogbo ẹ̀yin tí ó ti kẹ́dùn fún un.
11 Så skolen I få dia eder mätta vid hennes hugsvalelses bröst; så skolen I få suga med lust av hennes rika barm.
Nítorí pé ẹ̀yin yóò mu ẹ o sì ní ìtẹ́lọ́rùn nínú ọmú rẹ̀ tí ó tu ni lára, ẹ̀yin yóò mu àmuyó ẹ ó sì gbádùn nínú àkúnwọ́sílẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ rẹ̀.”
12 Ty så säger HERREN: Se, jag vill låta frid komma över henne såsom en ström och folkens rikedomar såsom en översvämmande flod, och I skolen så få dia, I skolen bliva burna på armen och skolen få sitta i knäet och bliva smekta.
Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Èmi yóò fún un ní àlàáfíà gẹ́gẹ́ bí odò àti ọrọ̀ orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí ìṣàn omi; ẹ̀yin yóò mu ọmú, a ó sì gbé yín ní apá rẹ̀ a ó bá yín ṣeré ní orúkún rẹ̀.
13 Såsom en moder tröstar sin son, så skall jag trösta eder; ja, i Jerusalem skolen I få tröst.
Gẹ́gẹ́ bí ìyá ti í tu ọmọ rẹ̀ nínú, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò tù yín nínú a ó sì tù yín nínú lórí Jerusalẹmu.”
14 Och edra hjärtan skola glädja sig, när I fån se detta, och benen i edra kroppar skola hava livskraft såsom spirande gräs; och man skall förnimma, att HERRENS hand är med hans tjänare och att ogunst kommer över hans fiender.
Nígbà tí ẹ bá rí èyí, inú yín yóò dùn ẹ̀yin yóò sì gbilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí i koríko; ọwọ́ Olúwa ni a ó sọ di mí mọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ ni a ó fihàn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀.
15 Ty se, HERREN skall komma i eld, och hans vagnar skola vara såsom en stormvind; och han skall låta sin vrede drabba med hetta och sin näpst med eldslågor.
Kíyèsi i, Olúwa ń bọ̀ pẹ̀lú iná àti kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ tí ó dàbí ìjì líle; òun yóò mú ìbínú rẹ sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ìrunú, àti ìbáwí rẹ̀ pẹ̀lú ahọ́n iná.
16 Ty HERREN skall hålla dom med eld, och med sitt svärd skall han slå allt kött, och många skola de vara, som bliva slagna av HERREN.
Nítorí pẹ̀lú iná àti idà ni Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ lórí i gbogbo ènìyàn, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí Olúwa yóò pa.
17 De som låta inviga sig och rena sig till gudstjänst i lustgårdar, anförda av en som står där i mitten, de som äta svinkött och annan styggelse, ja, också möss, de skola allasammans förgås, säger HERREN.
“Gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sí mímọ́ tí wọ́n sì sọ ara wọn di mímọ́ láti lọ sínú ọgbà, tí wọ́n tẹ̀lé ẹni tí ó wà láàrín àwọn tí ó jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀ àti èkúté àti àwọn ohun ìríra mìíràn ni wọn yóò bá òpin wọn pàdé papọ̀,” ni Olúwa wí.
18 Jag känner deras gärningar och tankar. Den tid kommer, då jag skall församla alla folk och tungomål; och de skola komma och se min härlighet.
“Àti Èmi, nítorí ìgbésẹ̀ wọn àti èrò wọn, èmi ti múra tán láti wá kó àwọn orílẹ̀-èdè àti ahọ́n jọ, wọn yóò sì wá wo ògo mi.
19 Och jag skall göra ett tecken bland dem; och några av dem som bliva räddade skall jag sända såsom budbärare till hednafolken, till Tarsis, till Pul och Lud, bågskyttfolken, till Tubal och Javan, till havsländerna i fjärran, som icke hava hört något om mig eller sett min härlighet; och de skola förkunna min härlighet bland folken.
“Èmi yóò sì gbé àmì kan kalẹ̀ láàrín wọn, èmi yóò sì rán díẹ̀ nínú àwọn tí ó sálà lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè Tarṣiṣi, sí àwọn ará Libia àti Ludi, sí Tubali àti ará Giriki, àti sí àwọn erékùṣù tí ó jìnnà réré tí kò tí ìgbọ́ nípa òkìkí mi tàbí kí ó rí ògo mi. Wọn yóò kéde ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
20 Och på hästar och i vagnar och bärstolar och på mulåsnor och dromedarer skola de från alla folk föra alla edra bröder fram till mitt heliga berg i Jerusalem såsom ett spisoffer åt HERREN, säger HERREN, likasom Israels barn i rena kärl föra fram spisoffer till HERRENS hus.
Wọn yóò sì mú àwọn arákùnrin yín wá, láti gbogbo orílẹ̀-èdè, sí òkè mímọ́ mi ní Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọrẹ sí Olúwa lórí ẹṣin, lórí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti ọkọ̀-ẹṣin, àti lórí ìbáaka àti ìbákasẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn yóò kó wọn wá, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli ti mú ọrẹ oníhóró wọn wá, sínú Tẹmpili Olúwa nínú ohun èlò mímọ́.
21 Och jämväl sådana skall jag taga till mina präster, till mina leviter, säger HERREN.
Àti pé èmi yóò sì yan àwọn kan nínú wọn pẹ̀lú láti jẹ́ àlùfáà àti Lefi,” ni Olúwa wí.
22 Ty likasom de nya himlar och den nya jord, som jag vill göra, bliva beståndande inför mig, säger HERREN, så skall det ock vara med edra barn och med edert namn.
“Gẹ́gẹ́ bí àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun tí mo dá yóò ṣe wà níwájú mi títí láé,” ni Olúwa wí, “Bẹ́ẹ̀ ni orúkọ yín àti ìrandíran yín yóò pegedé.
23 Och nymånadsdag efter nymånadsdag och sabbatsdag efter sabbatsdag skall det ske, att allt kött kommer och tillbeder inför mig, säger HERREN.
Láti oṣù tuntun kan dé òmíràn àti láti ọjọ́ ìsinmi kan dé òmíràn, ni gbogbo ọmọ ènìyàn yóò wá, wọn yóò sì tẹríba níwájú mi,” ni Olúwa wí.
24 Och man skall gå ut och se med lust, huru de människor, som avföllo från mig, nu ligga där döda; ty deras mask skall icke dö, och deras eld skall icke utsläckas, och de skola vara till vämjelse för allt kött. Se Lustgård i Ordförkl.
“Wọn yóò sì jáde lọ wọn yóò sì lọ wo òkú àwọn tí wọ́n dìtẹ̀ sí mi; kòkòrò wọn kì yóò kú, bẹ́ẹ̀ ni iná wọn ni a kì yóò pa, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jẹ́ ohun ìríra fún gbogbo ọmọ ènìyàn.”

< Jesaja 66 >